< Rzymian 11 >

1 Mówię tedy: Izali Bóg odrzucił lud swój? Nie daj tego Boże! Albowiem i jam jest Izraelczyk z nasienia Abrahamowego, z pokolenia Benjaminowego.
Ǹjẹ́ mo ní, Ọlọ́run ha ta àwọn ènìyàn rẹ̀ nù bí? Kí a má ri. Nítorí Israẹli ni èmi pẹ̀lú, láti inú irú-ọmọ Abrahamu, ni ẹ̀yà Benjamini.
2 Nie odrzuciłci Bóg ludu swego, który przejrzał. Azaż nie wiecie, co mówi Pismo o Elijaszu? jako się przyczynia do Boga przeciwko Izraelowi mówiąc:
Ọlọ́run kò ta àwọn ènìyàn rẹ̀ nù ti ó ti mọ̀ tẹ́lẹ̀. Tàbí ẹ̀yin kò mọ bí ìwé mímọ́ ti wí ní ti Elijah? Bí ó ti ń bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ Ọlọ́run fún Israẹli, wí pé:
3 Panie! Proroki twoje pomordowali i ołtarze twoje zburzyli, a zostałem ja sam i szukają duszy mojej.
“Olúwa, wọ́n ti pa àwọn wòlíì rẹ, wọn sì ti wó àwọn pẹpẹ rẹ lulẹ̀; èmi nìkan ṣoṣo ni ó sì kù, wọ́n sì ń wá ẹ̀mí mi.”
4 Ale cóż mu mówi Boska odpowiedź? Zostawiłem sobie siedm tysięcy mężów, którzy nie skłonili kolana Baalowi.
Ṣùgbọ́n ìdáhùn wo ni Ọlọ́run fi fún un? “Mo ti ṣẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn kù sílẹ̀ fún ara mi, àwọn tí kò tẹ eékún ba fún Baali.”
5 Tak tedy i teraźniejszego czasu ostatki podług wybrania z łaski zostały.
Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ sì ni, ní àkókò yìí àṣẹ́kù àwọn ènìyàn kan wà nípa ìyànfẹ́ ti oore-ọ̀fẹ́.
6 A ponieważ z łaski, tedyć już nie z uczynków, inaczej łaska już by nie była łaską; a jeźli z uczynków, jużci nie jest łaska; inaczej uczynek już by nie był uczynkiem.
Bí ó bá sì ṣe pé nípa ti oore-ọ̀fẹ́ ni, ǹjẹ́ kì í ṣe ti iṣẹ́ mọ́; bí bẹ́ẹ̀ kọ́ oore-ọ̀fẹ́ kì yóò jẹ́ oore-ọ̀fẹ́ mọ́. Ṣùgbọ́n bí ó ṣe pé nípa ti iṣẹ́ ni, ǹjẹ́ kì í ṣe ti oore-ọ̀fẹ́ mọ́; bí bẹ́ẹ̀ kọ́, iṣẹ́ kì í ṣe iṣẹ́ mọ́.
7 Cóż tedy? Czego Izrael szuka, tego nie dostąpił; ale wybrani dostąpili, a inni zatwardzeni są,
Kí ha ni? Ohun tí Israẹli ń wá kiri, òun náà ni kò rí; ṣùgbọ́n àwọn ẹni àyànfẹ́ ti rí i, a sì sé àyà àwọn ìyókù le.
8 (Jako napisano: Dał im Bóg ducha twardego snu, oczy, aby nie widzieli i uszy, aby nie słyszeli), aż do dzisiejszego dnia.
Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé: “Ọlọ́run ti fún wọn ní ẹ̀mí oorun, àwọn ojú tí kò le ríran àti àwọn etí tí kò le gbọ́rọ̀, títí ó fi di òní olónìí yìí.”
9 A Dawid mówi: Niechaj im będzie stół ich sidłem i ułowieniem i otrąceniem i odpłatą.
Dafidi sì wí pé: “Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìdẹ̀kùn àti tàkúté, ohun ìkọ̀sẹ̀ àti ẹ̀san fún wọn.
10 Niech zaćmione będą oczy ich, aby nie widzieli, a grzbietu ich zawsze nachylaj.
Jẹ́ kí ojú wọn ṣókùnkùn, kí wọn kí ó má le ríran, Kí wọn kí ó sì tẹ ẹ̀yìn wọn ba nígbà gbogbo.”
11 Mówię tedy: Azaż się potknęli, aby padli? Nie daj tego Boże! Ale przez ich upadek doszło zbawienie pogan, aby je do zawiści przywiódł.
Ǹjẹ́ mo ní, wọ́n ha kọsẹ̀ kí wọn kí ó lè ṣubú? Kí a má ri i, ṣùgbọ́n nípa ìṣubú wọn, ìgbàlà dé ọ̀dọ̀ àwọn Kèfèrí, láti mú Israẹli jowú.
