< 1 Mojzes 48 >

1 Pripetilo se je po teh stvareh, da je Jožefu nekdo povedal: »Poglej, tvoj oče je bolan, « in ta je s seboj vzel svoja dva sinova, Manáseja in Efrájima.
Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀ si, a wí fún Josẹfu pé, “Baba rẹ ń ṣàìsàn,” nítorí náà, ó mú àwọn ọmọ rẹ̀ méjèèjì, Manase àti Efraimu lọ́wọ́ lọ pẹ̀lú rẹ̀.
2 In nekdo je Jakobu povedal ter rekel: »Glej, tvoj sin Jožef prihaja k tebi.« Izrael se je okrepil in se usedel na postelji.
Nígbà tí a sọ fún Jakọbu pé, “Josẹfu ọmọ rẹ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ,” Israẹli rọ́jú dìde jókòó lórí ibùsùn rẹ̀.
3 Jakob je Jožefu rekel: »Bog Vsemogočni se mi je prikazal pri Luzu, v kánaanski deželi, me blagoslovil
Jakọbu wí fún Josẹfu pé, “El-Ṣaddai, fi ara hàn mí ní Lusi ní ilẹ̀ Kenaani, níbẹ̀ ni ó sì ti súre fún mi.
4 in mi rekel: ›Glej, jaz te bom naredil rodovitnega in te namnožil in jaz bom iz tebe naredil množico ljudstev in to deželo bom dal tvojemu semenu za teboj za večno posest.‹
Ó sì wí fún mi pé, ‘Èmi yóò mú kí o bí sí i, ìwọ yóò sì pọ̀ sí i, èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, èmi yóò sì fún ìwọ àti irú-ọmọ rẹ lẹ́yìn rẹ ní ilẹ̀ yìí gẹ́gẹ́ bí ohun ìní ayérayé.’
5 In sedaj, tvoja dva sinova, Efrájim in Manáse, ki sta ti bila rojena v egiptovski deželi, preden sem prišel k tebi v Egipt, sta moja; kakor Ruben in Simeon, bosta moja.
“Nítorí náà báyìí, àwọn ọmọ rẹ méjèèjì tí a bí fún ọ ní ilẹ̀ Ejibiti, kí èmi kí ó tó tọ̀ ọ́ wá ní ìhín, ni mo sọ di ọmọ mi fúnra mi. Manase àti Efraimu yóò jẹ́ tèmi gẹ́gẹ́ bí Reubeni àti Simeoni ti jẹ́ tèmi.
6 Tvoji potomci pa, ki jih boš zaplodil za njima, bodo tvoji in imenovani bodo po imenu svojih bratov v svoji dediščini.
Àwọn ọmọ mìíràn tí ìwọ bá bí lẹ́yìn wọn yóò jẹ́ ọmọ rẹ. Ní ilẹ̀ tí wọn yóò jogún, orúkọ arákùnrin wọn ni a ó máa fi pè wọ́n.
7 Kar pa se mene tiče, ko sem prišel iz Padana, je v kánaanski deželi poleg mene umrla Rahela, na poti, ko je bilo le še malo poti, da pride v Efráto. Pokopal sem jo tam, na poti v Efráto; ta isti je Betlehem.«
Bí mo ti ń padà láti Padani, Rakeli kú ní ọ̀nà nígbà tí ó ṣì wà ní ilẹ̀ Kenaani, èyí tó mú ìbànújẹ́ bá mi, níbi tí kò jìnnà sí Efrata. Nítorí náà èmí sì sin ín sí ẹ̀bá ọ̀nà tí ó lọ sí Efrata” (tí ṣe Bẹtilẹhẹmu).
8 Izrael je zagledal Jožefova sinova in rekel: »Kdo sta ta [dva]?«
Nígbà tí Israẹli rí àwọn ọmọ Josẹfu, ó béèrè wí pé, “Àwọn wo nìyí?”
9 Jožef je svojemu očetu rekel: »Onadva sta moja sinova, katera mi ju je Bog dal na tem kraju.« Rekel je: »Privedi ju, prosim te, k meni in jaz ju bom blagoslovil.«
Josẹfu fún baba rẹ̀ lésì pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Ọlọ́run ti fi fún mi ní ìhín.” Nígbà náà ni Israẹli wí pé, “Kó wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi kí èmi kí ó ba à le súre fún wọn.”
10 Torej, Izraelove oči so bile od starosti zatemnjene, tako da ni mogel videti. In privedel ju je bliže k njemu in on ju je poljubil ter ju objel.
Báyìí, ojú Israẹli ti ń di bàìbàì nítorí ogbó, agbára káká sì ni ó fi ń ríran. Josẹfu sì kó àwọn ọmọ rẹ̀ súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, baba rẹ̀ fẹnukò wọ́n ni ẹnu, ó sì dì mọ́ wọn.
11 Izrael je Jožefu rekel: »Nisem si mislil, da bom videl tvoj obraz in, glej, Bog mi je pokazal tudi tvoje seme.«
Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Èmi kò lérò rárá pé, mo tún le rí ojú rẹ mọ́ láéláé, ṣùgbọ́n Ọlọ́run tún fún mi ní àǹfààní, mo sì tún rí àwọn ọmọ rẹ pẹ̀lú.”
12 Jožef ju je prestavil izmed svojih kolen in se sam, s svojim obrazom, priklonil k zemlji.
Nígbà náà ni Josẹfu kó àwọn ọmọ náà kúrò ní orí eékún baba rẹ̀, ó wólẹ̀, ó sì tẹríba.
