< Mariko 6 >

1 Thuutha ũcio Jesũ akiuma kũu agĩthiĩ itũũra rĩao, arĩ hamwe na arutwo ake.
Jesu fi ibẹ̀ sílẹ̀ lọ sí ìlú rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
2 Mũthenya wa Thabatũ wakinya, Jesũ akĩambĩrĩria kũruta andũ ũhoro arĩ thĩinĩ wa thunagogi, na andũ aingĩ arĩa maamũiguire makĩgega. Nao makĩũrania atĩrĩ, “Mũndũ ũyũ aarutire maũndũ maya kũ? Nĩ ũũgĩ wa mũthemba ũrĩkũ ũyũ aheetwo, atĩ o na nĩaringaga ciama!
Nígbà tí ó di ọjọ́ ìsinmi, ó lọ sí Sinagọgu láti kọ́ àwọn ènìyàn, ẹnu sì ya àwọn ènìyàn púpọ̀ tí ó gbọ́. Wọ́n wí pé, “Níbo ni ọkùnrin yìí gbé ti rí nǹkan wọ̀nyí? Irú ọgbọ́n kí ni èyí tí a fi fún un, tí irú iṣẹ́ ìyanu báyìí ń ti ọwọ́ rẹ̀ ṣe?
3 Githĩ ũyũ ti ũrĩa bundi wa mbaũ? Githĩ ũyũ ti mũrũ wa Mariamu, o we mũrũ wa nyina na Jakubu na Jusufu na Judasi na Simoni. Na aarĩ a nyina githĩ matirĩ gũkũ hamwe na ithuĩ?” Nao makĩmũrakarĩra.
Gbẹ́nàgbẹ́nà náà kọ́ yìí? Ọmọ Maria àti arákùnrin Jakọbu àti Josẹfu, Judasi àti Simoni? Àwọn arábìnrin rẹ̀ gbogbo ha kọ́ ni ó ń bá wa gbé níhìn-ín yìí?” Wọ́n sì kọsẹ̀ lára rẹ̀.
4 Jesũ akĩmeera atĩrĩ, “Kũndũ mũnabii ataheagwo gĩtĩĩo no itũũra-inĩ rĩake, na kwa andũ a nyũmba yao, na gwake mũciĩ.”
Nígbà náà, Jesu wí fún wọn pé, “A máa ń bu ọlá fún wòlíì níbi gbogbo àfi ní ìlú ara rẹ̀ àti láàrín àwọn ìdílé àti àwọn ẹbí òun pàápàá.”
5 Nake Jesũ ndaahotire kũringa ciama kũu, o tiga atĩ nĩaigĩrĩire andũ mataarĩ aingĩ moko arĩa maarĩ arũaru nao makĩhona.
Nítorí àìgbàgbọ́ wọn, òun kò lè ṣe iṣẹ́ ìyanu ńlá láàrín wọn, àfi àwọn aláìsàn díẹ̀ tí ó gbé ọwọ́ lé lórí, tí wọ́n sì rí ìwòsàn.
6 Nake akĩgega nĩ ũndũ wa ũrĩa maagĩte wĩtĩkio. Jesũ agĩcooka agĩthiĩ akĩrutanaga itũũra gwa itũũra.
Ẹnu si yà á nítorí àìgbàgbọ́ wọn. Lẹ́yìn náà, Jesu lọ sí àárín àwọn ìletò kéékèèké, ó sì ń kọ́ wọn.
7 Agĩcooka agĩĩta arutwo arĩa ikũmi na eerĩ, akĩmatũma mathiĩ eerĩ eerĩ na akĩmahe ũhoti wa kũingata ngoma thũku.
Ó sì pe àwọn méjìlá náà sọ́dọ̀ rẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí rán wọn lọ ní méjì méjì, Ó sì fi àṣẹ fún wọn lórí ẹ̀mí àìmọ́.
8 Na akĩmeera atĩrĩ, “Mũtigekuuĩre kĩndũ o nakĩ rũgendo-inĩ tiga o mũtirima; na mũtigakuue mũgate, kana mondo, kana mbeeca ibeeti-inĩ cianyu.
O sọ fún wọn pé, wọn kò gbọdọ̀ mú ohunkóhun lọ́wọ́, àfi ọ̀pá ìtìlẹ̀ wọn. Wọn kò gbọdọ̀ mú oúnjẹ, àpò ìgbànú, tàbí owó lọ́wọ́.
9 Ĩkĩrai iraatũ no mũtigakuue nguo cia kũgarũrĩra.
