< Geneză 37 >

1 Şi Iacob a locuit în ţara în care tatăl său a fost străin, în ţara lui Canaan.
Jakọbu sì gbé ilẹ̀ Kenaani ní ibi ti baba rẹ̀ ti gbé.
2 Acestea sunt generaţiile lui Iacob. Iosif, fiind în vârstă de şaptesprezece ani, păştea turma cu fraţii săi; şi băiatul era cu fiii Bilhei şi cu fiii Zilpei, soţiile tatălui său; şi Iosif a adus tatălui său vorbirea lor rea.
Èyí ni àwọn ìtàn Jakọbu. Nígbà tí Josẹfu di ọmọ ọdún mẹ́tàdínlógún, ó ń ṣọ́ agbo ẹran pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀, àwọn ọmọ Biliha àti Silipa aya baba rẹ̀ Josẹfu sì ń ròyìn àwọn aburú tí wọ́n ń ṣe fún baba wọn.
3 Acum Israel iubea pe Iosif mai mult decât pe toţi copiii lui, deoarece el era fiul bătrâneţii sale; şi i-a făcut o haină pestriţă.
Israẹli sì fẹ́ràn Josẹfu ju gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀ tókù lọ, nítorí ní ọjọ́ ogbó rẹ̀ ni ó bí i. O sì dá aṣọ aláràbarà tí ó kún fún onírúurú ọnà lára fún un.
4 Şi când fraţii lui au văzut că tatăl lor îl iubea mai mult decât pe toţi fraţii săi, l-au urât şi nu puteau să îi vorbească paşnic.
Nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ rí i pé baba àwọn fẹ́ràn rẹ̀ ju gbogbo wọn lọ, wọ́n kórìíra rẹ̀, wọ́n sì ń fi ẹ̀tanú bá a gbé, kò sì sí àlàáfíà láàrín wọn.
5 Şi Iosif a visat un vis şi l-a spus fraţilor săi şi ei l-au urât încă şi mai mult.
Josẹfu lá àlá kan, nígbà tí ó sì sọ fún àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n túbọ̀ kórìíra rẹ̀ sí i.
6 Şi le-a spus: Ascultaţi, vă rog, acest vis pe care l-am visat:
O wí fún wọn pé, “Ẹ fetí sí àlá tí mo lá,
7 Şi, iată, noi legam snopi în câmp şi, iată, snopul meu s-a ridicat şi a stat chiar drept în picioare; şi, iată, snopii voştri au stat de jur împrejur şi se prosternau snopului meu.
sá à wò ó, àwa ń yí ìtí ọkà nínú oko, ó sì ṣe ìtí ọkà tèmi sì dìde dúró ṣánṣán, àwọn ìtí ọkà tiyín sì dúró yí ìtí tèmi ká, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún un.”
8 Şi fraţii lui i-au spus: Vei domni într-adevăr peste noi? Sau vei avea într-adevăr stăpânire peste noi? Şi l-au urât încă şi mai mult pentru visele lui şi pentru cuvintele lui.
Àwọn arákùnrin rẹ̀ wí fún un pé, “Ìwọ ń gbèrò àti jẹ ọba lé wa lórí bí? Tàbí ìwọ ó ṣe olórí wa nítòótọ́?” Wọn sì túbọ̀ kórìíra rẹ̀ sí i, nítorí àlá rẹ̀ àti nítorí ohun tí ó wí.
9 Şi a visat încă un vis şi l-a spus fraţilor săi şi a zis: Iată, am visat încă un vis; şi, iată, soarele şi luna şi unsprezece stele mi s-au prosternat.
O sì tún lá àlá mìíràn, ó sì tún sọ ọ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀. Ó wí pé, ẹ tẹ́tí sí mi, “Mo tún lá àlá mìíràn, wò ó, oòrùn, òṣùpá àti ìràwọ̀ mọ́kànlá ń foríbalẹ̀ fún mi.”
10 Şi l-a spus tatălui său şi fraţilor săi şi tatăl său l-a mustrat şi i-a zis: Ce este acest vis pe care l-ai visat? Vom veni eu şi mama ta şi fraţii tăi, într-adevăr, să ne prosternăm ţie până la pământ?
Nígbà tí ó sọ fún baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú, baba rẹ̀ bá a wí pé, “Irú àlá wo ni ìwọ lá yìí? Ṣé ìyá rẹ, pẹ̀lú èmi àti àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ yóò wá foríbalẹ̀ níwájú rẹ ni?”
11 Şi fraţii lui l-au invidiat, dar tatăl său a dat atenţie acestei spuse.
Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì ń ṣe ìlara rẹ̀ ṣùgbọ́n baba rẹ̀ pa ọ̀rọ̀ náà mọ́ lọ́kàn rẹ̀.
12 Şi fraţii lui au mers să pască turma tatălui lor în Sihem.
Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì da ẹran baba wọn lọ sí Ṣekemu.
