< Nehemiasza 9 >

1 Potem dnia dwudziestego i czwartego tegoż miesiąca zgromadzili się synowie Izraelscy, i pościli w worzech, i posypali się prochem.
Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kan náà, àwọn ọmọ Israẹli péjọpọ̀, wọ́n gbààwẹ̀, wọ́n wọ aṣọ ọ̀fọ̀, wọ́n sì da eruku sórí ara wọn.
2 A odłączyło się nasienie Izraelskie od wszystkich cudzoziemców, a stanąwszy wyznawali grzechy swe i nieprawości ojców swych.
Àwọn ọkùnrin Israẹli sì ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò nínú gbogbo àwọn àjèjì. Wọ́n dúró ní ààyè e wọn, wọ́n sì ń jẹ́wọ́ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ẹ wọn àti iṣẹ́ búburú àwọn baba wọn.
3 I powstali na miejscach swych, a czytali księgi zakonu Pana, Boga swego, cztery kroć przez dzień, i cztery kroć wyznawali a kłaniali się Panu Bogu swemu.
Wọ́n dúró sí ibi tí wọ́n wà, wọ́n sì fi ìdámẹ́rin ọjọ́ kà nínú ìwé òfin Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì tún fi ìdámẹ́rin mìíràn ní ìjẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti ní sí sin Olúwa Ọlọ́run wọn.
4 Zatem stanęli na stopniach Lewitów Jesua i Bani, Kadmiel, Sebanijasz, Bunni, Serebijasz, Bani, Chenani, a wołali głosem wielkim do Pana Boga swego.
Nígbà náà ni Jeṣua, àti Bani, Kadmieli, Ṣebaniah, Bunni, Ṣerebiah, Bani àti Kenaani gòkè dúró lórí àwọn àtẹ̀gùn àwọn ọmọ Lefi, wọ́n sì fi ohùn rara kígbe sí Olúwa Ọlọ́run wọn.
5 I mówili Lewitowie Jesua, i Kadmiel, Bani, Hasabnejasz, Serebijasz, Odyjasz, Sebanijasz, Petachyjasz: Wstańcie, błogosławcie Panu, Bogu waszemu, od wieku aż na wieki, a niech błogosławią imieniowi twojemu chwalebnemu i wywyższonemu nad wszelkie błogosławieństwo i chwałę.
Nígbà náà ni àwọn ọmọ Lefi: Jeṣua, Kadmieli, Bani, Haṣbneiah, Ṣerebiah, Hodiah, Ṣebaniah àti Petahiah—wí pé, “Ẹ dìde ẹ fi ìyìn fún Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó wà láé àti láéláé.” “Ìbùkún ni fún orúkọ rẹ tí ó ní ògo, kí ó sì di gbígbéga ju gbogbo ìbùkún àti ìyìn lọ.
6 Ty, Panie! sam, ty sam, tyś uczynił niebo, nieba niebios, i wszystko wojsko ich, ziemię, i wszystko co jest na niej, morza, i wszystko, co w nich jest, a ty ożywiasz to wszystko; a wojska niebieskie tobie się kłaniają.
Ìwọ nìkan ni Olúwa. Ìwọ ni ó dá ọ̀run, àní àwọn ọ̀run tí ó ga jù pẹ̀lú gbogbo ogun wọn, ayé àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀, òkun, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀. Ìwọ sì pa gbogbo wọn mọ́ láàyè, ogun ọ̀run sì ń sìn ọ́.
7 Tyś jest, Panie Boże! któryś wybrał Abrama, a wywiodłeś go z Ur Chaldejskiego, i dałeś mu imię Abraham.
“Ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run, tí ó yan Abramu tí ó sì mú u jáde láti Uri ti Kaldea, tí ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Abrahamu.
8 I znalazłeś serce jego wierne przed obliczem twojem, i uczyniłeś z nim przymierze, że dasz ziemię Chananejczyka, Hetejczyka, Amorejczyka, i Ferezejczyka, i Jebuzejczyka, i Giergiezejczyka, że ją dasz nasieniu jego, i ziściłeś słowa twoje; boś ty sprawiedliwy.
Ìwọ sì rí í pé ọkàn rẹ̀ jẹ́ olóòtítọ́ sí ọ, ìwọ sì dá májẹ̀mú pẹ̀lú u rẹ̀ láti fi ilẹ̀ àwọn ará a Kenaani, Hiti, Amori, Peresi, Jebusi àti Girgaṣi fún irú àwọn ọmọ rẹ̀. Ìwọ ti pa ìpinnu rẹ̀ mọ́ nítorí tí ìwọ jẹ́ olódodo.
