< I Kronik 15 >

1 A gdy sobie pobudował Dawid domy w mieście swojem, i nagotował miejsce skrzyni Bożej, i rozbił jej namiot,
Lẹ́yìn ìgbà tí Dafidi ti kọ́ ilé fún ara rẹ̀ ní ìlú Dafidi. Ó sì fi ààyè sílẹ̀ fún àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ó sì pàgọ́ fún un.
2 Tedy rzekł Dawid: Niegodzi się nosić skrzyni Bożej jedno Lewitom. Tych bowiem obrał Pan, aby nosili skrzynię Bożą, i służyli mu aż na wieki.
Nígbà náà Dafidi wí pé, kò sí ẹnìkan àyàfi àwọn ọmọ Lefi ni ó lè gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, nítorí Olúwa yàn wọ́n láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àti láti máa ṣe ìránṣẹ́ níwájú rẹ̀ títí láé.
3 Przetoż zebrał Dawid wszystkiego Izraela do Jeruzalemu, aby przeniósł skrzynię Pańską na miejsce jej, które jej był zgotował.
Dafidi kó gbogbo àwọn ọmọ Israẹli jọ ní Jerusalẹmu láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ibi tí ó ti pèsè sílẹ̀ fún un.
4 I zgromadził Dawid synów Aaronowych i Lewitów.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Aaroni àti àwọn ọmọ Lefi tí Dafidi péjọ papọ̀.
5 Z synów Kaatowych: Uryjela przedniejszego, i braci jego sto i dwadzieścia,
Ọgọ́fà nínú àwọn ọmọ Kohati; Urieli olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
6 Z synów Merarego: Asajasza przedniejszego, i braci jego dwieście i dwadzieścia.
Igba ó lé ogún nínú àwọn ọmọ Merari; Asaiah olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
7 Z synów Giersonowych: Joela przedniejszego, i braci jego sto i trzydzieści.
Àádóje nínú àwọn ọmọ Gerṣoni; Joẹli olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
8 Z synów Elisafanowych: Semejasza przedniejszego, i braci jego dwieście.
Igba nínú àwọn ọmọ Elisafani; Ṣemaiah olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
9 Z synów Hebronowych: Elijela przedniejszego, i braci jego ośmdziesiąt.
Ọgọ́rin nínú àwọn ọmọ Hebroni; Elieli olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
10 Z synów Hasyjelowych: Aminadaba przedniejszego, i braci jego sto i dwanaście.
Méjìléláàádọ́fà nínú àwọn ọmọ Usieli; Amminadabu olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
11 Tedy wezwał Dawia Sadoka i Abijatara, kapłanów, także Lewitów Uryjela, Asajasza, i Joela, Semejasza, i Elijela, i Aminadaba;
Dafidi sì ránṣẹ́ pe Sadoku, Abiatari tí wọ́n jẹ́ àlùfáà, àti Urieli, Asaiah. Joẹli, Ṣemaiah, Elieli àti Amminadabu tí wọ́n jẹ́ Lefi.
12 I rzekł do nich: Wyście przedniejsi z domów ojcowskich między Lewitami; poświęćcież się i z braćmi swoimi, abyście przynieśli skrzynię Pana, Boga Izraelskiego, na miejsce, którem jej nagotował.
Ó sì fi fún wọn pé, “Ẹ̀yin ni olórí àwọn ìdílé Lefi; ẹ̀yin àti àwọn Lefi ènìyàn yín, ẹ ya ara yín sí mímọ́ kí ẹ lè gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, lọ sí ibi tí mó ti pèsè sílẹ̀ fún un.
13 Albowiem iżeście tego pierwej nie uczynili, uczynił rozerwanie Pan, Bóg nasz, między nami; bośmy go nie szukali według przystojności.
Nítorí tí ẹ̀yin ọmọ Lefi kò gbe gòkè wá ní ìgbà àkọ́kọ́ ti Olúwa Ọlọ́run fi ìbínú rẹ̀ ko lù wá. Àwa kò sì ṣe ìwádìí lọ́wọ́ rẹ̀ nípa bí a ti ń ṣe é gẹ́gẹ́ bí ọ́nà tí a là sílẹ̀.”
14 Poświęcili się tedy kapłani i Lewitowie, aby przynieśli skrzynię Pana, Boga Izraelskiego.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi ya ara wọn sí mímọ́ láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa gòkè wá, Ọlọ́run Israẹli.
15 I niesli synowie Lewitów skrzynię Bożą, jako był rozkazał Mojżesz według słowa Pańskiego, na ramionach swych, na drążkach które przy niej były.
Nígbà náà ni àwọn Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run pẹ̀lú ọ̀pá ní èjìká wọn gẹ́gẹ́ bí Mose ti pa á láṣẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.
16 I rzekł Dawid przedniejszym z Lewitów, aby postanowili z braci swoich śpiewaków z instrumentami muzycznemi, z lutniami, z cytrami, i z cymbałami, aby słyszany był wyniesiony głos z weselem.
Dafidi sọ fún àwọn olórí àwọn Lefi láti yan àwọn arákùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí akọrin láti kọ orin ayọ̀, pẹ̀lú àwọn ohun èlò orin olókùn, dùùrù, àti símbálì.
17 I postanowili Lewitowie Hemana, syna Joelowego, a z braci jego Asafa, syna Barachyjaszowego, a z synów Merarego, braci ich, Etana syna Chysajowego;
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn Lefi yan Hemani ọmọ Joẹli; àti nínú àwọn arákùnrin rẹ̀, Asafu ọmọ Berekiah, àti nínú àwọn ọmọ Merari arákùnrin wọn, Etani ọmọ Kuṣaiah;
18 A z nimi braci ich w rzędzie wtórym: Zacharyjasza, Bena, i Jazyjela, i Semiramota, i Jechyjela, i Unni, Elijaba, i Benajasza, Maasejasza, i Matytyjasza, i Elifelego, i Miknejasza, i Obededoma, i Jehijela, odźwiernych.
