< I Kronik 16 >

1 A gdy przynieśli skrzynię Bożą, i postawili ją w pośród namiotu, który był Dawid rozbił, tedy sprawowali całopalenia i ofiary spokojne przed Bogiem.
Wọ́n gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, wá sínú àgọ́ ti Dafidi ti pèsè fún un, wọ́n sì gbé ẹbọ sísun àti ọrẹ ìdàpọ̀ kalẹ̀ níwájú Ọlọ́run.
2 A gdy dokończył Dawid ofiarować całopalenia, i ofiar spokojnych, błogosławił ludowi w imię Pańskie.
Lẹ́yìn tí Dafidi parí ẹbọ sísun àti ọrẹ ìdàpọ̀, ó bùkún àwọn ènìyàn ní orúkọ Olúwa.
3 I rozdzielił wszystkim mężom Izraelskim, od męża aż do niewiasty, każdemu po bochenku chleba, i po sztuce mięsa, i po łagiewce wina.
Nígbà náà ó fún olúkúlùkù ọkùnrin àti obìnrin ọmọ Israẹli ní ìṣù àkàrà kan, àkàrà dídùn ti àkókò kan àti àkàrà dídùn ti èso àjàrà kan.
4 A postanowił przed skrzynią Pańską z Lewitów sługu, aby wspominali, i wyznawali, i chwalili Pana, Boga Izraelskiego.
Ó yan díẹ̀ lára àwọn ará Lefi láti máa jọ́sìn níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, àti láti ṣe ìrántí àti dúpẹ́ àti láti yin Olúwa, Ọlọ́run Israẹli.
5 Asaf był przedniejszy, a wtóry po nim Zacharyjasz, Jehyjel, i Semiramot, i Jechyjel i Matytyjasz, i Elijab, i Benajasz, i Obededom, i Jechyjel; ci na instrumentach, na lutniach, na harfach, ale Asaf na cymbałach, grali.
Asafu ni olóyè, àtẹ̀lé rẹ ni Sekariah, Jehieli, Ṣemiramotu, Asieli, Mattitiah, Eliabu, Benaiah, Obedi-Edomu àti Jeieli, àwọn ni yóò lu ohun èlò orin olókùn àti dùùrù haapu. Asafu ni yóò lu símbálì kíkan.
6 Benajasz zaś i Jachazyjel kapłani z trąbami ustawiczne byli przed skrzynią przymierza Bożego.
Àti Benaiah àti Jahasieli àwọn àlùfáà ni yóò fọn ìpè nígbà gbogbo níwájú àpótí ẹ̀rí májẹ̀mú ti Ọlọ́run.
7 Dopiero dnia onego najpierwej postanowił Dawid, aby tym psalmem chwalony był Pan przez Asafa i braci jego:
Ní ọjọ́ náà Dafidi kọ́kọ́ fi lé Asafu àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ orin Dafidi ti ọpẹ́ sí Olúwa.
8 Wysławiajcie Pana, wzywajcie imienia jego, a opowiadajcie między narodami sprawy jego.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ẹ pe orúkọ rẹ̀, ẹ fi iṣẹ́ rẹ̀ hàn nínú àwọn ènìyàn fún ohun tí ó ṣe
9 Śpiewajcie mu, grajcie mu, rozmawiajcie o wszystkich cudach jego.
Ẹ kọrin sí i, ẹ kọrin ìyìn, sí i, ẹ sọ ti gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀.
10 Chlubcie się w imieniu świętem jego, a niech się rozraduje serce szukających Pana.
Ìyìn nínú orúkọ rẹ̀ mímọ́; jẹ kí ọkàn àwọn tí ó yin Olúwa kí ó yọ̀.
11 Szukajcie Pana, i mocy jego; szukajcie oblicza jego zawżdy.
Ẹ wá Olúwa àti agbára rẹ̀; e wá ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
12 Wspominajcie dziwne sprawy jego, które czynił, i cuda jego, i sądy ust jego.
Rántí àwọn ìyanu tí Ó ti ṣe, iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ àti ìdájọ́ tí Ó ti sọ.
13 O nasienie Izraelskie, słudzy jego! O synowie Jakóbowi, wybrani jego!
A! ẹ̀yin ìran ọmọ Israẹli ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn ọmọ Jakọbu, ẹ̀yin tí ó ti yàn.
