< Geneză 30 >

1 Şi când Rahela a văzut că ea nu îi naşte lui Iacob copii, Rahela a invidiat pe sora ei; şi i-a spus lui Iacob: Dă-mi copii sau altfel mor.
Nígbà tí Rakeli rí i pe òun kò bímọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí ṣe ìlara sí Lea, arábìnrin rẹ̀, ó sì wí fún Jakọbu pé, “Fún mi lọ́mọ, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó kú!”
2 Şi mânia lui Iacob s-a aprins împotriva Rahelei şi a spus: Sunt eu în locul lui Dumnezeu care a oprit de la tine rodul pântecelui?
Inú sì bí Jakọbu sí i, ó sì wí pé, “Èmi ha wà ní ipò Ọlọ́run, ẹni tí ó mú ọ yàgàn bí?”
3 Iar ea a spus: Iată, pe servitoarea mea, Bilha, intră la ea; şi va naşte pe genunchii mei, ca eu de asemenea să am copii prin ea.
Nígbà náà ni Rakeli wí pé, “Biliha ìránṣẹ́bìnrin mi nìyìí, bá a lòpọ̀, kí ó ba à le bí ọmọ fún mi, kí èmi si le è tipasẹ̀ rẹ̀ ní ọmọ.”
4 Şi i-a dat-o pe Bilha, roaba ei, de soţie; şi Iacob a intrat la ea.
Báyìí ni Rakeli fi Biliha fún Jakọbu ní aya, ó sì bá a lòpọ̀.
5 Şi Bilha a rămas însărcinată şi i-a născut lui Iacob un fiu.
Biliha sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Jakọbu.
6 Şi Rahela a spus: Dumnezeu m-a judecat şi a auzit de asemenea vocea mea şi mi-a dat un fiu; de aceea i-a pus numele Dan.
Rakeli sì wí pé, “Ọlọ́run ti ṣe ìdájọ́ mi; ó sì ti gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi, ó sì fún mi ni ọmọkùnrin kan.” Nítorí ìdí èyí ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ní Dani.
7 Şi Bilha, servitoarea Rahelei, a rămas însărcinată din nou şi i-a născut lui Iacob un al doilea fiu.
Biliha, ọmọ ọ̀dọ̀ Rakeli sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kejì fún Jakọbu.
8 Şi Rahela a spus: Cu mari lupte am luptat cu sora mea şi am învins; şi i-a pus numele Neftali.
Nígbà náà ni Rakeli wí pé, “Mo ti bá ẹ̀gbọ́n mi ja ìjàkadì ńlá, èmi sì ti borí.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Naftali.
9 Când Leea a văzut că ea a încetat să nască, a luat pe Zilpa, servitoarea ei, şi i-a dat-o lui Iacob de soţie.
Nígbà tí Lea sì ri pé òun ko tún lóyún mọ́, ó sì fi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, Silipa fún Jakọbu bí aya.
10 Şi Zilpa, servitoarea Leei, i-a născut lui Iacob un fiu.
Silipa ọmọ ọ̀dọ̀ Lea sì bí ọmọkùnrin kan fún Jakọbu.
11 Şi Leea a spus: O trupă înarmată vine; şi i-a pus numele Gad.
Nígbà náà ni Lea wí pé, “Orí rere ni èyí!” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Gadi.
12 Şi Zilpa, servitoarea Leei, i-a născut lui Iacob un al doilea fiu.
Silipa ọmọ ọ̀dọ̀ Lea sì tún bí ọmọkùnrin kejì fún Jakọbu.
13 Şi Leea a spus: Fericită sunt, căci fiicele mă vor numi binecuvântată; şi i-a pus numele Aşer.
Nígbà náà ni Lea wí pé, “Mo ní ayọ̀ gidigidi! Àwọn ọmọbìnrin yóò sì máa pe mí ní Alábùkún fún.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Aṣeri.
14 Şi Ruben a mers în zilele secerişului grâului şi a găsit mandragore în câmp şi le-a adus la mama lui, Leea. Atunci Rahela i-a spus Leei: Dă-mi, te rog, din mandragorele fiului tău.
