< Mika 1 >

1 KA olelo a Iehova ka mea i hiki mai ia Mika no Moreseta, i na la o Iotama, Ahaza, a o Hezekia, na'lii o ka Iuda, ka mea ana i ike ai no Samaria, a no Ierusalema.
Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Mika ará Moreṣeti wá ní àkókò ìjọba Jotamu, Ahasi, àti Hesekiah, àwọn ọba Juda nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaria àti Jerusalẹmu.
2 E hoolohe, e na kanaka a pau; E haliu mai, e ka honua, a me kona mea i piha ai: A e lilo o Iehova ka Haku i mea hoike ku e ia oukou, O ka Haku mai kona luakini hoano mai.
Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn, fetísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀, kí Olúwa Olódùmarè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín, Olúwa láti inú tẹmpili mímọ́ rẹ̀ wá.
3 No ka mea, aia hoi, e hele mai o Iehova mai kona wahi mai, A e iho ilalo a e hehi maluna o na wahi kiekie o ka honua.
Wò ó! Olúwa ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀; yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.
4 A hehee na mauna malalo iho ona, A e wahiia na awawa, E like me ke kepau imua o ke ahi, A me ka wai i nininiia ma kahi pali.
Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀, àwọn àfonífojì yóò sì pínyà, bí idà níwájú iná, bí omi tí ó ń sàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.
5 No ka lawehala ana o ka Iakoba keia mea a pau, a no na hewa o ko ka hale o Iseraela. He aha ka hala o ka Iakoba? aole anei o Samaria? A owai na wahi kiekie o Iuda? aole anei o Ierusalema?
Nítorí ìré-òfin-kọjá Jakọbu ni gbogbo èyí, àti nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli. Kí ni ìré-òfin-kọjá Jakọbu? Ǹjẹ́ Samaria ha kọ? Kí ni àwọn ibi gíga Juda? Ǹjẹ́ Jerusalẹmu ha kọ?
6 A e hoohalike au ia Samaria me he puu la o ke kula, A me he wahi kanu la no ka pawaina; A e hoolei iho au i na pohaku ona ma ke awawa, A e hoike aku au i kona mau kahua.
“Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaria bí òkìtì lórí pápá, bí ibi ti à ń lò fún gbígbin ọgbà àjàrà. Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì. Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.
7 A e ulupaia kona mau kii kalai a pau, A o kona waiwai moe kolohe e puhiia i ke ahi, A e luku aku au i kona mau kii a pau: No ka mea, ua loaa ia ia ua mea la no ka uku o ka wahine moe kolohe, A e hoihoiia aku ia i ka uku o ka wahine moe kolohe.
Gbogbo àwọn ère fínfín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́ gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹmpili rẹ̀ ni a ó fi iná sun, Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run. Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà, gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”
8 No keia mea, e auwe iho au, a e aoa, A e hele wale au, me ke kapa aahu ole; E hoohalike au i ka auwe ana me ko ka ilio hihiu, A i ka alala ana me ko ka iana wahine.
Nítorí èyí, èmi yóò sì sọkún, èmi yóò sì pohùnréré ẹkún: èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ìhòhò. Èmi yóò ké bí akátá, èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.
9 No ka mea, o kona eha he eha make ia, a ua hiki mai ia i ka Iuda; Ua hiki mai i ka pukapa o kou poe kanaka, a i Ierusalema.
Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlèwòtán; ó sì ti wá sí Juda. Ó sì ti dé ẹnu-bodè àwọn ènìyàn mi, àní sí Jerusalẹmu.
10 Mai hai aku oukou ia ma Gata, mai auwe oukou i ka auwe ana; Ma ka hale o Apera e kau i ka lepo maluna iho ou.
Ẹ má ṣe sọ ní Gati ẹ má ṣe sọkún rárá. Ní ilẹ̀ Beti-Ofra mo yí ara mi nínú eruku.
11 E hele aku oe, e ka mea e noho ana ma Sapira, me kou hilahila uhi ole; Aole i hele mai iwaho ka mea o noho ana ma Zaanana, ma ka auwe ana o Betezela; E lawe no ia i kona noho ana mai o oukou aku.
Ẹ kọjá lọ ni ìhòhò àti ni ìtìjú, ìwọ tí ó ń gbé ni Ṣafiri. Àwọn tí ó ń gbé ni Saanani kì yóò sì jáde wá. Beti-Eseli wà nínú ọ̀fọ̀; a ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.
12 No ka mea, o ka mea e noho ana ma Marota, ua nawaliwali ia no ka iini i ka maikai; Aka, iho mai la ka ino mai Iehova mai ma ka pukapa o Ierusalema.
Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Marati ń retí ìre, ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
13 E ka mea o noho la ma Lakisa, e hoopaa i ka halekaa i ka lio mama; Oia ke poo o ka hewa no ke kaikamahine o Ziona; No ka mea, ua loaa na lawehala o ka Iseraela iloko ou.
Ìwọ olùgbé Lakiṣi, dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára. Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀ sí àwọn ọmọbìnrin Sioni, nítorí a rí àìṣedéédéé Israẹli nínú rẹ̀.
14 No ia mea, e haawi aku oe i na makana no Moresetagata: E lilo na hale o Akeziba i mea hoopunipuni no na'lii o ka Iseraela.
Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún Moreṣeti Gati. Àwọn ilé Aksibu yóò jẹ́ ẹlẹ́tàn sí àwọn ọba Israẹli.
15 Aka hoi, e lawe mai no au i hooilina nou, e ka mea e noho ana ma Maresa: A e hele mai ka nani o ka Iseraela i Adulama.
Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Meraṣa. Ẹni tí ó jẹ́ ògo Israẹli yóò sì wá sí Adullamu.
16 E hooohule oe, a e ako i ke oho no na keiki o kou makemake; E hoomahuahua oe i kou ohule ana, e like me ka aeto; No ka mea, ua hele pio aku la lakou mai ou aku la.
Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀ nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára, sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún, nítorí wọn yóò kúrò lọ́dọ̀ rẹ lọ sí ìgbèkùn.

< Mika 1 >