14 On jest Pan, Bóg nasz; po wszystkiej ziemi sądy jego.
Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa; ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
15 Pamiętajcie aż na wieki na przymierze jego, na słowow, które przykazał do tysiącznego pokolenia;
Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
16 Które postanowił z Abrahamem, i na przysięgę jego z Izaakiem;
májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
17 I postanowił to Jakóbowi za prawo, a Izraelowi za przymierze wieczne,
Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
18 Mówiąc: Tobie dam ziemię Chananejską za sznur dziedzictwa waszego.
“Sí ọ, ni èmi yóò fún ní ilẹ̀ Kenaani. Gẹ́gẹ́ bí ààyè tí ìwọ yóò jogún.”
19 Choć was była mała liczba, a przez krótki czas byliście przychodniami w niej;
Nígbà tí wọn kéré ní iye, wọ́n kéré gidigidi, wọ́n sì jẹ́ àlejò níbẹ̀,
20 I przechodzili od narodu do narodu, i od królestwa do innego ludu:
wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè láti ìjọba kan sí èkejì.
21 Nie dopuścił nikomu, aby ich uciskać miał, i karał dla nich królów,
Kò gba ọkùnrin kankan láyè láti pọ́n wọn lójú; nítorí tiwọn, ó bá àwọn ọba wí.
22 Mówiąc: Nie tykajcie pomazańców moich, a prorokom moim nie czyńcie nic złego.
“Má ṣe fọwọ́ kan àwọn ẹni àmì òróró mi; má ṣe pa àwọn wòlíì mi lára.”
23 Śpiewajcie Panu wszystka ziemio; opowiadajcie ode dnia do dnia zbawienie jego.
Kọrin sí Olúwa gbogbo ayé; ẹ máa fi ìgbàlà rẹ̀ hàn láti ọjọ́ dé ọjọ́.
24 Opowiadajcie między narodami chwałę jego, i między wszystkimi ludźmi dziwne sprawy jego;
Kéde ògo à rẹ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun ìyàlẹ́nu tí ó ṣe láàrín gbogbo ènìyàn.
25 Bo wielki jest Pan, i chwalebny bardzo, i straszniejszy nad wszystkich bogów;
Nítorí títóbi ni Olúwa òun sì ni ìyìn yẹ jùlọ; òun ni kí a bẹ̀rù ju gbogbo àwọn Ọlọ́run lọ.
26 Gdyż bogowie pogańscy są bałwanami; ale Pan niebiosa uczynił.
Nítorí gbogbo àwọn ọlọ́run orílẹ̀-èdè jẹ́ àwọn òrìṣà, ṣùgbọ́n Olúwa dá àwọn ọ̀run.
27 Sława i zacność przed nim, moc i wesele na miejscu jego.
Dídán àti ọláńlá ni ó wà níwájú rẹ̀; agbára àti ayọ̀ ni ó wà ní ibi ibùgbé rẹ̀.
28 Przynieście Panu pokolenia narodów, przynieście Panu chwałę i moc.
Fi fún Olúwa, ẹ̀yin ìdílé àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ fi ògo àti ipá fún Olúwa.
29 Przynieście Panu chwałę imienia jego, przynieście dary, a przychodźcie przed obliczności jego; kłaniajcie się Panu w ozdobie świętobliwości.
Fún Olúwa ní ìyìn nítorí orúkọ rẹ̀; gbé ọrẹ kí ẹ sì wá síwájú rẹ̀. Sìn Olúwa nínú inú dídùn ìwà mímọ́ rẹ̀.
30 Bójcie się oblicza jego wszystka ziemio, a będzie utwierdzony okrąg ziemi, aby się nie poruszył.
Wárìrì níwájú rẹ̀, gbogbo ayé! Ayé sì fi ìdí múlẹ̀; a kò sì le è ṣí i.
31 Niech się rozradują niebiosa, a niech się rozweseli ziemia, a niech mówią w narodach: Pan króluje!
Jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó yọ̀, jẹ́ kí ayé kí ó ṣe inú dídùn; lẹ́ kí wọn kí ó sọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, pé “Olúwa jẹ ọba!”