Ní ọjọ́ kan, ní àkókò ìkórè ọkà jéró, Reubeni jáde lọ sí oko, ó sì rí èso mándrákì, ó sì mú un tọ Lea ìyá rẹ̀ wá. Rakeli sì wí fún Lea pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ní ara èso mándrákì tí ọmọ rẹ mú wá.”
15 Iar Leea i-a spus: Este puţin lucru că ai luat pe soţul meu? Şi voieşti să iei şi mandragorele fiului meu? Şi Rahela a spus: De aceea el să se culce cu tine la noapte pentru mandragorele fiului tău.
Ṣùgbọ́n Lea dalóhùn pé, “Ọkọ mi tí o gbà kò tó kọ́? Ṣe ìwọ yóò tún gba èso mándrákì ọmọ mi pẹ̀lú?” Rakeli sì dáhùn pé, “Ó dára, yóò sùn tì ọ́ lálẹ́ yìí nítorí èso mándrákì ọmọ rẹ.”
16 Şi Iacob a venit de la câmp pe înserat şi Leea a ieşit să îl întâlnească şi a spus: Trebuie să intri la mine; căci cu adevărat te-am angajat cu mandragorele fiului meu. Şi el s-a culcat cu ea în acea noapte.
Nítorí náà, nígbà tí Jakọbu ti oko dé ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ náà, Lea jáde lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí pé, “O ní láti sun ọ̀dọ̀ mi ní alẹ́ yìí nítorí mo ti fi èso mándrákì tí ọmọ mi wá bẹ̀ ọ́ lọ́wẹ̀.” Nítorí náà ni Jakọbu sùn tì í ní alẹ́ ọjọ́ náà.
17 Şi Dumnezeu a dat ascultare Leei şi ea a rămas însărcinată şi i-a născut lui Iacob al cincilea fiu.
Ọlọ́run sì gbọ́ ti Lea, ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin karùn-ún fún Jakọbu.
18 Şi Leea a spus: Dumnezeu mi-a dat plata mea, pentru că am dat pe servitoarea mea soţului meu; şi i-a pus numele Isahar.
Nígbà náà ni Lea wí pé, “Ọlọ́run ti sẹ̀san ọmọ ọ̀dọ̀ mi ti mo fi fún ọkọ mi fún mi,” ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Isakari.
19 Şi Leea a rămas însărcinată din nou şi i-a născut lui Iacob al şaselea fiu.
Lea sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kẹfà fún Jakọbu.
20 Şi Leea a spus: Dumnezeu m-a înzestrat cu o zestre bună; acum soţul meu va locui cu mine, deoarece i-am născut şase fii; şi i-a pus numele Zabulon.
Nígbà náà ni Lea tún wí pé “Ọlọ́run ti fún mi ní ẹ̀bùn iyebíye, nígbà yìí ni ọkọ mi yóò máa bu ọlá fún mi.” Nítorí náà ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ni Sebuluni.
21 Şi mai apoi ea a născut o fiică şi i-a pus numele Dina.
Lẹ́yìn èyí, ó sì bí ọmọbìnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Dina.
22 Şi Dumnezeu şi-a amintit de Rahela şi Dumnezeu i-a dat ascultare şi i-a deschis pântecele.
Nígbà náà ni Ọlọ́run rántí Rakeli, Ọlọ́run sì gbọ́ tirẹ̀, ó sì ṣí i ní inú.
23 Şi ea a rămas însărcinată şi a născut un fiu şi a spus: Dumnezeu mi-a luat ocara;
Ó lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan ó sì wí pé, “Ọlọ́run ti mú ẹ̀gàn mi kúrò.”
24 Şi i-a pus numele Iosif şi a spus: DOMNUL îmi va adăuga un alt fiu.
Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ni Josẹfu, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ kí Olúwa kí ó fi ọmọkùnrin mìíràn kún un fún mi.”
25 Şi s-a întâmplat, când Rahela a născut pe Iosif, că Iacob i-a spus lui Laban: Trimite-mă, ca să merg la locul meu şi în ţara mea.
Lẹ́yìn tí Rakeli ti bí Josẹfu, Jakọbu wí fún Labani pé, “Jẹ́ kí èmi máa lọ sí ilẹ̀ mi tí mo ti wá.
26 Dă-mi soţiile mele şi copiii mei, pentru care ţi-am servit şi lasă-mă să plec, pentru că ştii serviciul meu pe care ţi l-am făcut.
