< 1 Mojzes 47 >

1 Potem je prišel Jožef in povedal faraonu ter rekel: »Moj oče, moji bratje, njihovi tropi, njihove črede in vse, kar imajo, so prišli iz kánaanske dežele. Glej, v gošenski deželi so.«
Josẹfu lọ sọ fún Farao pé, “Baba mi àti àwọn arákùnrin mi, pẹ̀lú agbo ẹran, agbo màlúù àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, ti dé láti ilẹ̀ Kenaani, wọ́n sì ti wà ní ilẹ̀ Goṣeni báyìí.”
2 Vzel je nekatere izmed svojih bratov, pet mož in jih predstavil faraonu.
Ó yan márùn-ún àwọn arákùnrin rẹ́, ó sì fi wọ́n han Farao.
3 Faraon je njegovim bratom rekel: »Kakšen je vaš poklic?« Faraonu so odgovorili: »Tvoji služabniki so pastirji, tako mi, kakor tudi naši očetje.«
Farao béèrè lọ́wọ́ àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Kí ni iṣẹ́ yín?” Wọ́n sì fèsì pé, “Darandaran ni àwọn ìránṣẹ́ rẹ, gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti jẹ́ darandaran.”
4 Poleg tega so faraonu rekli: »Zato smo prišli, da začasno prebivamo v deželi, kajti tvoji služabniki nimajo pašnika za svoje trope, kajti huda lakota je v kánaanski deželi. Sedaj te torej prosimo, naj tvoji služabniki prebivajo v gošenski deželi.«
Wọ́n sì tún sọ fun un síwájú sí i pé, “A wá láti gbé ìhín yìí fún ìgbà díẹ̀ nítorí ìyàn náà mú púpọ̀ ní ilẹ̀ Kenaani, àwọn ohun ọ̀sìn àwa ìránṣẹ́ rẹ kò sì rí ewéko jẹ. Nítorí náà jọ̀wọ́ má ṣàì jẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ rẹ tẹ̀dó sí ilẹ̀ Goṣeni.”
5 Faraon je Jožefu spregovoril, rekoč: »Tvoj oče in tvoji bratje so prišli k tebi.
Farao wí fún Josẹfu pé, “Baba rẹ àti àwọn arákùnrin rẹ tọ̀ ọ́ wá,
6 Egiptovska dežela je pred teboj. V najboljši deželi pripravi svojemu očetu in bratom, da prebivajo. V gošenski deželi naj prebivajo in če poznaš med njimi katerekoli marljive ljudi, potem jih naredi gospodarje nad mojo živino.«
ilẹ̀ Ejibiti sì nìyí níwájú rẹ, mú àwọn arákùnrin rẹ tẹ̀dó sí ibi tí ó dára jù nínú ilẹ̀ náà. Jẹ́ kí wọn máa gbé ní Goṣeni. Bí o bá sì mọ ẹnikẹ́ni nínú wọn tí ó ní ẹ̀bùn ìtọ́jú ẹran, fi wọ́n ṣe olùtọ́jú ẹran ọ̀sìn mi.”
7 Jožef je privedel svojega očeta Jakoba in ga postavil pred faraona in Jakob je blagoslovil faraona.
Nígbà náà ni Josẹfu mú Jakọbu baba rẹ̀ wọlé wá sí iwájú Farao. Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu súre fún Farao tán.
8 Faraon je Jakobu rekel: »Koliko si star?«
Farao béèrè lọ́wọ́ Jakọbu pé, “Ọmọ ọdún mélòó ni ọ́?”
9 Jakob je faraonu rekel: »Dni let mojega popotovanja je sto trideset let. Malo in zli so bili dnevi let mojega življenja in nisem dosegel dni let življenja svojih očetov v dneh njihovega popotovanja.«
Jakọbu sì dá Farao lóhùn, “Ọdún ìrìnàjò ayé mi jẹ́ àádóje, ọjọ́ mi kò pọ̀, ó sì kún fún wàhálà, síbẹ̀ kò ì tí ì tó ti àwọn baba mi.”
10 Jakob je blagoslovil faraona in odšel izpred faraona.
Nígbà náà ni Jakọbu tún súre fún Farao, ó sì jáde lọ kúrò níwájú rẹ̀.
11 Jožef je namestil svojega očeta in svoje brate ter jim dal posest v egiptovski deželi, v najboljšem delu dežele, v Ramesésovi deželi, kakor je faraon zapovedal.
Josẹfu sì fi baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ sí ilẹ̀ Ejibiti, ó sì fún wọn ní ohun ìní ní ibi tí ó dára jù ní ilẹ̀ náà, ní agbègbè Ramesesi bí Farao ti pàṣẹ.
12 Jožef je vzdrževal svojega očeta, svoje brate in vso družino svojega očeta s kruhom, glede na njihove družine.
Josẹfu sì pèsè oúnjẹ fún baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi iye àwọn ọmọ wọn.
