< Efeseni 4 >

1 De aceea eu, prizonierul Domnului, vă implor să umblați demni de chemarea cu care sunteți chemați,
Nítorí náà, èmi òǹdè nínú Olúwa ń bẹ̀ yín pé kí ẹ̀yin máa gbé ìgbé ayé tí ó yẹ sí ìpè tí a pè yín sí.
2 Cu toată umilința și blândețea, cu îndelungă răbdare, răbdând unii altora în dragoste,
Pẹ̀lú ìrẹ̀lẹ̀ gbogbo àti inú tútù, pẹ̀lú ìpamọ́ra, ẹ máa fi ìfẹ́ faradà fún ẹnìkejì yín.
3 Străduindu-vă să țineți unitatea Duhului în legătura păcii.
Kí ẹ sì máa làkàkà láti pa ìṣọ̀kan Ẹ̀mí mọ́ ni ìdàpọ̀ àlàáfíà.
4 Este un singur trup și un singur Duh, precum și voi sunteți chemați într-o singură speranță a chemării voastre;
Ara kan ni ń bẹ, àti Ẹ̀mí kan, àní bí a ti pè yín sínú ìrètí kan nígbà tí a pè yín.
5 Un singur Domn, o singură credință, un singur botez,
Olúwa kan, ìgbàgbọ́ kan àti ìtẹ̀bọmi kan.
6 Un singur Dumnezeu și Tată al tuturor, care este peste toți și prin toți și în voi toți.
Ọlọ́run kan àti Baba gbogbo aráyé, ẹni tí ó ṣe olórí ohun gbogbo àti nípá gbogbo àti nínú ohun gbogbo.
7 Dar fiecăruia dintre noi îi este dat har conform măsurii darului lui Cristos.
Ṣùgbọ́n olúkúlùkù wa ni a fi oore-ọ̀fẹ́ fun gẹ́gẹ́ bi òsùwọ̀n ẹ̀bùn Kristi.
8 De aceea el spune: Când s-a urcat în înălțime, a dus în captivitate captivitatea și a dat daruri oamenilor.
Nítorí náà a wí pé: “Nígbà tí ó gòkè lọ sí ibi gíga, ó di ìgbèkùn ni ìgbèkùn, ó sì fi ẹ̀bùn fun ènìyàn.”
9 (Și că el s-a urcat, ce înseamnă decât că el de asemenea a coborât mai întâi în părțile de jos ale pământului?
(Ǹjẹ́ ní ti pé, “Ó gòkè lọ!” Kín ni ó túmọ̀ sí, bí kò ṣe pé ó kọ́ sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú lọ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀?
10 Cel ce a coborât este chiar cel ce a urcat mult deasupra tuturor cerurilor, ca să umple toate lucrurile.)
Ẹni tí ó ti sọ̀kalẹ̀, Òun kan náà ni ó sì ti gòkè rékọjá gbogbo àwọn ọ̀run, kí ó lè kún ohun gbogbo.)
11 Și el a dat pe unii apostoli, și pe unii profeți, și pe unii evangheliști, și pe unii păstori și învățători,
Nítorí náà ó sì ti fi àwọn kan fún ni bí aposteli; àti àwọn mìíràn bí i wòlíì; àti àwọn mìíràn bí efangelisti, àti àwọn mìíràn bí olùṣọ́-àgùntàn àti olùkọ́ni.
12 Pentru desăvârșirea sfinților, pentru lucrarea servirii, pentru edificarea trupului lui Cristos,
Fún àṣepé àwọn ènìyàn mímọ́ fun iṣẹ́ ìránṣẹ́, fún ìmúdàgbà ara Kristi.
13 Până vom ajunge toți la unitatea credinței și a cunoașterii Fiului lui Dumnezeu, la omul desăvârșit, la măsura staturii plinătății lui Cristos;
Títí gbogbo wa yóò fi dé ìṣọ̀kan ìgbàgbọ́ àti ìmọ̀ Ọmọ Ọlọ́run, títí a ó fi di ọkùnrin, títí a ó fi dé ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìwọ̀n Kristi.
14 Ca să nu mai fim copii, aruncați încoace și încolo și purtați de fiecare vânt de doctrină prin șiretlicul oamenilor și prin viclenie iscusită, prin care pândesc să înșele;
Kí àwa má ṣe jẹ́ èwe mọ́, tí a ń fi gbogbo afẹ́fẹ́ ẹ̀kọ́ tì síwá tì sẹ́yìn, tí a sì fi ń gbá kiri, nípa ìtànjẹ ènìyàn, nípa àrékérekè fun ọgbọ́nkọ́gbọ́n àti mú ni ṣìnà.
15 Ci, vorbind adevărul în dragoste, să creștem în toate în el, care este capul, Cristos;
Ṣùgbọ́n ká a máa sọ òtítọ́ ní ìfẹ́, kí a lè máa dàgbàsókè nínú rẹ̀ ní ohun gbogbo ẹni tí i ṣe orí, àní Kristi.
16 Din care întregul trup bine închegat și strâns legat împreună, prin aportul fiecărei încheieturi, conform lucrării efective în măsura fiecărei părți, își face creșterea trupului pentru edificarea lui însuși în dragoste.
Láti ọ̀dọ̀ ẹni ti ara náà tí a ń so ṣọ̀kan pọ̀, tí ó sì ń fi ara mọ́ra, nípasẹ̀ oríkèé kọ̀ọ̀kan tí a ti pèsè, nígbà tí ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan bá ń ṣiṣẹ́ dáradára, yóò mú ara dàgbà, yóò sì gbé ara òun tìkára rẹ̀ dìde nínú ìfẹ́.
