< Galateni 1 >

1 Pavel, apostol (nu de la oameni, nici prin om, ci prin Isus Cristos și Dumnezeu Tatăl, care l-a înviat dintre morți),
Paulu, aposteli tí a rán kì í ṣe láti ọ̀dọ̀ ènìyàn wá, tàbí nípa ènìyàn, ṣùgbọ́n nípa Jesu Kristi àti Ọlọ́run Baba, ẹni tí ó jí i dìde kúrò nínú òkú.
2 Și toți frații care sunt cu mine, bisericilor Galatiei,
Àti gbogbo àwọn arákùnrin tí ó wà pẹ̀lú mi, Sí àwọn ìjọ ní Galatia:
3 Har vouă și pace de la Dumnezeu Tatăl și de la Domnul nostru Isus Cristos,
Oore-ọ̀fẹ́ sí yín àti àlàáfíà láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wá àti Jesu Kristi Olúwa,
4 Care s-a dat pe sine însuși pentru păcatele noastre, ca să ne elibereze din această lume rea, conform voii lui Dumnezeu și Tatălui nostru; (aiōn g165)
ẹni tí ó fi òun tìkára rẹ̀ dípò ẹ̀ṣẹ̀ wa, kí ó lè gbà wá kúrò nínú ayé búburú ìsinsin yìí, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ Ọlọ́run àti Baba wa, (aiōn g165)
5 A lui fie gloria pentru totdeauna și întotdeauna! Amin. (aiōn g165)
ẹni tí ògo wà fún láé àti láéláé. Àmín. (aiōn g165)
6 Mă minunez că așa de repede v-ați întors de la cel ce v-a chemat în harul lui Cristos, la o evanghelie diferită,
Ó yà mi lẹ́nu pé ẹ tètè yapa kúrò lọ́dọ̀ ẹni tí ó pè yín sínú oore-ọ̀fẹ́ Kristi, sí ìyìnrere mìíràn.
7 Care nu este una adevărată, ci sunt unii care vă tulbură și voiesc să pervertească evanghelia lui Cristos.
Nítòótọ́, kò sí ìyìnrere mìíràn bí ó tilẹ̀ ṣe pé àwọn kan wà, tí ń yọ yín lẹ́nu, tí wọ́n sì ń fẹ́ yí ìyìnrere Kristi padà.
8 Dar chiar dacă noi sau un înger din cer vă va predica orice altă evanghelie decât aceea pe care v-am predicat-o noi, să fie blestemat!
Ṣùgbọ́n bí ó ṣe àwa ni tàbí angẹli kan láti ọ̀run wá, ni ó bá wàásù ìyìnrere mìíràn fún yín ju èyí tí a tí wàásù rẹ̀ fún yín lọ, jẹ́ kí ó di ẹni ìfibú títí láéláé!
9 Cum am spus noi mai înainte, așa spun acum din nou: Dacă vă va predica cineva orice altă evanghelie decât aceea pe care ați primit-o, să fie blestemat!
Bí àwa ti wí ṣáájú, bẹ́ẹ̀ ni mo sì tún wí nísinsin yìí pé, bí ẹnìkan bá wàásù ìyìnrere mìíràn fún yín ju èyí tí ẹ̀yin tí gbà lọ, jẹ́ kí ó di ẹni ìfibú títí láéláé!
10 Căci acum pe oameni conving, sau pe Dumnezeu? Sau caut să plac oamenilor? Căci dacă aș plăcea încă oamenilor, nu aș fi robul lui Cristos.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ènìyàn ni èmi ń wá ojúrere rẹ̀ ní tàbí Ọlọ́run? Tàbí ènìyàn ni èmi ń fẹ́ láti wù bí? Bí èmi bá ń fẹ́ láti wu ènìyàn, èmi kò lè jẹ́ ìránṣẹ́ Kristi.
11 Dar vă fac cunoscut, fraților, că evanghelia care a fost predicată de mine nu este conform omului,
Mo fẹ́ kí ẹ mọ̀, ará, pé ìyìnrere tí mo tí wàásù kì í ṣe láti ipa ènìyàn.
