< Luka 6 >

1 Mũthenya ũmwe wa Thabatũ, Jesũ akĩgerera mĩgũnda-inĩ ya ngano, nao arutwo ake makĩambĩrĩria gũtua ngira imwe cia ngano, magĩcirigitha na moko, makĩrĩa ngano.
Ní ọjọ́ ìsinmi kejì, Jesu ń kọjá láàrín oko ọkà; àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì ń ya ìpẹ́ ọkà, wọ́n sì ń jẹ ẹ́.
2 Afarisai amwe makĩmooria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ kĩratũma mwĩke ũrĩa gũtetĩkĩrĩtio nĩ watho mũthenya wa Thabatũ?”
Àwọn kan nínú àwọn Farisi sì wí fún wọn pé, “Ki lo de tí ẹ̀yin fi ń ṣe èyí tí kò yẹ láti ṣe ní ọjọ́ ìsinmi?”
3 Jesũ akĩmacookeria atĩrĩ, “Kaĩ mũtathomete ũrĩa Daudi eekire, rĩrĩa we na arĩa maarĩ nake maarĩ ahũtu?
Jesu sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin kò kà nípa ohun tí Dafidi ṣe, nígbà tí ebi ń pa òun tìkára rẹ̀ àti àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀;
4 Aatoonyire Nyũmba ya Ngai, akĩoya na akĩrĩa mĩgate ĩrĩa yamũrĩirwo Ngai, ĩrĩa ateetĩkĩrĩtio kũrĩa nĩ watho tiga no athĩnjĩri-Ngai meetĩkĩrĩtio kũmĩrĩa, na agĩcooka akĩhe arĩa maarĩ nake ĩmwe yayo.”
bi ó ti wọ ilé Ọlọ́run lọ, tí ó sì mú àkàrà ìfihàn tí ó sì jẹ ẹ́, tí ó sì fi fún àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ pẹ̀lú; tí kò yẹ fún un láti jẹ, bí kò ṣe fún àwọn àlùfáà nìkan ṣoṣo?”
5 Jesũ agĩcooka akĩmeera atĩrĩ, “Mũrũ wa Mũndũ nĩwe Mwathani wa Thabatũ.”
Ó sì wí fún wọn pé, “Ọmọ Ènìyàn ni Olúwa Ọjọ́ Ìsinmi.”
6 Na rĩrĩ, mũthenya ũngĩ wa Thabatũ nĩathiire thunagogi-inĩ, akĩrutana, nakuo nĩ kwarĩ na mũndũ warĩ mwonju guoko gwake kwa ũrĩo.
Ní ọjọ́ ìsinmi mìíràn, ó wọ inú Sinagọgu lọ, ó sì ń kọ́ni, ọkùnrin kan sì ń bẹ níbẹ̀ tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ rọ.
7 Nao Afarisai na arutani a watho nĩmacaragia ũndũ mangĩthitangĩra Jesũ, nĩ ũndũ ũcio makĩmũrora mũno, mone kana nĩekũhonania mũthenya wa Thabatũ.
Àwọn akọ̀wé àti àwọn Farisi ń ṣọ́ ọ, bóyá yóò mú un láradá ní ọjọ́ ìsinmi; kí wọn lè rí ọ̀nà láti fi ẹ̀sùn kàn án.
8 Nowe Jesũ, tondũ nĩamenyaga ũrĩa meeciiragia, akĩĩra mũndũ ũcio wonjete guoko atĩrĩ, “Ũkĩra ũrũgame mbere ya andũ othe.” Nĩ ũndũ ũcio agĩũkĩra akĩrũgama hau.
Ṣùgbọ́n ó mọ èrò inú wọn, ó sì wí fún ọkùnrin náà tí ọwọ́ rẹ̀ rọ pé, “Dìde, kí o sì dúró láàrín.” Ó sì dìde dúró.
9 Jesũ agĩcooka akĩmeera atĩrĩ, “Ngũmũũria atĩrĩ, nĩ ũndũ ũrĩkũ mwĩtĩkĩrie nĩ watho mũthenya wa Thabatũ: nĩ gwĩka wega kana nĩ gwĩka ũũru, nĩ kũhonokia muoyo kana nĩ kũũniina?”