13 Jožef je prijel oba, Efrájima na svojo desnico proti Izraelovi levici in Manáseja na svojo levico proti Izraelovi desnici in ju privedel k njemu.
Josẹfu sì mú àwọn méjèèjì, Efraimu ni o fi sí ọwọ́ ọ̀tún òun tìkára rẹ̀, èyí tí í ṣe ọwọ́ òsì fún Israẹli, ó sì fi Manase sí ọwọ́ òsì ara rẹ̀, èyí tí ó bọ́ sí ọwọ́ ọ̀tún Israẹli.
14 Izrael je iztegnil svojo desnico in jo položil na Efrájimovo glavo, ki je bil mlajši, svojo levico pa na Manásejevo glavo, premišljeno vodeč svoji roki, kajti Manáse je bil prvorojenec.
Israẹli sì na ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ jáde, ó sì gbe lé Efraimu lórí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun ni àbúrò, ó sì fi ọwọ́ rẹ̀ tàsé ara wọn, ó sì na ọwọ́ òsì lé Manase lórí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Manase ni àkọ́bí.
15 Blagoslovil je Jožefa in rekel: »Bog, pred katerim sta hodila moja očeta, Abraham in Izak, Bog, ki me je hranil vse moje dolgo življenje do današnjega dne,
Nígbà náà ni ó súre fún Josẹfu wí pé, “Ǹjẹ́ kí Ọlọ́run, ẹni tí baba mi Abrahamu àti Isaaki rìn níwájú rẹ̀, Ọlọ́run tí ó ti jẹ́ olùtọ́jú àti aláàbò mi ní gbogbo ọjọ́ ayé mi títí di òní,
16 angel, ki me je odkupil od vsega zla, naj blagoslovi dečka. Naj bo moje ime imenovano na njiju in ime mojih očetov, Abrahama in Izaka. Naj zrasteta v množico na sredi zemlje.«
Angẹli tí ó dá mi ní ìdè kúrò lọ́wọ́ gbogbo ewu, kí ó súre fún àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí. Kí a máa fi orúkọ mi pè wọ́n àti orúkọ àwọn baba mi Abrahamu àti Isaaki, kí wọn kí ó sì pọ̀ sí i lọ́pọ̀lọ́pọ̀ lórí ilẹ̀ ayé.”
17 Ko je Jožef videl, da je njegov oče svojo desnico položil na Efrájimovo glavo, ga je to razžalilo in prijel je roko svojega očeta, da jo odmakne z Efrájimove glave na Manásejevo glavo.
Nígbà tí Josẹfu rí i pé baba òun gbé ọwọ́ ọ̀tún lé Efraimu lórí, inú rẹ̀ bàjẹ́, ó sì gbá ọwọ́ baba rẹ̀ mú láti gbé ọwọ́ rẹ̀ kúrò lórí Efraimu lọ sí orí Manase.
18 Jožef je svojemu očetu rekel: »Ne tako, moj oče, kajti ta je prvorojenec, svojo desnico položi na njegovo glavo.«
Josẹfu wí fun pé, “Rárá, baba mi, èyí ni àkọ́bí, orí rẹ̀ ni kí ìwọ kí o gbé ọwọ́ ọ̀tún rẹ lé.”
19 Njegov oče pa je odklonil in rekel: »Vem to, moj sin, vem to, tudi on bo postal ljudstvo in tudi on bo velik, toda njegov mlajši brat bo resnično večji kakor on in njegovo seme bo postalo množica narodov.«
Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ kò gbà, ó wí pé, “Mo mọ̀, ọmọ mi, mo mọ̀. Òun náà yóò di orílẹ̀-èdè, òun náà yóò sì di ńlá. Ṣùgbọ́n àbúrò rẹ̀ yóò di ẹni ńlá jù ú lọ, irú-ọmọ rẹ yóò sì di ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè.”
20 Blagoslovil ju je ta dan, rekoč: »V tebi bo Izrael blagoslovljen, rekoč: ›Bog [naj] te naredi kakor Efrájima in kakor Manáseja‹« in Efrájima je postavil pred Manáseja.
Ó súre fún wọn lọ́jọ́ náà pé, “Ní orúkọ yín ni Israẹli yóò máa súre yìí pé, ‘Kí Ọlọ́run ṣe ọ́ bí i ti Efraimu àti Manase.’” Ó sì gbé Efraimu gẹ́gẹ́ bí ẹ̀gbọ́n sí Manase.
21 Izrael je rekel Jožefu: »Glej, jaz umrem, toda Bog bo z vami in vas bo ponovno privedel v deželo vaših očetov.
Nígbà náà ni Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Ọjọ́ ikú mi súnmọ́ etílé, ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò wà pẹ̀lú yín, yóò sì mú un yín padà sí ilẹ̀ àwọn baba yín.
22 Poleg tega sem ti dal en delež nad tvojimi brati, ki sem ga s svojim mečem in s svojim lokom vzel iz roke Amoréjcev.«
Pẹ̀lúpẹ̀lú èmi yóò fún ọ ní ìpín kan ju ti àwọn arákùnrin rẹ lọ. Ilẹ̀ tí mo fi idà àti ọ̀kọ̀ mi gbà lọ́wọ́ àwọn ará Amori.”

< 1 Mojzes 48 >