< Izajasza 44 >

1 A teraz słuchaj Jakóbie sługo mój! i ty, Izraelu! któregom wybrał.
“Ṣùgbọ́n gbọ́ nísinsin yìí, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, àti Israẹli, ẹni tí mo ti yàn.
2 Tak mówi Pan, który cię uczynił, i który cię ukształtował zaraz z żywota matki, i który cię wspomaga: Nie bój się Jakóbie, sługo mój! i uprzejmy, któregom wybrał.
Ohun tí Olúwa wí nìyìí ẹni tí ó dá ọ, ẹni tí ó ti mọ̀ ọ́n láti inú ìyá rẹ wá, àti ẹni tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ pẹ̀lú. Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu, ìránṣẹ́ mi, Jeṣuruni ẹni tí mo ti yàn.
3 Bo wyleję wody na pragnącego, a potoki na suchą ziemię; wyleję Ducha mego na nasienie twoje, i błogosławieństwo moje na potomki twoje.
Nítorí èmi yóò da omi sí ilẹ̀ tí ń pòǹgbẹ àti àwọn odò ní ilẹ̀ gbígbẹ, Èmi yóò tú Ẹ̀mí mi sí ara àwọn ọmọ rẹ, àti ìbùkún mi sórí àwọn àrọ́mọdọ́mọ rẹ.
4 I rozkrzewią się jako między trawą, i jako wierzby przy ciekących wodach.
Wọn yóò dàgbàsókè gẹ́gẹ́ bí i koríko nínú pápá oko tútù, àti gẹ́gẹ́ bí igi Poplari létí odò tí ń sàn.
5 Ten rzecze: Jam jest Pański, a ów się ozowie do imienia Jakóbowego, a inny się zapisze ręką swą Panu, i imieniem Izraelskim będzie się nazywał.
Ọ̀kan yóò wí pé, ‘Èmi jẹ́ ti Olúwa’; òmíràn yóò pe ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí orúkọ Jakọbu; bẹ́ẹ̀ ni òmíràn yóò kọ ọ́ sí ọwọ́ rẹ̀, ‘Ti Olúwa,’ yóò sì máa jẹ́ orúkọ náà Israẹli.
6 Tak mówi Pan, król Izraelski, i odkupiciel jego, Pan zastępów: oprócz mnie niemasz Boga.
“Ohun tí Olúwa wí nìyìí ọba Israẹli àti Olùdáǹdè, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ àti ẹni ìgbẹ̀yìn, lẹ́yìn mi kò sí Ọlọ́run kan.
7 Bo któż jako Ja ogłasza i opowiada to, i sporządza mi to, zaraz od onego czasu, jakom rozsądził lud na świecie? a kto przyszłe rzeczy, i to, co ma być, oznajmi im?
Ta ni ó dàbí ì mi? Jẹ́ kí o kéde rẹ̀. Jẹ́ kí ó wí kí ó sì gbé síwájú mi kí ni ó ti ṣẹlẹ̀ láti ìgbà tí mo fi ìdí àwọn ènìyàn ìṣẹ̀ǹbáyé kalẹ̀, àti kí ni ohun tí ń sì ń bọ̀, bẹ́ẹ̀ ni, jẹ́ kí ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ ohun tí ń bọ̀ wá.
8 Nie bójcież się, ani sobą trwożcie. Izalim wam tego z dawna nie oznajmił, i nie opowiedział? Tegoście wy mnie sami świadkami. Izali jest Bóg oprócz mnie? Niemasz zaiste skały; Ja o żadnej nie wiem.
Má ṣe wárìrì, má ṣe bẹ̀rù. Ǹjẹ́ èmi kò ti kéde èyí tí mo sì ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ tipẹ́tipẹ́? Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi. Ǹjẹ́ Ọlọ́run kan ha ń bẹ lẹ́yìn mi? Bẹ́ẹ̀ kọ́, kò sí àpáta mìíràn; Èmi kò mọ ọ̀kankan.”
9 Tworzyciele bałwanów wszyscy nic nie są, i te najmilsze rzeczy ich nic im nie pomogą; czego oni sobie sami świadkami będąc, nic nie widzą, ani rozumieją, żeby się wstydzić mogli.
Gbogbo àwọn tí ń gbẹ́ ère jásí asán, àti àwọn ohun tí wọn ń kó pamọ́ kò jámọ́ nǹkan kan. Àwọn tí yóò sọ̀rọ̀ fún wọn fọ́ lójú; wọ́n jẹ́ aláìmọ̀kan sí ìtìjú ara wọn.
10 Kto tworzy boga, i bałwana leje, do niczego się to nie przygodzi.
Ta ni ó mọ òrìṣà kan tí ó sì ya ère, tí kò lè mú èrè kankan wá fún un?
11 Oto wszyscy, i uczestnicy ich będą pohańbieni; owszem, rzemieślnicy ich, ci nad innych ludzi, choćby się wszyscy zebrali i stanęli, lękać się muszą, i społem pohańbieni będą.
