< Luka 5 >

1 Na rĩrĩ, mũthenya ũmwe Jesũ arũngiĩ hũgũrũrũ-inĩ cia iria rĩa Genesareti, nakĩo kĩrĩndĩ kĩa andũ aingĩ nĩkĩahatĩkanaga kĩmũkuhĩrĩrie nĩguo gĩthikĩrĩrie ũhoro wa Ngai,
Ó sì ṣe, nígbà tí ìjọ ènìyàn súnmọ́ ọn láti gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, tí ó sì dúró létí adágún Genesareti.
2 nake akĩona tũtarũ twĩrĩ hũgũrũrũ-inĩ cia iria rĩu, tũtigĩtwo ho nĩ ategi a thamaki, arĩa maathambagia neti ciao cia gũtega.
Ó rí ọkọ̀ méjì ti o wá létí adágún: èyí tí àwọn apẹja ti sọ̀kalẹ̀ kúrò nínú wọn, nítorí tí wọ́n ń fọ àwọ̀n wọn.
3 Agĩtoonya gatarũ kamwe, nako kaarĩ ga Simoni, akĩmũthaitha agatoonyatoonyie maaĩ-inĩ, kehere hũgũrũrũ-inĩ. Agĩcooka agĩikara thĩ, akĩambĩrĩria kũruta andũ ũhoro arĩ gatarũ-inĩ kau.
Ó sì wọ ọ̀kan nínú àwọn ọkọ̀ náà, tí í ṣe ti Simoni, ó sì bẹ̀ ẹ́ kí ó tì í sí ẹ̀yìn díẹ̀ kúrò ní ilẹ̀. Ó sì jókòó, ó sì ń kọ́ ìjọ ènìyàn láti inú ọkọ̀ náà.
4 Na aarĩkia kwaria, akĩĩra Simoni atĩrĩ, “Twara gatarũ haarĩa hariku, mũikũrũkie neti maaĩ-inĩ, mũtege thamaki.”
Bí ó sì ti dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ, ó wí fún Simoni pé, “Tì í sí ibú, kí o sì ju àwọ̀n yín sí ìsàlẹ̀ fún àkópọ̀.”
5 Nake Simoni akĩmũcookeria atĩrĩ, “Mwathi witũ, tũrutĩte wĩra mũritũ ũtukũ wothe, na tũtinanyiita kĩndũ o na kĩ. No tondũ nĩwoiga ũguo-rĩ, nĩngũikũrũkia neti.”
Simoni sì dáhùn ó sì wí fún un pé, “Olùkọ́ni, gbogbo òru ni àwa fi ṣiṣẹ́, àwa kò sì mú nǹkan kan: ṣùgbọ́n nítorí ọ̀rọ̀ rẹ èmi ó ju àwọ̀n náà sí ìsàlẹ̀.”
6 Maarĩkia gwĩka ũguo, makĩnyiita thamaki nyingĩ mũno, nginya neti ciao ikĩambĩrĩria gũtuĩka.
Nígbà tí wọ́n sì ti ṣe èyí, wọ́n kó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹja: àwọ̀n wọn sì ya.
7 Nĩ ũndũ ũcio makĩheneria arĩa maarutithanagia wĩra nao, arĩa maarĩ gatarũ kau kangĩ moke mamateithie, nao magĩũka makĩiyũria tũtarũ twerĩ ki, o nginya tũkĩambĩrĩria gũtoonyerera maaĩ-inĩ.
Wọ́n sì pe àwọn ẹgbẹ́ wọn, tí ó wà nínú ọkọ̀ kejì, kí wọn kí ó wá ràn wọ́n lọ́wọ́. Wọ́n sì wá, wọ́n kó ẹja ọkọ̀ méjèèjì sì kún, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í rì.
8 Hĩndĩ ĩrĩa Simoni Petero onire ũguo, akĩĩgũithia maru-inĩ ma Jesũ, akĩmwĩra atĩrĩ, “Njeherera Mwathani; niĩ ndĩ mũndũ mwĩhia!”
