< Księga Sędziów 15 >

1 Po [kilku] dniach, w czasie żniw pszenicy, Samson odwiedził swoją żonę. Przyniósł jej koźlątko i mówił: Wejdę do swojej żony, do jej pokoju. Lecz jej ojciec nie pozwolił mu wejść.
Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ní àkókò ìkórè alikama, Samsoni mú ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan láti bẹ ìyàwó rẹ̀ wò. Ó ní, “Èmi yóò wọ yàrá ìyàwó mi lọ.” Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ kò gbà á láààyè láti wọlé.
2 Jej ojciec powiedział: Myślałem, że ją znienawidziłeś, dałem ją więc twemu towarzyszowi. Czy jej młodsza siostra nie jest piękniejsza od niej? Weź ją sobie zamiast niej.
Baba ìyàwó dá a lóhùn pé, “Ó dá mi lójú pé o kórìíra rẹ̀, torí náà mo ti fi fún ọ̀rẹ́ rẹ, ṣe bí àbúrò rẹ̀ obìnrin kò ha lẹ́wà jùlọ? Fẹ́ ẹ dípò rẹ̀.”
3 I Samson odpowiedział im: Już teraz będę bez winy wobec Filistynów, choć uczynię im coś złego.
Samsoni dáhùn pé, “Ní àkókò yìí tí mo bá ṣe àwọn Filistini ní ibi èmi yóò jẹ́ aláìjẹ̀bi.”
4 Poszedł więc Samson i nałapał trzysta lisów, wziął pochodnie, przywiązał ogon do ogona, a pośrodku między dwoma ogonami uwiązał po jednej pochodni.
Samsoni sì jáde lọ, ó mú ọ̀ọ́dúnrún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ ó so ìrù wọn mọ́ ara wọn ní méjì méjì. Ó mú ètùfù iná, ó so ó mọ́ àwọn ìrù tí ó so pọ̀.
5 Potem podpalił pochodnie i wypuścił [je] na zboża Filistynów, i spalił tak stogi, jak i stojące zboża oraz winnice z oliwkami.
Ó fi iná ran àwọn ètùfù tí ó so náà, ó sì jọ̀wọ́ wọn lọ́wọ́ lọ sínú àwọn oko ọkà àwọn Filistini. Ó jó àwọn pòpóòrò ọkà tí ó dúró àti àwọn tí a dì ní ìtí, ìtí, pẹ̀lú àwọn ọgbà àjàrà àti olifi.
6 Wtedy Filistyni powiedzieli: Któż to uczynił? I odpowiedziano: Samson, zięć Timnity, ponieważ ten odebrał mu żonę i dał ją jego towarzyszowi. Poszli więc Filistyni i spalili ją i jej ojca.
Nígbà tí àwọn Filistini béèrè pé, “Ta ni ó ṣe èyí?” Wọ́n dá wọn lóhùn pé, “Samsoni ará Timna ni, nítorí a gba ìyàwó rẹ̀ fún ọ̀rẹ́ rẹ̀.” Nítorí náà àwọn Filistini lọ wọ́n sì sun obìnrin náà àti baba rẹ̀.
7 Samson powiedział im: Chociaż tak uczyniliście, jeszcze się zemszczę na was, a potem ustąpię.
Samsoni sọ fún un pé, “Nítorí pé ẹ̀yin ṣe èyí, èmi ó gbẹ̀san lára yín, lẹ́yìn náà èmi yóò sì dẹ́kun.”
8 I zadał im wielką klęskę, bijąc od bioder aż do goleni, po czym odszedł i zamieszkał na wierzchołku skały Etam.
Ó kọlù wọ́n pẹ̀lú ìbínú àti agbára ńlá, ó sì pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú wọn. Lẹ́yìn náà ni ó lọ, ó sì dúró nínú ihò àpáta kan nínú àpáta Etamu.
9 Wtedy Filistyni wyruszyli, rozbili obóz w Judzie i rozciągnęli się [aż] do Lechi.
Àwọn ará Filistini sì dìde ogun sí Juda, wọ́n ti tan ara wọn ká sí agbègbè Lehi.
10 Mężczyźni Judy wówczas powiedzieli: Dlaczego wyruszyliście przeciwko nam? I odpowiedzieli: Przyszliśmy, aby związać Samsona i uczynić mu tak, jak [on] nam uczynił.
Àwọn ọkùnrin Juda sì béèrè pé, “Èéṣe tí ẹ fi wá gbóguntì wá?” Ìdáhùn wọn ni pé, “A wá láti mú Samsoni ní ìgbèkùn, kí a ṣe sí i bí òun ti ṣe sí wa.”
11 Wyruszyło więc trzy tysiące mężczyzn z Judy na szczyt skały Etam i powiedzieli do Samsona: Czy nie wiesz, że Filistyni panują nad nami? I co nam uczyniłeś? I odpowiedział im: Jak oni mi uczynili, tak ja im uczyniłem.
