< Luka 7 >
1 Nake Jesũ aarĩkia kwaria maũndũ macio mothe andũ makĩmũiguaga, agĩtoonya Kaperinaumu.
Nígbà tí ó sì parí gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀ fun àwọn ènìyàn, ó wọ Kapernaumu lọ.
2 No kũu nĩ kwarĩ na ndungata ya mũnene-wa-thigari-igana, ĩrĩa mũmĩathi eendete mũno, nayo yarĩ ndwaru hakuhĩ gũkua.
Ọmọ ọ̀dọ̀ balógun ọ̀rún kan, tí ó ṣọ̀wọ́n fún un, ṣàìsàn, ó sì ń kú lọ.
3 Nake mũnene ũcio wa thigari igana aigua ũhoro wa Jesũ, agĩtũma athuuri a Ayahudi kũrĩ we makamũũrie oke ahonie ndungata yake.
Nígbà tí ó sì gbúròó Jesu, ó rán àwọn àgbàgbà Júù sí i, ó ń bẹ̀ ẹ́ pé kí ó wá mú ọmọ ọ̀dọ̀ òun láradá.
4 Nao maakinya kũrĩ Jesũ, makĩmũthaitha magwatĩirie mũno, makĩmwĩra atĩrĩ, “Mũndũ ũyũ nĩagĩrĩirwo gwĩkwo ũguo nĩwe,
Nígbà tí wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ Jesu, wọ́n fi ìtara bẹ̀ ẹ́, pé, “Ó yẹ ní ẹni tí òun ìbá ṣe èyí fún.
5 tondũ nĩendete rũrĩrĩ rwitũ na nĩatwakĩire thunagogi.”
Nítorí tí ó fẹ́ràn orílẹ̀-èdè wa, ó sì ti kọ́ Sinagọgu kan fún wa.”
6 Nĩ ũndũ ũcio Jesũ agĩthiĩ nao. Na marĩ hakuhĩ gũkinya mũciĩ, mũnene ũcio wa thigari igana akĩmũtũmĩra arata makamwĩre atĩrĩ, “Mwathani, tiga gwĩthĩĩnia tondũ ndiagĩrĩire wee ũũke gwakwa mũciĩ.
Jesu sì ń bá wọn lọ. Nígbà tí kò sì jìn sí etí ilé mọ́, balógun ọ̀rún náà rán àwọn ọ̀rẹ́ sí i, pé, “Olúwa, má ṣe yọ ara rẹ lẹ́nu, nítorí tí èmi kò yẹ tí ìwọ ìbá fi wọ abẹ́ òrùlé mi.
7 O na nokĩo itanona njagĩrĩire gũũka kũrĩ we. No uga o kiugo, na ndungata yakwa nĩĩkũhona.
Nítorí náà èmi kò sì rò pé èmi náà yẹ láti tọ̀ ọ́ wá, ṣùgbọ́n sọ ní gbólóhùn kan, a ó sì mú ọmọ ọ̀dọ̀ mi láradá.
8 Nĩgũkorwo niĩ mwene ndĩ mũndũ wathagwo, na ndĩ na thigari njathaga. Ndeera ũmwe ‘Thiĩ,’ nĩathiiaga, na ndeera ũngĩ atĩrĩ, ‘Ũka,’ nĩokaga. Na ningĩ ndeera ndungata yakwa atĩrĩ, ‘Ĩka ũna,’ nĩĩkaga.”
Nítorí èmi náà pẹ̀lú jẹ́ ẹni tí a fi sí abẹ́ àṣẹ, tí ó ní ọmọ-ogun lẹ́yìn mi, mo sì wí fún ọ̀kan pé, ‘Lọ,’ a sì lọ; àti fún òmíràn pé, ‘Wá,’ a sì wá; àti fún ọmọ ọ̀dọ̀ mi pé, ‘Ṣe èyí,’ a sì ṣe é.”
9 Rĩrĩa Jesũ aiguire ũguo, akĩgega, akĩhũgũkĩra kĩrĩndĩ kĩrĩa kĩamũrũmĩrĩire, agĩkĩĩra atĩrĩ, “Ngũmwĩra atĩrĩ, ndionete mũndũ ũrĩ na wĩtĩkio mũnene ũũ Isiraeli guothe!”