Nígbà tí Simoni Peteru sì rí i, ó wólẹ̀ lẹ́bàá eékún Jesu, ó wí pé, “Lọ kúrò lọ́dọ̀ mi Olúwa; nítorí ẹlẹ́ṣẹ̀ ni mí.”
9 Nĩgũkorwo we na arĩa othe maarĩ nao nĩmagegire mũno nĩ ũndũ wa thamaki iria maanyiitĩte,
Ẹnu sì yà wọ́n, àti gbogbo àwọn tí ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀, fún àkópọ̀ ẹja tí wọ́n kó,
10 o na Jakubu na Johana, ariũ a Zebedi, arĩa maarutithanagia wĩra na Simoni nĩmagegire. Nake Jesũ akĩĩra Simoni atĩrĩ, “Tiga gwĩtigĩra; kuuma rĩu ũrĩtegaga andũ.”
bẹ́ẹ̀ ni Jakọbu àti Johanu àwọn ọmọ Sebede, tí ń ṣe alábákẹ́gbẹ́ Simoni. Jesu sì wí fún Simoni pé, “Má bẹ̀rù; láti ìsinsin yìí lọ ìwọ ó máa mú ènìyàn.”
11 Nĩ ũndũ ũcio makiumĩria tũtarũ twao hũgũrũrũ-inĩ cia iria, magĩtiga indo ciao ciothe, makĩmũrũmĩrĩra.
Nígbà tí wọ́n sì ti mú ọkọ̀ wọn dé ilẹ̀, wọ́n fi gbogbo rẹ̀ sílẹ̀, wọ́n sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn lọ.
12 Na rĩrĩ, hĩndĩ ĩmwe rĩrĩa Jesũ aarĩ itũũra-inĩ rĩmwe-rĩ, nĩguokire mũndũ waiyũrĩtwo nĩ mangũ mwĩrĩ wothe. Na rĩrĩa onire Jesũ, akĩĩgũithia, agĩturumithia ũthiũ wake thĩ, akĩmũthaitha, akĩmwĩra atĩrĩ, “Mwathani, ũngĩenda-rĩ, no ũũtherie.”
Ó sì ṣe, nígbà tí Jesu wọ ọ̀kan nínú àwọn ìlú náà, kíyèsi i, ọkùnrin kan tí ẹ̀tẹ̀ bò wa síbẹ̀: nígbà tí ó rí Jesu, ó wólẹ̀, ó sì ń bẹ̀ ẹ́, wí pé, “Olúwa, bí ìwọ bá fẹ́, ìwọ lè sọ mí di mímọ́.”
13 Jesũ agĩtambũrũkia guoko gwake, akĩhutia mũndũ ũcio, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ĩĩ, nĩngwenda. Therio!” Na o hĩndĩ ĩyo akĩhonio mangũ.
Jesu sì na ọwọ́ rẹ̀, ó fi kàn án, ó ní, “Mo fẹ́, ìwọ di mímọ́!” Lójúkan náà ẹ̀tẹ̀ sì fi í sílẹ̀ lọ.
14 Jesũ agĩcooka akĩmũkaania, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ndũkeere mũndũ o na ũ, no thiĩ, ũkeyonanie kũrĩ mũthĩnjĩri-Ngai, na ũrute magongona marĩa Musa aathanire nĩ ũndũ wa gũtherio gwaku, arĩ ũira kũrĩ o.”
Ó sì kìlọ̀ fún u pé, “Kí ó má ṣe sọ fún ẹnìkan: ṣùgbọ́n kí ó lọ, kí ó sì fi ara rẹ̀ hàn fún àlùfáà, kí ó sì ta ọrẹ fún ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Mose ti pàṣẹ gẹ́gẹ́ bi ẹ̀rí fun wọn.”
15 Na rĩrĩ, ngumo yake ĩgĩkĩrĩrĩria kũhunja makĩria, o nginya kĩrĩndĩ kĩingĩ ma kĩa andũ gĩgĩũka kũmũthikĩrĩria na kũhonio mĩrimũ yao.