Òun àti nǹkan rẹ̀ wọ̀nyí ni a ó dójútì; àwọn oníṣọ̀nà kò yàtọ̀, ènìyàn ni wọ́n. Jẹ́ kí gbogbo wọn gbárajọ kí wọ́n sì fi ìdúró wọn hàn; gbogbo wọn ni a ó mú bọ́ sínú ìpayà àti àbùkù.
12 Kowal kleszczami robi przy węglu, a młotami kształtuje bałwana; gdy go robi mocą ramienia swego, aż od głodu w nim i siły ustają, ani pije wody, aż i omdlewa.
Alágbẹ̀dẹ mú ohun èlò, ó fi ń ṣiṣẹ́ nínú èédú; ó fi òòlù ya ère kan, ó ṣe é pẹ̀lú agbára apá rẹ̀, ebi ń pa á, àárẹ̀ sì mú un; kò mu omi rárá, ìrẹ̀wẹ̀sì dé bá a.
13 Cieśla zaś rozcięga sznur, znaczy sznurem farbowanym, i ociosuje toporem, i cyrklem rozmierza go, i czyni go na podobieństwo męża, i na podobieństwo pięknego człowieka, aby mieszkał w domu.
Gbẹ́nàgbẹ́nà fi ìwọ̀n wọ́n ọ́n ó sì fi lẹ́ẹ̀dì ṣe àmì sí ara rẹ̀, Ó tún fi ìfà fá a jáde ó tún fi òsùwọ̀n ṣe àmì sí i. Ó gbẹ́ ẹ ní ìrí ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ènìyàn nínú ògo rẹ̀, kí ó lè máa gbé nínú ilé òrìṣà.
14 Narąbie sobie cedrów, i bierze cyprys i dąb, albo to, co jest najmocniejszego między drzewem leśnem, albo wsadzi jawór, który za deszczem odrasta;
Ó gé igi kedari lulẹ̀, tàbí bóyá ó mú sípírẹ́ṣì tàbí igi óákù. Ó jẹ́ kí ó dàgbà láàrín àwọn igi inú igbó, ó sì le gbin igi páínì, èyí tí òjò mú kí ó dàgbà.
15 I używa tego człowiek do palenia, albo wziąwszy z niego, ogrzewa się przy nim, także roznieca ogień, aby napiekł chleba, nadto z tegoż drzewa robi sobie boga, i kłania mu się; czyni z niego bałwana, i klęka przed nim.
Ohun èlò ìdáná ni fún ènìyàn; díẹ̀ nínú rẹ̀ ni ó mú láti mú kí ara rẹ̀ lọ́wọ́ọ́rọ́, ó dá iná ó sì fi ṣe àkàrà. Ṣùgbọ́n bákan náà ni ó ṣe òrìṣà tí ó sì ń sìn ín; ó yá ère, ó sì ń foríbalẹ̀ fún un.
16 Część jego pali ogniem, przy drugiej części jego mięso je, piecze pieczeń i nasycony bywa; także rozgrzewa się, i mówi: Ehej! rozgrzałem się, widziałem ogień.
Ìlàjì igi náà ni ó jó nínú iná; lórí i rẹ̀ ni ó ti ń tọ́jú oúnjẹ rẹ̀, ó dín ẹran rẹ̀ ó sì jẹ àjẹyó. Ó tún mú ara rẹ̀ gbóná ó sì sọ pé, “Á à! Ara mi gbóná, mo rí iná.”
17 A z ostatku jego czyni boga, bałwana swego; klęka przed nim, kłania się, i modli mu się, mówiąc: Wybaw mię, boś ty bóg mój.
Nínú èyí tí ó kù ni ó ti ṣe òrìṣà, ère rẹ̀; ó foríbalẹ̀ fún un, ó sì sìn ín. Ó gbàdúrà sí i, ó wí pé, “Gbà mí, ìwọ ni Ọlọ́run mi.”
18 Nie wiedzą, ani rozumieją, przeto, że Bóg zaślepił oczy ich, aby nie widzieli, i serca ich, aby nie rozumieli.
Wọn kò mọ nǹkan kan, nǹkan kan kò yé wọn; a fi ìbòjú bo ojú wọn, wọn kò lè rí nǹkan kan; bẹ́ẹ̀ ni àyà wọn sébọ́, wọn kò lè mọ nǹkan kan.
19 I nie uważają tego w sercu swojem, nie mająż to umiejętności ani baczenia, aby rzekli: Część z niego spaliłem ogniem, a przy węglu jego napiekłem chleba, upiekłem mięso, i najadłem się; i mamże ja z ostatku jego obrzydliwość uczynić, a przed kloc em drewnianym klękać?
Kò sí ẹni tí ó dúró láti ronú, kò sí ẹni tí ó ní ìmọ̀ tàbí òye láti sọ wí pé, “Ìlàjì rẹ̀ ni mo fi dáná; mo tilẹ̀ ṣe àkàrà lórí èédú rẹ̀, mo dín ẹran, mo sì jẹ ẹ́. Ǹjẹ́ ó wá yẹ kí n ṣe ohun ìríra kan nínú èyí tí ó ṣẹ́kù bí? Ǹjẹ́ èmi yóò ha foríbalẹ̀ fún ìtì igi?”