Wọn kò tilẹ̀ gbọdọ̀ mú ìpààrọ̀ bàtà tàbí aṣọ lọ́wọ́.
10 Rĩrĩa rĩothe mwatoonya nyũmba, ikarai kuo nginya rĩrĩa mũkoima itũũra rĩu.
Jesu wí pé, “Ẹ dúró sí ilé kan ní ìletò kan. Ẹ má ṣe sípò padà láti ilé dé ilé, nígbà tí ẹ bá wà ní ìlú náà.
11 Na kũrĩa andũ matakamũnyiita ũgeni kana marege kũmũthikĩrĩria-rĩ, mũkiuma kuo mũkaaribariba magũrũ manyu rũkũngũ rũitĩke, rũtuĩke ũira wa kũmatuĩra ciira.”
Ẹnikẹ́ni tí kò bá sì gbà yín, tí kò sì gbọ́rọ̀ yín, nígbà tí ẹ̀yin bá jáde kúrò níbẹ̀, ẹ gbọn eruku ẹsẹ̀ yín síbẹ̀ fún ẹ̀rí fún wọn.”
12 Nao makiumagara magĩthiĩ makĩhunjagia atĩ andũ merire.
Wọ́n jáde lọ láti wàásù ìrònúpìwàdà fún àwọn ènìyàn.
13 Ningĩ makĩingata ndaimono nyingĩ na magĩitĩrĩria andũ aingĩ arĩa maarĩ arũaru maguta nao makĩhona.
Wọ́n lé ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ẹ̀mí àìmọ́ jáde. Wọ́n sì ń fi òróró kun orí àwọn tí ara wọn kò dá, wọ́n sì mú wọn láradá.
14 Mũthamaki Herode nĩaiguire ũhoro ũcio, nĩgũkorwo rĩĩtwa rĩa Jesũ nĩrĩagĩte igweta mũno. Andũ amwe moigaga atĩrĩ, “Johana Mũbatithania nĩariũkĩte kuuma kũrĩ arĩa akuũ, na nĩkĩo arĩ na hinya mũnene ũguo wa kũringa ciama.”
Láìpẹ́, ọba Herodu gbọ́ nípa Jesu, nítorí níbi gbogbo ni a ti ń sọ̀rọ̀ iṣẹ́ ìyanu rẹ̀. Ọba náà rò pé, “Johanu Onítẹ̀bọmi jíǹde kúrò nínú òkú, nítorí náà ni iṣẹ́ ìyanu ṣe ń ṣe láti ọwọ́ rẹ.”
15 Angĩ nao makoiga atĩrĩ, “Ũyũ nĩ Elija.” Angĩ nao makoiga atĩrĩ, “Ũyũ nĩ mũnabii ta ũmwe wa arĩa a tene.”
Àwọn mìíràn wí pé, “Elijah ní.” Àwọn mìíràn wí pé, “Wòlíì bí ọ̀kan lára àwọn àtijọ́ tó ti kú ló tún padà sáyé.”
16 Nowe Herode rĩrĩa aiguire ũhoro ũcio, akiuga atĩrĩ, “Johana, mũndũ ũrĩa ndaatinithirie mũtwe-rĩ, nĩariũkĩte kuuma kũrĩ arĩa akuũ!”
Ṣùgbọ́n nígbà tí Herodu gbọ́ èyí, ó wí pé “Johanu tí mo tí bẹ́ lórí ni ó ti jíǹde kúrò nínú òkú.”
17 Nĩgũkorwo, Herode we mwene nĩanyiitithĩtie Johana na akamũikithia njeera. Eekĩte ũguo nĩ ũndũ wa Herodia, ũrĩa warĩ mũtumia wa mũrũ wa nyina Filipu, nĩgũkorwo Herode nĩamũhikĩtie.
Herodu fúnra rẹ̀ sá ti ránṣẹ́ mú Johanu, tìkára rẹ̀ sínú túbú nítorí Herodia aya Filipi arákùnrin rẹ̀ nítorí tí ó fi ṣe aya.
18 Nake Johana nĩeraga Herode atĩrĩ, “Ndũrĩ na rũtha kũhikia mũtumia wa mũrũ wa maitũguo.”
Johanu sì ti wí fún Herodu pé, “Kò tọ́ sí ọ láti fi ìyàwó arákùnrin rẹ ṣe aya.”
