< Ezechiela 3 >

1 I rzekł do mnie: Synu człowieczy! co przed tobą jest, zjedz; zjedz te księgi, a idź i mów do domu Izraelskiego.
Síwájú sí i, ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, jẹ ohun tí ó wà níwájú rẹ, jẹ ìwé kíká yìí; kí o sì lọ fi bá ilé Israẹli sọ̀rọ̀.”
2 Otworzyłem tedy usta swe, i dał mi zjeść one księgi,
Mo sì ya ẹnu mi, ó sì mú mi jẹ ìwé kíká náà.
3 A mówił do mnie: Synu człowieczy! nakarm brzuch twój, a wnętrzności twoje napełnij temi księgami, któreć daję. I zjadłem je, i były w ustach moich słodkie jako miód.
Ó tún sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, jẹ ìwé kíká tí mo fún ọ yìí, fi bọ́ inú àti ikùn rẹ.” Nígbà náà ni mo jẹ ẹ́, dídùn rẹ̀ dàbí oyin ní ẹnu mi.
4 Zatem rzekł do mnie: Synu człowieczy! idź a wnijdź do domu Izraelskiego, i mów słowy mojemi do nich.
Ó sì tún sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, lọ ni ìsinsin yìí bá mi sọ ọ̀rọ̀ mi fún ilé Israẹli.
5 Bo cię nie do ludu nieznajomej mowy, albo trudnego języka posyłam, ale do domu Izraelskiego;
A kò rán ọ sí àwọn tó ń sọ èdè àjèjì tàbí tí èdè wọn ṣòro láti gbọ́, ṣùgbọ́n orílẹ̀-èdè Israẹli ni mo rán ọ sí
6 Nie do wielu narodów nieznajomej mowy, i trudnego języka, którychbyś słów nie zrozumiał, którzy jednak, gdybym cię do nich posłał, usłuchaliby cię.
kì í ṣe sí ọ̀pọ̀ ènìyàn tó ń sọ àjèjì èdè tàbí tí èdè wọn ṣòro láti gbọ́, àwọn tí ọ̀rọ̀ wọn le fún ọ láti gbọ́ yé. Dájúdájú bí mo bá rán ọ sí wọn, wọn ìbá sì fetísílẹ̀ sí ọ.
7 Lecz dom Izraelski nie będzie cię chciał usłuchać, ponieważ mnie samego usłuchać nie chcą; bo wszystek dom Izraelski jest twardego czoła i zatwardzonego serca.
Ṣùgbọ́n ilé Israẹli kò fẹ́ gbọ́ tìrẹ nítorí pé wọn kò fẹ́ láti gbọ́ tèmi, torí pé aláìgbọ́ràn àti ọlọ́kàn líle ni gbogbo ilé Israẹli.
8 Ale otom uczynił twarz twoję twardą przeciwko twarzy ich, a czoło twe twarde przeciwko czołu ich.
Ṣùgbọ́n bí i tiwọn lèmi náà yóò ṣe jẹ́ kí ojú àti ọkàn rẹ le.
9 Uczyniłem czoło twe jako dyjament, i twardsze nad skałę; nie bójże się ich, ani się lękaj twarzy ich, przeto, że są domem odpornym.
Èmi yóò ṣe iwájú orí rẹ bí òkúta tó le jùlọ, ànító le ju òkúta-ìbọn lọ. Má ṣe bẹ̀rù wọn tàbí jẹ́ kí wọn ó dáyà já ọ. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìdílé ọlọ̀tẹ̀ ni wọ́n.”
10 I rzekł do mnie: Synu człowieczy! wszystkie słowa moje, które mówić będę do ciebie, przyjmij do serca twego, a słuchaj uszyma twemi.
Ó sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ń sọ, kí o sì gba gbogbo ọ̀rọ̀ yìí sí ọkàn rẹ.
11 Idź a wnijdź do pojmanych, do synów ludu twego, i mów do nich, a powiedz im: Tak mówi panujący Pan, niech oni słuchają, albo nie.
