< Mariko 7 >
1 Na rĩrĩ, Afarisai na arutani amwe a watho arĩa moimĩte Jerusalemu makĩũngana harĩ Jesũ na
Àwọn Farisi sì péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, àti àwọn kan nínú àwọn akọ̀wé, tí ó wá láti Jerusalẹmu,
2 makĩona arutwo ake amwe makĩrĩa irio na moko maarĩ na thaahu, ũguo nĩ ta kuuga, matethambĩte moko.
wọ́n sì ṣe àkíyèsí wí pé díẹ̀ nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Jesu ń fi ọwọ́ àìmọ́ jẹun, èyí yìí ni wẹ ọwọ́.
3 (Afarisai na Ayahudi othe matirĩĩaga irio matethambĩte moko mao wega kũringana na kĩrĩra gĩa athuuri.
(Àwọn Farisi, àti gbogbo àwọn Júù, bí wọ́n kò bá wẹ ọwọ́ wọn gidigidi, wọn kì í jẹun nítorí wọ́n ti pa òfin àtọwọ́dọ́wọ́ àwọn àgbà mọ́.
4 Rĩrĩa moima ndũnyũ matingĩrĩa matambĩte gwĩthamba. Na nĩ marũmagia irĩra ingĩ, ta gũthambia ikombe, na nyũngũ o na mbirika).
Nígbà tí wọ́n bá sì ti ọjà dé sílé, wọn kò gbọdọ̀ fi ọwọ́ kan oúnjẹ àfi tí wọ́n bá bu omi wẹ ara wọn. Èyí sì jẹ́ ọ̀kan nínú ogunlọ́gọ̀ àpẹẹrẹ òfin àti ìlànà tí wọ́n ti dì mú fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún sẹ́yìn, bí i fífọ kọ́ọ̀bù, àwọn ìkòkò, àti kẹ́tù.)
5 Nĩ ũndũ ũcio Afarisai na Arutani a watho makĩũria Jesũ atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ gĩtũmaga arutwo aku mage gũtũũra kũringana na irĩra cia athuuri, na makarĩĩaga irio na moko marĩ na thaahu?”
Nítorí èyí àwọn Farisi àti àwọn olùkọ́ òfin béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Èéṣe tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ kò tẹ̀lé àwọn òfin àtọwọ́dọ́wọ́ àwọn àgbà nítorí wọ́n fi ọwọ́ àìmọ́ jẹun?”
6 Nake Jesũ akĩmacookeria atĩrĩ, “Isaia aaririe ma rĩrĩa aarathire ũhoro wanyu, inyuĩ hinga ici; o ta ũrĩa kwandĩkĩtwo atĩrĩ: “‘Andũ aya maaheaga gĩtĩĩo na mĩromo, no ngoro ciao ikoragwo irĩ kũraya na niĩ.
Jesu dá wọn lóhùn wí pé, “Ẹyin àgàbàgebè yìí, òtítọ́ ni wòlíì Isaiah ń sọtẹ́lẹ̀ nípa tí ẹ̀yin àgàbàgebè, bí a ti kọ ọ́ pé: “‘Àwọn ènìyàn wọ̀nyí fi ẹnu wọn bu ọlá fún mi ṣùgbọ́n ọkàn wọn jìnà sí mi.
7 Nao maahooyaga o tũhũ; morutani marĩa marutanaga no mawatho ma andũ.’
Ìsìn wọn jẹ́ lásán, ìkọ́ni wọ́n jẹ́ kìkìdá òfin tí àwọn ènìyàn fi ń kọ́ni.’
8 Mũtiganĩirie maathani ma Ngai, mũkarũmia irĩra cia andũ.”
Nítorí tí ẹ̀yin fi òfin Ọlọ́run sí apá kan, ẹ̀yin ń tẹ̀lé àṣà àwọn ènìyàn.”
9 Agĩcooka akĩmeera atĩrĩ, “Ti-itherũ nĩmũgĩĩte na njĩra njega ya gũtiganĩria maathani ma Ngai atĩ nĩguo mũrũmie irĩra cianyu ene!
Ó si wí fún wọn: “Ẹ̀yin sá à mọ̀ bí ẹ ti ń gbé òfin Ọlọ́run jù sẹ́yìn kí ẹ lè mú òfin tiyín ṣẹ.