Nígbà náà ni ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin láti Juda sọ̀kalẹ̀ lọ sí ihò àpáta nínú àpáta Etamu, wọ́n sì sọ fún Samsoni pé, “Kò ti yé ọ pé àwọn Filistini ní ń ṣe alákòóso lórí wa? Kí ni o ṣe sí wa?” Òun sì dáhùn pé, “Ohun tí wọ́n ṣe sí mi ni èmi náà ṣe sí wọn.”
12 I powiedzieli mu: Przyszliśmy, aby cię związać i wydać w ręce Filistynów. Samson odpowiedział im: Przysięgnijcie mi, że sami się na mnie nie targniecie.
Wọ́n wí pé, “Àwa wá láti dè ọ́, kí a sì fi ọ́ lé àwọn Filistini lọ́wọ́.” Samsoni wí pé, “Ẹ búra fún mi pé, ẹ̀yin kì yóò fúnra yín pa mí.”
13 A oni mu odpowiedzieli: Nie, tylko zwiążemy cię i wydamy w ich ręce, lecz cię nie zabijemy. Związali go więc dwoma nowymi powrozami i sprowadzili go ze skały.
“Àwa gbà,” ni ìdáhùn wọn. “Àwa yóò kàn dè ọ́, àwa yóò sì fi ọ́ lé wọn lọ́wọ́, àwa kì yóò pa ọ́.” Wọ́n sì dé pẹ̀lú okùn tuntun méjì, wọ́n sì mú u jáde wá láti ihò àpáta náà.
14 Gdy przybył do Lechi, Filistyni z krzykiem wyszli mu na spotkanie. Wtedy Duch PANA zawładnął nim i powrozy, które były na jego ramionach, stały się jak lniane nici spalone ogniem i rozerwały się więzy na jego rękach.
Bí ó ti súnmọ́ Lehi, àwọn Filistini ń pariwo bí wọ́n ṣe ń tò bọ̀. Ẹ̀mí Olúwa bà lé e pẹ̀lú agbára. Àwọn okùn ọwọ́ rẹ̀ dàbí òwú tí ó jóná, ìdè ọwọ́ rẹ̀ já kúrò ní ọwọ́ rẹ̀.
15 Następnie znalazł świeżą oślą szczękę, wyciągnął po nią rękę, wziął ją i zabił nią tysiąc mężczyzn.
Nígbà tí ó rí egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tuntun kan, ó mú un, ó sì fi pa ẹgbẹ̀rún ọkùnrin.
16 Potem Samson powiedział: Szczęką oślą, stos na stosach, szczęką oślą zabiłem tysiąc mężczyzn.
Samsoni sì wí pé, “Pẹ̀lú egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan, mo sọ wọ́n di òkìtì kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Pẹ̀lú egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan, mo ti pa ẹgbẹ̀rún ọkùnrin.”
17 A gdy przestał mówić, wyrzucił szczękę z ręki i nazwał to miejsce Ramat-Lechi.
Nígbà tí ó dákẹ́ ọ̀rọ̀ í sọ, ó ju egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ náà nù, wọ́n sì pe ibẹ̀ ní Ramati-Lehi (ìtumọ̀ rẹ̀ jẹ́ egungun àgbọ̀n ìsàlẹ̀ pa).
18 Wtedy odczuł wielkie pragnienie i zawołał do PANA: Ty dałeś przez rękę swego sługi to wielkie wybawienie, a teraz mam umrzeć z pragnienia albo wpaść w ręce nieobrzezanych?
Nítorí tí òǹgbẹ gbẹ ẹ́ gidigidi, ó ké pe Olúwa, wí pé, “Ìwọ ti fún ìránṣẹ́ ní ìṣẹ́gun tí ó tóbi yìí. Ṣé èmi yóò ha kú pẹ̀lú òǹgbẹ, kí èmi sì ṣubú sí ọwọ́ àwọn aláìkọlà ènìyàn?”
19 A Bóg rozszczepił [wgłębienie] skalne, które było w Lechi, i wyszły z niego wody. Napił się i ożył jego duch, i odzyskał siły. Dlatego nadał temu miejscu nazwę: En-Hakkore, a jest [ono] w Lechi aż do dziś.
Nígbà náà ni Ọlọ́run la kòtò ìsun omi tí ó wà ní Lehi, omi sì tú jáde láti inú rẹ̀. Nígbà tí Samsoni mú mi tan, agbára rẹ̀ sì padà, ọkàn sì sọjí, fún ìdí èyí wọ́n pe ìsun omi náà ni. Ẹni Hakkore (orísun ẹni tí ó pe Ọlọ́run) èyí tí ó sì wà ní Lehi di òní.
20 I sądził Izraela za dni Filistynów przez dwadzieścia lat.
Samsoni ṣe ìdájọ́ Israẹli fún ogún ọdún ní àkókò àwọn ará Filistini.

< Księga Sędziów 15 >