Lọ nísinsin yìí sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ tó wà ní ìgbèkùn. Sọ fún wọn pé báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí yálà wọ́n gbọ́ tàbí wọn kò gbọ́.”
12 Tedy mię duch podniósł, i słyszałem za sobą głos grzmotu wielkiego: Błogosławiona niech będzie chwała Pańska z miejsca swego;
Nígbà náà ni ẹ̀mí gbé mi sókè, mo sì gbọ́ ohùn ìró ńlá lẹ́yìn mi tó sọ pé, kí a gbé ògo Olúwa ga láti ibùgbé rẹ̀ wá!
13 I szum skrzydeł onych zwierząt, które się naspół dotykały, i głos kół naprzeciwko nim, i głos grzmotu wielkiego.
Bẹ́ẹ̀ ni mo tún gbọ́ ariwo ìyẹ́ apá àti kẹ̀kẹ́ àwọn ẹ̀dá alààyè náà pẹ̀lú ariwo tó dàbí àrá ńlá.
14 A duch podniósł mię i wziął mię. I odszedłem z gorzkością w rozgniewaniu ducha mego; ale ręka Pańska nademną mocna była.
Ẹ̀mí náà sì gbé mi sókè, ó sì mú mi lọ, mo lọ pẹ̀lú ọkàn kíkorò àti ìbínú nínú ẹ̀mí mi, pẹ̀lú ọwọ́ líle Olúwa ni ara mi.
15 I przyszedłem do pojmanych do Telabib, którzy mieszkali przy rzece Chebar, i siadłem gdzie oni mieszkali, a siedziałem tam siedm dni w pośrodku ich, zdumiawszy się.
Nígbà náà ni mo lọ sí etí odò Kebari níbi tí àwọn ìgbèkùn ń gbé ni Teli-Abibu. Níbẹ̀ níbi tí wọ́n ń gbé, mo jókòó láàrín wọn pẹ̀lú ìyanu, fún ọjọ́ méje.
16 A gdy minęło siedm dni, było słowo Pańskie do mnie mówiące:
Lẹ́yìn ọjọ́ méje, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
17 Synu człowieczy! Dałem cię stróżem domowi Izraelskiemu, abyś słysząc słowo z ust moich napomniał ich odemnie.
“Ọmọ ènìyàn, mo ti fi ọ́ ṣe olùṣọ́ fún ilé Israẹli; nítorí náà gbọ́ ọ̀rọ̀ tí mo ń sọ, fún wọn ní ìkìlọ̀ láti ọ̀dọ̀ mi.
18 Gdybym Ja rzekł niepobożnemu: Śmiercią umrzesz, a nie napomniałbyś go, i nie mówiłbyś, abyś go odwiódł od niezbożnej drogi jego, tak, żebyś go przy żywocie zachował, tedy onci niezbożny w nieprawości swojej umrze; ale krwi jego z ręki twojej szukać będę.
Bí mo bá sọ fún ènìyàn búburú pé, dájúdájú, ‘Ìwọ yóò kú,’ tí ìwọ kò sì kìlọ̀ fún ènìyàn búburú yìí láti dáwọ́ ìwà ibi rẹ̀ dúró, kí o sì gba ẹ̀mí rẹ̀ là, ènìyàn búburú náà yóò kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ní ọwọ́ rẹ ni èmi yóò ti béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
19 Lecz jeźlibyś ty napomniał niezbożnego, a nie odwróciłby się od niezbożności swej, i od drogi swej niezbożnej, tedy onci w nieprawości swojej umrze; ale ty duszę swoję wybawisz.
Ṣùgbọ́n bí o bá kìlọ̀ fún ènìyàn búburú, tí ó kọ̀ tí kò fi ìwà búburú rẹ̀ sílẹ̀, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀; ṣùgbọ́n ọrùn tìrẹ ti mọ́.