32 Niech zaszumi morze, i ze wszystkiem, co w niem jest; niech się rozraduje pole, i wszystko, co na niem jest.
Jẹ́ kí ọ̀run kí ó tún dún padà, àti gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀; Jẹ́ kí àwọn pápá kí ó hó fún ayọ̀, àti gbogbo ohun tí ó wà nínú rẹ̀!
33 Tedy się rozweselą drzewa leśne przed Panem; albowiem przyszedł sądzić ziemię.
Nígbà náà ni igi igbó yóò kọrin, wọn yóò kọrin fún ayọ̀ níwájú Olúwa, nítorí tí ó wá láti ṣèdájọ́ ayé.
34 Wysłwiajcie Pana; albowiem dobry, bo na wieki trwa miłosierdzie jego.
Fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; ìfẹ́ ẹ rẹ̀ dúró títí láé.
35 A mówcie: Zachowaj nas, Boże zbawienia naszego! i zgromadź nas, a wyrwij nas od pogan, abyśmy wielbili imię święte twoje, i chlubili się w chwale twojej.
Ké lóhùn rara, “Gbà wá, Ọlọ́run olùgbàlà a wa; kó wa jọ kí o sì gbà wá kúrò lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, kí àwa kí ó lè fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ, kí àwa kí ó lè yọ̀ nínú ìyìn rẹ̀.”
36 Błogosławiony Pan, Bóg Izraelski, od wieków aż na wieki. I rzekł wszystek lud Amen, i chwalił Pana.
Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láé àti láéláé. Lẹ́yìn náà gbogbo àwọn ènìyàn wí pé, “Àmín,” wọ́n “Yin Olúwa.”
37 I zostawił tam Dawid przed skrzynią przymierza Pańskiego Asafa i braci jego, aby służyli przed skrzynią ustawicznie według potrzeby dnia każdego.
Dafidi fi Asafu àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa láti jíṣẹ́ níbẹ̀ déédé, gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ṣe gbà.
38 Lecz Obededoma i braci ich sześdziesiąt i ośm, Obededoma mówię, syna Jedytunowego, i Hosę, uczynił odźwiernymi.
Ó fi Obedi-Edomu àti méjìdínláàádọ́rin ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ láti ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú wọn. Obedi-Edomu mọ Jedutuni, àti Hosa pẹ̀lú jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà.
39 A Sadoka kapłana, i braci jego kapłanów postawił przed przybytkiem Pańskim na wyżynie, która była w Gabaon,
Dafidi fi Sadoku àlùfáà àti àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ níwájú Àgọ́ Olúwa ní ibi gíga ní Gibeoni.
40 Aby ofiarowali całopalenia Panu na ołtarzu całopalenia ustawicznie rano i w wieczór, a to według wszystkiego, co napisano w zakonie Pańskim, który przykazał Izraelowi.
Láti gbé pẹpẹ ẹbọ sísun déédé, àárọ̀ àti ìrọ̀lẹ́ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ sínú òfin Olúwa, tí ó ti fún Israẹli.
41 A z nimi Hemana i Jedytuna, i innych na to obranych, którzy byli z imienia mianowani, aby chwalili Pana, przeto iż na wieki trwa miłosierdzie jego.
Pẹ̀lú wọn ni Hemani àti Jedutuni àti ìyókù tí a mú àti yàn nípasẹ̀ orúkọ láti fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró títí láéláé
42 A między nimi Heman i Jedytun, trąbili i grali na trąbach, na cymbałach, i na innych instrumentach muzycznych Bogu; ale synów Jedytunowych postawił u wrót.
Hemani àti Jedutuni ni wọ́n dúró fún fífọn ìpè àti Kimbali àti fún lílo ohun èlò yòókù fún orin Ọlọ́run. Àwọn ọmọ Jedutuni wà ní ipò dídúró ní ẹnu-ọ̀nà.
43 A tak rozszedł się wszystek lud, każdy do domu swego. Dawid się też wrócił, aby błogosławił domowi swemu.
Nígbà náà gbogbo àwọn ènìyàn kúrò, olúkúlùkù sí ilé rẹ̀: Dafidi yípadà láti súre fún ìdílé rẹ̀.

< I Kronik 16 >