20 Taki się karmi popiołem, serce jego zwiedzione unosi go, aby nie mógł wybawić duszy swojej, ani rzec: Izali to nie jest oszukanie, co jest w prawicy mojej?
Ó ń jẹ eérú, ọkàn ẹlẹ́tàn ni ó ṣì í lọ́nà; òun kò lè gba ara rẹ̀ là, tàbí kí ó wí pé, “Ǹjẹ́ nǹkan tí ó wà lọ́wọ́ ọ̀tún mi yìí irọ́ kọ́?”
21 Pomnijże na to, Jakóbie i Izraelu! przeto, żeś ty jest sługą moim. Stworzyłem cię, sługaś ty mój; o Izraelu! nie zapomnę na cię.
“Rántí àwọn nǹkan wọ̀nyí, ìwọ Jakọbu, nítorí ìránṣẹ́ mi ni ìwọ, ìwọ Israẹli. Èmi ti dá ọ, ìránṣẹ́ mi ni ìwọ ṣe, ìwọ Israẹli, Èmi kì yóò gbàgbé rẹ.
22 Gładzę nieprawości twoje jako obłok, a grzechy twoje jako mgłę; nawróć się do mnie, bom cię odkupił.
Èmi ti gbá gbogbo ìkùnà rẹ dànù bí i kurukuru, àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ bí ìrì òwúrọ̀. Padà sọ́dọ̀ mi, nítorí mo ti rà ọ́ padà.”
23 Śpiewajcie niebiosa, bo to Pan uczynił; wykrzykajcie niskości ziemi, zabrzmijcie chwałę góry, las, i wszystkie drzewa w nim; albowiem Pan odkupił Jakóba, a w Izraelu sławnym się uczynił.
Kọrin fáyọ̀, ẹ̀yin ọ̀run, nítorí Olúwa ló ti ṣe èyí; kígbe sókè, ìwọ ilẹ̀ ayé nísàlẹ̀. Bú sí orin, ẹ̀yin òkè ńlá, ẹ̀yin igbó àti gbogbo igi yín, nítorí Olúwa ti ra Jakọbu padà, ó ti fi ògo rẹ̀ hàn ní Israẹli.
24 Tak mówi Pan, odkupiciel twój, i który cię utworzył wnet z żywota matki: Ja Pan wszystko czynię, sam rozciągam niebiosa, rozpościeram ziemię mocą swoją.
“Ohun tí Olúwa wí nìyìí Olùràpadà rẹ tí ó mọ ọ́ láti inú ìyá rẹ wá: “Èmi ni Olúwa tí ó ti ṣe ohun gbogbo tí òun nìkan ti na àwọn ọ̀run tí o sì tẹ́ ayé pẹrẹsẹ òun tìkára rẹ̀,
25 Wniwecz obracam znamiona praktykarzów, i wieszczków do szaleństwa przywodzę; i mędrców na wstecz obracam, a umiejętność ich głupią czynię.
ta ni ó ba àmì àwọn wòlíì èké jẹ́ tí ó sì sọ àwọn aláfọ̀ṣẹ di òmùgọ̀, tí ó dojú ìmọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n délẹ̀ tí ó sì sọ wọ́n di òmùgọ̀,
26 Potwierdzam słowa sługi swego, a radę posłów swych wykonywam. Który mówię o Jeruzalemie: Mieszkać w niem będę; a o miastach Judzkich: Pobudowane będą; bo spustoszenia ich pobuduję;
ẹni tí ó gbé ọ̀rọ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ jáde tí ó sì mú àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ wá sí ìmúṣẹ, “ẹni tí ó wí nípa ti Jerusalẹmu pé, ‘A ó máa gbé inú rẹ̀,’ àti ní ti àwọn ìlú Juda, ‘A ó tún kọ́,’ àti àwọn ahoro rẹ̀, ‘Èmi yóò mú un bọ̀ sípò,’
27 Który mówię głębinie: Wyschnij, Ja potoki twe wysuszę;
ta ni ó sọ fún omi jíjìn pé, ‘Ìwọ gbẹ, èmi yóò sì mú omi odò rẹ gbẹ,’
28 Który mówię o Cyrusie: On pasterz mój, bo wszystkę wolę moję wykona; i rzecze Jeruzalemowi: Będziesz zbudowane; a kościołowi: Będziesz założony.
ta ni ó sọ nípa Kirusi pé, ‘Òun ni Olùṣọ́-àgùntàn mi àti pé òun yóò ṣe ohun gbogbo tí mo fẹ́; òun yóò sọ nípa Jerusalẹmu pé, “Jẹ́ kí a tún kọ́,” àti nípa tẹmpili, “Jẹ́ kí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé ilẹ̀.”’”

< Izajasza 44 >