19 Nĩ ũndũ ũcio Herodia agĩtuma Johana ũthũ na akĩenda kũmũũragithia. No ndangĩahotire gwĩka ũguo,
Nítorí náà ni Herodia ṣe ní sínú, òun sì fẹ́ pa á, ṣùgbọ́n kò le ṣe é.
20 nĩgũkorwo Herode nĩetigĩrĩte Johana na akamũgitagĩra, tondũ nĩoĩ atĩ aarĩ mũndũ mũthingu na mũtheru. Herode nĩathikagĩrĩria Johana, no nĩatangĩkaga mũno amũigua; no nĩendaga mũno kũmũthikĩrĩria.
Nítorí Herodu bẹ̀rù Johanu, ó sì mọ̀ ọ́n ni olóòtítọ́ ènìyàn àti ẹni mímọ́, ó sì ń tọ́jú rẹ̀. Nígbà tí Herodu ba gbọ́rọ̀ Johanu, ó máa ń dààmú síbẹ̀, ó sì fi ayọ̀ gbọ́rọ̀ rẹ̀.
21 Na rĩrĩ, mũthenya ũmwe Herodia nĩagĩire na mweke. Herode nĩarugithirie iruga inene rĩa kũririkana mũthenya wa gũciarwo gwake, nake agĩĩta anene arĩa maamũteithagia na atongoria ake a mbũtũ cia ita, na andũ arĩa maarĩ igweta kũu Galili.
Níkẹyìn Herodia rí ààyè. Àkókò yìí ni ọjọ́ ìbí Herodu, òun sì pèsè àsè ní ààfin ọba fún àwọn olùrànlọ́wọ́ rẹ̀: àwọn balógun àti àwọn ènìyàn pàtàkì ní Galili.
22 Na rĩrĩa mwarĩ wa Herodia aatoonyire kũu maarĩ na akĩina-rĩ, agĩkenia Herode na ageni ake arĩa meetĩtwo iruga rĩu. Mũthamaki akĩĩra mũirĩtu ũcio atĩrĩ, “Hooya o kĩrĩa gĩothe ũngĩenda na nĩngũkũhe.”
Nígbà náà, ni ọmọbìnrin Herodia wọlé láti jó. Inú Herodu àti àwọn àlejò rẹ̀ dùn tó bẹ́ẹ̀. Ọba sọ fún ọmọbìnrin náà pé, “Béèrè ohunkóhun tí ìwọ bá fẹ́ lọ́wọ́ mi, èmi ó sì fi fún ọ.”
23 Akĩĩhĩta, akĩmwĩra atĩrĩ, “Kĩrĩa gĩothe ũngĩhooya nĩngũkũhe, o na angĩkorwo nĩ nuthu ya ũthamaki wakwa.”
Ó sì búra fún un wí pé, “Ohunkóhun tí ìwọ bá fẹ́, ìbá à ṣe ìdajì ìjọba mi ni, èmi yóò fi fún ọ.”
24 Mũirĩtu ũcio agĩthiĩ akĩũria nyina atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ ngwĩtia?” Nyina akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ĩtia mũtwe wa Johana Mũbatithania.”
Ó jáde lọ sọ fún ìyá rẹ̀ pé, “Kí ní kí ń béèrè?” Ó dáhùn pé, “Orí Johanu Onítẹ̀bọmi.”
25 O rĩmwe mũirĩtu ũcio akĩhiũha, agĩtoonya he mũthamaki, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ngwenda ũũhe o rĩu mũtwe wa Johana Mũbatithania ũrĩ thĩinĩ wa kiuga.”
Ọmọbìnrin yìí sáré padà wá sọ́dọ̀ Herodu ọba. Ó sì wí fún un pé, “Mo ń fẹ́ orí Johanu Onítẹ̀bọmi nísinsin yìí nínú àwopọ̀kọ́.”
26 Mũthamaki akĩigua kĩeha mũno, no tondũ wa mwĩhĩtwa wake na nĩ ũndũ wa ageni ake, ndangĩaregire gwĩka ũguo orĩtio.
Inú ọba sì bàjẹ́ gidigidi, ṣùgbọ́n nítorí àwọn ìbúra rẹ, àti nítorí àwọn tí ó bá a jókòó pọ̀, kò sì fẹ́ kọ̀ fún un.
