< II Kronik 34 >

1 Ośm lat było Jozyjaszowi, gdy królować począł, a trzydzieści i jeden lat królował w Jeruzalemie.
Josiah sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì dí ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n.
2 Ten czynił, co było dobrego przed oczyma Pańskiemi, chodząc drogami Dawida, ojca swego, i nie uchylał się ani na prawo ani na lewo.
Ó sì ṣe ohun tí ó dára ní ojú Olúwa, ó sì rìn ọ̀nà baba rẹ̀ Dafidi, kò sì yà sí ọwọ́ ọ̀tún tàbí òsì.
3 Bo ósmego roku królowania swego, będąc jeszcze dziecięciem, począł szukać Boga Dawida, ojca swego, a dwunastego roku począł oczyszczać Judę i Jeruzalem od wyżyn i od gajów święconych, i od bałwanów, i od rytych obrazów.
Ní ọdún kẹjọ ìjọba rẹ̀, nígbà tí ó sì wà ní ọ̀dọ́mọdé, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í wá ojú Ọlọ́run baba Dafidi. Ní ọdún kejìlá. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí fọ Juda àti Jerusalẹmu mọ́ kúrò ní ibi gíga rẹ̀, ère òrìṣà Aṣerah, àti ère yíyá àti ère dídà.
4 Albowiem przed oczyma jego pokażono ołtarze Baalów, i bałwany słoneczne, które były w górze na nich, podciął: także i gaje święcone, i obrazy ryte, i obrazy odlane pokruszył i potarł, a rozmiotał je po grobach tych, którzy im ofiarowali.
Lábẹ́ àpẹẹrẹ àwọn pẹpẹ Baali ni a yí lulẹ̀, ó sì fọ́ àwọn ère sí wẹ́wẹ́, ó run àwọn pẹpẹ tí ó wà lórí rẹ̀, wọ́n sì fọ́ túútúú, àwọn ère Aṣerah àti àwọn òrìṣà. Èyí tí ó fọ́ wọn sì lúúlúú, ó sì gbọ̀n wọ́n sí orí isà òkú àti àwọn tí ó ń rú ẹbọ sí wọn.
5 Kości też kapłanów popalił na ołtarzach ich, i oczyścił Judę i Jeruzalem;
Ó sì sun àwọn egungun àwọn àlùfáà lórí pẹpẹ wọn, bẹ́ẹ̀ sì ni ó sì wẹ Juda àti Jerusalẹmu mọ́.
6 Także i miasta Manasesowe i Efraimowe, i Symeonowe, aż do Neftalima, i pustynie ich okoliczne.
Ní ìlú Manase, Efraimu àti Simeoni, àní títí ó fi dé Naftali, àti nínú àwọn, ó tú ilé wọn yíkákiri.
7 A tak poburzył ołtarze, i gaje święcone, i bałwany pokruszył w sztuki, i wszystkie obrazy powycinał we wszystkiej ziemi Izraelskiej; potem się wrócił do Jeruzalemu.
Ó sì wó pẹpẹ àti ère Aṣerah lulẹ̀ àti àwọn ère yíyá àti àwọn òrìṣà, ó sì gùn ó sì ti ké gbogbo àwọn ère orí pẹpẹ lulẹ̀ ní gbogbo àyíká Israẹli. Lẹ́yìn náà ó padà sí Jerusalẹmu.
8 A roku ośmnastego królowania swego, gdy oczyścił ziemię i dom Pański, posłał Safana, syna Azalijaszowego, i Maasajasza, przełożonego miasta, i Joacha, syna Joachazowego, kanclerza, aby naprawiono dom Pana, Boga jego.
Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Josiah ni a ti wẹ ilẹ̀ náà mọ́ àti ilé Olúwa, ó sì rán Ṣafani ọmọ Asalia àti Maaseiah olórí ìlú náà, pẹ̀lú Joah, ọmọ Joahasi, akọ̀wé, láti tún ilé Olúwa Ọlọ́run ṣe.