Kó àwọn ọmọ àti ìyàwó mi fún mi, àwọn ẹni tí mo ti torí wọn sìn ọ́. Ki èmi lè máa bá ọ̀nà mi lọ. O sá à mọ bí mo ti ṣiṣẹ́ sìn ọ́ tó.”
27 Şi Laban i-a spus: Te rog, dacă am găsit favoare în ochii tăi, rămâi, căci am învăţat prin experienţă că DOMNUL m-a binecuvântat din cauza ta.
Ṣùgbọ́n Labani wí fún un pé, “Bí o bá ṣe pé mo rí ojúrere rẹ, jọ̀wọ́ dúró, nítorí, mo ti ṣe àyẹ̀wò rẹ, mo sì rí i pé Olúwa bùkún mi nítorí rẹ.
28 Iar el a spus: Rânduieşte-mi plăţile tale şi ţi le voi da.
Sọ ohun tí o fẹ́ gẹ́gẹ́ bí owó iṣẹ́ ẹ̀ rẹ, èmi yóò sì san án.”
29 Iar el i-a spus: Ştii cum ţi-am servit şi că turma ta era cu mine.
Jakọbu sì wí fún un pé, “Ìwọ sá à mọ bí mo ti ṣiṣẹ́ sìn ọ́ àti bí ẹran ọ̀sìn rẹ ti pọ̀ si lábẹ́ ìtọ́jú mi.
30 Căci era puţin ce ai avut înainte ca eu să vin şi acum a sporit într-o mulţime; şi DOMNUL te-a binecuvântat de la venirea mea şi acum, când voi îngriji şi de casa mea?
Ìwọ̀nba díẹ̀ sá à ni o ní kí èmi tó dé, ó sì ti pọ̀ sí i gidigidi, Olúwa sì ti bùkún ọ nínú gbogbo èyí tí mo ṣe. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, nígbà wo ní èmi yóò pèsè fún ìdílé tèmi.”
31 Iar el a spus: Ce să îţi dau? Şi Iacob a spus: Nu îmi da nimic, dacă vei face acest lucru pentru mine, voi paşte şi voi ţine din nou turma ta;
Ó sì tún béèrè wí pé, “Kín ni kí èmi ó fi fún ọ?” Jakọbu dáhùn pé, “Má fun mi ni ohunkóhun, ṣùgbọ́n bí ìwọ yóò bá ṣe ohun tí mo fẹ́ sọ yìí, èmi yóò sì máa bá ọ tọ́jú àwọn agbo ẹran rẹ, èmi yóò sì máa bọ́ wọn.
32 Voi trece prin toată turma ta astăzi, mutând de acolo toate cele pestriţe şi pătate şi toate cele cenuşii dintre oi şi pe cele pestriţe şi pătate dintre capre şi din aceasta va fi plata mea.
Jẹ́ kí èmi kí ó la agbo ẹran kọjá ní òní, èmi yóò sì mú gbogbo àgùntàn onílà àti èyí tí ó ní àmì, àti gbogbo àgbò dúdú pẹ̀lú ewúrẹ́ onílà tàbí tí ó ní àmì. Àwọn wọ̀nyí ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ mi.
33 Aşa va răspunde dreptatea mea pentru mine în timpul ce vine, când vine timpul pentru plata mea înaintea feţei tale; fiecare vită care nu este pestriţă sau pătată dintre capre şi cenuşie dintre oi, aceea va fi socotită de mine ca furată.
Òtítọ́ inú mi yóò sì jẹ́rìí fún mi ní ọjọ́ iwájú nígbà tí ìwọ bá wo owó iṣẹ́ mi tí ìwọ san fún mi, yóò sì ṣe pé gbogbo èyí tí kì í bá ṣe onílà tàbí alámì nínú ewúrẹ́ tàbí tí kì í ṣe dúdú nínú àgùntàn, tí o bá rí ni ọ̀dọ̀ mi ni kí o kà sí mi lọ́rùn pé jíjí ni mo jí gbé.”
34 Şi Laban a spus: Iată, aş voi să fie conform cuvântului tău.
Labani sì dáhùn pé, “Mo fi ara mọ́ ọn, ṣe bí ìwọ ti wí.”