13 In ni bilo kruha v vsej deželi, kajti lakota je bila zelo huda, tako da je egiptovska dežela in vsa kánaanska dežela zaradi lakote slabela.
Ṣùgbọ́n kò sí oúnjẹ ní gbogbo ilẹ̀ náà nítorí tí ìyàn náà mú púpọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ Ejibiti àti ilẹ̀ Kenaani gbẹ nítorí ìyàn náà.
14 Jožef je zbral ves denar, ki se je našel v egiptovski deželi in v kánaanski deželi, za žito, ki so ga kupovali. In Jožef je denar prinesel v faraonovo hišo.
Josẹfu gba gbogbo owó tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti àti Kenaani ní ìpààrọ̀ fún ti ọkà tí wọn ń rà, ó sì mú owó náà wá sí ààfin Farao.
15 Ko pa je v egiptovski deželi in v kánaanski deželi zmanjkalo denarja, so vsi Egipčani prišli k Jožefu in rekli: »Daj nam kruha, kajti zakaj bi umrli v tvoji prisotnosti? Kajti denarja je zmanjkalo.«
Nígbà tí owó wọn tán pátápátá ní Ejibiti àti Kenaani, gbogbo Ejibiti wá bá Josẹfu, wọ́n wí pé, “Fún wa ní oúnjẹ, èéṣe tí a ó fi kú ní ojú rẹ? Gbogbo owó wa ni a ti ná tán.”
16 Jožef je rekel: »Dajte svojo živino in jaz vam bom dal za vašo živino, če je denarja zmanjkalo.«
Josẹfu wí pé, “Ẹ mú àwọn ẹran ọ̀sìn yín wá, èmi yóò fún un yín ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹran ọ̀sìn yín, níwọ̀n bí owó yín ti tan.”
17 Svojo živino so privedli k Jožefu in Jožef jim je dal kruha v zameno za konje in za trope in za živino od čred in za osle in to leto jih je nahranil s kruhom za vso njihovo živino.
Nítorí náà wọ́n mú àwọn ẹran ọ̀sìn wọn tọ Josẹfu wá, ó sì fún wọn ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹṣin, àgùntàn, ewúrẹ́, màlúù àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn. Ó sì mú wọn la ọdún náà já, tí ó ń fún wọn ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹran ọ̀sìn wọn.
18 Ko je bilo to leto končano, so prišli k njemu drugo leto in mu rekli: » Tega ne bomo skrivali pred mojim gospodom, da je naš denar porabljen. Moj gospod ima tudi naše črede in živino. Sploh ni veliko ostalo v očeh mojega gospoda, razen naših teles in naših zemljišč.
Nígbà tí ọdún náà parí, wọn padà tọ̀ ọ́ wá ní ọdún tí ó tẹ̀lé, wọn wí pé, “A kò le fi pamọ́ fun olúwa wa pé níwọ̀n bí owó wa ti tan tí gbogbo ẹran ọ̀sìn wa sì ti di tirẹ̀ pé, kò sí ohunkóhun tókù fún olúwa wa bí kò ṣe ara wa àti ilẹ̀ wa.
19 Zakaj bi umrli pred tvojimi očmi, tako mi kakor naša dežela? Kupi nas in našo deželo za kruh, pa bomo mi in naša dežela služabniki faraonu. Daj nam seme, da bomo lahko živeli in ne umrli, da dežela ne bo zapuščena.«
Èéṣe tí àwa yóò fi parun lójú rẹ, ra àwa tìkára wa àti ilẹ̀ wa ní ìpààrọ̀ fún oúnjẹ, àwa àti ilẹ̀ wa yóò sì wà nínú ìgbèkùn Farao. Fún wa ni oúnjẹ kí àwa kí ó má ba à kú, kí ilẹ̀ wa má ba à di ahoro.”
20 Jožef je vso egiptovsko deželo kupil za faraona, kajti Egipčani so prodali vsak človek svoje polje, ker je nad njimi prevladala lakota in tako je dežela postala faraonova.
Nítorí náà Josẹfu ra gbogbo ilẹ̀ tí ó wà ní Ejibiti fún Farao, kò sí ẹnìkan tí ó ṣẹ́kù ní Ejibiti tí kò ta ilẹ̀ tirẹ̀ nítorí ìyàn náà mú jù fún wọn. Gbogbo ilẹ̀ náà sì di ti Farao,
21 Kar se tiče ljudstva, jih je premestil v mesta, od enega konca egiptovskih meja, celo do drugega njegovega konca.
Josẹfu sì sọ gbogbo ará Ejibiti di ẹrú láti igun kan dé èkejì.
22 Samo zemljišč duhovnikov ni pokupil, kajti duhovniki so imeli od faraona njim določen delež in jedli svoj delež, ki jim ga je faraon dajal, zato svojih zemljišč niso prodali.