10 Nĩgũkorwo Musa oigire atĩrĩ, ‘Tĩĩa thoguo na nyũkwa,’ na, ‘Ũrĩa wothe ũkaaruma ithe kana nyina no nginya ooragwo.’
Mose fún un yín ní òfin yìí láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run pé, ‘Bọ̀wọ̀ fún baba òun ìyá rẹ.’ Ó tún sọ pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ̀rọ̀ aburú sí baba tàbí ìyá rẹ̀ ní láti kú ni.’
11 No inyuĩ muugaga atĩ mũndũ angĩĩra ithe kana nyina atĩrĩ, ‘Kĩrĩa ingĩagũteithia nakĩo nĩ Korubani’ (ũguo nĩ kuuga, nĩ kĩheo kĩamũrĩre Ngai),
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wá sọ pé ó dára bákan náà fún ọkùnrin kan bí kò bá tilẹ̀ pèsè fún àìní àwọn òbí rẹ̀, ṣùgbọ́n kí o sọ fún wọn pé, ‘Ẹ má ṣe bínú baba tàbí ìyá mi, n kò lè ràn yín lọ́wọ́ nísinsin yìí,’ nítorí tí mo ti fi ẹ̀bùn tí ǹ bá fi fún un yín fún Ọlọ́run.
12 na mũticookaga kũmwĩtĩkĩria ekĩre ithe kana nyina ũndũ.
Bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin kò si jẹ́ kí ó ṣe ohunkóhun fún baba tàbí ìyá rẹ̀ mọ́.
13 Nĩ ũndũ ũcio mũkaagithia kiugo kĩa Ngai kĩene na ũndũ wa kĩrĩra kĩanyu kĩrĩa mũthiiaga mũgĩtiganagĩra. Na nĩmwĩkaga maũndũ maingĩ ta macio.”
Ẹ̀yin ń fi òfin àtọwọ́dọ́wọ́ tiyín tí ẹ fi lélẹ̀, sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run di asán àti ọ̀pọ̀ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin ń ṣe.”
14 O rĩngĩ Jesũ agĩĩta kĩrĩndĩ harĩ we agĩkĩĩra atĩrĩ, “Inyuĩ andũ aya othe, thikĩrĩriai na mũigue.
Lẹ́yìn náà, Jesu pe ọ̀pọ̀ ènìyàn láti wá gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀. Ó sì wí fún wọn pé, “Gbogbo yín ẹ tẹ́tí sílẹ̀ kí ẹ sì jẹ́ kí èyí ó yé e yín.
15 Gũtirĩ kĩndũ kĩrĩ nja ya mũndũ kĩngĩmũgwatia ‘thaahu’ nĩ ũndũ wa gũtoonya thĩinĩ wake. No rĩrĩ, kĩrĩa kiumaga thĩinĩ wa mũndũ nĩkĩo kĩmũgwatagia ‘thaahu’.”
Kò sí ohunkóhun láti òde ènìyàn, tí ó wọ inú rẹ̀ lọ, tí ó lè sọ ọ́ di aláìmọ́, ṣùgbọ́n àwọn nǹkan tí ó ti inú rẹ jáde, àwọn wọ̀nyí ní ń sọ ènìyàn di aláìmọ́.”
16 (Aakorwo mũndũ arĩ na matũ ma kũigua, nĩakĩigue).
17 Thuutha wa gũtigana na kĩrĩndĩ na gũtoonya nyũmba, arutwo ake makĩmũũria ũhoro wa ngerekano ĩyo.
Nígbà tí Jesu sì wọ inú ilé kan lọ, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn tẹ̀lé é, wọ́n sì béèrè ìtumọ̀ àwọn òwe tí ó pa.
18 Nake Jesũ akĩmooria atĩrĩ, “O na inyuĩ mũtirĩ mũrataũkĩrwo o na rĩu? Kaĩ mũtooĩ atĩ gũtirĩ kĩndũ gĩtoonyaga thĩinĩ wa mũndũ kuuma na nja kĩngĩmũgwatia thaahu?
Jesu béèrè wí pé, “Àbí kò sí èyí tí ó yé yín nínú ọ̀rọ̀ náà? Ẹ̀yin kò rí i wí pé ohunkóhun tí ó wọ inú ènìyàn láti òde kò lè sọ ènìyàn di aláìmọ́?
