< Księga Sędziów 14 >
1 Samson poszedł do Timny i zobaczył tam kobietę z córek Filistynów.
Nígbà kan Samsoni gòkè lọ sí Timna níbẹ̀ ni ó ti rí ọmọbìnrin Filistini kan.
2 A gdy wrócił, oznajmił swemu ojcu i swej matce: Widziałem w Timnie kobietę z córek Filistynów. Weźcie mi ją więc za żonę.
Nígbà tí ó darí dé, ó sọ fún àwọn òbí rẹ̀ pé, “Mo rí obìnrin Filistini kan ní Timna: báyìí ẹ fẹ́ ẹ fún mi bí aya mi.”
3 Jego ojciec i matka powiedzieli mu: Czy nie ma kobiety wśród córek twych braci ani w całym moim ludzie, że chcesz iść i wziąć sobie żonę spośród nieobrzezanych Filistynów? Samson odpowiedział swemu ojcu: Weźcie mi tę, bo spodobała się moim oczom.
Baba àti ìyá rẹ̀ dáhùn pé, “Ṣé kò sí obìnrin tí ó dára tí ó sì tẹ́ ọ lọ́rùn ní àárín àwọn ìbátan rẹ, tàbí láàrín gbogbo àwọn ènìyàn wa? Ṣé ó di dandan fún ọ láti lọ sí àárín àwọn Filistini aláìkọlà kí o tó fẹ́ ìyàwó?” Ṣùgbọ́n Samsoni wí fún baba rẹ̀ pé, “Fẹ́ ẹ fún mi torí pé inú mi yọ́ sí i púpọ̀púpọ̀.”
4 A jego ojciec i matka nie wiedzieli, że to wyszło od PANA, bo on szukał sposobności przeciwko Filistynom. W tym czasie bowiem Filistyni panowali nad Izraelem.
(Àwọn òbí rẹ̀ kò mọ̀ pé ọ̀dọ̀ Olúwa ni nǹkan yìí ti wá, ẹni tí ń wá ọ̀nà àti bá Filistini jà; nítorí àwọn ni ń ṣe àkóso Israẹli ní àkókò náà.)
5 Samson poszedł więc ze swoim ojcem i [swoją] matką do Timny i przyszli do winnic Timny. A oto młody, ryczący lew wybiegł mu naprzeciw.
Samsoni sọ̀kalẹ̀ lọ sí Timna òun àti baba àti ìyá rẹ̀. Bí wọ́n ṣe ń súnmọ́ àwọn ọgbà àjàrà tí ó wà ní Timna, láìròtẹ́lẹ̀, ọ̀dọ́ kìnnìún kan jáde síta tí ń ké ramúramù bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀.
6 Wtedy Duch PANA zawładnął nim i rozdarł on lwa, jakby rozdarł koźlę, choć nie miał nic w ręku. Jednak swojemu ojcu i [swojej] matce nie powiedział o tym, co uczynił.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé e pẹ̀lú agbára tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi fa kìnnìún náà ya pẹ̀lú ọwọ́ rẹ̀ lásán bí ẹní ya ọmọ ewúrẹ́, ṣùgbọ́n òun kò sọ ohun tí ó ṣe fún baba tàbí ìyá rẹ̀.
7 Potem przyszedł i rozmawiał z tą kobietą, a ona podobała się Samsonowi.
Ó sì lọ bá obìnrin náà sọ̀rọ̀, inú Samsoni sì yọ́ sí i.
8 A kiedy po kilku dniach wrócił, aby ją pojąć [za żonę], zboczył [z drogi], aby obejrzeć padlinę lwa. A oto rój pszczół i miód [były] w padlinie lwa.
Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, nígbà tí ó padà lọ láti gbé e níyàwó, ó yà lọ láti wo òkú kìnnìún náà. Inú rẹ̀ ni ó ti bá ọ̀pọ̀ ìṣù oyin àti oyin,
9 Wziął go do rąk, szedł drogą i jadł, a gdy przyszedł do swego ojca i [swej] matki, dał im i jedli. Nie powiedział im jednak, że miodu nabrał z padliny lwa.
ó fi ọwọ́ ha jáde, ó sì ń jẹ ẹ́ bí ó ti ń lọ. Nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ àwọn òbí rẹ̀, ó fún wọn ní díẹ̀, àwọn náà sì jẹ, ṣùgbọ́n kò sọ fún wọn pé ara òkú kìnnìún ni òun ti rí oyin náà.
10 Potem jego ojciec poszedł do tej kobiety i Samson wyprawił tam wesele. Tak bowiem zwykli czynić młodzieńcy.
Baba rẹ̀ sì sọ̀kalẹ̀ lọ láti kí obìnrin náà. Samsoni sì ṣe àsè gẹ́gẹ́ bí àṣà ọkọ ìyàwó ní àkókò náà.
11 A gdy [Filistyni] ujrzeli go, wzięli trzydziestu towarzyszy, aby przy nim byli.
Nígbà tí ó fi ara hàn, tí àwọn ènìyàn náà rí i wọ́n fún un ní ọgbọ̀n àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ láti wá bá a kẹ́gbẹ́.
12 I Samson powiedział do nich: Zadam wam zagadkę. Jeśli ją rozwiążecie w ciągu siedmiu dni wesela i wyjaśnicie mi ją, dam wam trzydzieści prześcieradeł i trzydzieści szat zamiennych.
