< Izajasza 45 >

1 To mówi Pan pomazańcowi swemu Cyrusowi, którego prawicę ujmę, a porażę przed nim narody, i biodra królów rozpaszę, a pootwieram przed nim wrota, i bramy nie będą zamknięte.
“Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún ẹni òróró rẹ̀, sí Kirusi, ọwọ́ ọ̀tún ẹni tí mo dì mú láti dojú àwọn orílẹ̀-èdè bolẹ̀ níwájú rẹ̀ àti láti gba ohun ìjà àwọn ọba lọ́wọ́ wọn, láti ṣí àwọn ìlẹ̀kùn níwájú rẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé a kì yóò ti àwọn ẹnu-ọ̀nà.
2 Ja przed tobą pójdę, a krzywe drogi wyprostuję, wrota miedziane skruszę, a zawory żelazne porąbię;
Èmi yóò lọ síwájú rẹ, Èmi ó sì tẹ́ àwọn òkè ńlá pẹrẹsẹ Èmi yóò fọ gbogbo ẹnu-ọ̀nà idẹ èmi ó sì gé ọ̀pá irin.
3 I dam ci skarby skryte, i klejnoty schowane, abyś poznał, żem Ja Pan, Bóg Izraelski, który cię przyzywam imieniem twojem.
Èmi yóò sì fún ọ ní àwọn ọrọ̀ ibi òkùnkùn, ọrọ̀ tí a kó pamọ́ sí àwọn ibi tí ó fi ara sin, tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ yóò fi mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ.
4 Dla sługi mego Jakóba, i dla Izraela, wybranego mego, nazwałem cię imieniem twojem, przezwiskiem twojem, chociaż mię nie znasz.
Nítorí Jakọbu ìránṣẹ́ mi àti Israẹli ẹni tí mo yàn, Mo pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ, mo sì gbé oyè kan kà ọ́ lórí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò gbà mí.
5 Jam Pan, a niemasz żadnego więcej, oprócz mnie niemasz żadnego Boga; przepasałem cię, aczkolwiek mię nie znasz:
Èmi ni Olúwa, àti pé kò sí ẹlòmíràn; yàtọ̀ sí èmi kò sí ọlọ́run kan, Èmi yóò fún ọ ní okun, bí o kò tilẹ̀ tí ì gbà mí,
6 Aby poznali od wschodu słońca, i od zachodu słońca, iż niemasz żadnego oprócz mnie, Jam Pan, a niemasz żadnego więcej;
tí o fi jẹ́ pé láti ìlà-oòrùn títí dé ibi ìwọ̀ rẹ̀ kí ènìyàn le mọ̀, kò sí ẹnìkan lẹ́yìn mi. Èmi ni Olúwa, lẹ́yìn mi kò sí ẹlòmíràn mọ́.
7 Który czynię światłość, i stwarzam ciemności; sprawuję pokój, i stwarzam złe. Ja Pan czynię to wszystko.
Mo dá ìmọ́lẹ̀, mo sì dá òkùnkùn, Mo mú àlàáfíà wá, Mo sì dá àjálù; Èmi Olúwa ni ó ṣe nǹkan wọ̀nyí.
8 Spuście niebiosa rosę z góry, a obłoki niech kropią sprawiedliwość; niech się otworzy ziemia, a niech wyrośnie zbawienie, a sprawiedliwość niech wespół zakwitnie. Ja Pan sprawię to.
“Ìwọ ọ̀run lókè rọ òjò òdodo sílẹ̀; jẹ́ kí àwọsánmọ̀ kí ó rọ̀ ọ́ sílẹ̀. Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó yanu gbagada, jẹ́ kí ìgbàlà kí ó dìde sókè, jẹ́ kí òdodo kí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀; Èmi Olúwa ni ó ti dá a.
9 Biada temu, który się spiera z stworzycielem swoim, będąc skorupą, jako inne skorupy gliniane. Izali glina rzecze garncarzowi swemu: Cóż czynisz? Robota twoja zaprawdę nikczemna jest.