27 Nĩ ũndũ ũcio agĩtũma mũthigari ũmwe wa arĩa maamũrangagĩra, o hĩndĩ ĩyo akĩmwatha athiĩ arehe mũtwe wa Johana. Mũndũ ũcio agĩthiĩ njeera agĩtinia Johana mũtwe
Nítorí èyí, ọba rán ẹ̀ṣọ́ kan, ó fi àṣẹ fún un pé, kí ó gbé orí Johanu wá. Ọkùnrin náà sì lọ, ó bẹ́ Johanu lórí nínú túbú.
28 akĩũrehe na kiuga, akĩnengera mũirĩtu ũcio, nake akĩũnengera nyina.
Ó sì gbé orí Johanu wa nínú àwopọ̀kọ́. Ó sì gbé e fún ọmọbìnrin náà. Òun sì gbé e tọ ìyá rẹ̀ lọ.
29 Nao arutwo a Johana maigua ũhoro ũcio, magĩũka, makĩoya mwĩrĩ wake, magĩthiĩ, makĩũthika.
Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu gbọ́, wọ́n wá gbé òkú rẹ̀, wọ́n sì lọ tẹ́ ẹ sínú ibojì.
30 Atũmwo nĩmagomanire harĩ Jesũ, makĩmwĩra maũndũ marĩa mothe meekĩte, na marĩa maarutĩte andũ.
Àwọn aposteli kó ara wọn jọ sí ọ̀dọ̀ Jesu, wọ́n sí ròyìn ohun gbogbo tí wọ́n ti ṣe àti ohun gbogbo tí wọ́n ti kọ́ni.
31 Na tondũ wa ũrĩa andũ aingĩ mookaga magĩthiiaga-rĩ, matingĩahotire kuona o na hĩndĩ ya kũrĩa irio, nake Jesũ akĩmeera atĩrĩ, “Ũkai inyuĩ oiki, tũthiĩ handũ hatarĩ inegene, tũkahurũke.”
Nígbà tí Jesu rí i pé ọ̀pọ̀ ènìyàn ń lọ tí wọ́n sì ń bọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ààyè fún wọn láti jẹun, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ jẹ́ kí a kúrò láàrín ọ̀pọ̀ ènìyàn wọ̀nyí fún ìgbà díẹ̀, kí a sì sinmi.”
32 Nĩ ũndũ ũcio makĩingĩra gatarũ marĩ oiki, magĩthiĩ handũ hataarĩ andũ.
Nítorí náà, wọ́n wọ ọkọ̀ ojú omi kúrò níbẹ̀ lọ sí ibi tí ó parọ́rọ́.
33 Nao andũ aingĩ arĩa maamonire magĩthiĩ, makĩmamenya, magĩtengʼera na magũrũ moimĩte matũũra-inĩ mothe, magĩkinya mbere yao.
Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ ènìyàn ni o rí wọn nígbà tí wọ́n ń lọ. Àwọn wọ̀nyí sì tún wá láti ìlú ńlá gbogbo wọn sáré gba etí Òkun, wọ́n ṣáájú wọn gúnlẹ̀ ní èbúté.
34 Na rĩrĩa Jesũ oimire gatarũ, akĩona andũ aingĩ, akĩmaiguĩra tha, tondũ maatariĩ ta ngʼondu itarĩ na mũrĩithi. Nĩ ũndũ ũcio akĩambĩrĩria kũmaruta maũndũ maingĩ.
Bí Jesu ti ń sọ̀kalẹ̀ láti inú ọkọ̀ náà, ó bá ọ̀pọ̀ ènìyàn bí i tí àtẹ̀yìnwá, tí wọ́n ti ń dúró dè e. Ó káàánú fún wọn, nítorí wọ́n dàbí àgùntàn tí kò ní olùtọ́jú. Ó sì kọ́ wọn ni ọ̀pọ̀ nǹkan tí ó yẹ kí wọ́n mọ̀.
35 Na gwatua gũtuka, arutwo ake magĩthiĩ kũrĩ we, makĩmwĩra atĩrĩ, “Gũkũ nĩ werũ-inĩ na rĩu gũkiriĩ gũtuka.
Nígbà tí ọjọ́ sì ti bù lọ tán, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, wọ́n wí fún un pé, ibi aṣálẹ̀ ni ìbí yìí, ọjọ́ sì bù lọ tán.
36 Ĩra andũ aya mathiĩ nĩguo makinye mĩgũnda-inĩ na matũũra-inĩ marĩa me hakuhĩ makegũrĩre kĩndũ gĩa kũrĩa.”
“Rán àwọn ènìyàn wọ̀nyí láti lọ sí àwọn abúlé àti ìlú láti ra oúnjẹ fún ara wọn.”