Samsoni sọ fún wọn pé, “Ẹ jẹ́ kí n pa àlọ́ kan fún un yín, bí ẹ̀yin bá lè fún mi ní ìtumọ̀ rẹ̀ láàrín ọjọ́ méje àsè yìí, tàbí ṣe àwárí àlọ́ náà èmi yóò fún un yín ní ọgbọ̀n aṣọ tí a fi òwú ọ̀gbọ̀ hun, àti ọgbọ̀n ìpààrọ̀ aṣọ ìyàwó.
13 A jeśli mi [jej] nie rozwiążecie, wtedy to wy dacie mi trzydzieści prześcieradeł i trzydzieści szat zamiennych. Odpowiedzieli mu: Zadaj swoją zagadkę, a my jej posłuchamy.
Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin kò bá le sọ ìtumọ̀ rẹ̀ fún mi, ẹ̀yin yóò fún mi ní ọgbọ̀n aṣọ tí a fi òwú ọ̀gbọ̀ hun àti ọgbọ̀n ìpààrọ̀ aṣọ ìgbéyàwó.” Wọ́n dáhùn pé, “Sọ àlọ́ rẹ fún wa jẹ́ kí a gbọ́.”
14 I powiedział do nich: Z pożerającego wyszedł pokarm, a z mocnego wyszła słodycz. I przez trzy dni nie mogli rozwiązać tej zagadki.
Ó dáhùn pé, “Láti inú ọ̀jẹun ni ohun jíjẹ ti jáde wá; láti inú alágbára ni ohun dídùn ti jáde wá.” Ṣùgbọ́n fún odidi ọjọ́ mẹ́ta ni wọn kò fi rí ìtumọ̀ sí àlọ́ náà.
15 I powiedzieli siódmego dnia do żony Samsona: Namów swego męża, aby nam zdradził zagadkę, inaczej spalimy ogniem ciebie i dom twego ojca. Czy po to nas wezwaliście, aby nas ograbić? Czy nie po to?
Ní ọjọ́ kẹrin, wọ́n wí fún ìyàwó Samsoni, pé, “Tan ọkọ rẹ kí ó lè ṣe àlàyé àlọ́ náà fún wa, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ àwa yóò sun ìwọ àti ìdílé baba rẹ̀ ní iná. Tàbí ṣe o pè wá sí ibi àsè yìí láti sọ wá di òtòṣì tàbí kó wa lẹ́rú ni?”
16 Płakała więc żona Samsona przed nim, mówiąc: Tak naprawdę nienawidzisz mnie i nie kochasz mnie. Zadałeś synom mego ludu zagadkę i nie chcesz mi jej wyjaśnić. I powiedział jej: Oto nie wyjaśniłem jej swojemu ojcu i [swojej] matce, a tobie miałbym ją wyjaśnić?
Nígbà náà ni ìyàwó Samsoni ṣubú lé e láyà, ó sì sọkún ní iwájú rẹ̀ pé, “O kórìíra mi! O kò sì ní ìfẹ́ mi nítòótọ́, o pàlọ́ fún àwọn ènìyàn mi, ìwọ kò sì sọ ìtumọ̀ rẹ̀ fún mi.” “Èmi kò tí ì ṣe àlàyé rẹ̀ fún baba àti ìyá mi, báwo ni èmi ó ṣe sọ ìtumọ̀ rẹ̀ fún ọ.”
17 I płakała przed nim przez siedem dni, póki trwało wesele. A siódmego dnia wyjaśnił jej, bo mu się naprzykrzała. A ona powiedziała zagadkę synom swego ludu.
Fún gbogbo ọjọ́ méje tí wọ́n fi ṣe àsè náà ni ó fi sọkún, nítorí náà ní ọjọ́ keje ó sọ ìtumọ̀ àlọ́ fún un nítorí pé ó yọ ọ́ lẹ́nu ní ojoojúmọ́. Òun náà sì sọ ìtumọ̀ àlọ́ náà fún àwọn ènìyàn rẹ̀.
18 A siódmego dnia przed zachodem słońca mężczyźni tego miasta powiedzieli do niego: Cóż słodszego nad miód, a co mocniejszego nad lwa? On im odpowiedział: Gdybyście nie orali moją jałowicą, nie odgadlibyście mojej zagadki.
Kí ó tó di àṣálẹ́ ọjọ́ keje àwọn ọkùnrin ìlú náà sọ fún un pé, “Kí ni ó dùn ju oyin lọ? Kí ni ó sì lágbára ju kìnnìún lọ?” Samsoni dá wọn lóhùn pé, “Bí kì í bá ṣe pé ẹ fi ọ̀dọ́ abo màlúù mi kọ ilẹ̀, ẹ̀yin kò bá tí mọ ìtumọ̀ sí àlọ́ mi.”
19 Potem zstąpił na niego Duch PANA i poszedł do Aszkelonu, zabił trzydziestu mężczyzn spośród nich, zdjął z nich łupy i dał [szaty] zamienne tym, którzy rozwiązali zagadkę. I rozpalił się jego gniew, i poszedł do domu swojego ojca.
Lẹ́yìn èyí, ẹ̀mí Olúwa bà lé e pẹ̀lú agbára. Ó lọ sí Aṣkeloni, ó pa ọgbọ̀n nínú àwọn ọkùnrin wọn, ó gba àwọn ohun ìní wọn, ó sì fi àwọn aṣọ wọn fún àwọn tí ó sọ ìtumọ̀ àlọ́ náà. Ó sì padà sí ilé baba rẹ̀ pẹ̀lú ìbínú ríru.
20 Żona Samsona zaś została oddana jego towarzyszowi, który był jego przyjacielem.
Wọ́n sì fi ìyàwó Samsoni fún ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, tí ó jẹ́ ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ rẹ̀ nígbà ìgbéyàwó rẹ̀.