“Ègbé ni fún ènìyàn tí ó ń bá Ẹlẹ́dàá rẹ̀ jà, ẹni tí òun jẹ́ àpáàdì kan láàrín àwọn àpáàdì tí ó wà lórí ilẹ̀. Ǹjẹ́ amọ̀ lè sọ fún amọ̀kòkò, pé: ‘Kí ni ohun tí ò ń ṣe?’ Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ lè sọ pé, ‘Òun kò ní ọwọ́?’ (questioned)
10 Biada temu, który mówi ojcu: Cóż płodzisz? a niewieście: Cóż porodzisz?
Ègbé ni fún ẹni tí ó sọ fún baba rẹ̀ pé, ‘Kí ni o bí?’ tàbí sí ìyá rẹ̀, ‘Kí ni ìwọ ti bí?’
11 Tak mówi Pan, Święty Izraelski, i Twórca jego: O przyszłe rzeczy pytajcie mię, a synów moich, i sprawę rąk moich poruczajcie mi.
“Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Ẹni Mímọ́ Israẹli, àti Ẹlẹ́dàá rẹ̀. Nípa ohun tí ó ń bọ̀, ǹjẹ́ o ń bi mí léèrè nípa àwọn ọmọ mi, tàbí kí o pàṣẹ fún mi nípa iṣẹ́ ọwọ́ mi bí?
12 Jam uczynił ziemię, i człowiekam na niej stworzył. Jam jest, którego ręce rozciągnęły niebiosa, a wszystkiemu wojsku ich rozkazuję.
Èmi ni ẹni tí ó dá ilẹ̀ ayé tí ó sì da ọmọ ènìyàn sórí i rẹ̀. Ọwọ́ mi ni ó ti ta àwọn ọ̀run; mo sì kó àwọn àgbájọ ìràwọ̀ rẹ̀ síta.
13 Jam go wzbudził w sprawiedliwości, i wszystkie drogi jego wyprostuję. Onci zbuduje miasto moje, a więźniów moich wypuści, nie za okup, ani za dar, mówi Pan zastępów.
Èmi yóò gbé Kirusi sókè nínú òdodo mi. Èmi yóò mú kí gbogbo ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́. Òun yóò tún ìlú mi kọ́ yóò sì tú àwọn àtìpó mi sílẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún owó tàbí ẹ̀bùn kan, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
14 Tak mówi Pan: Praca Egipska, i kupiectwo Murzynów, i Sebejczyków, mężowie wysocy do ciebie przyjdą, a twoi będą; za tobą chodzić będą, w pętach pójdą, tobie się kłaniać, i tobie się korzyć będą, mówiąc: Tylko w tobie jest Bóg, a niemasz żadnego więcej, oprócz tego Boga.
Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Àwọn èròjà ilẹ̀ Ejibiti àti àwọn ọjà ilẹ̀ Kuṣi, àti àwọn Sabeani— wọn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ wọn yóò sì jẹ́ tìrẹ; wọn yóò máa wọ́ tẹ̀lé ọ lẹ́yìn, wọn yóò máa wá lọ́wọ̀ọ̀wọ́. Wọn yóò máa foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀, wọn yóò sì máa bẹ̀bẹ̀ níwájú rẹ pé, ‘Nítòótọ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ kò sì ṣí ẹlòmíràn; kò sí ọlọ́run mìíràn.’”
15 Zaprawdę tyś jest Bóg skryty, Bóg Izraelski, zbawiciel.
Nítòótọ́ ìwọ jẹ́ Ọlọ́run tí ó fi ara rẹ̀ pamọ́, Ìwọ Ọlọ́run àti Olùgbàlà Israẹli,
16 Wszyscy się oni zawstydzą, i pohańbieni będą; czyniciele bałwanów społu z hańbą odstąpią.
Gbogbo àwọn tí ó ń gbẹ́ ère ni ojú yóò tì wọn yóò sì kan àbùkù; gbogbo wọn ni yóò bọ́ sínú àbùkù papọ̀.
17 Ale Izrael zbawion będzie przez Pana zbawieniem wiecznem; nie zawstydzicie się, ani będziecie pohańbieni, aż na wieki wieczne.
Ṣùgbọ́n Israẹli ni a ó gbàlà láti ọwọ́ Olúwa pẹ̀lú ìgbàlà ayérayé; a kì yóò kàn yín lábùkù tàbí kí a dójútì yín, títí ayé àìnípẹ̀kun.
