< 5 Mosebok 1 >

1 Dette er de ord Moses talte til hele Israel i ørkenen på hin side Jordan, i ødemarken, midt imot Suf, mellem Paran og Tofel og Laban og Haserot og Di-Sahab,
Wọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ tí Mose sọ fún gbogbo Israẹli ní aginjù, aginjù ìlà-oòrùn Jordani, ni Arabah, ní òdìkejì Ṣufi, ní àárín Parani àti Tofeli, Labani, Haserotu àti Disahabu.
2 elleve dagsreiser fra Horeb efter den vei som fører til Se'ir-fjellene, til Kades-Barnea.
(Ọjọ́ mọ́kànlá ni ó gbà láti rin ìrìnàjò láti Horebu dé Kadeṣi-Barnea, bí a bá gba ọ̀nà òkè Seiri.)
3 Det var i det firtiende år, i den ellevte måned, på den første dag i måneden Moses talte til Israels barn og bar frem alt det Herren hadde befalt ham å tale til dem,
Ní ìgbà tí ó pé ogójì ọdún, ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kọ́kànlá, Mose sọ ohun gbogbo tí Olúwa pàṣẹ nípa àwọn ọmọ Israẹli fún wọn.
4 efterat han hadde slått Sihon, amorittenes konge, som bodde i Hesbon, og ved Edre'i hadde slått Og, kongen i Basan, som bodde i Astarot.
Èyí ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣẹ́gun Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani ni ó ṣẹ́gun ní Edrei, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu.
5 På hin side Jordan, i Moabs land, tok Moses sig fore å utlegge denne lov og sa:
Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani tí ó wà nínú ilẹ̀ Moabu ni Mose bẹ̀rẹ̀ sísọ àsọyé òfin wọ̀nyí wí pé:
6 Herren vår Gud talte til oss ved Horeb og sa: Lenge nok har I opholdt eder ved dette fjell.
Olúwa Ọlọ́run wa bá wa sọ̀rọ̀ ní Horebu pé, “Ẹ ti dúró ní orí òkè yìí pẹ́ tó.
7 Bryt nu op og gi eder på veien til amoritter-fjellene og til alle de folk som bor deromkring, i ødemarken, i fjellbygdene og i lavlandet og i sydlandet og ved havstranden, til kana'anittenes land og til Libanon, helt til den store elv, elven Frat.
Ẹ yípadà kí ẹ sì tẹ̀síwájú ní ìrìnàjò yín lọ sí ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, ẹ tọ gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń gbé Arabah lọ ní aginjù, ní àwọn orí òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀, ní gúúsù àti ní etí Òkun, lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani àti lọ sí Lebanoni, títí fi dé odò ńlá Eufurate.
8 Se, jeg har gitt landet i eders vold; dra avsted og innta det land som Herren har tilsvoret eders fedre Abraham, Isak og Jakob å ville gi dem og deres ætt efter dem!
Wò ó, èmi tí fi ilẹ̀ yí fún un yín, ẹ wọ inú rẹ̀ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí Olúwa ti búra wí pé òun yóò fún àwọn baba yín: fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu, àti fún àwọn àrọ́mọdọ́mọ wọn.”
9 Dengang sa jeg til eder: Jeg makter ikke alene å bære eder.
Mo wí fún un yín nígbà náà pé, “Èmi nìkan kò lè dá ẹrù u yín gbé.
10 Herren eders Gud har gjort eder tallrike, så I idag er som stjernene på himmelen i mengde;
Olúwa Ọlọ́run yín ti sọ yín di púpọ̀ lónìí, ẹ̀yin sì ti pọ̀ bí ìràwọ̀ ní ojú ọ̀run.
11 og måtte bare Herren, eders fedres Gud, gjøre eder tusen ganger flere enn I er, og velsigne eder, som han har tilsagt eder!
Kí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín sọ yín di púpọ̀ ní ọ̀nà ẹgbẹ̀rún sí i, kí ó sì bùkún un yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
12 Men hvorledes kan jeg alene bære strevet og møien med eder og alle eders tretter?
Báwo ni èmi nìkan ṣe lè máa ru àjàgà àti ìṣòro yín àti èdè-àìyedè yín?