12 A ponieważ upadek ich jest bogactwem świata, a umniejszenie ich bogactwem pogan, jakoż daleko więcej ich zupełność?
Ṣùgbọ́n bí ìṣubú wọn bá di ọrọ̀ ayé, àti bí ìfàsẹ́yìn wọn bá di ọrọ̀ àwọn Kèfèrí; mélòó mélòó ni kíkún ọrọ̀ wọn?
13 Albowiem mówię wam poganom, ilem ja jest Apostołem pogan, usługiwanie moje zalecam,
Ẹ̀yin tí i ṣe Kèfèrí ni èmi sá à ń bá sọ̀rọ̀, níwọ̀n bí èmi ti jẹ́ aposteli àwọn Kèfèrí, mo gbé oyè mi ga
14 Azażbym jako ku zawiści pobudził ciało moje i zbawiłbym niektóre z nich.
bí ó le ṣe kí èmi kí ó lè mú àwọn ará mi jowú, àti kí èmi kí ó lè gba díẹ̀ là nínú wọn.
15 Albowiem jeźlić odrzucenie ich jest pojednaniem świata, cóż będzie przyjęcie ich, tylko ożycie od umarłych?
Nítorí bí títanù wọn bá jẹ́ ìlàjà ayé, gbígbà wọn yóò ha ti rí, bí kò sí ìyè kúrò nínú òkú?
16 Ponieważ jeźli pierwiastki święte, tedyć i zaczynienie; a jeźli korzeń święty, tedyć i gałęzie.
Ǹjẹ́ bí àkọ́so bá jẹ́ mímọ́, bẹ́ẹ̀ ni àkópọ̀ yóò jẹ́ mímọ́; bí gbòǹgbò bá sì jẹ́ mímọ́, bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ẹ̀ka rẹ̀ náà.
17 A jeźli niektóre z gałęzi odłamane są, a ty, któryś był płonną oliwą, jesteś wszczepiony zamiast nich i stałeś się uczestnikiem korzenia i tłustości oliwnego drzewa:
Ṣùgbọ́n bí a bá ya nínú àwọn ẹ̀ka kúrò, tí a sì lọ́ ìwọ, tí í ṣe igi òróró igbó sára wọn, tí ìwọ sì ń bá wọn pín nínú gbòǹgbò àti ọ̀rá igi olifi náà,
18 Nie chlubże się przeciw gałęziom, bo jeźli się chlubisz, wiedzże, iż nie ty korzenia nosisz, ale korzeń ciebie.
má ṣe ṣe féfé sí àwọn ẹ̀ka igi náà. Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá ṣe féfé, ìwọ kọ́ ni ó rù gbòǹgbò, ṣùgbọ́n gbòǹgbò ni ó rù ìwọ.
19 Ale rzeczesz: Odłamane są gałęzie, abym ja był wszczepiony.
Ǹjẹ́ ìwọ ó wí pé, “A ti fa àwọn ẹ̀ka náà ya, nítorí kí a lè lọ́ mi sínú rẹ̀.”
20 Dobrze; dla niedowiarstwa odłamane są, ale ty wiarą stoisz; nie bądźże hardej myśli, ale się bój.
Ó dára; nítorí àìgbàgbọ́ ni a ṣe fà wọn ya kúrò, ìwọ sì dúró nípa ìgbàgbọ́ rẹ. Má ṣe gbé ara rẹ ga, ṣùgbọ́n bẹ̀rù.
21 Albowiem jeźli Bóg przyrodzonym gałęziom nie przepuścił, wiedz, że i tobie nie przepuści.
Nítorí bí Ọlọ́run kò bá dá ẹ̀ka-ìyẹ́ka sí, kíyèsára kí ó má ṣe ṣe àìdá ìwọ náà sí.
22 Obaczże tedy dobrotliwość i srogość Bożą; przeciwko tym wprawdzie, którzy upadli, srogość, ale przeciwko tobie dobrotliwość, jeźlibyś trwał w dobroci; inaczej i ty będziesz wycięty.
Nítorí náà wo oore àti ìkáàánú Ọlọ́run; lórí àwọn tí ó ṣubú, ìkáàánú; ṣùgbọ́n lórí ìwọ, oore, bi ìwọ bá dúró nínú oore rẹ̀; kí a má bá ké ìwọ náà kúrò.
23 Aleć i oni, jeźli nie będą trwali w niedowiarstwie, wszczepieni zaś będą, gdyż mocny jest Bóg one zasię wszczepić.
Àti àwọn pẹ̀lú, bí wọn kò bá jókòó sínú àìgbàgbọ́, a ó lọ́ wọn sínú rẹ̀, nítorí Ọlọ́run le tún wọn lọ́ sínú rẹ̀.