Nígbà náà ni Jesu wí fún wọn pé, “Èmi bi yín léèrè, Ó ha tọ́ láti máa ṣe rere ni ọjọ́ ìsinmi, tàbí láti máa ṣe búburú? Láti gba ọkàn là, tàbí láti pa á run?”
10 Akĩĩhũgũra, akĩmarora othe, agĩcooka akĩĩra mũndũ ũcio atĩrĩ, “Tambũrũkia guoko gwaku.” Nake agĩĩka o ro ũguo; nakuo guoko gwake gũkĩhonio biũ.
Nígbà tí ó sì wo gbogbo wọn yíká, ó wí fún ọkùnrin náà pé, “Na ọwọ́ rẹ.” Ó sì ṣe bẹ́ẹ̀: ọwọ́ rẹ̀ sì padà bọ̀ sípò gẹ́gẹ́ bí èkejì.
11 Nao makĩrakara mũno, makĩambĩrĩria kũũrania ũrĩa mangĩĩka Jesũ.
Wọ́n sì kún fún ìbínú gbígbóná; wọ́n sì bá ara wọn rò ohun tí àwọn ìbá ṣe sí Jesu.
12 Mũthenya ũmwe Jesũ nĩoimagarire agĩthiĩ kĩrĩma-inĩ akahooe, akĩraara akĩhooya Ngai ũtukũ wothe.
Ni ọ̀kan nínú àwọn ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, Jesu lọ sí orí òkè láti gbàdúrà, ó sì fi gbogbo òru náà gbàdúrà sí Ọlọ́run.
13 Gwakĩa-rĩ, agĩĩta arutwo ake moke harĩ we, agĩthuura andũ ikũmi na eerĩ ao, akĩmatua atũmwo, nao nĩ:
Nígbà tí ilẹ̀ sì mọ́, ó pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀; nínú wọn ni ó sì yan méjìlá, tí ó sì sọ ní aposteli:
14 Simoni (ũrĩa aatuire Petero), na Anderea mũrũ wa nyina, na Jakubu, na Johana, na Filipu, na Baritholomayo,
Simoni (ẹni tí a pè ní Peteru) àti Anderu arákùnrin rẹ̀, Jakọbu, Johanu, Filipi, Bartolomeu,
15 na Mathayo, na Toma, na Jakubu wa Alufayo, na Simoni ũrĩa wetagwo Zelote,
Matiu, Tomasi, Jakọbu ọmọ Alfeu, Simoni tí a ń pè ní Sealoti,
16 na Judasi wa Jakubu, na Judasi Mũisikariota ũrĩa wamũkunyanĩire.
Judea arákùnrin Jakọbu, àti Judasi Iskariotu tí ó di ọ̀dàlẹ̀.
17 Nake Jesũ agĩikũrũka hamwe nao, makĩrũgama handũ haarĩ haraganu. Gĩkundi kĩnene kĩa arutwo ake kĩarĩ ho, o na andũ aingĩ mũno kuuma Judea guothe, na Jerusalemu, o na kuuma ndeere-inĩ cia Turo na Sidoni,
Ó sì bá wọn sọ̀kalẹ̀, ó sì dúró ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, àti ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn, láti gbogbo Judea, àti Jerusalẹmu, àti agbègbè Tire àti Sidoni, tí wọ́n wá láti gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀, àti láti gba ìmúláradá kúrò nínú ààrùn wọn;
18 nao mookĩte nĩguo mamũigue na mahonio mĩrimũ yao. Nao arĩa maanyamaragio nĩ ngoma thũku makĩhonio,
àti àwọn tí ara wọn kún fún ẹ̀mí àìmọ́ ni ó sì mú láradá.
19 nao andũ othe makĩgeria kũmũhutia, tondũ hinya nĩwoimaga thĩinĩ wake na ũkamahonia othe.