Ṣùgbọ́n òkìkí rẹ̀ ń kàn kálẹ̀: tó bẹ́ẹ̀ tí ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn sì jùmọ̀ pàdé láti gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀, àti láti gba ìwòsàn lọ́dọ̀ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ àìlera wọn.
16 No Jesũ nĩeheragĩra andũ, agathiĩ kũndũ gũtarĩ andũ kũhoera Ngai kuo.
Ṣùgbọ́n lọ́pọ̀ ìgbà ni Jesu a máa yẹra kúrò si ibi ìdákẹ́rọ́rọ́, òun á sì máa dá wà láti gbàdúrà.
17 Mũthenya ũmwe nĩ kũrutana aarutanaga, nao Afarisai na arutani a watho arĩa mookĩte kuuma matũũra mothe ma Galili, na Judea, na Jerusalemu, maikarĩte thĩ hau. Naguo hinya wa Ngai wa kũhonania warĩ hamwe na Jesũ.
Ní ọjọ́ kan, bí ó sì ti ń kọ́ni, àwọn Farisi àti àwọn amòfin jókòó pẹ̀lú rẹ̀, àwọn tí ó ti àwọn ìletò Galili gbogbo, àti Judea, àti Jerusalẹmu wá: agbára Olúwa sì ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀ láti mú wọn láradá.
18 Na rĩrĩ, nĩhookire andũ makuuĩte mũndũ na kĩbarĩ, warũarĩte mũrimũ wa gũkua ciĩga, nao makĩgeria kũmũtoonyia nyũmba mamũige harĩ Jesũ.
Sá à sì kíyèsi i, àwọn ọkùnrin kan gbé ẹnìkan tí ó ní ààrùn ẹ̀gbà wà lórí àkéte: wọ́n ń wá ọ̀nà àti gbé e wọlé, àti láti tẹ́ ẹ síwájú Jesu.
19 Na rĩrĩa maagire njĩra ya gwĩka ũguo nĩ ũndũ wa ũingĩ wa andũ, makĩhaica nyũmba-igũrũ magĩtharia maturubarĩ, makĩmũikũrũkĩria mwanya-inĩ ũcio o arĩ kĩbarĩ-inĩ, nginya gatagatĩ-inĩ ka andũ acio makĩmũiga o hau Jesũ aarĩ.
Nígbà tí wọn kò sì rí ọ̀nà tí wọn ìbá fi gbé e wọlé nítorí ìjọ ènìyàn, wọ́n gbé e gun òkè àjà ilé lọ, wọ́n sọ̀ ọ́ kalẹ̀ sí àárín èrò ti òun ti àkéte rẹ̀ níwájú Jesu.
20 Rĩrĩa Jesũ onire wĩtĩkio wao, akĩmwĩra atĩrĩ, “Mũrata, nĩwarekerwo mehia maku.”
Nígbà tí ó sì rí ìgbàgbọ́ wọn, ó wí pé, “Ọkùnrin yìí, a darí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jì ọ́.”
21 Nao Afarisai na arutani a watho makĩambĩrĩria gwĩciiria ngoro-inĩ ciao, makiuga atĩrĩ, “Kaĩ mũndũ ũyũ arĩ ũ, ũkũruma Ngai? Nũũ ũngĩhota kũrekanĩra mehia, tiga Ngai we wiki?”
Àwọn akọ̀wé àti àwọn Farisi bẹ̀rẹ̀ sí í gbèrò wí pé, “Ta ni eléyìí tí ń sọ ọ̀rọ̀-òdì? Ta ni ó lè dárí ẹ̀ṣẹ̀ ji ni bí kò ṣe Ọlọ́run nìkan ṣoṣo.”
22 Nowe Jesũ nĩamenyaga ũrĩa meeciiragia na akĩmooria atĩrĩ, “Mũreciiria maũndũ macio ngoro-inĩ cianyu nĩkĩ?
Jesu sì mọ èrò inú wọn, ó dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ẹ fi ń ro nǹkan wọ̀nyí nínú ọkàn yín?