13 Şi Israel i-a spus lui Iosif: Nu pasc fraţii tăi turma în Sihem? Vino şi te voi trimite la ei. Iar el i-a spus: Iată-mă.
Israẹli sì wí fún Josẹfu pé, “Ṣé o mọ̀ pé, àwọn arákùnrin rẹ ń da ẹran ní Ṣekemu, wá, jẹ́ kí n rán ọ sí wọn.” Josẹfu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
14 Iar el i-a spus: Du-te, te rog, să vezi dacă este bine cu fraţii tăi şi bine cu turmele; şi adu-mi cuvânt înapoi. Astfel l-a trimis din valea Hebronului şi a venit la Sihem.
O sì wí fún un pé, “Lọ wò bí àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn agbo ẹran bá wà ní àlàáfíà, kí o sì wá jíṣẹ́ fún mi.” Ó sì rán Josẹfu lọ láti àfonífojì Hebroni. Nígbà tí Josẹfu dé Ṣekemu,
15 Şi un anumit bărbat l-a găsit şi, iată, el rătăcea în câmp; şi bărbatul l-a întrebat, spunând: Ce cauţi?
ọkùnrin kan sì rí i tí ó ń rìn kiri inú pápá, ó sì bi í pé, “Kín ni ò ń wá?”
16 Iar el a spus: Caut pe fraţii mei; spune-mi te rog, unde îşi pasc ei turmele.
Ó sì dáhùn pé, “Àwọn arákùnrin mi ni mò ń wá, ǹjẹ́ o mọ ibi tí wọ́n wà pẹ̀lú agbo ẹran?”
17 Şi bărbatul a spus: Au plecat deja de aici; fiindcă i-am auzit spunând: Să mergem la Dotan. Şi Iosif a mers după fraţii săi şi i-a găsit la Dotan.
Ọkùnrin náà dáhùn pé, “Wọ́n ti kúrò ní ìhín, mo gbọ́ tí wọ́n ń wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a lọ sí Dotani.’” Josẹfu sì wá àwọn arákùnrin rẹ̀ lọ, ó sì rí wọn ní tòsí Dotani.
18 Şi când l-au văzut de departe, chiar înainte ca el să se apropie de ei, au uneltit împotriva lui să îl ucidă.
Ṣùgbọ́n bí wọ́n sì ti rí i tí ń bọ̀ lókèèrè, kí ó sì tó dé ọ̀dọ̀ wọn, wọn gbìmọ̀ pọ̀ láti pa á.
19 Şi au spus unul altuia: Iată, vine acest visător.
“Alálàá ni ń bọ̀ yìí,” ni wọ́n ń wí fún ara wọn.
20 Şi acum, aşadar, veniţi să îl ucidem şi să îl aruncăm în vreo groapă şi vom spune: Ceva fiară rea l-a mâncat; şi vom vedea ce vor deveni visele lui.
“Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a pa á. Kí a sì ju òkú rẹ̀ sínú kòtò, a ó sì wí pé, ẹranko búburú ni ó pa á, kí a máa wo ọ̀nà tí àlá rẹ̀ yóò gbà ṣẹ.”
21 Şi Ruben a auzit aceasta şi l-a scăpat din mâinile lor; şi a spus: Să nu îl ucidem.
Nígbà tí Reubeni gbọ́ èyí, ó gbìyànjú láti gbà á sílẹ̀ ní ọwọ́ wọn, ó sì wí pé, “Ẹ má ṣe jẹ́ kí a gba ẹ̀mí rẹ̀,
22 Şi Ruben le-a spus: Nu vărsaţi sânge, ci aruncaţi-l în această groapă care este în pustie şi nu puneţi mâna pe el; ca să îl scape din mâinile lor, să îl predea tatălui său din nou.
ẹ má ṣe jẹ́ kí a ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, ẹ má ṣe fọwọ́ kàn án, ẹ kúkú jù ú sínú kòtò láààyè nínú aginjù níbí.” Reubeni sọ èyí, kí ó ba à le gbà á kúrò lọ́wọ́ wọn, kí ó sì dá a padà lọ fún baba rẹ̀.
23 Şi s-a întâmplat, când Iosif a ajuns la fraţii săi, că l-au dezbrăcat pe Iosif de haina lui, haina pestriţă care era pe el;
Nítorí náà, nígbà tí Josẹfu dé ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n bọ́ ẹ̀wù rẹ̀—Ẹ̀wù ọlọ́nà, aláràbarà tí ó wọ̀—
24 Şi l-au luat şi l-au aruncat într-o groapă; şi groapa era goală, nu era apă în ea.
wọ́n mú un, wọ́n sì jù ú sínú kòtò. Kòtò náà sì ṣófo, kò sí omi nínú rẹ̀.
25 Şi au şezut să mănânce pâine şi şi-au ridicat ochii şi au privit şi, iată, o ceată de ismaeliţi a venit din Galaad cu cămilele lor, purtând mirodenii şi balsam şi smirnă, mergând să le coboare în Egipt.