Gbogbo ìjọ ènìyàn sì ń fẹ́ láti fọwọ́ kàn án, nítorí tí àṣẹ ń jáde lára rẹ̀, ó sì mú gbogbo wọn láradá.
20 Nake akĩrora arutwo ake, akiuga atĩrĩ: “Kũrathimwo-rĩ, nĩ inyuĩ athĩĩni, nĩgũkorwo ũthamaki wa Ngai nĩ wanyu.
Nígbà tí ó sì gbé ojú rẹ̀ sókè sí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, ó ní: “Alábùkún fún ni ẹ̀yin òtòṣì, nítorí tiyín ni ìjọba Ọlọ́run.
21 Kũrathimwo-rĩ, nĩ inyuĩ mũhũũtaga rĩu, nĩgũkorwo nĩmũkahũũnio. Kũrathimwo-rĩ, nĩ inyuĩ mũrarĩra rĩu, nĩgũkorwo nĩmũgatheka.
Alábùkún fún ni ẹ̀yin tí ebi ń pa nísinsin yìí; nítorí tí ẹ ó yóò. Alábùkún fún ni ẹ̀yin tí ń sọkún nísinsin yìí: nítorí tí ẹ̀yin ó rẹ́rìn-ín.
22 Kũrathimwo-rĩ, nĩ inyuĩ hĩndĩ ĩrĩa andũ mekũmũmena, na meyamũre kũrĩ inyuĩ, na mamũrume, na mathũkĩrĩrie rĩĩtwa rĩanyu, nĩ ũndũ wa Mũrũ wa Mũndũ.
Alábùkún fún ni ẹ̀yin, nígbà tí àwọn ènìyàn bá kórìíra yín, tí wọ́n bá yà yín kúrò nínú ẹgbẹ́ wọn, tí wọ́n bá gàn yín, tí wọ́n bá ta orúkọ yín nù bí ohun búburú, nítorí Ọmọ Ènìyàn.
23 “Mũthenya ũcio nĩmũgakena na mũrũgarũge, tondũ mũcaara wanyu nĩ mũingĩ Igũrũ. Nĩgũkorwo ũguo noguo maithe mao meekire anabii.
“Ẹ jẹ́ kí inú yín dùn, kí ẹ sì fò fún ayọ̀, nítorí púpọ̀ ní èrè yín ni ọ̀run. Báyìí ni àwọn baba yín ṣe ṣe sí àwọn wòlíì.
24 “No rĩrĩ, kaĩ mũrĩ na haaro inyuĩ itonga-ĩ, nĩgũkorwo nĩmũrĩkĩtie kwamũkĩra kũnyamarũrwo kwanyu.
“Ègbé ni fún ẹ̀yin ọlọ́rọ̀ nítorí ẹ ti gba ìtùnú yín.
25 Kaĩ mũrĩ na haaro inyuĩ arĩa mũhũũniĩ rĩu-ĩ, nĩgũkorwo nĩmũkahũũta. Kaĩ mũrĩ na haaro arĩa mũratheka rĩu-ĩ, nĩgũkorwo nĩmũgacakaya na mũrĩre.
Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ó yó, nítorí ebi yóò pa yín, Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ń rẹ́rìn-ín nísinsin yìí, nítorí tí ẹ̀yin ó ṣọ̀fọ̀, ẹ̀yin ó sì sọkún.
26 Kaĩ mũrĩ na haaro inyuĩ hĩndĩ ĩrĩa andũ othe mekũmũgaathĩrĩria-ĩ, nĩgũkorwo ũguo noguo maithe mao meekaga anabii a maheeni.
Ègbé ni fún yín, nígbà tí gbogbo ènìyàn bá ń sọ̀rọ̀ yín ní rere, nítorí bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni àwọn baba wọn ṣe sí àwọn wòlíì èké.
27 “No ngũmwĩra atĩrĩ inyuĩ arĩa mũũthikĩrĩirie: endagai thũ cianyu, na mwĩkage wega arĩa mamũthũire,
“Ṣùgbọ́n mo wí fún ẹ̀yin tí ń gbọ́ mi, ẹ fẹ́ àwọn ọ̀tá yín, ṣoore fún àwọn tí ó kórìíra yín.
