< Nahuma 1 >

1 K A OLELO no Nineva. O ka Buke o ka wanana a Nahuma, no Elekosa.
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ nípa Ninefe. Ìwé ìran Nahumu ará Elkoṣi.
2 Ua lili ke Akua, a o Iehova ka mea hoopai, O Iehova ka mea hoopai, a he huhu kona; O Iehova ka mea hoopai i kona poe ku e, A oia ke malama i ka huhu no kona poe enemi.
Ọlọ́run ń jẹ owú, ó sì ń gbẹ̀san, Olúwa ń gbẹ̀san, ó sì kún fún ìbínú. Olúwa ń gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀. Ìbínú rẹ̀ kò sì yí padà lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀.
3 Ua hookaulua o Iehova i ka huhu, a he nui ka mana, Aole loa ia e kala wale aku: Aia no ke ala o Iehova, iloko o ka puahiohio, a me ka ino, A o na ao ka lepo o kona mau wawae.
Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì tóbi ní agbára; Olúwa kì yóò fi àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ sílẹ̀ láìjìyà. Ọ̀nà rẹ̀ wà nínú afẹ́fẹ́ àti nínú ìjì, ìkùùkuu sánmọ̀ sì ni eruku ẹsẹ̀ rẹ̀.
4 Papa aku no ia i ke kai, a hoomaloo iho la ia mea, A hoomaloo iho i na muliwai a pau: Ua mae o Basana, a me Karemela; A ua mae ka pua o Lebanona.
Ó bá òkun wí, ó sì mú kí ó gbẹ; Ó sìsọ gbogbo odò di gbígbẹ. Baṣani àti Karmeli sì rọ. Ìtànná Lebanoni sì rẹ̀ sílẹ̀.
5 Ua hoonaueia na mauna e ia, A ua hee iho la na puu; Neenee ka aina ia ia iho mai kona alo ae, A o ka honua, a me na mea a pau e noho ana iloko.
Àwọn òkè ńlá wárìrì níwájú rẹ̀, àwọn òkè kéékèèké sì di yíyọ́, ilẹ̀ ayé sì jóná níwájú rẹ̀, àní ayé àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.
6 Owai la ka mea e ku imua o kona inaina? Owai la ka mea e ku mai i ka wela o kona huhu? Ua nininiia kona huhu me he ahi la, Ua hiolo iho na pohaku ma ona la.
Ta ni ó lé dúró níwájú ìbínú rẹ̀? Ta ni ó lé faradà gbígbóná ìbínú rẹ̀? Ìbínú rẹ̀ tú jáde bí iná; àwọn àpáta sì fọ́ túútúú níwájú rẹ̀.
7 Ua maikai o Iehova, he paku oia i ka la popilikia; A ua ike no ia i ka poe hilinai ia ia.
Rere ni Olúwa, òun ni ààbò ní ọjọ́ ìpọ́njú. Òun sì tọ́jú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e,
8 Me ka wai nui e holo ana, a hooki loa aku ia i kona wahi, A e hahai ka pouli i kona poe enemi.
ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìkún omi ńlá ní òun yóò fi ṣe ìparun láti ibẹ̀ dé òpin; òkùnkùn yóò sì máa lépa àwọn ọ̀tá rẹ̀.
9 Heaha ko oukou manao ku e ia Iehova? E hooki loa aku ia, aole e hiki palua mai ka popilikia.
Kí ni ẹ̀yìn ń gbìmọ̀ lòdì sí Olúwa? Òun yóò fi òpin sí i, ìpọ́njú kì yóò wáyé ní ìgbà kejì.
10 No ka mea, e like me na laau kuku, ua huipuia lakou, A ua ona lakou e like me ka poe ona, E hoopauia lakou e like me ka opala maloo loa.
Wọn yóò sì lọ́lù papọ̀ bí ẹ̀gún òṣùṣú wọn yóò sì mu àmupara nínú ọtí wáìnì wọn a ó sì run wọn gẹ́gẹ́ bi àgékù koríko gbígbẹ.
11 Ua puka mai ka mea mai ou mai la e manao hewa ana ia Iehova; He kakaolelo hewa,
Láti ọ̀dọ̀ rẹ, ìwọ Ninefe, ni ẹnìkan ti jáde wá tí ó ń gbèrò ibi sí Olúwa ti ó sì ń gbìmọ̀ búburú.
12 Peneia i olelo mai o Iehova, Ina ua maluhia lakou, a nui hoi, A e hookiia lakou pela, a e hele ae la ia: A ua hoohaahaa aku au ia oe, aole nae au e hoohaahaa hou aku ia oe.
Báyìí ni Olúwa wí: “Bí wọ́n tilẹ̀ ni ìfọwọ́sowọ́pọ̀, tí wọ́n sì pọ̀ níye, ṣùgbọ́n, báyìí ní a ó ké wọn lulẹ̀, nígbà tí òun ó bá kọjá. Bí mo tilẹ̀ ti pọ́n ọ lójú ìwọ Juda, èmi kì yóò pọ́n ọ lójúmọ́.
13 Ano hoi, e hemo ia'u kana auamo mai ou aku la: A e moku ia'u kou mau kaula.
Nísinsin yìí ni èmi yóò já àjàgà wọn kúrò ní ọrùn rẹ èmi yóò já ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ rẹ dànù.”
14 A ua kauoha mai o Iehova nou, Aole e lulu hou ia kou inoa: Mailoko mai o ka hale o kou mau akua, e oki aku au i ke kii kalai, a me ke kii hoohehee: E hana iho au i kou halekupapau, no ka mea, ua hoowahawahaia oe.
Olúwa ti fi àṣẹ kan lélẹ̀ nítorí tìrẹ Ninefe: “Ìwọ kì yóò ni irú-ọmọ láti máa jẹ́ orúkọ rẹ mọ́, Èmi yóò pa ère fínfín àti ère dídà run tí ó wà nínú tẹmpili àwọn ọlọ́run rẹ. Èmi yóò wa ibojì rẹ, nítorí ẹ̀gbin ni ìwọ.”
15 Aia hoi, maluna o na mauua na wawae o ka mea e hai ana i ka mea maikai, E hoike ana hoi i ka malu! E Iuda, e malama i kau mau ahaaina; E hooko i kau mau hoohiki ana: No ka mea, aole e hele hou ka mea aia ma ou la, Ua oki loa ia'ku oia.
Wò ó, lórí àwọn òkè, àwọn ẹsẹ̀ ẹni tí ó mú ìròyìn ayọ̀ wá, ẹni tí ó ń kéde àlàáfíà. Ìwọ Juda, pa àṣẹ rẹ tí ó ní ìrònú mọ́, kí ó sì san àwọn ẹ̀jẹ́ rẹ. Àwọn ènìyàn búburú kì yóò sì gbóguntì ọ́ mọ́; wọn yóò sì parun pátápátá.

< Nahuma 1 >