< 2 Књига дневника 2 >
1 И науми Соломун да зида дом имену Господњем и дом царски себи.
Solomoni pinnu láti kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa àti ilé kan fún ìjọba rẹ̀
2 И одброја Соломун седамдесет хиљада носилаца и осамдесет хиљада који ће тесати у гори, и три хиљаде и шест стотина настојника над њима.
Solomoni sì yan ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin àwọn ọkùnrin láti ru ẹrù àti ọ̀kẹ́ mẹ́rin àwọn ọkùnrin gẹ́gẹ́ bi olùgé-òkúta ní àwọn òkè àti ẹgbẹ̀rún mẹ́rìndínlógójì gẹ́gẹ́ bí àwọn alábojútó lórí wọn.
3 И посла Соломун ка Хираму, цару тирском, и поручи му: Како је чинио Давиду оцу мом и слао му дрва кедрових да зида себи кућу где ће седети, учини тако и мени.
Solomoni rán iṣẹ́ yìí sí Hiramu ọba Tire: “Rán àwọn igi kedari sí mi gẹ́gẹ́ bí o ti ṣe fún baba à mi Dafidi. Nígbà tí ó fi igi kedari ránṣẹ́ sí i láti kọ́ ààfin tí ó ń gbé.
4 Ево рад сам зидати дом имену Господа Бога свог да му га посветим да се кади пред њим кадом мирисним и да се постављају хлебови вазда и да се приносе жртве паљенице јутром и вечером, и у суботе и на младине и на празнике Господа Бога нашег, што треба да бива у Израиљу довека.
Nísinsin yìí, èmi n kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run mi àti láti yà á sí mímọ́ fún un àti láti sun tùràrí olóòórùn dídùn níwájú rẹ̀, fún gbígbé àkàrà ìfihàn ìgbàkúgbà, àti fún ṣíṣe ẹbọ sísun ní gbogbo àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́ àti ní ọjọọjọ́ ìsinmi àti oṣù tuntun àti ní àjọ̀dún tí a yàn ti Olúwa Ọlọ́run wa. Èyí ni àṣẹ fún Israẹli láéláé.
5 А дом који ћу зидати биће велик, јер је Бог наш већи од свих богова.
“Ilé Olúwa tí èmi yóò kọ́ yóò tóbi, nítorí pé Ọlọ́run wa tóbi ju gbogbo àwọn ọlọ́run mìíràn lọ.
6 А ко би могао Њему сазидати дом кад Га небо и небеса над небесима не могу обухватити? И ко сам ја да му сазидам дом? Него само да се кади пред Њим.
Ṣùgbọ́n ta ni ó le è kọ́ ilé fún Olúwa, níwọ̀n ìgbà tí àwọn ọ̀run, àní ọ̀run àwọn ọ̀run tó ga jùlọ, kò le è gbà á? Ta ni èmi nígbà náà láti kọ́ ilé fún Olúwa, bí kò ṣe kìkì àti sun ẹbọ sun ẹbọ níwájú rẹ̀?
7 Тако сада пошљи ми човека вештог, који уме радити од злата и од сребра и од бронзе и од гвожђа и од скерлета и од црвца и од порфире, и који зна резати, да ради с уметницима које имам код себе у Јудеји и у Јерусалиму, које је добавио Давид, отац мој.
“Nítorí náà, rán ọkùnrin kan sí mi, tí a kọ́ láti ṣiṣẹ́ pẹ̀lú wúrà àti fàdákà àti idẹ àti irin, àti ní àwọ̀ àlùkò àti àwọ̀ pupa fòò àti ní àwọ̀ ojú ọ̀run, tí ó jẹ́ onímọ̀ nínú iṣẹ́ igi gbígbẹ́ láti ṣiṣẹ́ ní Juda àti Jerusalẹmu pẹ̀lú àwọn onímọ̀ oníṣọ̀nà tí baba à mi Dafidi pèsè.
8 И пошаљи ми дрва кедрових и јелових и алмугима с Ливана, јер знам да слуге твоје умеју сећи дрва ливанска; а ево слуге ће моје бити с твојим слугама,
“Fi ìtì igi kedari, junifa àti algumu ránṣẹ́ sí mi, láti Lebanoni, nítorí tí mo mọ̀ pé àwọn ọkùnrin rẹ ní ìmọ̀ nínú gígé igi rírẹ́. Àwọn ọkùnrin mi yóò ṣiṣẹ́ pẹ̀lú àwọn ọkùnrin rẹ.
9 Да ми приправе много дрва, јер дом што ћу зидати биће велик и диван.
Láti pèsè ọ̀pọ̀ igi rírẹ́ fún mi, nítorí ilé Olúwa tí mo kọ́ gbọdọ̀ tóbi kí o sì lógo púpọ̀.