23 Nĩ ũndũ ũrĩkũ mũhũthũ; nĩ kwĩra mũndũ, ‘Nĩwarekerwo mehia maku,’ kana nĩ kũmwĩra, ‘Ũkĩra wĩtware’?
Èwo ni ó yá jù: láti wí pé, ‘A dárí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jì ọ́,’ tàbí láti wí pé, ‘Dìde kí ìwọ sì máa rìn’?
24 No nĩgeetha mũmenye atĩ Mũrũ wa Mũndũ arĩ na ũhoti gũkũ thĩ wa kũrekanĩra mehia-rĩ ….” Akĩĩra mũndũ ũcio wakuĩte ciĩga atĩrĩ, “Ndakwĩra atĩrĩ, ũkĩra, oya kĩbarĩ gĩaku, ũinũke.”
Ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin lè mọ̀ pé Ọmọ Ènìyàn ní agbára ní ayé láti dárí ẹ̀ṣẹ̀ ji ni.” Ó wí fún ẹlẹ́gbà náà pé, “Mo wí fún ọ, dìde, sì gbé àkéte rẹ, kí o sì máa lọ sí ilé!”
25 O hau hau akĩrũgama mbere yao, akĩoya kĩbarĩ kĩrĩa akomeire, na akĩinũka mũciĩ akĩgoocaga Ngai.
Ó sì dìde lọ́gán níwájú wọn, ó gbé ohun tí ó dùbúlẹ̀ lé, ó sì lọ sí ilé rẹ̀, ó yin Ọlọ́run lógo.
26 Nao andũ othe nĩmagegire na magĩkumia Ngai. Makĩiyũrwo nĩ guoya, makiuga atĩrĩ, “Ũmũthĩ nĩtuonete maũndũ tũtarĩ tuona.”
Ẹnu sì ya gbogbo wọn, wọ́n sì yin Ọlọ́run lógo, ẹ̀rù sì bà wọ́n, wọ́n ń wí pé, “Àwa rí ohun ìyanu lónìí.”
27 Thuutha wa ũguo, Jesũ akiumagara na akĩona mũndũ warĩ mwĩtia wa mbeeca cia igooti wetagwo Lawi aikarĩte harĩa heetagĩrio mbeeca cia igooti. Jesũ akĩmwĩra atĩrĩ, “Nũmĩrĩra.”
Lẹ́hìn èyí, Jesu jáde lọ, ó sì rí agbowó òde kan tí à ń pè ní Lefi, ó jókòó sí ibi tí ó ti ń gba owó òde, Jesu sì wí fún un pé, “Tẹ̀lé mi,”
28 Nake Lawi agĩũkĩra, agĩtiga indo ciake ciothe, akĩmũrũmĩrĩra.
Lefi sì fi ohun gbogbo sílẹ̀ ó sì ń tẹ̀lé e.
29 Lawi agĩcooka akĩrugithĩria Jesũ iruga inene gwake mũciĩ, na gĩkundi kĩnene kĩa etia mbeeca cia igooti o na andũ angĩ nĩmarĩĩanagĩra nao.
Lefi sì ṣe àsè ńlá kan fún Jesu ní ilé rẹ̀, ọ̀pọ̀ àwọn agbowó òde àti àwọn mìíràn sì ń jẹun pẹ̀lú wọn.
30 No Afarisai na arutani a watho arĩa maarĩ a gĩkundi kĩao magĩtetia arutwo ake makĩmooria atĩrĩ, “Mũrĩĩanagĩra na mũkanyuuanĩra na etia mbeeca cia igooti na andũ ehia nĩkĩ?”
Ṣùgbọ́n àwọn Farisi, àwọn olùkọ́ òfin tí ó jẹ́ ara wọn fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ-ẹ̀yìn pe, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń jẹun tí ẹ sì ń mú pẹ̀lú àwọn agbowó òde àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.”
31 Nake Jesũ akĩmacookeria atĩrĩ, “Andũ arĩa agima mĩĩrĩ tio mabataragio nĩ ndagĩtarĩ, no nĩ arĩa arũaru.
Jesu dáhùn ó wí fún wọn pé, “Ẹni tí ara rẹ̀ le kò nílò oníṣègùn, bí kò ṣe ẹni tí ara rẹ̀ kò dá.