37 Nowe akĩmacookeria akĩmeera atĩrĩ, “Maheei kĩndũ gĩa kũrĩa arĩ inyuĩ.” Nao makĩmũũria atĩrĩ, “Ũrenda tũthiĩ tũkagũre mĩgate ya dinari magana meerĩ tũmahe marĩe?”
Ṣùgbọ́n Jesu sọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Ẹ fún wọn ní oúnjẹ.” Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn wí fún pé, “Èyí yóò ná wa tó owó iṣẹ́ ọ̀yà oṣù mẹ́jọ, ṣe kí a lọ fi èyí ra àkàrà fún àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn yìí láti jẹ.”
38 Nake akĩmooria atĩrĩ, “Mũrĩ na mĩgate ĩigana? Thiĩi mũrore.” Hĩndĩ ĩrĩa maarorire makĩmwĩra atĩrĩ, “Harĩ na mĩgate ĩtano, na thamaki igĩrĩ.”
Jesu tún béèrè pé, “Ìṣù àkàrà mélòó ni ẹ̀yin ni lọ́wọ́? Ẹ lọ wò ó.” Wọ́n padà wá jíṣẹ́ pé, “Ìṣù àkàrà márùn-ún àti ẹja méjì.”
39 Nake Jesũ agĩathana andũ othe maikare thĩ ikundi ikundi kũu nyeki-inĩ ĩrĩa yarĩ ho nduru.
Nígbà náà ni Jesu sọ fún ọ̀pọ̀ ènìyàn náà kí a mú wọn jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ̀gbẹ́ lórí koríko.
40 Nĩ ũndũ ũcio magĩikara thĩ marĩ ikundi cia andũ igana na cia andũ mĩrongo ĩtano.
Lẹ́sẹ̀kan náà, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í jókòó, ní àádọ́ta tàbí ọgọọgọ́rùn-ún.
41 Nake akĩoya mĩgate ĩyo ĩtano na thamaki icio igĩrĩ, akĩrora na igũrũ, agĩcookia ngaatho na akĩenyũranga mĩgate ĩyo. Agĩcooka akĩmĩnengera arutwo ake mahe andũ. Ningĩ akĩoya thamaki icio igĩrĩ akĩmagayania othe.
Nígbà tí ó sì mú ìṣù àkàrà márùn-ún àti ẹja méjì náà, ó gbé ojú rẹ̀ sókè ọ̀run. Ó dúpẹ́ fún oúnjẹ náà, ó bù wọ́n sí wẹ́wẹ́, ó fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ láti gbé e kalẹ̀ síwájú àwọn ènìyàn náà àti àwọn ẹja méjì náà ni ó pín fún gbogbo wọn.
42 Nao othe makĩrĩa makĩhũũna,
Gbogbo wọn sì jẹ àjẹyó.
43 nao arutwo makĩũngania cienyũ cia mĩgate na cia thamaki iria ciatigarĩte makĩiyũria ciondo ikũmi na igĩrĩ.
Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sì kó agbọ̀n méjìlá tí ó kún fún àjẹkù àkàrà àti ti ẹja pẹ̀lú.
44 Mũigana wa arũme arĩa othe maarĩire irio icio maarĩ ngiri ithano.
Àwọn tí ó sì jẹ́ àkàrà náà tó ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún márùn-ún ọkùnrin.
45 Na hĩndĩ o ĩyo Jesũ akĩĩra arutwo ake matoonye gatarũ mathiiage mbere yake makinye Bethisaida, mũira wa oigĩre kĩrĩndĩ ũhoro.
Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ lẹ́yìn èyí, Jesu pàṣẹ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ láti padà sínú ọkọ̀ kí wọn sì ṣáájú rékọjá sí Betisaida. Níbẹ̀ ni òun yóò ti wà pẹ̀lú wọn láìpẹ́. Nítorí òun fúnra a rẹ̀ yóò dúró sẹ́yìn láti rí i pé àwọn ènìyàn túká lọ ilé wọn.
46 Thuutha wa kũmoigĩra ũhoro, akĩambata kĩrĩma-inĩ agĩthiĩ kũhooya.
Lẹ́yìn náà, ó lọ sórí òkè láti lọ gbàdúrà.
47 Na gũgĩkinya hwaĩ-inĩ, gatarũ kaarĩ gatagatĩ ka iria, nake Jesũ aarĩ thĩ nyũmũ arĩ wiki.
Nígbà tí ó di alẹ́, ọkọ̀ wà láàrín Òkun, òun nìkan sì wà lórí ilẹ̀.