Nígbà tí Jesu gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ẹnu sì yà, ó sì yípadà sí ìjọ ènìyàn tí ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ó wí pé, “Mo wí fún yín pé èmi kò rí irú ìgbàgbọ́ ńlá bí èyí nínú àwọn ènìyàn Israẹli.”
10 Nao andũ arĩa maatũmĩtwo magĩcooka mũciĩ magĩkora ngombo ĩyo ĩrĩ honu.
Nígbà tí àwọn oníṣẹ́ sì padà sí ilé, wọ́n bá ọmọ ọ̀dọ̀ náà tí ń ṣàìsàn, ara rẹ̀ ti dá.
11 Ihinda inini rĩathira, Jesũ agĩthiĩ itũũra rĩetagwo Naini, nao arutwo ake na andũ gĩkundi kĩnene magĩthiĩ nake.
Ní ọjọ́ kejì, ó lọ sí ìlú kan tí a ń pè ní Naini, àwọn púpọ̀ nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì ń bá a lọ àti ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn.
12 Na rĩrĩa akuhĩrĩirie kĩhingo gĩa itũũra rĩu, mũndũ wakuĩte nĩarutagwo kuo na aarĩ mwana wa mũmwe, nake nyina aarĩ mũtumia wa ndigwa. Nao andũ aingĩ a itũũra rĩu maarĩ hamwe nake.
Bí ó sì ti súnmọ́ ẹnu ibodè ìlú náà, sì kíyèsi i, wọ́n ń gbé òkú ọkùnrin kan jáde, ọmọ kan ṣoṣo náà tí ìyá rẹ̀ bí, ó sì jẹ́ opó: ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn ìlú náà sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
13 Rĩrĩa Mwathani onire mũtumia ũcio, akĩmũiguĩra tha, akĩmwĩra atĩrĩ, “Tiga kũrĩra.”
Nígbà tí Olúwa sì rí i, àánú rẹ̀ ṣe é, ó sì wí fún un pé, “Má sọkún mọ́.”
14 Agĩcooka agĩthiĩ, akĩhutia ithandũkũ, nao arĩa maarĩkuuĩte makĩrũgama. Agĩcooka akiuga atĩrĩ, “Mwanake, ndakwĩra atĩrĩ, ũkĩra!”
Ó sì wá, ó sì fi ọwọ́ tọ́ pósí náà: àwọn tí ń rù ú dúró jẹ́. Ó sì wí pé, “Ọ̀dọ́mọkùnrin, mo wí fún ọ, dìde!”
15 Mũndũ ũcio wakuĩte agĩũkĩra, akĩambĩrĩria kwaria, nake Jesũ akĩmũnengerana kũrĩ nyina.
Ẹni tí ó kú náà sì dìde jókòó, ó bẹ̀rẹ̀ sí i fọhùn. Ó sì fà á lé ìyá rẹ̀ lọ́wọ́.
16 Andũ othe makĩiyũrwo nĩ guoya na makĩgooca Ngai, makiuga atĩrĩ, “Mũnabii mũnene nĩokĩte gatagatĩ gaitũ. Ngai nĩokĩte gũteithia andũ ake.”
Ẹ̀rù sì ba gbogbo wọn: wọ́n sì yin Ọlọ́run lógo, pé, “Wòlíì ńlá dìde nínú wa,” àti pé, “Ọlọ́run sì wá bẹ àwọn ènìyàn rẹ̀ wò!”
17 Nayo ngumo ya Jesũ ĩkĩhunja Judea guothe o na bũrũri ũrĩa wagũthiũrũrũkĩirie.
Òkìkí rẹ̀ sì kàn ní gbogbo Judea, àti gbogbo agbègbè tí ó yí i ká.
18 Nao arutwo a Johana nĩmamũheire ũhoro wa maũndũ macio mothe. Nake Johana agĩĩta arutwo ake eerĩ,
Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu sì sọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí fún un.