12 Fiindcă nici nu am primit-o de la om, nici nu am învățat-o de la om, ci prin revelația lui Isus Cristos.
N kò gbà á lọ́wọ́ ènìyàn kankan, bẹ́ẹ̀ ni a kò fi kọ́ mi, ṣùgbọ́n mo gbà á nípa ìfihàn láti ọ̀dọ̀ Jesu Kristi.
13 Fiindcă ați auzit de purtarea mea de odinioară, în iudaism, că persecutam peste măsură biserica lui Dumnezeu și o pustiiam;
Nítorí ẹ̀yin ti gbúròó ìgbé ayé mi nígbà àtijọ́ nínú ìsìn àwọn Júù, bí mo tí ṣe inúnibíni sí ìjọ ènìyàn Ọlọ́run rékọjá ààlà, tí mo sì lépa láti bà á jẹ́.
14 Și creșteam în iudaism peste mulți de o vârstă cu mine, din națiunea mea, fiind peste măsură de zelos pentru tradițiile părinților mei.
Mo sì ta ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ẹlẹgbẹ́ mi yọ nínú ìsìn àwọn Júù láàrín àwọn ìran mi, mo sì ni ìtara lọ́pọ̀lọ́pọ̀ sì òfin àtọwọ́dọ́wọ́ àwọn baba mi.
15 Dar când i-a plăcut lui Dumnezeu, care m-a pus deoparte din pântecele mamei mele și m-a chemat prin harul său,
Ṣùgbọ́n nígbà tí ó wú Ọlọ́run ẹni tí ó yà mí sọ́tọ̀ láti inú ìyá mi wá, tí ó sì pé mi nípa oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀.
16 Pentru a revela pe Fiul său în mine, ca să îl predic printre păgâni, îndată, nu am primit sfat de la carne și sânge,
Láti fi ọmọ rẹ̀ hàn nínú mi, kì èmi lè máa wàásù ìyìnrere rẹ̀ láàrín àwọn aláìkọlà; èmi kò wá ìmọ̀ lọ sọ́dọ̀ ẹnikẹ́ni,
17 Nici nu am urcat la Ierusalim la cei care au fost apostoli înainte de mine, ci m-am dus în Arabia și m-am întors din nou la Damasc.
bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gòkè lọ sì Jerusalẹmu tọ àwọn tí í ṣe aposteli ṣáájú mi, ṣùgbọ́n mo lọ sí Arabia, mo sì tún padà wá sí Damasku.
18 Apoi, după trei ani, am urcat la Ierusalim să îl văd pe Petru și am rămas cu el cincisprezece zile.
Lẹ́yìn ọdún mẹ́ta, nígbà náà ni mo gòkè lọ sì Jerusalẹmu láti lọ kì Peteru, mo sì gbé ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní ìjọ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún,
19 Dar nu am văzut pe un altul dintre apostoli decât pe Iacov, fratele Domnului.
èmi kò ri ẹlòmíràn nínú àwọn tí ó jẹ́ aposteli, bí kò ṣe Jakọbu arákùnrin Olúwa.
20 Și în cele ce vă scriu, iată, înaintea lui Dumnezeu, nu mint.
Nǹkan tí èmi ń kọ̀wé sí yín yìí, kíyèsi i, níwájú Ọlọ́run èmi kò ṣèké.
21 După aceea am venit în ținuturile Siriei și Ciliciei;
Lẹ́yìn náà mo sì wá sí agbègbè Siria àti ti Kilikia.
22 Și eram necunoscut la față bisericilor din Iudeea care erau în Cristos.
Mo sì jẹ́ ẹni tí a kò mọ̀ lójú fún àwọn ìjọ tí ó wà nínú Kristi ni Judea.
23 Ci auzeau numai că: Cel ce ne persecuta odată, acum predică credința pe care odinioară el o pustiia.
Wọ́n kàn gbọ́ ìròyìn wí pé, “Ẹni tí ó tí ń ṣe inúnibíni sí wa rí, ní ìsinsin yìí ti ń wàásù ìgbàgbọ́ náà tí ó ti gbìyànjú láti bàjẹ́ nígbà kan rí.”
24 Și glorificau pe Dumnezeu în mine.
Wọ́n sì yin Ọlọ́run lógo nítorí mi.

< Galateni 1 >