48 Nake akĩona arutwo makĩĩgũmĩra gũtwara gatarũ, tondũ rũhuho rwerekeire na kũrĩa moimaga. Na rĩrĩ, ta thaa kenda cia ũtukũ, Jesũ agĩthiĩ kũrĩ o agereire maaĩ igũrũ. Nake aarĩ o hakuhĩ kũmahĩtũka,
Ó rí i wí pé àwọn ọmọ-ẹ̀yìn wà nínú wàhálà púpọ̀ ní wíwa ọkọ̀ náà nítorí ti ìjì líle ṣe ọwọ́ òdì sí wọn, nígbà tí ó sì dì ìwọ̀n ìṣọ́ kẹrin òru, ó tọ̀ wọ́n wá, ó ń rìn lórí omi Òkun, òun sì fẹ́ ré wọn kọjá,
49 no-o mamuona agereire maaĩ igũrũ magĩĩciiria nĩ ngoma moonaga. Magĩkaya
ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n rí i tí ó ń rìn, wọ́n rò pé iwin ni. Wọ́n sì kígbe sókè lóhùn rara,
50 tondũ othe nĩmamuonire na magĩĩtigĩra mũno. O hĩndĩ ĩyo Jesũ akĩmeera atĩrĩ, “Ũmĩrĩriai! Nĩ niĩ. Tigai gwĩtigĩra.”
nítorí gbogbo wọn ni ó rí i, tí ẹ̀rù sì bà wọ́n. Ṣùgbọ́n òun sọ̀rọ̀ sí wọn lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ pé, “Ẹ mú ọkàn le! Èmi ni. Ẹ má bẹ̀rù.”
51 Agĩcooka agĩtoonya gatarũ kau maarĩ, naruo rũhuho rũgĩtuĩka. Nao makĩgega mũno,
Nígbà náà ni ó gòkè sínú ọkọ̀ pẹ̀lú wọn, ìjì líle náà sì dáwọ́ dúró. Ẹ̀rù sì bà wọ́n rékọjá gidigidi, ẹnu sì yà wọ́n.
52 tondũ matiataũkĩirwo nĩ ũhoro wa mĩgate ĩyo; ngoro ciao ciarĩ o nyũmũ.
Wọn kò sá tó ni òye iṣẹ́ ìyanu ti ìṣù àkàrà, nítorí ti ọkàn wọn yigbì.
53 Na maarĩkia kũringa mũrĩmo ũrĩa ũngĩ, magĩkinya Genesareti, makĩoha gatarũ kao hũgũrũrũ-inĩ cia iria.
Lẹ́yìn tí wọ́n la Òkun náà kọjá, wọ́n gúnlẹ̀ sí Genesareti. Wọ́n sì so ọkọ̀ sí èbúté.
54 Maarĩkia kuuma gatarũ-inĩ, o rĩmwe andũ makĩmenya Jesũ.
Wọ́n jáde kúrò nínú ọkọ̀. Àwọn ènìyàn tó wà níbẹ̀ rí Jesu, wọ́n sì dá a mọ̀ ọ́n.
55 Magĩtuĩkania bũrũri-inĩ ũcio wothe magakuuaga andũ arĩa maarĩ arũaru na ibarĩ, makĩmatwaraga kũrĩa guothe maiguaga atĩ nĩkuo arĩ.
Wéré, wọ́n ròyìn dídé rẹ̀, gbogbo àwọn ènìyàn sáré gbé gbogbo àwọn aláìsàn lórí àkéte wọn wá pàdé rẹ̀.
56 Na kũrĩa guothe aathiiaga, mĩciĩ-inĩ, na tũtũũra-inĩ o na kana mĩgũnda-inĩ, o maigaga arĩa arũaru ndũnyũ-inĩ, na makamũthaitha ametĩkĩrie naarĩ mahutie gĩcũrĩ kĩa nguo yake, na arĩa othe maamũhutirie makĩhona.
Ní ibi gbogbo tí ó sì dé, yálà ní abúlé, ìlú ńlá tàbí àrọ́ko, ń ṣe ni wọ́n ń kó àwọn aláìsàn pàdé rẹ̀ ní àárín ọjà. Wọ́n sì ń bẹ̀ ẹ́ kí ó jẹ́ kí wọn fi ọwọ́ kan etí aṣọ rẹ̀, gbogbo àwọn tí wọ́n sì fi ọwọ́ kàn án ni a mú láradá.

< Mariko 6 >