< Josvas 2 >
1 Josva, Nuns sønn, sendte hemmelig to speidere fra Sittim og sa: Gå avsted og se eder om i landet og særlig i Jeriko! De gikk avsted og kom inn i huset til en skjøge som hette Rahab, og de lå der om natten.
Nígbà náà ni Joṣua ọmọ Nuni rán àwọn ayọ́lẹ̀wò méjì jáde ní àṣírí láti Ṣittimu. Ó sì wí pé, “Ẹ lọ wo ilẹ̀ náà, pàápàá Jeriko.” Wọ́n sì lọ, wọ́n wọ ilé panṣágà kan, tí à ń pè ní Rahabu wọ́n sì dúró síbẹ̀.
2 Da blev det meldt til kongen i Jeriko: Nogen menn av Israels barn er kommet hit i natt for å utspeide landet.
A sì sọ fún ọba Jeriko, “Wò ó! Àwọn ará Israẹli kan wá ibí ní alẹ́ yìí láti wá yọ́ ilẹ̀ yí wò.”
3 Så sendte kongen i Jeriko bud til Rahab og lot si: Kom hit med de menn som kom til dig og tok inn i ditt hus! De er kommet for å utspeide hele landet.
Ọba Jeriko sì ránṣẹ́ sí Rahabu pé, “Mú àwọn ọkùnrin nì tí ó tọ̀ ọ́ wá, tí ó wọ inú ilé rẹ jáde wá, nítorí wọ́n wá láti yọ́ gbogbo ilẹ̀ yìí wò ni.”
4 Men kvinnen tok og skjulte de to menn, og så sa hun: Det er så at disse menn kom til mig, men jeg visste ikke hvor de var fra;
Ṣùgbọ́n obìnrin náà ti mú àwọn ọkùnrin méjì náà o sì fi wọ́n pamọ́. Ó sì wí pé, “Lóòtítọ́ ní àwọn ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi, ṣùgbọ́n èmi kò mọ ibi tí wọ́n ti wá.
5 og i mørkningen da porten skulde lukkes, gikk mennene ut; jeg vet ikke hvor de tok veien. Skynd eder og sett efter dem, så når I dem nok igjen.
Nígbà tí ilẹ̀ ṣú, nígbà tí ó tó àkókò láti ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè, àwọn ọkùnrin náà sì jáde lọ. Èmi kò sì mọ ọ̀nà tí wọ́n gbà lọ. Ẹ lépa wọn kíákíá. Ẹ̀yin yóò bá wọn.”
6 Men hun hadde latt dem stige op på taket og skjult dem under linstenglene som hun hadde liggende utbredt der på taket.
(Ṣùgbọ́n ó ti mú wọn gòkè àjà ó sì fi wọ́n pamọ́ sí abẹ́ pòròpòrò ọkà tó tò jọ sí orí àjà.)
7 Så satte mennene efter dem på veien til Jordan, til vadestedene; og porten blev lukket, så snart de som satte efter dem, var gått ut.
Àwọn ọkùnrin náà jáde lọ láti lépa àwọn ayọ́lẹ̀wò náà ní ọ̀nà tí ó lọ sí ìwọdò Jordani, bí àwọn tí ń lépa wọn sì ti jáde, wọ́n ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè.
8 Før speiderne hadde lagt sig, gikk hun op til dem på taket,
Kí àwọn ayọ́lẹ̀wò náà tó sùn ní alẹ́, ó gòkè tọ̀ wọ́n lọ lókè àjà.
9 og hun sa til dem: Jeg vet at Herren har gitt eder landet, og at redsel for eder er falt på oss, og at alle landets innbyggere forgår av angst for eder.
Ó sì sọ fún wọn, “Èmi mọ̀ pé Olúwa ti fún un yín ní ilẹ̀ yìí àti pé ẹ̀rù u yín ti sọ wá di ojo dé ibi pé ìdí gbogbo àwọn tí ó n gbé ilẹ̀ yìí ti di omi nítorí i yín.
10 For vi har hørt at Herren tørket ut vannet i det Røde Hav foran eder da I drog ut av Egypten, og vi har hørt hvad I gjorde med begge amoritter-kongene på hin side Jordan, Sihon og Og, som I slo med bann.
Àwa ti gbọ́ bí Olúwa ti mú omi Òkun Pupa gbẹ níwájú u yín nígbà tí ẹ̀yin jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, àti ohun tí ẹ̀yin ṣe sí Sihoni àti Ogu, àwọn ọba méjèèjì ti Amori ti ìlà-oòrùn Jordani, tí ẹ̀yin parun pátápátá.
11 Da vi hørte det, blev vårt hjerte fullt av angst, og nu er det ikke mere nogen som har mot til å møte eder; for Herren eders Gud han er Gud både i himmelen der oppe og på jorden her nede.
Bí a ti gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ọkàn wa pami kò sì sí okun kankan fún wa mọ́ nítorí i yín, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni Ọlọ́run ní òkè ọ̀run àti ní ayé.