9 Wejżałeś zaiste na utrapienie ojców naszych w Egipcie, a wołanie ich wysłuchałeś nad morzem Czerwonem.
“Ìwọ rí ìpọ́njú àwọn baba ńlá wa ní Ejibiti; ìwọ gbọ́ igbe ẹkún wọn ní Òkun Pupa.
10 A pokazywałeś znaki i cuda na Faraonie, i na wszystkich sługach jego, i na wszystkim ludu ziemi jego; boś poznał, że sobie hardzie postępowali przeciwko nim, i uczyniłeś sobie imię, jako się to dziś pokazuje.
Ìwọ rán iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu sí Farao, sí gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ àti sí gbogbo ènìyàn ilẹ̀ ẹ rẹ̀, nítorí ìwọ mọ ìwà ìgbéraga tí àwọn ará Ejibiti hù sí wọn. Ìwọ ra orúkọ fún ara à rẹ, èyí tí ó sì wà títí di òní yìí.
11 I rozdzieliłeś morze przed nimi, a przeszli przez pośrodek morza po suszy; a tych, którzy ich gonili, wrzuciłeś w głębokości, jako kamień w wody gwałtowne.
Ìwọ pín òkun níwájú wọn, nítorí kí wọn lè kọjá ní ìyàngbẹ ilẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ sọ àwọn tí ń lépa wọn sínú ibú, bí òkúta sínú omi ńlá.
12 A w słupie obłokowym prowadziłeś ich we dnie, a w słupie ognistym w nocy, abyś im oświecał drogę, którą iść mieli.
Ní ọ̀sán ìwọ darí i wọn pẹ̀lú ọ̀wọn àwọsánmọ̀ àti ní òru ni ìwọ darí i wọn pẹ̀lú ọ̀wọn iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀nà tí wọn yóò gbà.
13 Potemeś na górę Synaj zstąpił, i mówiłeś do nich z nieba, a dałeś im sądy prawe, i zakony prawdziwe, ustawy i rozkazania dobre.
“Ìwọ sọ̀kalẹ̀ wá sí orí òkè Sinai; ìwọ bá wọn sọ̀rọ̀ láti ọ̀run. Ìwọ fún wọn ní ìlànà àti àwọn òfin tí ó jẹ́ òdodo tí ó sì tọ́ àti ìlànà tí ó dára.
14 I sabat twój święty oznajmiłeś im, a przykazania i ustawy, i zakon wydałeś im przez Mojżesza, sługę twego.
Ìwọ mú ọjọ́ ìsinmi rẹ mímọ́ di mí mọ̀ fún wọn, o sì fún wọn ní àwọn ìlànà, àwọn àṣẹ àti àwọn òfin láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ.
15 Dałeś im też chleb w głodzie ich z nieba, i wodęś im z skały wywiódł w pragnieniu ich, a rozkazałeś im, aby szli, i posiedli ziemię, o którąś podniósł rękę swą, że im ją dasz.
Ìwọ fún wọn ní oúnjẹ láti ọ̀run wá nígbà tí ebi ń pa wọ́n àti nígbà òǹgbẹ, o fún wọn ní omi láti inú àpáta; o sì sọ fún wọn pé, kí wọ́n lọ láti lọ gba ilẹ̀ náà tí ìwọ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti fi fún wọn nípa ìgbọ́wọ́sókè.
16 Ale oni i ojcowie nasi hardzie sobie poczynali, i zatwardzili kark swój, i nie słuchali rozkazania twego.
“Ṣùgbọ́n àwọn, baba ńlá wa, wọ́n ṣe ìgbéraga, wọ́n sì ṣe agídí, wọn kò sì tẹríba fún àwọn ìlànà rẹ.
17 Owszem nie chcieli słuchać, ani wspomnieli na cuda twoje, któreś czynił, przy nich; ale zatwardziwszy kark swój postanowili sobie wodza, chcąc się wrócić w niewolę swoję w uporze swoim. Lecz ty, o Boże miłościwy, łaskawy, i miłosierny, nieskwapli wy, i wielkiego miłosierdzia! nie opuściłeś ich.