28 na ningĩ mũrathimage arĩa mamũrumaga, na mũhooyagĩre arĩa mamwĩkaga ũũru.
Súre fún àwọn tí ń fi yín ré, sì gbàdúrà fún àwọn tí ń kẹ́gàn yín.
29 Na rĩrĩ, mũndũ angĩkũgũtha rũthĩa rũmwe, mũhũgũkĩrie rũu rũngĩ o naruo. Na mũndũ angĩgũtunya igooti rĩaku, ndũkamũgirie kuoya o na kanjũ yaku.
Ẹni tí ó bá sì lù ọ́ ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ kan, yí kejì sí i pẹ̀lú; àti ẹni tí ó gba agbádá rẹ, má ṣe dá a dúró láti gba ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ pẹ̀lú.
30 Mũndũ o wothe angĩkũhooya kĩndũ mũhe, na mũndũ o wothe angĩoya kĩndũ gĩaku, ndũkamwĩtie.
Sì fi fún gbogbo ẹni tí ó tọrọ lọ́dọ̀ rẹ; lọ́dọ̀ ẹni tí ó sì kó ọ ní ẹrù, má sì ṣe padà béèrè.
31 Ĩkagai andũ arĩa angĩ o ũrĩa mũngĩenda mamwĩkage.
Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin sì ti fẹ́ kí ènìyàn ṣe sí yín, kí ẹ̀yin sì ṣe bẹ́ẹ̀ sí wọn pẹ̀lú.
32 “Rĩu-rĩ, angĩkorwo mwendete o arĩa mamwendete-rĩ, mwakĩĩguna na kĩ? O na ‘ehia’ nĩmendaga arĩa mamendete.
“Ǹjẹ́ bí ẹ̀yin bá fẹ́ àwọn tí ó fẹ́ yín, ọpẹ́ kí ni ẹ̀yin ní? Àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pẹ̀lú ń fẹ́ àwọn tí ó fẹ́ wọn.
33 Na mũngĩkorwo mwĩkaga wega o arĩa mamwĩkaga wega-rĩ, mwakĩĩguna na kĩ? Nĩgũkorwo ehia o nao nĩmekaga o ũguo.
Bí ẹ̀yin sì ṣoore fún àwọn tí ó ṣoore fún yín, ọpẹ́ kín ni ẹ̀yin ní? Àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pẹ̀lú ń ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.
34 Na ningĩ mũngĩkorwo mũkombithagia o arĩa mwĩhokete nĩmakamũrĩha-rĩ, mwakĩĩguna na kĩ? O na ehia nĩmakombagĩra ehia arĩa angĩ, mehokete nĩmakarĩhwo ciothe.
Bí ẹ̀yin bá fi fún ẹni tí ẹ̀yin ń retí láti rí gbà padà, ọpẹ́ kín ni ẹ̀yin ní? Àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pẹ̀lú ń yá ẹlẹ́ṣẹ̀, kí wọn lè gba ìwọ̀n bẹ́ẹ̀ padà.
35 No rĩrĩ, endagai thũ cianyu, na mũciĩkage wega, o na mũkombithagie mũtekwĩhoka gũcookerio kĩndũ. Hĩndĩ ĩyo irĩhi rĩanyu nĩrĩkaneneha, na inyuĩ nĩmũgatuĩka ariũ a Ũrĩa-ũrĩ-Igũrũ-Mũno, nĩgũkorwo we nĩaiguagĩra arĩa matarĩ ngaatho tha o na arĩa aaganu.
Ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin fẹ́ àwọn ọ̀tá yín kí ẹ sì ṣoore, kí ẹ̀yin sì yá ẹlòmíràn, kí ẹ̀yin má ṣe retí láti rí nǹkan gbà padà; èrè yín yóò sì pọ̀, àwọn ọmọ Ọ̀gá-ògo ni a ó sì máa pè yín: nítorí tí ó ṣe rere fún aláìmoore àti fún ẹni búburú.