12 Så sverg mig nu til ved Herren, siden jeg har vist barmhjertighet mot eder, at også I vil vise barmhjertighet mot min fars hus, og gi mig således et tegn på eders ærlighet,
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ jọ̀wọ́ ẹ búra fún mi ní ti Olúwa pé ẹ̀yin yóò ṣe àánú fún ìdílé mi, nítorí pé mo ti ṣe yín ní oore. Ẹ̀yin yóò fún mi ní àmì tó dájú:
13 og la min far og min mor og mine brødre og mine søstre og alle som hører dem til, leve, og frels vårt liv fra døden!
pé ẹ̀yin yóò dá ẹ̀mí baba àti ìyá mi sí; arákùnrin mi àti arábìnrin mi, àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, àti pé ẹ̀yin yóò gbà wá là lọ́wọ́ ikú.”
14 Da sa mennene til henne: Med vårt eget liv skal vi svare for eders liv! Så sant I ikke lar nogen få vite noget om vårt ærend, skal vi, når Herren gir oss landet, vise barmhjertighet og trofasthet mot dig.
“Ẹ̀mí wa fún ẹ̀mí in yín!” àwọn ọkùnrin náà mú dá a lójú. “Tí ìwọ kò bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò sì fi òtítọ́ àti àánú bá ọ lò nígbà tí Olúwa bá fún wa ní ilẹ̀ náà.”
15 Så firte hun dem ned gjennem vinduet med et rep; for hennes hus lå ved byens mur, så hun bodde like ved muren.
Nígbà náà ní ó fi okùn sọ̀ wọ́n kalẹ̀ ní ojú u fèrèsé, nítorí ilé tí ó ń gbé wà ní ara odi ìlú.
16 Og hun sa til dem: Gå op i fjellene, så at de som forfølger eder, ikke treffer på eder, og hold eder skjult der i tre dager, til forfølgerne kommer tilbake; siden kan I gå hvor I vil.
Ó sì ti sọ fún wọn pé, “Ẹ lọ sí orí òkè, kí ẹ sì fi ara pamọ́ níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta kí àwọn tí ń lépa yín má ba à rí i yín títí tí wọn yóò fi darí. Lẹ́yìn náà kí ẹ máa bá ọ̀nà yín lọ.”
17 Mennene svarte: Vi holder oss for å være løst fra denne ed som du tok av oss,
Àwọn arákùnrin náà sì sọ fún un pé, “Kí ọrùn un wa ba à lè mọ́ kúrò nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú yìí.
18 hvis du ikke, når vi kommer inn i landet, binder denne snor av skarlagenfarvet tråd i det vindu som du har firet oss ned igjennem, og så samler din far og din mor og dine brødre og hele din slekt i huset hos dig.
Nígbà tí àwa bá wọ ilé è rẹ, ìwọ yóò so okùn aláwọ̀ aró yìí sí ojú fèrèsé èyí tí ìwọ fi sọ̀ wá kalẹ̀, kí ìwọ kí ó mú baba rẹ, ìyá rẹ, àwọn arákùnrin in rẹ àti gbogbo ìdílé è rẹ kí wọ́n wá sí inú ilé è rẹ.
19 Enhver som går ut av din husdør, hans blod komme over hans eget hode, og vi er skyldfri; men enhver som er hos dig i huset, hans blod komme over vårt hode, dersom der blir lagt hånd på ham.
Bí ẹnikẹ́ni bá jáde sí ìta láti inú ilé è rẹ sí inú ìgboro ìlú, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò sì wà ní orí ara rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí i rẹ̀. Fún ẹnikẹ́ni tí ó bá wà nínú ilé pẹ̀lú rẹ, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà ní orí i wa bí ẹnikẹ́ni bá fi ọwọ́ kàn án.
20 Og dersom du lar nogen få vite noget om vårt ærend, så er vi løst fra den ed du tok av oss.
Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò bọ́ nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú.”
21 Hun sa: La det være som I sier! Så lot hun dem gå, og de drog avsted; siden bandt hun den skarlagenfarvede snor i vinduet.
Ó dáhùn pé, “Ó dára bẹ́ẹ̀. Ẹ jẹ́ kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí sọ.” Ó sì rán wọn lọ wọ́n sì lọ. Ó sì so okùn òdòdó náà sí ojú fèrèsé.
22 De gikk til de kom op i fjellene; der blev de i tre dager, inntil de som forfulgte dem, var vendt tilbake; og forfølgerne lette på hele veien, men fant dem ikke.
Nígbà tí wọ́n kúrò, wọ́n sì lọ sí orí òkè wọ́n sì dúró ní ibẹ̀ ní ọjọ́ mẹ́ta, títí àwọn alépa fi wá wọn ní gbogbo ọ̀nà wọ́n sì padà láìrí wọn.
23 Så vendte de to menn om og gikk ned fra fjellene og satte over elven og kom til Josva, Nuns sønn, og fortalte ham alt det som hadde hendt dem.
Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin méjì náà padà. Wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè, wọ odò, wọ́n sì wá sí ọ̀dọ̀ Joṣua ọmọ Nuni wọ́n sì sọ fún un gbogbo ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wọn.
24 Og de sa til Josva: Herren har gitt hele landet i vår hånd; alle landets innbyggere holder endog på å forgå av angst for oss.
Wọ́n sì sọ fún Joṣua, “Nítòótọ́ ni Olúwa tí fi gbogbo ilẹ̀ náà lé wa lọ́wọ́; gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà ni ìbẹ̀rùbojo ti mú nítorí i wa.”