18 Bo tak mówi Pan, który stworzył niebiosa (ten Bóg, który stworzył ziemię, i uczynił ją! który ją utwierdził, nie na próżno stworzył ją, na mieszkanie utworzył ją): Jam Pan, a niemasz żadnego więcej.
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí, ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run, Òun ni Ọlọ́run; ẹni tí ó mọ tí ó sì dá ayé, Òun ló ṣe é; Òun kò dá a láti wà lófo, ṣùgbọ́n ó ṣe é kí a lè máa gbé ibẹ̀, Òun wí pé: “Èmi ni Olúwa, kò sì ṣí ẹlòmíràn.
19 Nie mówiłem potajemnie na miejscu ziemskiem ciemnem; nie na próżno mówię nasieniu Jakóbowemu: Szukajcie mię. Ja Pan mówię sprawiedliwość, a zwiastuję prawość.
Èmi kò sọ̀rọ̀ níbi tí ó fi ara sin, láti ibìkan ní ilẹ̀ òkùnkùn, Èmi kò tí ì sọ fún àwọn ìran Jakọbu pé, ‘Ẹ wá mi lórí asán.’ Èmi Olúwa sọ òtítọ́, Mo sì sọ èyí tí ó tọ̀nà.
20 Zgromadźcie się, a przyjdźcie; przybliżcie się wespół, wy, którzyście pozostali między poganami. Nic nie wiedzą, którzy się z drewnianemi bałwanami swemi noszą; bo się modlą bogu, który nie może wybawić.
“Ẹ kó ara yín jọ kí ẹ sì wá; ẹ kórajọ, ẹ̀yin ìsáǹsá láti àwọn orílẹ̀-èdè wá. Aláìmọ̀kan ni àwọn tí ó ń ru ère igi káàkiri, tí wọ́n gbàdúrà sí àwọn òrìṣà tí kò le gba ni.
21 Oznajmujcież a przywiedźcie innych, a niech pospołu w radę wnijdą, a ukażą, kto to od dawnego czasu przepowiedział? kto od onego czasu oznajmił? Izali nie Ja Pan? Boć niemasz żadnego innego Boga oprócz mnie. Niemasz Boga sprawiedliwego, i zbawiciela innego oprócz mnie.
Jẹ́ kí a mọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀, fihàn wá, jẹ́ kí wọn jọ dámọ̀ràn papọ̀. Ta ló ti sọ èyí lọ́jọ́ tí o ti pẹ́, ta ló ti wí èyí láti àtètèkọ́ṣe? Kì í ha á ṣe Èmi, Olúwa? Àti pé kò sí Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi, Ọlọ́run olódodo àti olùgbàlà; kò sí ẹlòmíràn àfi èmi.
22 Obejrzyjcież się na mię, abyście zbawione były wszystkie kończyny ziemi; bom Ja Bóg, a niemasz żadnego więcej.
“Yípadà sí mi kí a sì gbà ọ́ là, ẹ̀yin ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé; nítorí Èmi ni Ọlọ́run kò sì ṣí ẹlòmíràn.
23 Przysiągłem sam przez się; wyszło z ust moich słowo sprawiedliwe, które się nazad nie wróci: Że się mnie kłaniać będzie wszelkie kolano, i przysięgać każdy język.
Nípa èmi tìkára mi ni mo ti búra, ẹnu mi ni ó ti sọ ọ́ pẹ̀lú gbogbo ipá mi, ọ̀rọ̀ náà tí a kì yóò lè parẹ́. Níwájú mi ni gbogbo orúnkún yóò wólẹ̀; nípa mi ni gbogbo ahọ́n yóò búra.
24 Mówiąc: Tylko w Panu mam wszelką sprawiedliwość i siłę. Takowi aż do niego przyjdą; ale pohańbieni będą wszyscy, którzy się gniewem zapalają przeciwko niemu.
Wọn yóò sọ ní ti èmi, ‘Nínú Olúwa nìkan ni òdodo àti agbára wà.’” Gbogbo àwọn tí ó ti bínú sí; yóò wá sọ́dọ̀ rẹ̀ a ó sì dójútì wọn.
25 W Panu usprawiedliwione będzie, i przechwalać się będzie wszystko nasienie Izraelskie.
Ṣùgbọ́n nínú Olúwa gbogbo àwọn ìran Israẹli ni a ó rí ní òdodo, a o sì gbé wọn ga.

< Izajasza 45 >