9 Którzy przyszedłszy do Helkijasza, kapłana najwyższego, oddali pieniądze zniesione do domu Bożego, które byli zebrali Lewitowie, stróżowie progu, od synów Manasesowych i Efraimowych, i od wszystkich ostatków Izraelskich, i od wszystkiego Judy i Benjamina, a wrócili się do Jeruzalemu.
Wọ́n sì lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, ó sì fún un ní owó náà tí ó mú wá sí inú ilé Ọlọ́run, ti àwọn ọmọ Lefi ẹni tí ó jẹ́ aṣọ́bodè ti gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn Manase Efraimu àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ìyókù Israẹli àti ọ̀dọ̀ gbogbo ènìyàn Juda àti Benjamini wọ́n sì padà sí Jerusalẹmu.
10 I oddali je w ręce rzemieślników, przełożonych nad robotą domu Pańskiego, a oni je wydawali na robotników, którzy robili w domu Pańskim, naprawiając i utwierdzając dom.
Nígbà náà ni wọn sì fi le àwọn tí ń ṣiṣẹ́ ilé lọ́wọ́, àwọn tí ń ṣe alábojútó iṣẹ́ ilé Olúwa. Àwọn ọkùnrin yìí sì san owó fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń túnṣe, tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ní ilé Olúwa.
11 A dawali je cieślom i murarzom za skupowanie kamienia ciosanego, i drzewa na spajanie i na piętra domów, które byli popsuli królowie Judzcy.
Wọ́n sì tún fi owó fún àwọn oníṣọ̀nà àti àwọn olùkọ́lé láti ra òkúta gbígbẹ́ àti ìtì igi fún ìsopọ̀ àti igi rírẹ́ fún ìkọ́lé tí ọba Juda ti gbà láti túnṣe.
12 A mężowie oni byli wiernymi w tej pracy: a nad nimi byli przełożonymi Jachat, i Abdyjasz, Lewitowie, z synów Merarego, i Zacharyjasz i Mesullam z synów Kaatowych, którzy przynaglali robocie; a każdy z Lewitów umiał grać na instrumentach muzycznych.
Àwọn ọkùnrin náà ṣe iṣẹ́ náà pẹ̀lú òtítọ́, láti darí wọn ní Jahati àti Obadiah, àwọn ọmọ Lefi láti Merari, àti Sekariah àti Meṣullamu, sọ̀kalẹ̀ láti Kohati àwọn ọmọ Lefi gbogbo tí ó ní ọgbọ̀n ohun èlò orin.
13 Nad tymi też, którzy nosili brzemiona, i przynaglali robotnikom przy każdej robocie, byli z Lewitów pisarze, i przystawowie, i odźwierni.
Wọ́n sì ní olórí àwọn aláàárù àti àwọn alábojútó gbogbo àwọn òṣìṣẹ́ láti ibi iṣẹ́ sí ibi iṣẹ́, díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Lefi sì ní akọ̀wé, olùtọ́jú àti olùṣọ́nà.
14 A gdy wynaszali pieniądze zniesione do domu Pańskiego, znalazł Helkijasz kapłan księgi zakonu Pańskiego, podanego przez Mojżesza.
Nígbà tí wọ́n mú owó náà tí wọ́n mú wá sí ilé Olúwa, Hilkiah àlùfáà sì rí ìwé òfin Olúwa tí a ti fi fún un láti ọwọ́ Mose.
15 Tedy odpowiedział Helkijasz i rzekł do Safana pisarza: Znalazłem księgi zakonu w domu Pańskim. I oddał Helkijasz księgę Safanowi.
Hilkiah sì wí fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi ti rí ìwé òfin nínú ilé Olúwa.” Ó sì fi fún Ṣafani.
16 A Safan przyniósł onę księgę do króla; a przytem oznajmił to królowi, mówiąc: Wszystko, coś poruczył w rękę sług twoich, wykonywają:
Nígbà náà Ṣafani sì mú ìwé náà lọ sí ọ̀dọ̀ ọba ó sì ròyìn fún un. “Àwọn ìjòyè rẹ̀ ń ṣe gbogbo nǹkan tí a ti fi lé wọn lọ́wọ́.