13 Kom med nogen vise og forstandige og prøvede menn fra hver av eders stammer! Så vil jeg sette dem til høvdinger over eder.
Ẹ yan àwọn ọlọ́gbọ́n, olóye àti àwọn ẹni àpọ́nlé, láti inú ẹ̀yà yín kọ̀ọ̀kan, èmi yóò sì fi wọ́n ṣe olórí yín.”
14 Da svarte I mig: Det er både rett og godt det du sier.
Ẹ̀yin sì dá mi lóhùn wí pé, “Ohun tí ìwọ ti gbèrò láti ṣe nì dára.”
15 Så tok jeg høvdingene for eders stammer, vise og prøvede menn, og satte dem til høvdinger over eder, nogen over tusen og nogen over hundre og nogen over femti og nogen over ti, og jeg gjorde dem til tilsynsmenn over eders stammer.
Bẹ́ẹ̀ ni mo yan olórí àwọn ẹ̀yà yín, àwọn ọlọ́gbọ́n ọkùnrin, ẹni àpọ́nlé, mo sì fi jẹ olórí yín, olórí ẹgbẹẹ̀rún, olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, olórí àràádọ́ta, àti olórí mẹ́wàá mẹ́wàá gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹ̀yà yín.
16 Dengang bød jeg også eders dommere og sa: Hør på de saker som eders brødre har sig imellem, og døm med rettferdighet mellem en mann og hans bror eller en fremmed som bor hos ham!
Mo sì kìlọ̀ fún àwọn onídàájọ́ yín nígbà náà pé, ẹ gbọ́ èdè-àìyedè tí ó wà láàrín àwọn ènìyàn an yín kí ẹ sì ṣe ìdájọ́ òdodo, bóyá ẹjọ́ tí ó ṣẹlẹ̀ láàrín Israẹli sí Israẹli ni tàbí láàrín Israẹli kan sí àlejò.
17 I skal ikke gjøre forskjell på folk når I dømmer; den minste som den største skal I høre på. I skal ikke være redde for nogen, for dommen hører Gud til. Men om nogen sak er for vanskelig for eder, skal I føre den frem for mig; så vil jeg høre på den.
Ẹ má sì ṣe ojúsàájú ní ìdájọ́. Ẹ ṣe ìdájọ́ ẹni ńlá àti kékeré bákan náà. Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹnikẹ́ni torí pé ti Ọlọ́run ni ìdájọ́. Ẹjọ́ tí ó bá le jù fún un yín ni kí ẹ mú wá fún mi. Èmi yóò sì gbọ́ ọ.
18 Og på samme tid bød jeg eder alt det I skulde gjøre.
Nígbà náà ni èmi yóò sọ ohun tí ẹ ó ṣe fún un yín.
19 Så brøt vi op fra Horeb og drog gjennem hele den store og forferdelige ørken som I har sett, på veien til amoritter-fjellene, således som Herren vår Gud bød oss; og vi kom til Kades-Barnea.
Nígbà náà ní a gbéra láti Horebu, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wá, a sì la àwọn ilẹ̀ lókè Amori kọjá lọ dé gbogbo aginjù ńlá tí ó ba ni lẹ́rù nì tí ẹ̀yin ti rí, bẹ́ẹ̀ ni a sì dé Kadeṣi-Barnea.
20 Da sa jeg til eder: Nu er I kommet til amoritter-fjellene, som Herren vår Gud vil gi oss.
Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ ti dé ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, èyí tí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.
21 Se, Herren din Gud har gitt landet i din vold; dra op og innta det, som Herren, dine fedres Gud, har tilsagt dig! Frykt ikke og vær ikke redd!
Ẹ kíyèsi i, Olúwa Ọlọ́run yín ló ni ilẹ̀ náà. Ẹ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín tí sọ fún un yín. Ẹ má bẹ̀rù, ẹ má sì ṣe fòyà.”
22 Da kom I til mig alle sammen og sa: La oss sende folk i forveien for oss, så de kan utspeide landet for oss og gi oss beskjed om hvad vei vi skal dra dit op, og hvad byer vi kommer til!