19 akĩmatũma kũrĩ Mwathani makamũũrie atĩrĩ, “Wee nĩwe ũrĩa werĩtwo nĩagooka kana tweterere mũndũ ũngĩ?”
Nígbà tí Johanu sì pe àwọn méjì nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó rán wọn sọ́dọ̀ Olúwa, wí pé, “Ìwọ ni ẹni tí ń bọ̀, tàbí kí a máa retí ẹlòmíràn?”
20 Nao arutwo acio maakinya kũrĩ Jesũ makĩmwĩra atĩrĩ, “Johana Mũbatithania aatũtũma kũrĩ we tũkũũrie atĩrĩ, ‘Wee nĩwe ũrĩa werĩtwo nĩagooka kana tweterere mũndũ ũngĩ?’”
Nígbà tí àwọn ọkùnrin náà sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, wọ́n wí pé, “Johanu onítẹ̀bọmi rán wa sọ́dọ̀ rẹ, pé, ‘Ìwọ ni ẹni tí ń bọ̀, tàbí kí a máa retí ẹlòmíràn?’”
21 Ihinda-inĩ o rĩu Jesũ akĩhonia andũ aingĩ arĩa maarĩ na mĩrimũ, na ndwari, na akĩingata ngoma thũku o na agĩtũma andũ aingĩ arĩa maarĩ atumumu macooke kuona.
Ní wákàtí náà, ó sì ṣe ìmúláradá ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn nínú àìsàn, àti ààrùn, àti ẹ̀mí búburú; ó sì fi ìríran fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn afọ́jú.
22 Nĩ ũndũ ũcio agĩcookeria arĩa maatũmĩtwo atĩrĩ, “Cookai mũkeere Johana maũndũ marĩa muonete na mũkaigua: atĩ atumumu nĩ marona, na ithua nĩiretwara, na arĩa marĩ na mangũ nĩ marahonio, na andũ arĩa mataiguaga nĩmaraigua, na arĩa akuũ nĩmarariũkio, na Ũhoro-ũrĩa-Mwega nĩũrahunjĩrio arĩa athĩĩni.
Jesu sì dáhùn ó wí fún wọn pé, “Ẹ padà lọ, ẹ ròyìn nǹkan tí ẹ̀yin rí, tí ẹ̀yin sì gbọ́ fún Johanu: àwọn afọ́jú ń ríran, àwọn amúnkùn ún rìn, a sọ àwọn adẹ́tẹ̀ di mímọ́, àwọn adití ń gbọ́rọ̀, a ń jí àwọn òkú dìde, àti fún àwọn òtòṣì ni à ń wàásù ìyìnrere.
23 Kũrathimwo nĩ mũndũ ũrĩa ũtarahĩngwo nĩ ũndũ wakwa.”
Alábùkún fún sì ni ẹnikẹ́ni tí kò kọsẹ̀ lára mi.”
24 Andũ acio maatũmĩtwo nĩ Johana moima harĩ Jesũ, Jesũ akĩambĩrĩria kwarĩria andũ aingĩ ũhoro wa Johana, akĩmooria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ mwathiĩte kuona werũ-inĩ? Hihi mwathiĩte kuona kamũrangi kainainagio nĩ rũhuho?
Nígbà tí àwọn oníṣẹ́ Johanu padà lọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí í sọ fún ìjọ ènìyàn ní ti Johanu pé, “Kí ni ẹ̀yin jáde lọ sí ijù lọ wò? Ewéko tí afẹ́fẹ́ ń mì?
25 Angĩkorwo ti guo-rĩ, mwathiĩte kuona kĩ? Hihi nĩ mũndũ wĩhumbĩte nguo njega? Aca, arĩa mehumbaga nguo cia goro na magekenia na mĩago ya thĩ maikaraga nyũmba cia ũthamaki.
Ṣùgbọ́n kín ni ẹ̀yin jáde lọ wò? Ọkùnrin tí a wọ̀ ní aṣọ fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́? Wò ó, àwọn tí á wọ̀ ní aṣọ ògo, tí wọ́n sì ń jayé, ń bẹ ní ààfin ọba!