Bí wọ́n sì ti jókòó láti jẹun, wọ́n gbójú sókè, wọ́n sì rí àwọn oníṣòwò ará Iṣmaeli tí wọ́n ń wọ́ bọ̀ láti Gileadi. Ìbákasẹ wọn sì ru tùràrí, ìkunra àti òjìá, wọ́n ń lọ sí Ejibiti.
26 Şi Iuda a spus fraţilor săi: Ce folos este dacă ucidem pe fratele nostru şi ascundem sângele lui?
Juda wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Èrè kí ni ó jẹ́ bí a bá pa arákùnrin wa tí a bo ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ ti ọkàn wa sì ń dá wa lẹ́bi?
27 Veniţi şi să îl vindem ismaeliţilor şi să nu lăsăm mâna noastră să fie asupra lui, pentru că el este fratele nostru şi carnea noastră. Şi fraţii lui au fost mulţumiţi.
Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á tà á fún àwọn ará Iṣmaeli, kí àwa má sì pa á, ṣè bí àbúrò wa ni, ẹran-ara wa àti ẹ̀jẹ̀ wa ní i ṣe.” Àwọn arákùnrin rẹ̀ sì fi ara mọ́ ohun tí ó sọ.
28 Atunci au trecut pe acolo negustori madianiţi; şi au tras şi au scos pe Iosif din groapă şi au vândut pe Iosif ismaeliţilor pentru douăzeci de arginţi; iar ei au dus pe Iosif în Egipt.
Nítorí náà, nígbà tí àwọn oníṣòwò ara Midiani ń kọjá, àwọn arákùnrin Josẹfu fà á jáde láti inú kòtò, wọ́n sì tà á fún àwọn ará Iṣmaeli ní ogún owó wúrà, wọ́n sì mú Josẹfu lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.
29 Şi Ruben s-a întors la groapă; şi, iată, Iosif nu era în groapă; şi el şi-a rupt hainele.
Nígbà tí Reubeni padà dé ibi kòtò tí ó sì ri pé Josẹfu kò sí níbẹ̀ mọ́, ó fa aṣọ rẹ̀ ya pẹ̀lú ìbànújẹ́.
30 Şi s-a întors la fraţii săi şi a spus: Copilul nu mai este; iar eu, încotro voi merge?
Ó padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, ó sì wí pé, “Ọmọdékùnrin náà kò sí níbẹ̀ mọ́! Níbo ni ẹ fẹ́ kí n wọ̀ báyìí?”
31 Şi au luat haina lui Iosif şi au înjunghiat un ied dintre capre şi au înmuiat haina în sânge;
Nígbà náà ni wọ́n mú aṣọ Josẹfu, wọ́n pa ewúrẹ́ kan, wọ́n sì tẹ aṣọ náà bọ inú ẹ̀jẹ̀ ewúrẹ́ náà.
32 Şi au trimis haina pestriţă şi au adus-o la tatăl lor; şi au spus: Noi am găsit aceasta, cercetează acum dacă este haina fiului tău sau nu.
Wọ́n sì mú aṣọ ọlọ́nà aláràbarà náà padà sí ọ̀dọ̀ baba wọn, wọ́n sì wí pé, “A rí èyí he nínú oko, yẹ̀ ẹ́ wò, kí o sì mọ̀ bóyá ti ọmọ rẹ ni.”
33 Şi a cercetat-o şi a spus: Aceasta este haina fiului meu; o fiară rea l-a mâncat; Iosif este fără îndoială rupt în bucăţi.
Ó sì dá a mọ̀, ó wí pé, “Háà! Aṣọ ọmọ mi ni, ẹranko búburú ti pa á jẹ, láìṣe àní àní, ó ti fa Josẹfu ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.”
34 Şi Iacob şi-a rupt hainele şi a pus pânză de sac peste coapsele lui şi a jelit pentru fiul său multe zile.
Nígbà náà ni Jakọbu fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì ṣọ̀fọ̀ ọmọ rẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́.
35 Şi toţi fiii lui şi toate fiicele lui s-au ridicat să îl mângâie; dar el a refuzat să fie mângâiat; şi a spus: Jelind voi coborî în mormânt la fiul meu. Astfel a plâns tatăl său pentru el. (Sheol h7585)
Gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀ lọ́kùnrin, lóbìnrin wá láti tù ú nínú, ṣùgbọ́n kò gbà. Ó wí pé, “Rárá, nínú ọ̀fọ̀ yìí ni èmi yóò lọ sí isà òkú lọ́dọ̀ ọmọ mi.” Baba Josẹfu sì sọkún fún un. (Sheol h7585)
36 Şi madianiţii l-au vândut în Egipt lui Potifar, un ofiţer al lui Faraon şi căpetenia gărzii.
Ní gbogbo àkókò wọ̀nyí, àwọn ará Midiani ta Josẹfu ní Ejibiti fún Potifari, ọ̀kan nínú àwọn ìjòyè Farao, tí í ṣe olórí ẹ̀ṣọ́.

< Geneză 37 >