36 Iguanagĩrai tha, o ta ũrĩa Ithe wanyu aiguanagĩra tha.
Ǹjẹ́ kí ẹ̀yin ní àánú, gẹ́gẹ́ bí Baba yín sì ti ní àánú.
37 “Mũtigaciirithanagie nĩgeetha na inyuĩ mũtikanaciirithio. Mũtigatuanagĩre, nĩgeetha na inyuĩ mũtikanatuĩrwo. Rekanagĩrai, na inyuĩ nĩmũkarekerwo.
“Ẹ má ṣe dá ni lẹ́jọ́, a kì yóò sì dá yín lẹ́jọ́: ẹ má ṣe dá ni lẹ́bi, a kì yóò sì dá yín lẹ́bi: ẹ dáríjì, a ó sì dáríjì yín.
38 Heanagai, na inyuĩ nĩmũrĩheagwo na gĩthimi kĩega, gĩkindĩrĩtwo, kĩinainĩtio na gĩgaitĩkĩrĩra, nĩkĩo mũgaitĩrĩrwo nakĩo nguo-inĩ. Nĩgũkorwo gĩthimi kĩrĩa mũthimanagĩra nakĩo, no kĩo mũrĩthimagĩrwo nakĩo.”
Ẹ fi fún ni, a ó sì fi fún yín; òsùwọ̀n dáradára, àkìmọ́lẹ̀, àti àmìpọ̀, àkúnwọ́sílẹ̀, ni a ó wọ́n si àyà yín: nítorí òsùwọ̀n náà tí ẹ̀yin fi wọ́n, òun ni a ó padà fi wọ́n fún yín.”
39 Agĩcooka akĩmahe ngerekano ĩno, akĩmooria atĩrĩ, “Mũtumumu no atongorie mũtumumu ũrĩa ũngĩ? Githĩ eerĩ to magũe irima?
Ó sì pa òwe kan fún wọn wí pé, “Afọ́jú ha lè ṣe amọ̀nà afọ́jú bí? Àwọn méjèèjì kọ́ ni yóò ṣubú sínú ihò bí?
40 Mũrutwo ti mũnene kũrĩ mũmũruti, no ũrĩa wothe mũrute wega, no atuĩke ta mũmũruti.
Ẹni tí a ń kọ́ kì í ju olùkọ́ rẹ̀ lọ: ṣùgbọ́n olúkúlùkù ẹni tí a bá kọ dáradára, yóò dàbí olùkọ́ rẹ̀.
41 “Nĩ kĩĩ gĩgũtũma wone kĩhuti kĩrĩa kĩrĩ riitho rĩa mũrũ wa thoguo, no ũkaaga kũrũmbũiya mũgogo ũrĩa ũrĩ riitho rĩaku we mwene?
“Èétiṣe tí ìwọ fi ń wo ẹ̀rún igi tí ń bẹ ní ojú arákùnrin rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ kò kíyèsi ìtì igi tí ń bẹ ní ojú ara rẹ?
42 Wahota atĩa kwĩra mũrũ wa thoguo atĩrĩ, ‘Mũrũ wa baba, reke ngũrute kĩhuti kĩu kĩrĩ riitho rĩaku,’ o rĩrĩa wee wagĩte kuona mũgogo ũrĩa ũrĩ naguo riitho rĩaku? Wee hinga ĩno, amba ũrute mũgogo ũcio ũrĩ naguo riitho, nĩguo wone wega ũhote kũruta kĩhuti kĩrĩa kĩrĩ riitho rĩa mũrũ wa thoguo.
Tàbí ìwọ ó ti ṣe lè wí fún arákùnrin rẹ pé, ‘Arákùnrin, jẹ́ kí èmi yọ ẹ̀rún igi tí ń bẹ lójú rẹ,’ nígbà tí ìwọ tìkára rẹ kò kíyèsi ìtì igi tí ń bẹ lójú rẹ? Ìwọ àgàbàgebè, kọ́kọ́ yọ ìtí igi jáde kúrò lójú ara rẹ ná, nígbà náà ni ìwọ ó sì tó ríran gbangba láti yọ èérún igi tí ń bẹ lójú arákùnrin rẹ kúrò.