19 Nĩgũkorwo gĩtitoonyaga ngoro-inĩ yake, no gĩtoonyaga nda yake gĩgacooka gĩkoima mwĩrĩ-inĩ wake.” (Akiuga ũguo-rĩ, Jesũ nĩgũtua aatuaga atĩ irio ciothe itirĩ thaahu).
Nítorí tí kò lọ sínú ọkàn rẹ̀, ṣùgbọ́n sínú ara, a sì yà á jáde, a sì gbá gbogbo oúnjẹ dànù.” (Nípa sísọ èyí, Jesu fihàn pé gbogbo oúnjẹ jẹ́ “mímọ́.”)
20 Agĩthiĩ na mbere na kwaria, akiuga atĩrĩ, “Kĩrĩa kiumaga thĩinĩ wa mũndũ nĩkĩo kĩmũgwatagia thaahu.
Nígbà náà, ó fi kún un pé, “Èyí ti ó ti ọkàn ènìyàn jáde ni ń sọ ni di aláìmọ́.
21 Nĩgũkorwo ngoro-inĩ cia andũ nĩkuo kuumaga meciiria mooru, ũhũũri maraya, na ũici, na ũragani, na ũtharia,
Nítorí pé láti inú ọkàn ènìyàn ni àwọn èrò búburú wọ̀nyí ti ń jáde wá: àgbèrè, olè, ìpànìyàn, panṣágà,
22 na ũkoroku, na rũmena, na maheeni, na ũũra-thoni, na ũiru, na njambanio, na mwĩtĩĩo, o na ũrimũ.
ọ̀kánjúwà, odì yíyàn, ìtànjẹ, ìmọ-tara-ẹni, ìlara, ọ̀rọ̀ ẹ̀yìn, ìgbéraga, òmùgọ̀.
23 Maũru maya mothe moimaga thĩinĩ wa mũndũ na makamũgwatia thaahu.”
Gbogbo àwọn nǹkan búburú wọ̀nyí ń tí inú wá, àwọn ló sì ń sọ yín di aláìmọ́.”
24 Nake Jesũ akiuma kũu agĩthiĩ gũkuhĩ na Turo. Agĩtoonya nyũmba ĩmwe na ndeendaga mũndũ o na ũrĩkũ amenye atĩ arĩ kũu; no ndangĩahotire kwĩhitha.
Nígbà náà ni Jesu kúrò ní Galili, ó sí lọ sí agbègbè Tire àti Sidoni, ó sì gbìyànjú láti nìkan wà pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ fún àkókò díẹ̀, ṣùgbọ́n eléyìí kò ṣe é ṣe, nítorí pé kò pẹ́ púpọ̀ tí ó wọ ìlú nígbà tí ìròyìn dídé rẹ̀ tàn káàkiri.
25 Na rĩrĩ, mũtumia warĩ na kairĩtu kaarĩ na ngoma thũku rĩrĩa aiguire ũhoro wake, agĩũka akĩĩgũithia thĩ magũrũ-inĩ make.
Láìpẹ́, obìnrin kan tí ọmọbìnrin rẹ̀ ní ẹ̀mí àìmọ́ tọ̀ ọ́ wá, ó ti gbọ́ nípa Jesu, ó wá, ó sì wólẹ̀ lẹ́sẹ̀ Jesu.
26 Mũtumia ũcio aarĩ Mũyunani, waciarĩirwo Foinike ya Suriata. Nake agĩthaitha Jesũ aingate ngoma ĩyo thũku yume thĩinĩ wa kairĩtu gake.
Giriki ní obìnrin náà, Siro-Fonisia ní orílẹ̀-èdè rẹ̀. Ó bẹ Jesu kí ó bá òun lé ẹ̀mí èṣù náà jáde lára ọmọbìnrin òun.
27 Nake Jesũ akĩmwĩra atĩrĩ, “Reke ciana ciambe irĩe ihũũne, nĩgũkorwo ti wega kuoya mĩgate ya ciana na kũmĩikĩria ngui.”
Jesu sọ fún obìnrin yìí pé, “Ní àkọ́kọ́, ó yẹ kí a fi oúnjẹ tẹ́ àwọn ọmọ lọ́rùn ná. Nítorí kò tọ́ kí a mú oúnjẹ àwọn ọmọ fún àwọn ajá.”
28 Nake mũtumia ũcio akĩmũcookeria atĩrĩ, “Noguo Mwathani, no o na ngui irĩ rungu rwa metha nĩ irĩĩaga rũitĩki rũrĩa rũitagwo nĩ ciana.”