Nígbà náà ni gbogbo yín tọ̀ mí wá wí pé, “Jẹ́ kí a yan àwọn ayọ́lẹ̀wò láti yọ́ ilẹ̀ náà wò fún wa, kí wọn sì fún wa ní ìròyìn àwọn ọ̀nà tí a ó gbà àti àwọn ìlú tí a ó bá pàdé.”
23 Dette syntes jeg godt om, og jeg tok ut blandt eder tolv menn, én mann for hver stamme.
Èrò náà sì dára lójú mi, torí èyí ni mo ṣe yan àwọn ènìyàn méjìlá nínú yín, ẹnìkan láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.
24 Og de tok avsted og drog op i fjellene og kom til Eskol-dalen; og de utspeidet landet.
Wọ́n sì gòkè lọ sí ilẹ̀ òkè náà, wọ́n sì wá sí àfonífojì Eṣkolu, wọ́n sì yẹ̀ ẹ́ wò.
25 Og de tok med sig av landets frukter ned til oss, og de gav oss beskjed tilbake og sa: Det land som Herren vår Gud vil gi oss, er et godt land.
Wọ́n sì mú lára èso ilẹ̀ náà wá fún wa pé, “Ilẹ̀ tí ó dára ni Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”
26 Men I vilde ikke dra dit op; I var gjenstridige mot Herrens, eders Guds ord.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́ gòkè lọ; ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run yín.
27 Og I knurret i eders telter og sa: Herren hater oss; derfor har han ført oss ut av Egyptens land og vil gi oss i amorittenes hånd og ødelegge oss.
Ẹ kùn nínú àgọ́ ọ yín, ẹ sì wí pé, “Olúwa kórìíra wa, torí èyí ló fi mú wa jáde láti Ejibiti láti fi wá lé àwọn ará Amori lọ́wọ́ láti pa wá run.
28 Hvad er det for et land vi skal dra op til! Våre brødre har gjort vårt hjerte mistrøstig ved å si: Det er et folk som er større og høiere enn vi, og de har store byer med murer som når til himmelen; og der så vi også anakittenes barn.
Níbo la ó lọ? Àwọn arákùnrin wa ti kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá wa nípa sísọ pé, ‘Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga jù wá lọ; àwọn ìlú náà tóbi jọjọ bẹ́ẹ̀ ni odi wọn ga kan ọ̀run. A tilẹ̀ rí àwọn òmíràn (ìran Anaki) níbẹ̀.’”
29 Da sa jeg til eder: I skal ikke forferdes og ikke være redde for dem;
Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ má ṣojo, ẹ kò sì gbọdọ̀ bẹ̀rù wọn.
30 Herren eders Gud, som går foran eder, han skal stride for eder, således som I så han gjorde for eder i Egypten
Olúwa Ọlọ́run yín, tí ń ṣáájú yín yóò jà fún un yín; bí ó ti ṣe fún un yín ní Ejibiti lójú ẹ̀yin tìkára yín
31 og i ørkenen du har sett, der hvor Herren din Gud bar dig som en mann bærer sitt barn, på hele den vei I har vandret til I kom til dette sted.
àti ní aginjù. Níbẹ̀ ni ẹ ti rí i bí Olúwa Ọlọ́run yín ti gbé yín, bí baba ti í gbé ọmọ rẹ̀, ní gbogbo ọ̀nà tí ẹ lọ títí ẹ fi padà dé ibí yìí.”
32 Men allikevel trodde I ikke på Herren eders Gud,
Pẹ̀lú gbogbo èyí tí mo wí, ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín,
33 han som gikk foran eder på veien for å søke ut leirplass for eder, om natten i en ild, så I kunde se den vei I skulde gå, og om dagen i en sky.
tí ń ṣáájú u yín lọ ní gbogbo ọ̀nà yín, nípa fífi iná ṣe amọ̀nà yín ní òru àti ìkùùkuu ní ọ̀sán, láti fi àwọn ibi tí ẹ lè tẹ̀dó sí hàn yín àti àwọn ọ̀nà tí ẹ ó rìn.
34 Da Herren hørte eders tale, blev han vred og svor:
Nígbà tí Olúwa gbọ́ ohun tí ẹ sọ, inú bí i, ó sì búra wí pé,
35 Sannelig, ikke nogen av disse menn, av denne onde slekt, skal se det gode land jeg har svoret å ville gi eders fedre -
“Kò sí ọ̀kan nínú ìran búburú yìí tí yóò dé ilẹ̀ rere tí mo ti búra láti fún àwọn baba ńlá a yín.