àti pẹ̀lú wọn àwọn arákùnrin wọn tí a yàn bí olùrànlọ́wọ́ wọn: Sekariah, Jaasieli, Ṣemiramotu, Jehieli, Unni, Eliabu, Benaiah, Maaseiah, Mattitiah, Elifelehu, Mikimeiah, àti Obedi-Edomu àti Jeieli, àwọn aṣọ́bodè.
19 A śpiewacy Heman, Asaf, i Etan na cymbałach miedzianych głośno grali.
Àwọn akọrin sì ni Hemani, Asafu, àti Etani ti àwọn ti kimbali idẹ tí ń dún kíkan;
20 A Zacharyjasz, i Jazyjel, i Semiramot, i Jechyjel, i Unni, i Elijab, i Maasejasz, i Benajasz grali na lutniach przy śpiewaniu wysokiem.
Sekariah, Asieli, Ṣemiramotu, Jehieli, àti Unni, Eliabu, Maaseiah àti Benaiah àwọn tí ó gbọdọ̀ ta ohun èlò orin olókùn gẹ́gẹ́ bí alamoti,
21 A Matytyjasz, i Elifele, i Miknejasz, i Obededom, i Jechyjel, i Azazyjasz grali na cytrach przy śpiewaniu niskiem.
àti Mattitiah, Elifelehu, Mikneiah, Obedi-Edomu, Jeieli àti Asasiah ni ó ní láti ta ohun èlò olóhùn gooro, láti darí gẹ́gẹ́ bí ṣeminiti.
22 A Kienanijasz, przedniejszy z Lewitów, którzy nieśli skrzynię, rozrządzał, jakoby nieść miano; bo był roztropny.
Kenaniah olórí àwọn ará Lefi ni ó wà ní ìkáwọ́ orin èyí sì ni ojúṣe nítorí ó mòye nípa rẹ̀.
23 Ale Bacharyjasz i Elkana byli odźwiernymi u skrzyni.
Berekiah àti Elkana ni kí ó wà gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́nà fún àpótí ẹ̀rí.
24 A Sebanijasz i Jozafat, i Natanael, i Amasaj, i Zacharyjasz, i Benajasz, i Eliezer, kapłani, trąbili w trąby przed skrzynią Bożą; ale Obededom i Jechyjasz byli odźwiernymi u skrzyni.
Ṣebaniah, Jehoṣafati, Netaneli, Amasai, Sekariah, Benaiah àti Elieseri ní àwọn àlùfáà, tí o ń fún ìpè níwájú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run. Obedi-Edomu àti Jehiah ni ó sì gbọdọ̀ jẹ́ olùṣọ́nà fún àpótí ẹ̀rí.
25 A tak Dawid i starsi Izraelscy, i hetmani nad tysiącami szli, aby przeprowadzili skrzynię przymierza Pańskiego z domu Obededomowego z weselem.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti àwọn àgbàgbà Israẹli àti àwọn olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún lọ láti gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa láti ilé Obedi-Edomu, pẹ̀lú inú dídùn.
26 I stało się, gdy Bóg wspomógł Lewitów, niosących skrzynię przymierza Pańskiego, że ofiarowali siedm wołów, i siedm baranów.
Nítorí Ọlọ́run tì ràn wọ́n lọ́wọ́ àwọn ará Lefi ẹni tí ó gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa, akọ màlúù méje pẹ̀lú àgbò méje láti fi ṣé ìrúbọ.
27 A Dawid był obleczony w szatę bisiorową, także i wszyscy Lewitowie, którzy nieśli skrzynię, i śpiewacy, i Kienanijasz, rządca tych, co nieśli między śpiewakami; a Dawid miał na sobie efod lniany.
Dafidi sì wọ efodu; aṣọ ìgúnwà ọ̀gbọ̀ dáradára, àti gbogbo àwọn ọmọ Lefi tí ń ru àpótí ẹ̀rí náà, àti àwọn akọrin, àti Kenaniah olórí pẹ̀lú àwọn akọrin. Dafidi sì wọ aṣọ ìgúnwà funfun.
28 A tak wszystek Izrael prowadził skrzynię przymierza PaOskiego z weselem, i z hukiem kornetu, i trąby, i cymbałów, grając na lutniach i na cytrach.
Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo Israẹli gbé àpótí ẹ̀rí àti májẹ̀mú Olúwa gòkè wá pẹ̀lú ariwo, pẹ̀lú àyíká ìhó ayọ̀ àti láti fọn fèrè ti ìpè, àti kimbali, àti láti ta ohun èlò orin olókùn àti dùùrù olóhùn gooro.
29 I stało się, gdy skrzynia przymierza Pańskiego wchodziła do miasta Dawidowego, że Michol, córka Saulowa, wyglądając oknem ujrzała króla Dawida skaczącego, i grającego, i wzgardziła go w sercu swojem.
Bí àpótí ẹ̀rí Olúwa ti ń wọ ìlú ńlá Dafidi, Mikali ọmọbìnrin Saulu ń wò láti ojú fèrèsé nígbà tí ó sì rí ọba Dafidi ń jó, ó sì ń ṣe àjọyọ̀, ó sì kẹ́gàn rẹ̀ ní ọkàn rẹ̀.

< I Kronik 15 >