Obìnrin náà dáhùn wí pé, “Òótọ́ ni ọ̀rọ̀ yín Olúwa, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ajá pàápàá a máa ní àǹfààní láti jẹ èérún oúnjẹ tí ó bá bọ́ sílẹ̀ láti orí tábìlì.”
29 Jesũ agĩcooka akĩmwĩra atĩrĩ, “Nĩ ũndũ wa ũguo wacookia-rĩ, wĩthiĩre; ndaimono nĩyoima thĩinĩ wa mwarĩguo.”
“Ó sì wí fún un pé, nítorí ọ̀rọ̀ yìí, máa lọ, ẹ̀mí àìmọ́ náà ti jáde kúrò lára ọmọbìnrin rẹ.”
30 Mũtumia ũcio akĩinũka mũciĩ agĩkora kaana gake gakomete ũrĩrĩ-inĩ na ndaimono ĩrĩkĩtie gũthiĩ.
Nígbà tí ó padà dé ilé, ó bá ọmọbìnrin rẹ̀ ní ìdùbúlẹ̀ jẹ́jẹ́ lórí ibùsùn, ẹ̀mí àìmọ́ náà ti fi í sílẹ̀.
31 Ningĩ Jesũ akiuma kũu gũkuhĩ na Turo agĩtuĩkanĩria Sidoni, agĩikũrũka nginya iria-inĩ rĩa Galili, agĩtoonya bũrũri wa Dekapoli.
Nígbà náà ni Jesu fi agbègbè Tire àti Sidoni sílẹ̀, ó wá si Òkun Galili láàrín agbègbè Dekapoli.
32 Arĩ kũu andũ amwe makĩmũrehere mũndũ ũtaiguaga na ũtaaragia, makĩmũthaitha amũigĩrĩre guoko.
Níbẹ̀ ọkùnrin kan tí kò lè sọ̀rọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ Jesu, àwọn ènìyàn sì bẹ Jesu pé kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé e.
33 Na thuutha wa kũmũtwara handũ keheri-inĩ, haraaya na kĩrĩndĩ, Jesũ agĩtoonyia ciara ciake matũ ma mũndũ ũcio. Agĩcooka agĩtua mata na akĩhutia rũrĩmĩ rwa mũndũ ũcio namo.
Jesu sì mú ọkùnrin náà kúrò láàrín ọ̀pọ̀ ènìyàn. Ó sì fi àwọn ìka rẹ̀ sí etí ọkùnrin náà, ó tu itọ́ ṣọ́wọ́. Ó sì fi kan ahọ́n rẹ̀.
34 Akĩrora na igũrũ, akĩhũmũka na hinya, akĩmwĩra atĩrĩ, “Efatha!” (ũguo nĩ kuuga, “Hingũka!”).
Nígbà náà ni Jesu wòkè ọ̀run, ó sì mí kanlẹ̀, ó sì pàṣẹ wí pé, “Efata!” (èyí ni, “Ìwọ ṣí!”).
35 Aarĩkia kuuga ũguo matũ ma mũndũ ũcio makĩhingũka na rũrĩmĩ rwake rũkĩregera akĩambĩrĩria kwaria o wega.
Lójúkan náà, etí rẹ̀ sì ṣí, okùn ahọ́n rẹ̀ sì tú, ó sì ń sọ̀rọ̀ ketekete.
36 Nake Jesũ akĩmaatha matikeere mũndũ o na ũrĩkũ. No ũrĩa akĩragĩrĩria kũmakaania, noguo makĩragĩrĩria kwaria mũno ũhoro ũcio.
Jesu pàṣẹ fún ọ̀pọ̀ ènìyàn tó wà níbẹ̀ pé kí wọn má ṣe tan ìròyìn náà ká. Ṣùgbọ́n bí ó ti ń pa wọ́n lẹ́nu mọ́ tó, náà ni wọ́n ń tan ìròyìn náà káàkiri tó.
37 Nao andũ makĩgega mũno makĩria, makiuga atĩrĩ, “Nĩekĩte maũndũ mothe wega. O na agatũmaga andũ arĩa mataiguaga maigue na arĩa mataaragia maarie.”
Àwọn ènìyàn sì kún fún ìyanu, wọ́n wí pé, “Ó ṣe ohun gbogbo dáradára, Ó mú kí adití gbọ́rọ̀, odi sì sọ̀rọ̀.”