26 Mwagĩthiĩte kuona kĩ? Hihi mwathiĩte kuona mũnabii? Ĩĩ, ngũmwĩra atĩrĩ, muonire mũndũ ũkĩrĩte mũnabii.
Ṣùgbọ́n kí ni ẹ̀yin jáde lọ wò? Wòlíì? Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ó sì ju wòlíì lọ!
27 Ũyũ nĩwe ũrĩa ũhoro wake wandĩkĩtwo atĩrĩ: “‘Nĩngatũma mũtũmwo wakwa athiĩ mbere yaku, nake nĩagagũthondekera njĩra.’
Èyí yìí ni ẹni tí a ti kọ̀wé nítorí rẹ̀ pé: “‘Wò ó, èmi yóò rán oníṣẹ́ mi síwájú rẹ; ẹni tí yóò tún ọ̀nà rẹ ṣe níwájú rẹ.’
28 Ngũmwĩra atĩrĩ, harĩ andũ arĩa manaciarwo nĩ atumia-rĩ, gũtirĩ o na ũmwe mũnene gũkĩra Johana; no mũndũ ũrĩa mũnini mũno ũthamaki-inĩ wa Ngai, nĩ mũnene kũmũkĩra.”
Mo wí fún yín nínú àwọn tí a bí nínú obìnrin, kò sí wòlíì tí ó pọ̀ ju Johanu Onítẹ̀bọmi lọ, ṣùgbọ́n ẹni tí ó kéré jùlọ ní ìjọba Ọlọ́run, ó pọ̀jù ú lọ.”
29 (Andũ othe, o na etia mbeeca cia igooti, rĩrĩa maiguire ciugo cia Jesũ, magĩtĩkĩra atĩ njĩra ya Ngai nĩ ya ma, tondũ maabatithĩtio nĩ Johana.
(Gbogbo àwọn ènìyàn tí ó gbọ́ àti àwọn agbowó òde, wọ́n dá Ọlọ́run láre, nítorí tí a fi ìtẹ̀bọmi Johanu tẹ̀ wọn bọ mi.
30 No Afarisai na arutani a watho makĩregana na ũrĩa Ngai endaga meke, tondũ o matiabatithĩtio nĩ Johana.)
Ṣùgbọ́n àwọn Farisi àti àwọn amòfin kọ ète Ọlọ́run fún ara wọn, a kò bamitiisi wọn lọ́dọ̀ rẹ̀.)
31 Nake Jesũ akiuga atĩrĩ, “Andũ a rũciaro rũrũ ingĩmagerekania na kĩ? Matariĩ ta kĩ?
Jesu sì wí pé, “Kí ni èmi ìbá fi àwọn ènìyàn ìran yìí wé? Kí ni wọ́n sì jọ?
32 Matariĩ ta ciana ciikarĩte ndũnyũ igĩĩta iria ingĩ, igaciĩra atĩrĩ: “‘Twamũhuhĩire mũtũrirũ, mũkĩaga kũina; twamũinĩire rwĩmbo rwa macakaya, no mũtiarĩrire.’
Wọ́n dàbí àwọn ọmọ kékeré tí ó jókòó ní ibi ọjà, tí wọ́n sì ń kọ sí ara wọn, tí wọ́n sì ń wí pé, “‘Àwa fọn fèrè fún yín, ẹ̀yin kò jó, àwa sì ṣọ̀fọ̀ fún yín, ẹ̀yin kò sọkún!’
33 Nĩgũkorwo Johana Mũbatithania ookire atekũrĩa na atekũnyua ndibei, na inyuĩ mũkiuga atĩrĩ, ‘Arĩ na ndaimono.’
Nítorí Johanu Onítẹ̀bọmi wá, kò jẹ àkàrà, bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu ọtí wáìnì, ẹ̀yin sì wí pé, ‘Ó ní ẹ̀mí èṣù?’
34 Mũrũ wa Mũndũ ookire akĩrĩĩaga na akĩnyuuaga, na inyuĩ mũkiuga atĩrĩ, ‘Onei mũndũ mũkoroku na mũrĩĩu, mũrata wa etia mbeeca cia igooti na “ehia”.’