36 ingen uten Kaleb, Jefunnes sønn; han skal få se det; ham og hans barn vil jeg gi det land han har trådt på med sin fot, for han har trolig fulgt Herren.
Bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne. Òun ni yóò wọ̀ ọ́. Èmi yóò sì fún òun àti àwọn ìran rẹ̀ ní ilẹ̀ náà tí ó ti fi ẹsẹ̀ rẹ̀ tẹ̀; torí pé ó fi gbogbo ọkàn rẹ̀ tẹ̀lé Olúwa.”
37 Også mig blev Herren vred på for eders skyld og sa: Heller ikke du skal komme der inn.
Torí i tiyín ni Olúwa fi bínú sí mi wí pé, “Ìwọ náà kì yóò wọ ibẹ̀ bákan náà,
38 Josva, Nuns sønn, som går dig til hånde, han skal komme der inn; styrk ham, for han skal skifte det ut til arv blandt Israel.
ṣùgbọ́n Joṣua ọmọ Nuni tí ń ṣe olùrànlọ́wọ́ rẹ ni yóò wọ ibẹ̀. Mú un, ní ọkàn le torí pé, òun yóò ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli láti gba ilẹ̀ náà.
39 Og eders barn, som I sa vilde bli til rov, og eders sønner, som ennu ikke kan skille godt fra ondt, de skal komme der inn, dem vil jeg gi det, og de skal ta det i eie.
Àwọn èwe yín tí ẹ sọ pé wọn yóò kó lẹ́rú. Àwọn ọmọ yín tí ko tí ì mọ rere yàtọ̀ sí búburú ni yóò wọ ilẹ̀ náà.
40 Men vend I om og ta ut i ørkenen, på veien til det Røde Hav!
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, ẹ yí padà sí aginjù tí ó wà ní ọ̀nà tí ó lọ sí Òkun Pupa.”
41 Da svarte I og sa til mig: Vi har syndet mot Herren; nu vil vi dra op og stride, således som Herren vår Gud har befalt oss. Og I omgjordet eder med eders stridsvåben hver og en, og I holdt det for en lett sak å dra op i fjellene.
Nígbà náà ni ẹ fèsì wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí Olúwa. A ó sì gòkè lọ láti jà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wa.” Torí náà gbogbo yín ẹ mú ohun ìjà a yín, ẹ rò pé ó rọrùn láti gòkè lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè náà.
42 Da sa Herren til mig: Si til dem: I skal ikke dra op, og I skal ikke stride; for jeg er ikke med eder; I kommer bare til å bli slått av eders fiender.
Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ fún wọn, ‘Ẹ má ṣe gòkè lọ láti jà torí pé èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín. Àwọn ọ̀tá a yín yóò sì ṣẹ́gun yín.’”
43 Og jeg talte til eder, men I hørte ikke på mig; I var gjenstridige mot Herrens ord og dristet eder til å dra op i fjellene.
Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún yín, ẹ̀yin kò sì gbọ́, ẹ̀yin ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa, pẹ̀lú ìgbéraga yín, ẹ gòkè lọ sí ìlú olókè náà.
44 Da drog amorittene, som bodde der i fjellene, ut mot eder, og de forfulgte eder likesom en bisverm, og de slo eder sønder og sammen i Se'ir og drev eder like til Horma.
Àwọn ará Amori tí ń gbé ní àwọn òkè náà, dojúkọ yín bí àgbájọpọ̀ oyin. Wọ́n sì lù yín bolẹ̀ láti Seiri títí dé Horma.
45 Og I vendte tilbake og gråt for Herrens åsyn; men Herren hørte ikke på eders klager og vendte ikke sitt øre til eder.
Ẹ padà, ẹ sì sọkún níwájú Olúwa, òun kò sì fetí sí igbe ẹkún yín, Ó sì kọ etí dídi sí i yín.
46 Og I måtte bli i Kades i lang tid, hele den tid I var der.
Báyìí ni ẹ sì dúró ní Kadeṣi fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti ṣe.

< 5 Mosebok 1 >