< Psalmii 86 >

1 O rugăciune a lui David. Apleacă-ți urechea, DOAMNE, ascultă-mă, căci sunt sărac și nevoiaș.
Àdúrà ti Dafidi. Gbọ́, Olúwa, kí o sì dá mi lóhùn, nítorí mo jẹ́ tálákà àti aláìní.
2 Păstrează-mi sufletul, pentru că sunt sfânt, tu, Dumnezeul meu, salvează pe servitorul tău care se încrede în tine.
Dáàbò bò ayé mi, nítorí a ti yà mí sọ́tọ̀ fún ọ: ìwọ ni Ọlọ́run mi, gbà ìránṣẹ́ rẹ là tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
3 Fii milostiv cu mine, Doamne, căci zilnic strig către tine.
Ṣàánú fún mi, Olúwa, nítorí èmi ń pè ọ́ ní gbogbo ọjọ́.
4 Bucură sufletul servitorului tău, fiindcă spre tine, Doamne, îmi înalț sufletul.
Mú ayọ̀ wà fún ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ, Olúwa, ni mo gbé ọkàn mí sókè sí.
5 Căci tu, Doamne, ești bun și gata să ierți și plin de milă pentru toți cei ce te cheamă.
Ìwọ ń dáríjì, ìwọ sì dára, Olúwa, ìwọ sì ṣàánú fún gbogbo àwọn tí ń ké pè ọ́.
6 Deschide urechea, DOAMNE, la rugăciunea mea; și dă atenție vocii cererilor mele.
Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa; tẹ́tí sí ẹkún mi fún àánú.
7 În ziua tulburării mele te voi chema, fiindcă tu îmi vei răspunde.
Ní ọjọ́ ìpọ́njú mi èmi yóò pè ọ́, nítorí ìwọ yóò dá mi lóhùn.
8 Printre dumnezei nu este niciunul ca tine, Doamne; nici nu sunt lucrări ca lucrările tale.
Nínú àwọn òrìṣà kò sí ẹni tí ó dàbí i rẹ, Olúwa: kò sí àwọn iṣẹ́ tí a lè fiwé tìrẹ.
9 Toate națiunile făcute de tine vor veni și se vor închina înaintea ta, Doamne; și vor glorifica numele tău.
Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ dá yóò wá láti wá jọ́sìn níwájú rẹ, Olúwa; wọn ó mú ògo wà fún orúkọ rẹ̀.
10 Căci tu ești mare și faci lucruri minunate, tu singur ești Dumnezeu.
Nítorí pé ìwọ tóbi, ìwọ sì ń ṣe ohun ìyanu; ìwọ nìkan ni Ọlọ́run.
11 Învață-mă calea ta, DOAMNE, și voi umbla în adevărul tău; fă-mi inima neîmpărțită pentru a se teme de numele tău.
Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, Olúwa, èmi ó sì máa rìn nínú òtítọ́ rẹ; fún mi ní ọkàn tí kì í yapa, kí èmi kí ó ba lè bẹ̀rù orúkọ rẹ.
12 Te voi lăuda cu toată inima mea, Doamne, Dumnezeul meu, și voi glorifica numele tău pentru totdeauna.
Èmi ó yìn ọ́, Olúwa Ọlọ́run mi, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi; èmi ó fògo fún orúkọ rẹ títí láé.
13 Căci mare este mila ta către mine; și mi-ai eliberat sufletul din cel mai de jos iad. (Sheol h7585)
Nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ si mi; ìwọ ti gbà mí kúrò nínú ọ̀gbun isà òkú. (Sheol h7585)
14 Cei mândri s-au ridicat împotriva mea, Dumnezeule, și adunările celor violenți mi-au căutat sufletul; iar ei nu te-au pus înaintea lor.
Àwọn onígbèéraga ń dojúkọ mí, Ọlọ́run; àti ìjọ àwọn alágbára ń wá ọkàn mi kiri, wọn kò sì fi ọ́ pè.
15 Dar tu, Doamne, ești un Dumnezeu cu har și plin de compasiune, îndelung răbdător și abundent în milă și adevăr.
Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, jẹ́ aláàánú àti Ọlọ́run olójúrere, Ó lọ́ra láti bínú, Ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ àti òtítọ́.
16 Întoarce-te spre mine și ai milă de mine; dă puterea ta servitorului tău și salvează pe fiul roabei tale.
Yípadà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi; fún àwọn ènìyàn rẹ ní agbára kí o sì gba ọ̀dọ́mọkùnrin ìránṣẹ́bìnrin rẹ là.
17 Arată-mi un semn spre bine, ca să îl vadă cei ce mă urăsc și să fie rușinați, pentru că tu, Doamne, m-ai ajutat și m-ai mângâiat.
Fi àmì hàn mí fún rere, kí àwọn tí ó kórìíra mi lè ri, kí ojú lè tì wọ́n, nítorí ìwọ Olúwa ni ó ti tù mí nínú.

< Psalmii 86 >