17 Bo zebrawszy pieniądze, które się znalazły w domu Pańskim, oddali je w ręce przystawów i w ręce robotników.
Wọ́n ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa wọ́n sì ti fi lé àwọn alábojútó lọ́wọ́ àti àwọn òṣìṣẹ́.”
18 Nadto oznajmił Safan, pisarz, królowi mówiąc: Księgę mi też dał Helkijasz kapłan; i czytał ją Safan przed królem.
Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sì sọ fún ọba, “Hilkiah àlùfáà ti fún mi ní ìwé.” Ṣafani sì kà níwájú ọba.
19 A gdy słyszał król słowa zakonu, rozdarł szaty swoje.
Nígbà tí ọba sì gbọ́ ọ̀rọ̀ òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
20 I rozkazał król Helkijaszowi i Achykamowi, synowi Safanowemu, i Abdonowi, synowi Michasowemu, i Safanowi, pisarzowi, i Asajaszowi, słudze królewskiemu, mówiąc:
Ó sì pa àṣẹ yìí fún Hilkiah, Ahikamu ọmọ Ṣafani, Abdoni ọmọ Mika, Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
21 Idźcie, radźcie się Pana o mię, i o ostatek ludu w Izraelu i w Judzie około słów tych ksiąg, które są znalezione; bo wielka jest popędliwość Pańska, która jest wylana na nas, przeto, że nie strzegli ojcowie nasi słowa Pańskiego, aby czynili według wszystkiego, co jest napisane w tych księgach.
“Ẹ lọ kí ẹ lọ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi nípa àwọn ìyókù Israẹli àti Juda nípa ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ti jáde sí orí wa nítorí àwọn baba wa kò ti pa ọ̀rọ̀ Olúwa mọ́, wọn kò sì tí ì ṣe gẹ́gẹ́ bí i gbogbo èyí tí a kọ sínú ìwé yìí.”
22 A tak poszedł Helkijasz, i którzy byli przy królu, do Huldy prorokini, żony Selluma, syna Tekui, syna Hasrowego, stróża szat; a ona mieszkała w Jeruzalemie na drugiej stronie miasta; i mówili z nią o tem.
Hilkiah àti àwọn ènìyàn tí ọba yàn tọ Hulda wòlíì obìnrin láti ba sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tokhati tí a tún ń pè ní Tikfa, ọmọ Harhasi, olùtọ́jú ibi ìkáṣọsí. Ó sì ń gbé ní Jerusalẹmu, ní ìhà kejì.
23 Która rzekła do nich: Tak mówi Pan, Bóg Izraelski: Powiedzcie mężowi, który was posłał do mnie:
Ó sì wí fún wọn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli ti sọ, sọ fún àwọn ọkùnrin tí ó rán ọ sí mi pé,
24 Tak mówi Pan: Oto, Ja przywiodę złe na to miejsce, i na obywateli jego, wszystkie przeklęstwa napisane w tych księgach, które czytano przed królem Judzkim.
‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Èmi yóò sì mú ibi wá sí ìhín yìí àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gbogbo àní ègún tí a kọ sínú ìwé tí wọ́n ti kà níwájú ọba Juda.”
25 Przeto, że mię opuścili, i kadzili bogom cudzym, aby mię draźnili wszystkiemi sprawami rąk swoich; dlaczego wyleje się popędliwość moja na to miejsce, i nie będzie ugaszona.
Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀ wọ́n sì ti sun tùràrí sí ọlọ́run mìíràn wọ́n sì ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn ṣe, ìbínú yóò tú jáde wá sórí ibí yìí, a kì yóò sì paná rẹ̀.’
26 A królowi Judzkiemu, który was posłał o radę do Pana, tak powiedzcie: Tak mówi Pan, Bóg Izraelski, o słowach, któreś słyszał:
Sọ fún ọba Juda, ẹni tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa ti sọ, Ọlọ́run Israẹli, sọ nípa ọ̀rọ̀ wọ́n nì tí ìwọ gbọ́.
