< II Koryntian 11 >

1 Obyście chcieli na chwilę znosić głupstwo moje! ale i znaszajcie mię.
Mo rò wí pé ẹ ó faradà díẹ̀ nínú ìwà òmùgọ̀ mi ṣùgbọ́n bẹ́ẹ̀ ni, mo fẹ́ kí ẹ gbà mí láàyè.
2 Albowiem gorliwym jestem ku wam gorliwością Bożą; bom was przygotował, abym was stawił czystą panną jednemu mężowi Chrystusowi.
Nítorí pé èmi ń jowú lórí i yín bí ẹni ìwà-bí-Ọlọ́run, nítorí tí mo ti fì yín fún ọkọ kan, kí èmi bà á lè mú yín wá bí wúńdíá tí ó mọ́ sọ́dọ̀ Kristi.
3 Lecz boję się, by snać jako wąż oszukał Ewę chytrością swoją, tak też skażone myśli wasze nie odpadły od prostoty onej, która jest w Chrystusie.
Ṣùgbọ́n ẹ̀rù ń bà mí, kí ó má bà á jẹ́ pé, bí ejò ti tan Efa jẹ́ nípasẹ̀ àrékérekè rẹ̀, a lè mú ọkàn yín ṣáko lọ kúrò nínú òtítọ́ yín àti ìfarajì fún Kristi.
4 Bo gdyby kto przyszedł, co by inszego Jezusa opowiadał, któregośmy nie opowiadali; albo gdybyście innego ducha wzięli, któregoście nie wzięli, albo inszą Ewangieliję, którejście nie przyjęli, dobrze byście go znosili.
Nítorí bí ẹnìkan bá wá tí ó sì wàásù Jesu mìíràn, yàtọ̀ sí èyí tí a ti wàásù rí tàbí bí ẹ̀yin bá gba ẹ̀mí mìíràn, yàtọ̀ sí èyí tí ẹ ti gbà tàbí ìyìnrere mìíràn yàtọ̀ sí èyí tí ẹ ti gbà, tí ẹ sì ti yára tẹ́wọ́ gbà á.
5 Boć mam za to, żem nie był w niczem podlejszy, niżeli oni bardzo wielcy Apostołowie.
Nítorí mo rò pé èmi kò rẹ̀yìn nínú ohunkóhun sí àwọn àgbà Aposteli.
6 Bo chociażem też i prostakiem w mowie, wszakże nie w umiejętności; ale zgoła jawnymiśmy się stali we wszystkich rzeczach u was.
Bí mo tilẹ̀ jẹ́ òpè nínú ọ̀rọ̀ sísọ, kì í ṣe nínú ìmọ̀; ní ọ̀nàkọnà ni àwa ti fi èyí hàn dájúdájú fún yín nínú ohun gbogbo.
7 Izalim się grzechu dopuścił, żem samego siebie uniżył, abyście wy byli wywyższeni, a żem wam darmo Ewangieliję Bożą opowiadał?
Tàbí ẹ̀ṣẹ̀ ni mo dá bí èmi ti ń rẹ ara mí sílẹ̀ kí a lè gbé yín ga, nítorí tí mo wàásù ìyìnrere Ọlọ́run fún un yín lọ́fẹ̀ẹ́.
8 Złupiłem inne zbory, biorąc od nich żołd, abym wam służył; a będąc u was i cierpiąc niedostatek, nie obciążyłem próżnując nikogo.
Èmí ń ja ìjọ mìíràn ni olè nípa gbígba ìpèsè owó ki èmi bà á lè sìn yín.
9 Albowiem niedostatek mój dopełnili bracia, którzy przyszli z Macedonii, i we wszystkim strzegłem się, abym wam ciężkim nie był, i na potem strzec się będę.
Nígbà tí mo sì wà pẹ̀lú yín, tí mo sì ṣe aláìní, èmi kò dẹ́rù pa ẹnikẹ́ni, nítorí ohun tí mo ṣe aláìní ni àwọn ará tí ó ti Makedonia wá ti mú wá. Bẹ́ẹ̀ ni nínú ohun gbogbo mo pa ara mi mọ́ láti má ṣe jẹ́ ẹrù fún yín, èmi yóò sì pa ara mi mọ́ bẹ́ẹ̀.
10 Jestci prawda Chrystusowa we mnie, iż ta chluba nie będzie zatłumiona we mnie w krainach Achajskich.
Ó jẹ́ òtítọ́, Kristi tí ń bẹ nínú mi pé kò sí ẹni tí ó lè dá mi lẹ́kun ìṣògo yìí ni gbogbo ẹkùn Akaia.