Ṣùgbọ́n ṣá, kò ra ilẹ̀ àwọn àlùfáà, nítorí wọ́n ń gba ìpín oúnjẹ lọ́wọ́ Farao, wọn sì ní oúnjẹ tí ó tó láti inú ìpín tí Farao ń fún wọn. Ìdí nìyí tí wọn kò fi ta ilẹ̀ wọn.
23 Potem je Jožef rekel ljudstvu: »Glejte, danes sem kupil vas in vašo deželo za faraona. Glejte, tukaj je seme za vas in vi boste posejali deželo.
Josẹfu wí fún àwọn ènìyàn náà pé, “Níwọ́n ìgbà tí mo ti ra ẹ̀yin àti ilẹ̀ yín tan lónìí fún Farao, irúgbìn rèé, ẹ lọ gbìn ín sí ilẹ̀ náà.
24 Z donosom se bo zgodilo, da boste peti del dali faraonu, štirje deli pa bodo vaši lastni, za seme polja in za vašo hrano in za tiste iz vaših družin in za hrano za vaše malčke.«
Ṣùgbọ́n nígbà tí ìre oko náà bá jáde, ẹ ó mú ìdákan nínú ìdámárùn-ún rẹ̀ fún Farao. Ẹ le pa ìdámẹ́rin tókù mọ́ fún ara yín àti ìdílé yín àti àwọn ọmọ yín.”
25 Rekli so: »Rešil si naša življenja. Naj najdemo milost v očeh mojega gospoda, mi pa bomo faraonovi služabniki.«
Wọ́n dá á lóhùn pé, “O ti gbà wá là, ǹjẹ́ kí a rí ojúrere níwájú olúwa wa, àwa yóò di ẹrú Farao.”
26 Jožef je to naredil v egiptovski deželi [za] zakon do današnjega dne, da bo imel faraon peti del, razen dežele duhovnikov, ki ni postala faraonova.
Nítorí náà Josẹfu sọ ọ́ di òfin nípa ọ̀rọ̀ ilẹ̀ ni Ejibiti, ó sì wà bẹ́ẹ̀ di òní olónìí pé, ìdákan nínú ìdámárùn-ún ìre oko jẹ́ ti Farao, ilẹ̀ àwọn àlùfáà nìkan ni kò di ti Farao.
27 Izrael je prebival v egiptovski deželi, v pokrajini Gošen in v njej so imeli posesti in rastli ter se silno pomnožili.
Àwọn ará Israẹli sì tẹ̀dó sí Ejibiti ní agbègbè Goṣeni. Wọ́n ní ohun ìní fún ara wọn, wọ́n sì bí sí i tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n pọ̀ si gidigidi ní iye.
28 Jakob je v egiptovski deželi živel sedemnajst let. Tako je bila celotna Jakobova starost sto sedeminštirideset let.
Jakọbu gbé ní Ejibiti fún ọdún mẹ́tàdínlógún iye ọdún ọjọ́ ayé rẹ̀ sì jẹ́ ẹẹ́tàdínlàádọ́jọ.
29 Približal se je čas, ko je Izrael moral umreti in poklical je svojega sina Jožefa ter mu rekel: »Če sem sedaj našel milost v tvojem pogledu, položi, prosim te, svojo roko pod moje stegno ter z menoj postopaj dobrotljivo in iskreno. Ne pokoplji me, prosim te, v Egiptu,
Nígbà tí àkókò ń súnmọ́ etílé fún Israẹli láti kú, ó pe Josẹfu, ọmọ rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Bí mo bá rí ojúrere ni ojú rẹ̀ fi ọwọ́ rẹ sí abẹ́ itan mi, kí o sì ṣe ìlérí pé ìwọ yóò fi àánú àti òtítọ́ hàn sí mi. Má ṣe sin òkú mi sí ilẹ̀ Ejibiti.
30 temveč hočem ležati s svojimi očeti in ti me boš odnesel iz Egipta in me pokopal na njihovem grobišču.« Rekel je: »Storil bom kakor si rekel.«
Ṣùgbọ́n, nígbà tí mo bá sinmi pẹ̀lú àwọn baba mi, gbé mí jáde kúrò ní Ejibiti kí o sì sin mí sí ibi tí wọ́n sin àwọn baba mi sí.” Josẹfu sì dáhùn wí pé, “Èmi ó ṣe bí ìwọ ti wí.”
31 Rekel je: »Prisezi mi.« In prisegel mu je. In Izrael se je priklonil na vzglavju postelje.
Jakọbu wí pé, “Búra fún mi,” Josẹfu sì búra fún un. Israẹli sì tẹ orí rẹ̀ ba, bí ó ti sinmi lé orí ibùsùn rẹ̀.

< 1 Mojzes 47 >