24 Albowiem jeźliś ty jest wycięty z oliwy, z przyrodzenia płonnej, a przeciwko przyrodzeniu jesteś wszczepiony w dobrą oliwę, jakoż daleko więcej, którzy są według przyrodzenia, wszczepieni będą w swoję własną oliwę!
Nítorí bí a bá ti ké ìwọ kúrò lára igi òróró igbó nípa ẹ̀dá rẹ̀, tí a sì lọ́ ìwọ sínú igi òróró rere lòdì sí ti ẹ̀dá; mélòó mélòó ni a ó lọ́ àwọn wọ̀nyí, tí í ṣe ẹ̀ka-ìyẹ́ka sára igi òróró wọn?
25 Bo nie chcę, abyście nie mieli wiedzieć, bracia! tej tajemnicy, (żebyście nie byli sami u siebie mądrymi), iż zatwardzenie z części przyszło na Izraela, póki by nie weszła zupełność pogan.
Ará, èmi kò ṣá fẹ́ kí ẹ̀yin kí ó wà ní òpè ní ti ohun ìjìnlẹ̀ yìí, kí ẹ̀yin má ba á ṣe ọlọ́gbọ́n ní ojú ara yín, pé ìfọ́jú bá Israẹli ní apá kan, títí kíkún àwọn Kèfèrí yóò fi dé.
26 A tak wszystek Izrael będzie zbawiony, jako napisano: Przyjdzie z Syonu wybawiciel i odwróci niepobożności od Jakóba.
Bẹ́ẹ̀ ni a ó sì gba gbogbo Israẹli là, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé: “Ní Sioni ni Olùgbàlà yóò ti jáde wá, yóò sì yìí àìwà-bí-Ọlọ́run kúrò lọ́dọ̀ Jakọbu.
27 A toć będzie przymierze moje z nimi, gdy odejmę grzechy ich.
Èyí sì ni májẹ̀mú mi pẹ̀lú wọn. Nígbà tí èmi yóò mú ẹ̀ṣẹ̀ wọn kúrò.”
28 A tak według Ewangielii nieprzyjaciółmi są dla was; lecz według wybrania są miłymi dla ojców.
Nípa ti ìyìnrere, ọ̀tá ni wọ́n nítorí yín; bí ó sì ṣe ti ìyànfẹ́ ni, olùfẹ́ ni wọ́n nítorí ti àwọn baba.
29 Albowiem darów swoich i wezwania Bóg nie żałuje.
Nítorí àìlábámọ̀ ni ẹ̀bùn àti ìpè Ọlọ́run.
30 Bo jako i wy niekiedy nie wierzyliście Bogu, ale teraz dostąpiliście miłosierdzia dla ich niedowiarstwa,
Nítorí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin kò ti gba Ọlọ́run gbọ́ rí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí tí ẹ̀yin rí àánú gbà nípa àìgbàgbọ́ wọn.
31 Tak i oni teraz stali się nieposłusznymi, aby dla miłosierdzia wam okazanego i oni miłosierdzia dostąpili.
Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni àwọn wọ̀nyí tí ó ṣe àìgbọ́ràn nísinsin yìí, kí àwọn pẹ̀lú bá le rí àánú gbà nípa àánú tí a fihàn yín.
32 Albowiem zamknął je Bóg wszystkie w niedowiarstwo, aby się nad wszystkimi zmiłował. (eleēsē g1653)
Nítorí Ọlọ́run sé gbogbo wọn mọ́ pọ̀ sínú àìgbàgbọ́, kí ó le ṣàánú fún gbogbo wọn. (eleēsē g1653)
33 O głębokości bogactwa i mądrości, i znajomości Bożej! Jako są niewybadane sądy jego i niedoścignione drogi jego!
A! Ìjìnlẹ̀ ọ̀rọ̀ àti ọgbọ́n àti ìmọ̀ Ọlọ́run! Àwámárídìí ìdájọ́ rẹ̀ ti rí, ọ̀nà rẹ̀ sì jù àwárí lọ!
34 Bo któż poznał umysł Pański? albo kto był rajcą jego?
“Nítorí ta ni ó mọ ọkàn Olúwa? Tàbí ta ni í ṣe ìgbìmọ̀ rẹ̀?”
35 Albo kto mu co pierwej dał, a będzie mu zasię oddano?
“Tàbí ta ni ó kọ́ fi fún un, tí a kò sì san padà fún un?”
36 Albowiem z niego i przez niego i w nim są wszystkie rzeczy; jemu niech będzie chwała na wieki. Amen. (aiōn g165)
Nítorí láti ọ̀dọ̀ rẹ̀, àti nípa rẹ̀, àti fún un ni ohun gbogbo; ẹni tí ògo wà fún láéláé! Àmín. (aiōn g165)

< Rzymian 11 >