20 Także jeźliby się odwrócił sprawiedliwy od sprawiedliwości swojej, a czyniłby nieprawość, a Jabym położył zawadę przed nim, i takby umarł, a tybyś go nie napomniał: w grzechu swym umrze, a nie przyjdą na pamięć sprawiedliwości jego, które czynił, lecz krwi jego z ręki twojej szukać będę.
“Bákan náà, bí olódodo kan bá yípadà, tó sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe àìṣòdodo, tí mo sì fi ohun ìkọ̀sẹ̀ sí ọ̀nà rẹ̀, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. Nítorí pé ìwọ kọ̀ láti kìlọ̀ fún un, yóò kú sínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, a ó gbàgbé gbogbo ìwà rere tó ti hù tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n ní ọwọ́ rẹ̀ ni èmi yóò ti béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
21 Ale jeźlibyś ty napomniał sprawiedliwego, aby nie zgrzeszył ten sprawiedliwy, i nie grzeszyłby, zaiste żyć będzie, bo napomnienie przyjął, a ty duszę swoję wybawisz.
Ṣùgbọ́n bí o bá kìlọ̀ fún olódodo tó sì dáwọ́ ìwà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ dúró, dájúdájú òun yóò yè nítorí pé ó ti gba ìkìlọ̀, ọrùn tìrẹ sì mọ́.”
22 I była tam nademną ręka Pańska, i rzekł do mnie: Wstawszy wyjdź w pole, a tam się z tobą rozmówię.
Ọwọ́ Olúwa wà lára mi níbẹ̀, ó sì wí fún mi pé, “Dìde, lọ sí ibi tí ó tẹ́jú, èmi yóò sì bá ọ sọ̀rọ̀ níbẹ̀.”
23 A tak wstawszy szedłem w pole, a oto chwała Pańska stała tam, jako chwała, którąm widział u rzeki Chebar, i upadłem na oblicze moje.
Mo sì dìde, mo lọ sí ibi tí ó tẹ́jú. Ògo Olúwa dúró níbẹ̀, ó dàbí irú ògo tí mo rí létí odò Kebari, mo sì dojúbolẹ̀.
24 Tedy duch wstąpił w mię, a postawiwszy mię na nogi moje mówił do mnie, i rzekł mi: Wnijdź, zamknij się w domu swym.
Nígbà náà ni Ẹ̀mí wọ inú mi, tí ó sì tún gbé mi dúró. Ó sì wí fún mi pé, “Lọ, ti ara rẹ mọ́ inú ilé rẹ
25 Bo oto na cię, synu człowieczy! włożą powrozy, i zwiążą cię niemi, a nie będziesz mógł wynijść między nich.
ṣùgbọ́n ìwọ, ọmọ ènìyàn, wọn yóò fi okùn dè ọ́ mọ́lẹ̀; dé ibi pé ìwọ kò ní í le rìn káàkiri láàrín àwọn ènìyàn.
26 A Ja uczynię, że język twój przylgnie do podniebienia twego, i będziesz niemy, a nie będziesz im mężem strofującym, przeto, że są domem odpornym.
Èmi yóò mú kí ahọ́n rẹ lẹ̀ mọ́ àjà ẹnu rẹ, tó bẹ́ẹ̀ ti ìwọ yóò wà ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́. Ìwọ kò sì ní lè bá wọn wí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọlọ̀tẹ̀ ilé ní wọn.
27 Ale gdy z tobą mówić będę, otworzę usta twoje; tedy rzeczesz do nich: Tak mówi panujący Pan: Kto chce słuchać, niech słucha, a kto nie chce, niech nie słucha, gdyż domem odpornym są.
Ṣùgbọ́n nígbà tí èmi bá bá ọ sọ̀rọ̀, Èmi yóò ṣí ọ lẹ́nu, ìwọ yóò sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí.’ Ẹni tó bá fẹ́ kí ó gbọ́, ẹni tó bá fẹ́ kọ̀, kó kọ̀ nítorí ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n.

< Ezechiela 3 >