32 Niĩ ndiokire gwĩta andũ arĩa athingu, no nĩ arĩa ehia, nĩguo merire.”
Èmí kò wá láti pe àwọn olódodo bí kò ṣe àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ sí ìrònúpìwàdà.”
33 Nao makĩmwĩra atĩrĩ, “Arutwo a Johana nĩ meehingaga kũrĩa irio kaingĩ kaingĩ makahooya, o nao arutwo a Afarisai nĩmekaga o ũguo, no aku marĩĩaga na makanyua hĩndĩ ciothe.”
Wọ́n wí fún pé, “Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu a máa gbààwẹ̀, wọn a sì máa gbàdúrà, bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú sì ni àwọn ọmọ-ẹ̀yìn àwọn Farisi ṣùgbọ́n àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ a máa jẹ, wọn a sì máa mu pẹ̀lú.”
34 Nake Jesũ akĩmacookeria atĩrĩ, “No mwĩre ageni a mũhikania mehinge kũrĩa rĩrĩa e hamwe nao?
Jesu sì dáhùn ó wí fún wọn pé, “Ǹjẹ́ ó ṣe é ṣe kí àwọn àlejò ọkọ ìyàwó máa gbààwẹ̀ nígbà tí ọkọ ìyàwó wà pẹ̀lú wọn bí?
35 No rĩrĩ, ihinda nĩrĩgakinya rĩrĩa mũhikania akeeherio kuuma kũrĩ o; matukũ-inĩ macio-rĩ, nĩ makeehinga kũrĩa irio.”
Ṣùgbọ́n àkókò ń bọ̀ nígbà tí a ó gba ọkọ ìyàwó kúrò lọ́dọ̀ wọn, ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí ni wọn yóò gbààwẹ̀.”
36 Ningĩ Jesũ akĩmahe ũhoro na ngerekano ĩno, akĩmeera atĩrĩ, “Gũtirĩ mũndũ ũngĩtinia kĩraka kuuma harĩ nguo njerũ, agĩĩkĩre nguo ngũrũ. Angĩĩka ũguo, angĩkorwo atarũrĩte nguo njerũ, nakĩo kĩraka kĩu kĩa nguo ĩyo njerũ kĩage kwagĩrĩra nguo ĩyo ngũrũ.
Ó sì pa òwe yìí fún wọn wí pé, “Kò sí ẹni tó lè ya aṣọ tuntun kí ó sì rán mọ́, èyí tó ti gbó. Tí ó ba ṣe èyí, yóò ba aṣọ tuntun jẹ́, èyí tí ó tuntun náà kì yóò sì dọ́gba pẹ̀lú èyí tí ó ti gbó.
37 Ningĩ gũtirĩ mũndũ wĩkagĩra ndibei ya mũhihano mondo-inĩ ngũrũ. Angĩka ũguo, ndibei ĩyo ya mũhihano no ĩtarũre mondo icio, ndibei ĩyo ĩitĩke, nacio mondo icio itarũkange.
Àti wí pé, kò sí ẹni tí ó lè dá ọtí wáìnì tuntun sínú ògbólógbòó ìgò-awọ, tí ó bá ṣe èyí, wáìnì tuntun yóò fa awọ náà ya, wáìnì náà yóò dànù, awọ náà a sì bàjẹ́.
38 Aca, ti ta ũguo, ndibei ya mũhihano no nginya ĩĩkĩrwo mondo-inĩ njerũ.
Nítorí náà, ó tọ́ kí á da wáìnì tuntun sínú awọ tuntun.
39 O na gũtirĩ mũndũ thuutha wa kũnyua ndibei ngũrũ ũcookaga kwenda ndibei ĩyo ya mũhihano, nĩ ũndũ oigaga atĩrĩ, ‘Ĩrĩa ngũrũ nĩyo njega.’”
Kò sì ẹni tí yóò fẹ́ láti mu wáìnì tuntun lẹ́yìn tí ó bá ti mu ògbólógbòó tán, nítorí yóò wí pé, ‘Èyí tí ó jẹ́ ògbólógbòó dára jù.’”

< Luka 5 >