Ọmọ ènìyàn dé, ó ń jẹ, ó sì ń mu, ẹ̀yin sì wí pé, ‘Wò ó, ọ̀jẹun, àti ọ̀mùtí, ọ̀rẹ́ àwọn agbowó òde àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀!’
35 No ũũgĩ nĩũmenyekaga nĩ wa kĩhooto nĩ ciana ciaguo ciothe.”
Ṣùgbọ́n ọgbọ́n ni a dá láre nípasẹ̀ ọmọ rẹ.”
36 Na rĩrĩ, Mũfarisai ũmwe nĩetire Jesũ gwake makarĩanĩre irio cia hwaĩ-inĩ nake, nĩ ũndũ ũcio Jesũ agĩthiĩ nyũmba ya Mũfarisai ũcio, agĩikara metha-inĩ.
Farisi kan sì rọ̀ ọ́ kí ó wá bá òun jẹun, ó sì wọ ilé Farisi náà lọ ó sì jókòó láti jẹun.
37 Rĩrĩa mũndũ-wa-nja watũũrĩte mũtũũrĩre wa mehia itũũra-inĩ rĩu aamenyire atĩ Jesũ nĩararĩa irio nyũmba ya Mũfarisai ũcio-rĩ, agĩũka na cuba wa maguta manungi wega,
Sì kíyèsi i, obìnrin kan wà ní ìlú náà, ẹni tí i ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀, nígbà tí ó mọ̀ pé Jesu jókòó, ó ń jẹun ní ilé Farisi, ó mú ṣágo kékeré alabasita òróró ìkunra wá,
38 na akĩrũgama thuutha wake, o hau magũrũ-inĩ make, akĩrĩraga, na akĩambĩrĩria kũmũihũgia nyarĩrĩ na maithori make. Agĩcooka akĩmũgiria nyarĩrĩ na njuĩrĩ yake, agĩcimumunya, na agĩciitĩrĩria maguta manungi wega.
Ó sì dúró tì í lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ̀ lẹ́yìn, ó ń sọkún, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí i fi omijé wẹ̀ ẹ́ ní ẹsẹ̀, ó sì ń fi irun orí rẹ nù ún nù, ó sì ń fi ẹnu kò ó ní ẹsẹ̀, ó sì ń fi òróró kùn wọ́n.
39 Rĩrĩa Mũfarisai ũrĩa wamwĩtĩte onire ũndũ ũcio, akĩĩra na ngoro atĩrĩ, “Korwo mũndũ ũyũ nĩ mũnabii, nĩangĩamenya ũrĩa ũramũhutia nĩ mũndũ-wa-nja wa mũthemba ũrĩkũ, na atĩ nĩ mwĩhia.”
Nígbà tí Farisi tí ó pè é sì rí i, ó wí nínú ara rẹ̀ pé, “Ọkùnrin yìí ìbá ṣe wòlíì, ìbá mọ ẹni àti irú ẹni tí obìnrin yìí jẹ́ tí ń fi ọwọ́ kàn an, nítorí ẹlẹ́ṣẹ̀ ni.”
40 Jesũ akĩmwĩra atĩrĩ, “Simoni, ndĩ na ũndũ wa gũkwĩra.” Nake akiuga atĩrĩ, “Mũrutani, njĩĩra.”
Jesu sì dáhùn, ó wí fún un pé, “Simoni, Mo ní ohun kan sọ fún ọ.” Ó sì dáhùn pé, “Olùkọ́ máa wí.”
41 “Kũrĩ andũ eerĩ maarĩ na thiirĩ wa mũndũ wakombithanagia mbeeca. Ũmwe aarĩ na thiirĩ wa dinari magana matano, na ũrĩa ũngĩ dinari mĩrongo ĩtano.
“Ayánilówó kan wà tí ó ní ajigbèsè méjì: ọ̀kan jẹ ẹ́ ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta owó idẹ, èkejì sì jẹ ẹ́ ní àádọ́ta.