11 Dlategoż? czy że was nie miłuję? Bógci wie,
Nítorí kín ni? Nítorí èmi kò fẹ́ràn yín ni bí? Ọlọ́run mọ̀.
12 Ale co czynię, czynić jeszcze będę dlatego, abym odciął przyczynę tym, którzy przyczyny szukają, aby w tem, z czego się chlubią, byli znalezieni tacy, jako i my.
Èmi yóò tẹ̀síwájú láti máa ṣe ohun ti èmi ń ṣe láti le mú ìjákulẹ̀ bá àwọn tí wọn ń wá ọ̀nà láti bá wa dọ́gba nínú èyí ti àwa ń ṣògo lé lórí.
13 Albowiem takowi fałszywi Apostołowie są robotnicy zdradliwi, którzy się przemieniają w Apostoły Chrystusowe.
Nítorí irú àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ ni àwọn èké Aposteli àwọn ẹni ti ń ṣiṣẹ́ ẹ̀tàn, tí ń pa wọ́n dà di aposteli Kristi.
14 A nie dziw: bo i szatan sam przemienia się w Anioła światłości.
Kì í sì í ṣe ohun ìyanu; nítorí Satani, tìkára rẹ̀ ń pa ara rẹ̀ dàbí angẹli ìmọ́lẹ̀.
15 Nie wielka tedy, jeźli też słudzy jego przemieniają się, jakoby byli sługami sprawiedliwości, których koniec będzie podług uczynków ich.
Nítorí náà kì í ṣe ohun ńlá bí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú bá pa ara wọn dàbí àwọn ìránṣẹ́ òdodo; ìgbẹ̀yìn àwọn ẹni tí yóò rí gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn.
16 Znowu powiadam, żeby mię kto nie miał za głupiego; jeźliż inaczej, więc jako głupiego przyjmijcie mię, abym się ja też nieco maluczko przechwalał.
Mo sì tún wí pé, kí ẹnikẹ́ni má ṣe rò pé òmùgọ̀ ni mí; ṣùgbọ́n bí bẹ́ẹ̀ bá ni, ẹ gbà mí bí òmùgọ̀ kí èmi lè gbé ara mi ga díẹ̀.
17 Co mówię, nie mówięć jako od Pana, ale jako w głupstwie z strony tej bezpiecznej chluby.
Ohun tí èmi ń sọ, èmi kò sọ ọ́ nípa ti Olúwa, ṣùgbọ́n bí òmùgọ̀ nínú ìgbẹ́kẹ̀lé ìṣògo yìí.
18 Ponieważ się ich wiele chlubi według ciała, i ja się chlubić będę.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀, ni ó ń ṣògo nípa ti ara, èmi ó ṣògo pẹ̀lú.
19 Bo radzi znosicie głupich, będąc sami mądrymi.
Nítorí ẹ̀yin fi inú dídùn gba àwọn òmùgọ̀ nígbà tí ẹ̀yin tìkára yín jẹ́ ọlọ́gbọ́n.
20 Bo znosicie, choć was kto zniewala, choć kto pożera, choć kto bierze, choć się kto wynosi, choć was kto policzkuje.
Nítorí ẹ̀yin faradà á bí ẹnìkan bá sọ yín dí òǹdè, bí ẹnìkan bá jẹ́ yín run, bí ẹnìkan bá gbà lọ́wọ́ yín, bí ẹnìkan bá gbé ara rẹ̀ ga, bí ẹnìkan bá gbá yín lójú.
21 Mówiąc według zelżywości, jakobyśmy byli słabymi; lecz w czem kto śmiałym jest, (w głupstwie mówię) i jam śmiały.
Èmi ń wí lọ́nà ẹ̀gàn, bí ẹni pé àwa jẹ́ aláìlera! Ṣùgbọ́n nínú ohunkóhun tí ẹnìkan ti ní ìgboyà, èmi ń sọ̀rọ̀ bí òmùgọ̀, èmi ní ìgboyà pẹ̀lú.
22 Żydowie są, jestem i ja. Izraelczycy są, jestem i ja. Nasieniem Abrahamowem są, jestem i ja.
Heberu ni wọ́n bí? Bẹ́ẹ̀ ni èmi. Israẹli ni wọ́n bí? Bẹ́ẹ̀ ni èmi. Irú-ọmọ Abrahamu ní òun bí? Bẹ́ẹ̀ ni èmi.