17 De aceea spun aceasta și aduc mărturie în Domnul, ca voi de acum înainte să nu umblați cum umblă celelalte neamuri, în deșertăciunea minții lor,
Ǹjẹ́ èyí ni mo ń wí, tí mo sì ń jẹ́rìí nínú Olúwa pé, láti ìsinsin yìí lọ, kí ẹ̀yin má ṣe rìn mọ́, àní gẹ́gẹ́ bí àwọn aláìkọlà ti ń rìn nínú ìrònú asán wọn.
18 Având înțelegerea întunecată, fiind înstrăinați de viața lui Dumnezeu prin ignoranța care este în ei, din cauza orbirii inimii lor;
Òye àwọn ẹni tí ó ṣókùnkùn, a sì yà wọ́n nínú ìyè Ọlọ́run nítorí àìmọ̀ tí ń bẹ nínú wọn, nítorí líle ọkàn wọn.
19 Care, fiind nesimțitori, s-au dedat ei înșiși desfrânării, pentru a lucra toată necurăția cu lăcomie.
Àwọn ẹni tí ọkàn wọn le rékọjá, tí wọ́n sì ti fi ara wọn fún wọ̀bìà, láti máa fi ìwọra ṣiṣẹ́ ìwà èérí gbogbo.
20 Dar voi nu ați învățat astfel despre Cristos;
Ṣùgbọ́n a kò fi Kristi kọ́ yín bẹ́ẹ̀.
21 Dacă așa este că l-ați auzit și ați fost învățați de către el, precum adevărul este în Isus;
Bí ó bá ṣe pé nítòótọ́ ni ẹ ti gbóhùn rẹ̀ ti a sì ti kọ́ yín nínú rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí òtítọ́ ti ń bẹ nínú Jesu.
22 Ca voi să puneți deoparte cele referitoare la purtarea voastră de mai înainte, omul vechi, care este corupt conform poftelor înșelătoare;
Pé, ní tì ìwà yín àtijọ́, kí ẹ̀yin bọ́ ògbólógbòó ọkùnrin nì sílẹ̀, èyí tí ó díbàjẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ẹ̀tàn;
23 Și să vă înnoiți în duhul minții voastre;
kí ẹ sì di tuntun ni ẹ̀mí inú yín;
24 Și să vă îmbrăcați cu omul nou, care, conform lui Dumnezeu, este creat în dreptate și adevărată sfințenie.
kí ẹ sì gbé ọkùnrin tuntun ni wọ̀, èyí tí a dá ni àwòrán Ọlọ́run nínú òdodo àti ìwà mímọ́ ti òtítọ́.
25 De aceea punând deoparte minciuna, vorbiți adevărul fiecare cu aproapele lui, pentru că suntem membre unii altora.
Nítorí náà ẹ fi èké ṣíṣe sílẹ̀, ki olúkúlùkù yín kí ó máa ba ọmọnìkejì rẹ̀ sọ òtítọ́, nítorí ẹ̀yà ara ọmọnìkejì wa ni àwa jẹ́.
26 Mâniați-vă și nu păcătuiți; să nu apună soarele peste furia voastră,
Nínú ìbínú yín, ẹ máa ṣe ṣẹ̀, ẹ má ṣe jẹ́ kí oòrùn wọ̀ bá ìbínú yín,
27 Nici nu dați loc diavolului.
bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe fi ààyè ẹ̀gbẹ́ kan fún Èṣù.
28 Cel ce a furat, să nu mai fure, ci mai degrabă să muncească, lucrând cu mâinile ce este bun, ca să aibă să dea celui ce are nevoie.
Kí ẹni tí ń jalè má ṣe jalè mọ́: ṣùgbọ́n kí ó kúkú máa ṣe làálàá, kí ó máa fi ọwọ́ rẹ̀ ṣiṣẹ́ ohun tí ó dára, kí òun lè ní láti pín fún ẹni tí ó ṣe aláìní.
29 Să nu iasă din gura voastră niciun cuvânt stricat, ci doar ce este bun pentru folosul edificării, ca să dea har celor ce aud.
Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ìdíbàjẹ́ kan ti ẹnu yín jáde, ṣùgbọ́n irú èyí tí ó lè ràn ìdàgbàsókè wọn lọ́wọ́ gẹ́gẹ́ bí ohun tí wọ́n nílò, kí ó lè máa fi oore-ọ̀fẹ́ fún àwọn tí ń gbọ́.
30 Și nu mâhniți Duhul sfânt al lui Dumnezeu, prin care sunteți sigilați pentru ziua răscumpărării.
Ẹ má sì ṣe mú Ẹ̀mí Mímọ́ Ọlọ́run bínú, ẹni tí a fi ṣe èdìdì yín dé ọjọ́ ìdáǹdè.
31 Orice amărăciune și furie și mânie și strigăte și vorbire rea să fie înlăturate de la voi, împreună cu toată răutatea;
Gbogbo ìwà kíkorò àti ìbínú, àti ìrunú, àti ariwo, àti ọ̀rọ̀ búburú ni kí a mú kúrò lọ́dọ̀ yín, pẹ̀lú gbogbo àrankàn.
32 Și fiți buni unii cu alții, compătimitori, iertându-vă unii pe alții precum și Dumnezeu, pentru Cristos, v-a iertat pe voi.
Ẹ máa ṣoore fún ọmọnìkejì yín, ẹ ní ìyọ́nú, ẹ máa dáríjì ara yín, gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run nínú Kristi ti dáríjì yín.

< Efeseni 4 >