10 А ево, посланицима који ће сећи дрво, слугама твојим, даћу пшенице овршене двадесет хиљада кора, и двадесет хиљада кора јечма, и вина двадесет хиљада вата, и уља двадесет хиљада вата.
Èmi yóò fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ọkùnrin agégi tí ó ń gé ìtì igi náà ni ogún ẹgbẹ̀rún, alikama ilẹ̀ àti ogún ẹgbẹ̀rún, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ti barle; ogún ẹgbẹ̀rún, bati ọtí wáìnì àti ogún ẹgbẹ̀rún bati òróró olifi.”
11 И одговори Хирам цар тирски у књизи коју посла Соломуну: Што Господ љуби свој народ зато те постави царем над њим.
Hiramu ọba Tire fèsì padà nípasẹ̀ ìwé sí Solomoni: “Nítorí tí Olúwa fẹ́ràn àwọn ènìyàn rẹ̀, ó ti ṣe ọ́ ní ọba wọn.”
12 И говораше Хирам: Благословен да је Господ Бог Израиљев, који је створио небо и земљу, што је дао цару Давиду сина мудрог, паметног и разумног, који ће сазидати дом Господу и царски дом себи.
Hiramu fi kún un pe, “Ìyìn ni fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, tí ó dá ọ̀run òun ayé! O ti fún ọba Dafidi ní ọmọ tí ó gbọ́n, tí ó kún fún ìmọ̀ àti òye, tí yóò kọ́ ilé fún Olúwa àti ààfin fún ara rẹ̀.
13 Шаљем ти дакле човека вештог и разумног, Хирама Авива,
“Èmi ń rán Huramu-Abi, ọkùnrin tí ó kún fún ìmọ̀ àti òye sí ọ.
14 Сина једне жене између кћери Данових, коме је отац био Тирац; он уме радити од злата и од сребра, од бронзе, од гвожђа, од камена и од дрвета, од скерлета, и од порфире, и од танког платна и од црвца, и резати свашта, и измислити свашта вешто шта му се да, нека ради с твојим уметницима и с уметницима господара мог Давида, оца твог.
Ọmọbìnrin kan nínú àwọn ọmọbìnrin Dani àti tí baba a rẹ̀ wá láti Tire tí ó gbọ́ngbọ́n àti ṣiṣẹ́ ní wúrà àti ní fàdákà, ní idẹ, ní irin, ní òkúta àti ní ìtì igi, ní èse-àlùkò, ní aláró, àti ní ọ̀gbọ̀ tí ó dára, àti òdòdó, láti gbẹ́ onírúurú ohun gbígbẹ́ pẹ̀lú, àti láti ṣe àwárí ìmọ̀ ẹ̀rọ irú ẹ̀yàkẹ́yà tí a ó fún un ṣe. Òun yóò ṣiṣẹ́ pẹ̀lú àwọn ọlọ́gbọ́n rẹ̀, àti pẹ̀lú àwọn ọlọ́gbọ́n olúwa mi, Dafidi baba a rẹ.
15 Нека дакле пшеницу и јечам, уље и вино, што је рекао господар мој, пошаље слугама својим.
“Nísinsin yìí, jẹ́ kí olúwa mi rán àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ní alikama àti barle àti òróró Olifi náà àti ọtí tí ó ti ṣe ìlérí.
16 А ми ћемо насећи дрва на Ливану колико ти год треба, и спустићемо их у слаповима морем у Јопу, а ти их оданде вози у Јерусалим.
Àwa yóò sì gé gbogbo àwọn ìtí igi láti Lebanoni tí ìwọ yóò lò pẹ̀lú a ó gbé wọn fò lójú omi òkun lọ sí Joppa. Lẹ́yìn náà ìwọ lè kó wọn gòkè lọ sí Jerusalẹmu.”
17 Тада Соломун изброја све иностранце који беху у земљи Израиљевој после бројања кад их изброја Давид отац његов, и нађе их се сто и педесет и три хиљаде и шест стотина;
Solomoni ka iye àwọn àjèjì tí ó wà ní Israẹli lẹ́yìn kíka iye wọn tí baba a rẹ̀ Dafidi ti ṣe; a sì ka iye wọn sí ọ̀kẹ́ mẹ́jọ ó dín egbèjìlélọ́gbọ̀n.
18 И одреди од њих седамдесет хиљада који ће носити, и осамдесет хиљада који ће тесати у планини, а три хиљаде и шест стотина настојника да настоје да ради народ.
Ó sì yan ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà àádọ́rin nínú wọn láti ru ẹrù, àti ọ̀kẹ́ mẹ́rin láti ṣe àgọ́ òkúta lórí òkè, àti egbèjìdínlógún alábojútó láti kó àwọn ènìyàn ṣiṣẹ́.