35 Şi a scos în acea zi ţapii care erau vărgaţi şi pătaţi şi toate caprele care erau pestriţe şi pătate şi pe fiecare ce avea ceva alb pe ea şi tot ce era cenuşiu între oi şi le-a dat în mâna fiilor săi.
Ní ọjọ́ náà gan an ni Labani kó gbogbo ewúrẹ́ tí ó ní àmì tàbí ilà (àti òbúkọ àti abo, tí ó ní funfun díẹ̀ lára), pẹ̀lú gbogbo àgùntàn dúdú, ó sì fi wọ́n sí ìtọ́jú àwọn ọmọ rẹ̀.
36 Şi a pus trei zile de călătorie între el şi Iacob; şi Iacob a păscut restul turmelor lui Laban.
Ibi tí Labani àti Jakọbu sì wà sí ara wọn, sì tó ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Jakọbu sì ń tọ́jú agbo ẹran Labani tí ó kù.
37 Şi Iacob a luat toiege verzi de plop şi de alun şi de castan dulce; şi a descojit dungi albe pe ele şi a făcut să apară albul care era în toiege.
Nígbà náà ni Jakọbu gé ọ̀pá tẹ́ẹ́rẹ́ tútù kan lára igi Poplari, àti igi almondi àti igi Pileeni. Ó sì bó èèpo kúrò ní ibi kọ̀ọ̀kan lára igi náà láti fún igi náà ní àwọ̀ ju ẹyọ kan lọ.
38 Şi a pus toiegele pe care le descojise înaintea turmelor în jgheaburi, în adăpătoarele cu apă, când turmele veneau să bea, ca ele, când veneau să bea, să zămislească.
Ó sì mú àwọn ọ̀pá wọ̀nyí tì sí ọ̀ọ́kán agbada omi níbi tí àwọn ẹran ti lè rí i nígbà tí wọ́n bá wá mu omi.
39 Şi turmele zămisleau înaintea toiegelor şi năşteau miei vărgaţi, pestriţi şi pătaţi.
Tí àwọn ẹran bá sì ń gùn, níwájú àwọn ọ̀pá náà, wọn sì bí àwọn ẹran onílà àti alámì, àwọn tí ó ní tótòtó lára.
40 Şi Iacob a separat mieii şi întorcea feţele turmelor spre cele vărgate şi toate cele cenuşii în turma lui Laban; şi a pus propriile sale turme deoparte şi nu le-a pus cu turmele lui Laban.
Nígbà náà ni ó ya àwọn abo ẹran kúrò nínú agbo ẹran Labani, ó sì yà wọ́n sọ́tọ̀ kúrò lára àgbò, ó sì mú kí wọn máa gùn pẹ̀lú àwọn àgbò Jakọbu dúdú nìkan, bẹ́ẹ̀ ni ó kó agbo ẹran jọ fún ara rẹ̀ láti ara agbo ẹran Labani.
41 Şi s-a întâmplat, de câte ori oile mai puternice zămisleau, că Iacob aşeza toiegele înaintea ochilor oilor în jgheaburile de apă, ca ele să zămislească printre toiege.
Nígbàkígbà tí àwọn ẹran tí ó lera bá ń gùn, Jakọbu yóò fi àwọn ọ̀pá wọ̀nyí lélẹ̀ níwájú wọn, ní ibi tí wọn ti ń mu omi.
42 Dar când oile erau slabe, nu le punea înăuntru, aşa că cele mai slabe erau ale lui Laban şi cele mai puternice ale lui Iacob.
Ṣùgbọ́n tí ó bá jẹ́ wí pé wọn kò lera, kò ní fi àwọn ọ̀pá náà lélẹ̀. Nítorí náà, àwọn tí kò lera ń jẹ́ ti Labani, nígbà tí àwọn tí ó lera ń jẹ́ ti Jakọbu.
43 Şi acest bărbat a sporit peste măsură şi avea multe oi şi servitoare şi servitori şi cămile şi măgari.
Nítorí ìdí èyí, Jakọbu di ọlọ́rọ̀ gidigidi, agbo ẹran rẹ̀ pọ̀ àti àwọn ìránṣẹ́kùnrin, ìránṣẹ́bìnrin pẹ̀lú ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.

< Geneză 30 >