42 Na rĩrĩ, gũtirĩ o na ũmwe wao warĩ na mbeeca cia kũmũrĩha, nĩ ũndũ ũcio marĩ o eerĩ akĩmarekera thiirĩ ũcio. Rĩu-rĩ, acio eerĩ nũũ ũngĩmwenda makĩria?”
Nígbà tí wọn kò sì ní ohun tí wọn ó san, ó dáríjì àwọn méjèèjì. Wí nínú àwọn méjèèjì, ta ni yóò fẹ́ ẹ jù?”
43 Simoni akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ngwĩciiria nĩ ũrĩa warekeirwo thiirĩ ũrĩa mũnene.” Jesũ akiuga atĩrĩ, “Nĩwatua wega.”
Simoni dáhùn wí pé, “Mo ṣe bí ẹni tí ó dáríjì jù ni.” Jesu wí fún un pé, “Ìwọ ti dájọ́ náà dáradára.”
44 Agĩcooka akĩĩhũgũrĩra mũndũ-wa-nja ũcio, akĩĩra Simoni atĩrĩ, “Nĩũkuona mũndũ-wa-nja ũyũ? Njũkire nyũmba gwaku, no ndũnaahe maaĩ ma gwĩthamba nyarĩrĩ, no nĩanjihũgia nyarĩrĩ na maithori make, na acigiria na njuĩrĩ yake.
Ó sì yípadà sí obìnrin náà, ó wí fún Simoni pé, “Wo obìnrin yìí? Èmi wọ ilé rẹ, ìwọ kò fi omi wẹ ẹsẹ̀ fún mi: ṣùgbọ́n, omijé rẹ̀ ni ó fi ń rọ̀jò sí mi lẹ́sẹ̀ irun orí ni ó fi ń nù wọ́n nù.
45 Wee-rĩ, ndũnaamumunya, no mũndũ-wa-nja ũyũ, kuuma rĩrĩa ndonyire ndarĩ aratigithĩria kũmumunya nyarĩrĩ ciakwa.
Ìwọ kò fi ìfẹnukonu fún mi: ṣùgbọ́n òun, nígbà tí mo ti wọ ilé, kò dẹ́kun ẹnu fífi kò mí lẹ́sẹ̀.
46 Wee-rĩ, ndũnanjitĩrĩria maguta mũtwe, no ũyũ nĩanjitĩrĩirie maguta manungi wega nyarĩrĩ.
Ìwọ kò fi òróró pa mí lórí, ṣùgbọ́n òun ti fi òróró pa mí lẹ́sẹ̀.
47 Nĩ ũndũ ũcio ngũkwĩra atĩrĩ, nĩarekeirwo mehia make maingĩ. Nĩgũkorwo nĩendanĩte mũno. No ũrĩa ũrekeirwo mehia manini, endanaga o hanini.”
Ǹjẹ́ mo wí fún ọ, A dárí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó pọ̀ jì í: nítorí tí ó ní ìfẹ́ púpọ̀: ẹni tí a sì dárí díẹ̀ jì, òun náà ni ó ní ìfẹ́ díẹ̀.”
48 Jesũ agĩcooka akĩĩra mũndũ-wa-nja ũcio atĩrĩ, “Nĩwarekerwo mehia maku.”
Ó sì wí fún un pé, “A dárí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jì ọ́!”
49 Ageni arĩa angĩ makĩambĩrĩria kwĩrana atĩrĩ, “Kaĩ ũyũ akĩrĩ ũ, ũrarekanĩra o na mehia?”
Àwọn tí ó bá a jókòó jẹun sì bẹ̀rẹ̀ sí í rò nínú ara wọn pé, “Ta ni èyí tí ń dárí ẹ̀ṣẹ̀ ji ni pẹ̀lú?”
50 Jesũ akĩĩra mũndũ-wa-nja ũcio atĩrĩ, “Gwĩtĩkia gwaku nĩ gwakũhonokia; thiĩ na thayũ.”
Ó sì dáhùn wí fún obìnrin náà pé, “Ìgbàgbọ́ rẹ gbà ọ́ là, máa lọ ní àlàáfíà.”