27 Gdyż serce twoje zmiękczone jest, i upokorzyłeś się przed obliczem Bożem, słysząc słowa jego przeciwko temu miejscu, i przeciwko obywatelom jego, a upokorzywszy się przedemną rozdarłeś szaty swe, i płakałeś przedemną, przetożem cię wysłuchał, mówi Pan;
Nítorí ọkàn rẹ̀ dúró, ìwọ sì rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa nígbà tí ó gbọ́ ohun tí ó sọ lórí ibí yìí àti ènìyàn rẹ, nítorí ìwọ rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú mi tí o sì fa aṣọ rẹ ya, tí o sì lọ níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ ni Olúwa wí.
28 Oto ja cię zbiorę do ojców twoich, a będziesz włożony do grobu twego w pokoju, aby nie oglądały oczy twoje wszystkiego złego, które Ja przywiodę na to miejsce, i na obywateli jego. I odnieśli tę rzecz królowi.
Nísinsin yìí, Èmi ó kó ọ jọ pọ̀ sọ́dọ̀ àwọn baba rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kò sì ní rí gbogbo ibi tí èmi ó mú wá sórí ibí yìí àti lórí àwọn tí ń gbé ibẹ̀.’” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n mú ìdáhùn rẹ̀ padà sí ọ̀dọ̀ ọba.
29 Tedy posławszy król zgromadził wszystkich starszych z Judy i z Jeruzalemu.
Nígbà náà ni ọba sì pe gbogbo àwọn àgbàgbà Juda jọ àti Jerusalẹmu.
30 I wstąpił król do domu Pańskiego, i wszyscy mężowie Judzcy, i obywatele Jeruzalemscy, i kapłani i Lewitowie, i wszystek lud, od wielkiego aż do małego, i czytał gdy wszyscy słyszeli, wszystkie słowa ksiąg przymierza, które było znalezione w domu Pańskim.
Ó gòkè lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi—gbogbo àwọn ènìyàn láti ibi kéékèèké sí ńlá. Ó kà á sí etí ìgbọ́ ọ wọn, gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé májẹ̀mú, tí a ti rí nínú ilé Olúwa.
31 Potem stojąc król na miejscu swem, uczynił przymierze przed Panem, że chce chodzić za Panem, i strzedz przykazań jego, i świadectw jego, i ustaw jego, ze wszystkiego serca swego i ze wszystkiej duszy swojej, i pełnić słowa przymierza tego, które było w onych księgach napisane.
Ọba sì dúró ní ipò rẹ̀ ó sì tún májẹ̀mú dá níwájú Olúwa, láti tẹ̀lé Olúwa àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, àti ẹ̀rí rẹ̀ àti àṣẹ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀ àti gbogbo àyà rẹ̀ àti láti pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí a kọ sí inú ìwé yìí.
32 I rozkazał stać w tem przymierzu wszystkim, którzy znalezieni byli w Jeruzalemie i w Benjaminie; i czynili obywatele Jeruzalemscy według przymierza Boga, Boga ojców swoich.
Nígbà náà, ó sì mú kí gbogbo ènìyàn ní Jerusalẹmu àti Benjamini dúró nínú ẹ̀rí fún ara wọn, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ṣe èyí gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú Ọlọ́run, Ọlọ́run baba ńlá wọn.
33 Tedy uprzątnął Jozyjasz wszystkie obrzydłości ze wszystkich krain synów Izraelskich, a przywiódł do tego wszystkich, którzy się znajdowali w Izraelu, aby służyli Panu, Bogu swemu. Po wszystkie dni jego nie odstąpili od naśladowania Pana, Boga ojców swoich.
Josiah sì kó gbogbo ohun ìríra kúrò nínú gbogbo ìlú tí ń ṣe ti àwọn tí ó wà ní Israẹli, ó sì mú kí gbogbo àwọn tí ó wà ní Israẹli sin Olúwa Ọlọ́run wọn gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà láyè wọn, kò yà kúrò láti máa tọ Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn lẹ́yìn.

< II Kronik 34 >