Wọ́n kọ̀ láti fetísílẹ̀, wọ́n sì kùnà láti rántí iṣẹ́ ìyanu tí ìwọ ṣe ní àárín wọn. Wọ́n ṣe agídí, nínú ìṣọ̀tẹ̀ wọn, wọ́n yan olórí láti padà sí oko ẹrú wọn. Ṣùgbọ́n ìwọ Ọlọ́run tí ó ń dáríjì, olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú, ó lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́. Nítorí náà ìwọ kò sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀,
18 Nawet gdy sobie uczynili cielca ulanego, a mówili: Ten jest Bóg twój, który cię wywiódł z ziemi Egipskiej, i dopuścili się bluźnierstw wielkich,
nítòótọ́ nígbà tí wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù dídá, tí wọ́n sì wí pé, ‘Èyí ni Ọlọ́run rẹ tí ó mú ọ gòkè láti Ejibiti wá; tàbí nígbà tí wọ́n sọ ọ̀rọ̀-òdì tí ó burú jàì’.
19 Ty jednak dla litości twoich wielkich nie opuściłeś ich na puszczy; słup obłokowy nie odstąpił od nich we dnie, prowadząc ich w drodze, ani słup ognisty w nocy, oświecając ich, i drogę, którą iść mieli.
“Nítorí àánú ńlá rẹ, ìwọ kò kọ̀ wọ́n sílẹ̀ ní aginjù. Ní ọ̀sán ọ̀wọn ìkùùkuu kò kúrò ní ọ̀dọ̀ wọn láti ṣe amọ̀nà an wọn, tàbí ọ̀wọ́n iná láti tàn sí wọn ní òru ní ọ̀nà tí wọn yóò rìn.
20 Nadto ducha twojego dobrego dałeś im, aby ich uczył, i manny twojej nie odjąłeś od ust ich, i wodę dałeś im w pragnieniu ich.
Ìwọ fi ẹ̀mí rere rẹ fún wọn láti kọ́ wọn. Ìwọ kò dá manna rẹ dúró ní ẹnu wọn, ó sì fún wọn ní omi fún òǹgbẹ.
21 A tak przez czterdzieści lat żywiłeś ich na puszczy; na niczem im nie schodziło, szaty ich nie zwiotszały, i nogi ich nie napuchły.
Fún ogójì ọdún ni ìwọ fi bọ́ wọn ní aginjù; wọn kò ṣe aláìní ohunkóhun, aṣọ wọn kò gbó bẹ́ẹ̀ ni ẹsẹ̀ wọn kò wú.
22 I podałeś im królestwa i narody, któreś rozegnał po kątach, tak, że posiedli ziemię Sehonową, i ziemię króla Hesebońskiego, i ziemię Oga, króla Basańskiego.
“Ìwọ fi àwọn ìjọba àti àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn, ó sì fi gbogbo ilẹ̀ náà fún wọ́n. Wọ́n sì gba ilẹ̀ ọba Sihoni ará a Heṣboni àti ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani.
23 A synów ich rozmnożyłeś jako gwiazdy niebieskie, i wwiodłeś ich do ziemi, o którejś mawiał ojcom ich, że wnijdą i posiędą ją.
Ìwọ ti mú àwọn ọmọ wọn pọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ tí o ti sọ fún àwọn baba wọn pé kí wọn wọ̀, kí wọn sì jogún un rẹ̀.
24 Bo przyszedłszy synowie ich posiedli tę ziemię, gdyś poniżył przed nimi obywateli onej ziemi, Chananejczyków, i podałeś ich w ręce ich, i królów ich, i narody onej ziemi, aby się z nimi obchodzili według woli swojej.
Àwọn ọkùnrin wọn wọ inú rẹ̀, wọ́n sì gbà ilẹ̀ náà. Ìwọ sì tẹ orí àwọn ará a Kenaani, tí ń gbé inú ilẹ̀ náà ba níwájú wọn; ó fi àwọn ará a Kenaani lé wọn lọ́wọ́ pẹ̀lú àwọn ọba wọn àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà kí wọn ṣe wọn bí ó ti wù wọ́n.
25 Pobrali tedy miasta obronne, i ziemię tłustą, i posiedli domy pełne wszelkich dóbr, studnie wykopane, winnice, oliwnice, i drzew rodzajnych bardzo wiele; a jedli, i byli nasyceni, i otyli, i opływali w rozkoszy z dobroci twojej wielkiej.