23 Sługami Chrystusowymi są, (głupio mówię), więcej ja; w pracach obficiej, w razach nad miarę, w więzieniach obficiej, w śmierciach częstokroć.
Ìránṣẹ́ Kristi ni wọ́n bí? Èmi ń sọ bí òmùgọ̀, mo ta wọ́n yọ; ní ti làálàá lọ́pọ̀lọ́pọ̀, ní ti pàṣán, mo rékọjá, ní ti túbú nígbàkígbà, ní ti fífẹ́rẹ kú nígbà púpọ̀.
24 Od Żydów wziąłem pięciokroć po czterdzieści plag bez jednej.
Nígbà márùn-ún ni mo gba pàṣán ogójì dín ẹyọ kan lọ́wọ́ àwọn Júù.
25 Trzykrociem był bity rózgami; razem był kamionowany; trzykroć się ze mną okręt rozbił, dzień i noc byłem w głębokości morskiej;
Nígbà mẹ́ta ni a fi ọ̀gọ̀ lù mí, ẹ̀ẹ̀kan ṣoṣo ni a sọ mí ní òkúta, ẹ̀ẹ̀mẹta ni ọkọ̀ ojú omi mi rì, ọ̀sán kan àti òru kan ni mo wà nínú ibú.
26 W drogach częstokroć, w niebezpieczeństwach na rzekach, w niebezpieczeństwach od zbójców, w niebezpieczeństwach od swego narodu, w niebezpieczeństwach od pogan, w niebezpieczeństwach w mieście, w niebezpieczeństwach na puszczy, w niebezpieczeństwach na morzu, w niebezpieczeństwach między fałszywymi braćmi;
Ní ìrìnàjò nígbàkígbà, nínú ewu omi, nínú ewu àwọn ọlọ́ṣà, nínú ewu àwọn ará ìlú mi, nínú ewu àwọn aláìkọlà, nínú ewu ni ìlú, nínú ewu ní aginjù, nínú ewu lójú Òkun, nínú ewu láàrín àwọn èké arákùnrin.
27 W pracy i w utrapieniu, w niedosypianiu często, w głodzie, i w pragnieniu, w postach często, i w zimnie, i w nagości;
Nínú làálàá àti ìrora, nínú ìṣọ́ òru nígbàkígbà, nínú ebi àti òǹgbẹ, nínú àwẹ̀ nígbàkígbà, nínú òtútù àti ìhòhò.
28 Oprócz tego, co skądinąd przyda, ono naleganie na mię na każdy dzień i ono staranie o wszystkie zbory.
Pẹ̀lú nǹkan wọ̀nyí tí ó jẹ́ tí òde, ọ̀pọ̀ ni èyí tí ń wọn n dúró tì mí lójoojúmọ́, àní àníyàn fún gbogbo ìjọ.
29 Któż choruje, a ja nie choruję? Któż się gorszy, a ja nie palę?
Ta ni ó ṣe àìlera, tí èmi kò ṣe àìlera? Tàbí a mú kọsẹ̀, tí ara mi kò gbiná?
30 Jeźli się mam chlubić, z krewkości moich chlubić się będę.
Bí èmi yóò bá ṣògo, èmi ó kúkú máa ṣògo nípa àwọn nǹkan tí ó jẹ́ ti àìlera mi.
31 Bóg i Ojciec Pana naszego, Jezusa Chrystusa, który jest błogosławiony na wieki, wie, iż nie kłamię. (aiōn g165)
Ọlọ́run àti Baba Olúwa wá Jesu Kristi, ẹni tí ó jẹ́ olùbùkún jùlọ láéláé mọ̀ pé èmi kò ṣèké. (aiōn g165)
32 W Damaszku hetman ludu króla Arety osadził był strażą miasto Damaszek, chcąc mię pojmać;
Ní Damasku, baálẹ̀ tí ó wà lábẹ́ ọba Areta fi ẹgbẹ́ ogun ká ìlú àwọn ará Damasku mọ́, ó ń fẹ́ láti mú mi bí arúfin.
33 alem oknem po powrozie w koszyku przez mur był spuszczony i uszedłem rąk jego.
Láti ojú fèrèsé nínú agbọ̀n ni a sì ti sọ̀ mí kalẹ̀ lẹ́yìn odi, tí mo sì bọ́ lọ́wọ́ rẹ̀.

< II Koryntian 11 >