< Ezechiela 2 >
1 I rzekł do mnie: Synu człowieczy! stań na nogi twe, a będę mówił z tobą.
Ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, dìde dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ. Èmi yóò bá ọ sọ̀rọ̀.”
2 I wstąpił w mię duch, gdy przemówił do mnie, a postawił mię na nogi moje, i słyszałem mówiącego do mnie;
Bí ó ṣe ń sọ̀rọ̀, ẹ̀mí sì wọ inú mi ó mú mi dúró lórí ẹsẹ̀ mi, mo sì ń gbọ́ tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀.
3 Który rzekł do mnie: Synu człowieczy! Ja cię posyłam do synów Izraelskich, do narodów odpornych, którzy mi się sprzeciwili; oni i ojcowie ich występowali przeciwko mnie aż prawie do dnia tego:
Ó sọ pé, “Ọmọ ènìyàn, mo ń rán ọ sí àwọn ọmọ Israẹli, sí ọlọ̀tẹ̀ orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi; àwọn àti baba ńlá wọn ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi títí di òní olónìí.
4 Do tych, mówię, synów niewstydliwej twarzy, i zatwardziałego serca Ja cię posyłam, i rzeczesz im: Tak mówi panujący Pan.
Àwọn ènìyàn tí mo ń rán ọ sí jẹ́ aláìgbọ́ràn àti ọlọ́kàn líle. Sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí.’
5 Niech oni słuchają albo nie, gdyż domem odpornym są, przecież niech wiedzą, że prorok był w pośrodku ich.
Bí wọn fetísílẹ̀ tàbí wọn kò fetísílẹ̀ nítorí pé wọ́n ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n—wọn yóò mọ̀ pé wòlíì kan wà láàrín wọn.
6 Ale ty, synu człowieczy! nie bój się ich, ani się lękaj słów ich, że odporni a jako ciernie są przeciwko tobie, a że między niedźwiadkami mieszkasz; słów ich nie bój się, ani się twarzy ich lękaj, przeto, że domem odpornym są.
Àti ìwọ, ọmọ ènìyàn, má ṣe bẹ̀rù wọn tàbí ọ̀rọ̀ ẹnu wọn. Má ṣe bẹ̀rù, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òṣùṣú àti ẹ̀gún yí ọ ká, tí o sì ń gbé àárín àwọn àkéekèe. Má ṣe bẹ̀rù ohun tí wọ́n ń sọ tàbí bẹ̀rù wọn, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọlọ̀tẹ̀ ìdílé ni wọ́n.
7 Ale mów słowa moje do nich, niech oni słuchają albo nie, gdyż odpornymi są.
Ìwọ gbọdọ̀ sọ ọ̀rọ̀ mi fún wọn, bí wọ́n gbọ́ bí wọn kọ̀ láti gbọ́ torí pé ọlọ̀tẹ̀ ni wọ́n.
8 Lecz ty, synu człowieczy! słuchaj, co Ja mówię do ciebie: Nie bądź odporny, jako ten dom odporny; otwórz usta swe, a zjedz, coć dam.
Ṣùgbọ́n ìwọ, ọmọ ènìyàn, gbọ́ ohun tí mo ń sọ fún ọ. Má ṣe ṣọ̀tẹ̀ bí i ti ìdílé ọlọ́tẹ̀; la ẹnu rẹ kí o sì jẹ ohun tí mo fún ọ.”
9 I widziałem, a oto ręka była wyciągniona do mnie, a oto w niej zwinione księgi,
Mo sì wò, mo sì rí ọwọ́ kan tí a nà sí mi. Ìwé kíká sì wà níbẹ̀,
10 Które rozwinął przedemną; a były popisane z przodku i z końca, a w nich były napisane narzekania, i wzdychania i bieda.
ó sì tú ìwé náà fún mi. Ní ojú àti ẹ̀yìn ìwé náà ni a kọ ìpohùnréré ẹkún, ọ̀fọ̀ àti ègún sí.