Wọ́n gba àwọn ìlú olódi àti ilẹ̀ ọlọ́ràá; wọ́n gba àwọn ilé tí ó kún fún onírúurú gbogbo nǹkan rere, àwọn kànga tí a ti gbẹ́, àwọn ọgbà àjàrà, àwọn ọgbà olifi àti àwọn igi eléso ní ọ̀pọ̀lọpọ̀. Wọ́n jẹ, wọ́n yó, wọ́n sì sanra dáradára; wọ́n sì yọ̀ nínú oore ńlá rẹ.
26 Ale gdy cię rozdraźnili, i stalić się odpornymi, zarzuciwszy zakon twój w tył swój, a proroków twoich pobili, którzy się oświadczali przed nimi, aby ich nawrócili do ciebie, i dopuszczali się bluźnierstwa wielkiego:
“Ṣùgbọ́n wọ́n ṣe àìgbọ́ràn, wọ́n sì ṣọ̀tẹ̀ sí ọ; wọ́n gbàgbé òfin rẹ. Wọ́n pa àwọn wòlíì rẹ, tí o fi gbà wọn ni ìyànjú pé kí wọn yí padà sí ọ; wọ́n sì se ọ̀rọ̀-òdì tí ó burú jàì.
27 Podałeś ich w ręce nieprzyjaciołom ich, którzy ich trapili. A gdy czasu utrapienia swego wołali do ciebie, tyś ich z nieba wysłuchał, a według litości twoich wielkich dawałeś im wybawicieli, którzy ich wybawiali z rąk nieprzyjaciół ich.
Nítorí náà, ìwọ fi wọ́n lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, àwọn tí ó ni wọ́n lára. Ṣùgbọ́n nígbà tí a ni wọ́n lára wọ́n kígbe sí ọ. Ìwọ gbọ́ wọn láti ọ̀run wá àti nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, ìwọ fún wọn ní olùgbàlà, tí ó gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn.
28 Wtem, gdy trochę odpoczęli, znowu czynili złość przed twarzą twoją; przetoż opuściłeś ich w ręce nieprzyjaciół ich, aby panowali nad nimi. Lecz gdy się znowu nawrócili, a wołali do ciebie, tyś ich z nieba wysłuchał, i wybawiłeś ich według litości twoich przez wiele czasów.
“Ṣùgbọ́n bí wọ́n bá ti wà nínú ìsinmi, wọn a sì túnṣe búburú lójú rẹ. Nígbà náà ni ìwọ kọ̀ wọ́n sílẹ̀ ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá kí wọ́n lè jẹ ọba lórí wọn. Nígbà tí wọ́n bá sì tún kígbe sí ọ, ìwọ a gbọ́ láti ọ̀run wá, àti nínú àánú rẹ ni ìwọ gbà láti ìgbà dé ìgbà.
29 I oświadczałeś się przed nimi, abyś ich nawrócił do zakonu swego; ale oni sobie hardzie poczynali, a niesłuchali przykazań twoich, owszem przeciw sądom twoim grzeszyli, które gdyby człowiek czynił, żyłby przez nie; ale uchylając ramion swych, kark swój zatwardzili, i nie słuchali.
“Ìwọ kìlọ̀ fún wọn láti padà sínú òfin rẹ, ṣùgbọ́n wọ́n hu ìwà ìgbéraga, wọ́n sì ṣe àìgbọ́ràn si àṣẹ rẹ. Wọ́n ṣẹ̀ sí ìlànà rẹ, nípa èyí tí ènìyàn yóò yè tí wọ́n bá pa wọ́n mọ́. Nínú agídí ọkàn wọ́n kọ ẹ̀yìn sí ọ, wọ́n jẹ́ olórí kunkun wọn kò sì fẹ́ gbọ́.
30 Wszakżeś ty im folgował przez wiele lat, oświadczając się przed nimi Duchem twym przez proroków twoich; a gdy nie słuchali, podałeś ich w ręce narodów onych ziem.
Fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ni ìwọ fi ní sùúrù pẹ̀lú wọn. Nípa ẹ̀mí rẹ ni ìwọ kìlọ̀ fún wọn nípasẹ̀ àwọn wòlíì. Síbẹ̀ wọn kò fi etí sílẹ̀, nítorí náà ni ìwọ ṣe fi wọ́n lé àwọn aládùúgbò wọn lọ́wọ́.