43 “Gũtirĩ mũtĩ mwega ũciaraga maciaro mooru, kana mũtĩ mũũru ũgaciara maciaro mega.
“Nítorí igi rere kì í so èso búburú; bẹ́ẹ̀ ni igi búburú kì í so èso rere.
44 O mũtĩ ũmenyekaga na maciaro maguo mwene. Andũ matituaga ngũyũ kuuma mĩtĩ-inĩ ya mĩigua, o na kana magatua thabibũ kuuma congʼe-inĩ.
Olúkúlùkù igi ni a ń fi èso rẹ̀ mọ̀ ọn; nítorí lórí ẹ̀gún òṣùṣú, ènìyàn kì í ká èso ọ̀pọ̀tọ́ bẹ́ẹ̀ ni lórí ẹ̀gún ọ̀gàn a kì í ká èso àjàrà.
45 Mũndũ ũrĩa mwega aragia maũndũ mega kuuma mũthiithũ-inĩ wa ngoro yake, nake mũndũ ũrĩa mũũru aragia maũndũ mooru kuuma mũthiithũ-inĩ wa ngoro yake. Nĩgũkorwo kanua gake kaaragia o maũndũ marĩa maiyũrĩte ngoro yake.
Ènìyàn rere láti inú yàrá ìṣúra rere ọkàn rẹ̀ ní mú ohun rere jáde wá; àti ènìyàn búburú láti inú ìṣúra búburú ọkàn rẹ̀ ní í mú ohun búburú jáde wá: nítorí láti inú ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ọkàn ní ẹnu ti máa sọ jáde.
46 “Atĩrĩrĩ, mũnjĩtaga ‘Mwathani, Mwathani,’ nĩkĩ, na mũtiĩkaga ũrĩa ndĩmwĩraga?
“Nítorí náà, èéṣe tí ẹ̀yin ń pè mí ní, ‘Olúwa, Olúwa,’ tí ẹ̀yin kò sì ṣe ohun tí mo wí?
47 Nĩngũmuonia ũrĩa mũndũ ũrĩa ũũkaga kũrĩ niĩ, na akaigua ciugo ciakwa, na ageeka ũrĩa ciugĩte ahaana.
Ẹnikẹ́ni tí ó tọ̀ mí wá, tí ó sì ń gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí ó sì ń ṣe é, èmi yóò fi ẹni tí ó jọ hàn yín.
48 Ahaana ta mũndũ waakaga nyũmba, ũrĩa wenjire mũthingi, akĩũrikia na akĩwamba igũrũ rĩa ihiga. Hĩndĩ ĩrĩa kwagĩire mũiyũro wa maaĩ, kĩguũ gĩkĩgũtha nyũmba ĩyo na nditi, no gĩtiamĩenyenyirie, tondũ nĩyaakĩtwo wega.
Ó jọ ọkùnrin kan, tí ó kọ́ ilé, tí ó sì wa ilẹ̀ jìn, tí ó sì fi ìpìlẹ̀ sọlẹ̀ lórí àpáta, nígbà tí kíkún omi sì dé, ìgbì omi kọlu ilé náà, kò sì lè mì ín nítorí tí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ lórí àpáta.
49 No mũndũ ũrĩa ũiguaga ciugo ciakwa, na ndekaga ũrĩa ciugĩte, ahaana ta mũndũ ũrĩa waakire nyũmba ĩtarĩ na mũthingi. Na rĩrĩa kĩguũ kĩagũthire nyũmba ĩyo, ĩkĩmomoka, naguo mwanangĩko wayo warĩ mũnene.”
Ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́, tí kò sì ṣe é, ó dàbí ọkùnrin tí ó kọ́ ilé sí orí ilẹ̀ láìní ìpìlẹ̀; nígbà tí ìgbì omi kọlù ú, lọ́gán, ó sì wó; wíwó ilé náà sì pọ̀ púpọ̀.”

< Luka 6 >