31 Ale dla litości twoich wielkich nie dałeś ich na wytracenie, aniś ich opuścił; boś ty Bóg łaskawy i miłosierny.
Ṣùgbọ́n nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ, ìwọ kò mú òpin bá wọn tàbí kọ̀ wọ́n sílẹ̀, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú.
32 Teraz tedy o Boże nasz, Boże wielki, możny, i straszny! który strzeżesz przymierza i miłosierdzia, niech nie będzie małe przed tobą każde utrapienie, które przyszło na nas, na królów naszych, na kaiążąt naszych, i na kapłanów naszych, i na proroków naszych, i na ojców naszych, i na wszystek lud twój, ode dni królów Assyryjskich aż do dnia tego;
“Ǹjẹ́ nítorí náà, Ọlọ́run wa, Ọlọ́run tí ó tóbi, tí ó lágbára, tí ó sì ní ẹ̀rù, ẹni tí ó pa májẹ̀mú ìfẹ́ mọ́, má ṣe jẹ́ gbogbo ìnira yìí dàbí ohun kékeré ní ojú rẹ—ìnira tí ó ti wá sórí wa, sórí àwọn ọba wa àti àwọn olórí wa, sórí àwọn àlùfáà wa àti àwọn wòlíì, sórí àwọn baba wa àti sórí gbogbo ènìyàn rẹ̀, láti àwọn ọjọ́ àwọn ọba Asiria wá títí di òní.
33 Acześ ty jest sprawiedliwy we wszystkiem tem, co przyszło na nas; boś sprawiedliwie uczynił, a myśmy niezbożnie czynili.
Ìwọ jẹ́ olódodo nínú ohun gbogbo tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wa; ìwọ sì ti ṣe òtítọ́, nígbà tí a bá ṣe búburú.
34 I królowie nasi, książęta nasi, kapłani nasi, i ojcowie nasi nie pełnili zakonu twego, i nie przestrzegali przykazań twoich, i świadectw twych, któremiś się oświadczał przed nimi.
Àwọn ọba wa, àwọn olórí wa, àwọn àlùfáà wa, àti àwọn baba wa kò tẹ̀lé òfin rẹ; wọn kò fetísílẹ̀ sí àṣẹ rẹ tàbí àwọn ìkìlọ̀ tí ìwọ fún wọn.
35 Bo oni w królestwie swem i w dobroci twojej wielkiej, którąś im pokazał, i w ziemi przestronnej i tłustej, którąś im był dał, nie służyli tobie, ani się odwrócili od spraw złych swoich.
Àní nígbà tí wọ́n wà nínú ìjọba wọn, tí wọ́n ń gbádùn oore ńlá tí ìwọ fi fún wọn, ní ilẹ̀ tí ó tóbi tí ó sì lọ́ràá, wọn kò sìn ọ́ tàbí padà kúrò nínú àwọn ọ̀nà búburú wọn.
36 Oto myśmy dziś niewolnikami, i ziemia, którąś dał ojcom naszym, aby jedli owoc jej, i dobra jej, otośmy niewolnikami w niej.
“Ṣùgbọ́n wò ó, àwa jẹ́ ẹrú lónìí, àwa jẹ́ ẹrú ní ilẹ̀ tí ìwọ fún àwọn baba ńlá wa, nítorí kí wọn bá máa jẹ èso rẹ̀ àti ìre mìíràn tí ó mú jáde.
37 Już urodzaje swoje obfite wydaje królom, któreś postanowił nad nami dla grzechów naszych; panują nad ciały naszemi, i nad bydłem naszem według woli swej, tak, żeśmy w wielkiem uciśnieniu.
Nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkórè rẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ọba tí ó fi ṣe olórí wa. Wọ́n ń ṣe àkóso lórí wa àti lórí ẹran wa bí ó ti wù wọ́n, àwa sì wà nínú ìpọ́njú ńlá.
38 Wszakże w tem wszystkiem czynimy mocne przymierze, i zapisujemy je, które pieczętują książęta nasi, Lewitowie nasi, i kapłani nasi.
“Nítorí gbogbo èyí, a ń ṣe àdéhùn tí ó fẹsẹ̀múlẹ̀, a sì kọ ọ́ sínú ìwé, àwọn olórí ọmọ Lefi àwọn àlùfáà sì fi èdìdì dì í.”

< Nehemiasza 9 >