< Amosi 7 >

1 Mwathani Jehova aanyonirie ũũ: Nĩkũhaarĩria aharagĩria mĩrumbĩ ya ngigĩ thuutha wa magetha marĩa maagethagĩrwo mũthamaki, o ihinda rĩrĩa kĩmera gĩa keerĩ kĩambagĩrĩria.
Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè fihàn mí: Ó pèsè ọwọ́ eṣú lẹ́yìn ìgbà tí a kórè ìpín ọba, ní ìgbà ti èso ẹ̀ẹ̀kejì ń jáde bọ̀.
2 Ciarĩkia kũrĩa tũhuti tuothe, bũrũri ũgĩthera biũ, ngĩkaya ngiuga atĩrĩ, “Mwathani Jehova, marekere! Jakubu-rĩ, angĩhonoka gĩkuũ atĩa? Nĩgũkorwo nĩ mũnini mũno!”
Nígbà tí wọ́n jẹ koríko ilẹ̀ náà mọ́ féfé nígbà náà ni mo gbé ohùn mi sókè pé, “Olúwa Olódùmarè, mo bẹ̀ ọ́, dáríjì! Báwo ni Jakọbu yóò ha ṣe lè dìde? Òun kéré jọjọ!”
3 Nĩ ũndũ ũcio Jehova akĩigua tha. Jehova akiuga atĩrĩ, “Ũndũ ũcio ndũgwĩkĩka.”
Olúwa ronúpìwàdà nípa èyí. “Èyí kò ni ṣẹlẹ̀,” ni Olúwa wí.
4 Ningĩ Mwathani Jehova akĩnyonia ũũ: Mwathani Jehova nĩ gwĩtia eetagia mwaki amaciirithie naguo; mwaki ũcio ũkĩniaria maaĩ ma kũrĩa kũriku mũno, na ũkĩniina bũrũri.
Èyí ni ohun ti Olúwa Olódùmarè fihàn mí: Olúwa Olódùmarè ń pè fún ìdájọ́ pẹ̀lú iná; ó jó ọ̀gbun ńlá rún, ó sì jẹ ilẹ̀ run.
5 Ningĩ ngĩkaya, ngiuga atĩrĩ, “Mwathani Jehova ndagũthaitha, tiga! Jakubu-rĩ, angĩhonoka gĩkuũ atĩa? Nĩgũkorwo nĩ mũnini mũno!”
Nígbà náà ni mo gbé ohùn mi sókè pé, “Olúwa Olódùmarè jọ̀wọ́ má ṣe ṣe é! Báwo ni Jakọbu yóò ha ṣe lè dìde? Òun kéré jọjọ!”
6 Nĩ ũndũ ũcio Jehova akĩigua tha. Mwathani Jehova akiuga atĩrĩ, “Ũndũ ũcio o naguo ndũgwĩkĩka.”
Olúwa ronúpìwàdà nípa èyí. “Èyí náà kò ní ṣẹlẹ̀,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
7 Ningĩ akĩnyonia ũũ: Mwathani aarũgamĩte rũthingo-inĩ rwakĩtwo na rũgathimwo wega na kabirũ nake anyiitĩte rũrigi rwa kabirũ na guoko.
Èyí ni ohun tí ó fihàn mí: Olúwa dúró ní ẹ̀gbẹ́ odi ti a fi okùn ìwọ̀n mọ́, ti òun ti okùn ìwọ̀n tí ó rún ni ọwọ́ rẹ̀.
8 Nake Jehova akĩnjũũria atĩrĩ, “Amosi, nĩ kĩĩ ũroona”? Na niĩ ngĩmũcookeria atĩrĩ: “Nĩ kabirũ ndĩrona.” Ningĩ Jehova akĩnjĩĩra atĩrĩ, nĩ kabirũ ndĩracuuria gatagatĩ ka andũ akwa a Isiraeli, ndigacooka kũmaiguĩra tha rĩngĩ.
Olúwa sì bi mi pé, “Amosi, kí ni ìwọ rí?” Mo dáhùn pé, “Okùn ìwọ̀n.” Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Wò ó, Èmí ń gbé okùn ìwọ̀n kalẹ̀ láàrín àwọn Israẹli ènìyàn mi; Èmi kì yóò sì tún kọjá lọ́dọ̀ wọn mọ́.
9 “Kũndũ kũrĩa gũtũũgĩru kwa Isaaka nĩgũkaniinwo, na kũndũ kũrĩa kwamũre kwa Isiraeli nĩgũkanangwo; na nĩngokĩrĩra nyũmba ya Jeroboamu na rũhiũ rwakwa rwa njora.”
“Ibi gíga Isaaki wọ̀n-ọn-nì yóò sì di ahoro àti ibi mímọ Israẹli wọ̀n-ọn-nì yóò di ahoro. Èmi yóò sì fi idà dìde sí ilé Jeroboamu.”
10 Nake Amazia mũthĩnjĩri-ngai wa Betheli agĩtũmana kũrĩ Jeroboamu, mũthamaki wa Isiraeli, akĩmwĩra atĩrĩ, “Amosi nĩagũciirĩire agũũkĩrĩre arĩ o gũkũ thĩinĩ wa Isiraeli. Bũrũri ndũngĩhota gũkirĩrĩria ndeto ciake ciothe.
Nígbà náà Amasiah àlùfáà Beteli ránṣẹ́ sí Jeroboamu ọba Israẹli, wí pé: “Amosi ti dìde láti dìtẹ̀ sí ọ ni àárín gbùngbùn Israẹli. Ilẹ̀ kò sì le gba gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀.
11 Nĩgũkorwo Amosi aroiga atĩrĩ: “‘Jeroboamu akooragwo na rũhiũ rwa njora, na ti-itherũ andũ a Isiraeli nĩmagatahwo, matwarwo kũraya na bũrũri wao.’”
Nítorí èyí ni ohun ti Amosi ń sọ: “‘Jeroboamu yóò ti ipa idà kú, lóòtítọ́ Israẹli yóò lọ sí ìgbèkùn, jìnnà kúrò ní ilẹ̀ ìní wọn.’”
12 Ningĩ Amazia akĩĩra Amosi atĩrĩ, “Umagara wee muoni-maũndũ ũyũ! Cooka bũrũri wa Juda. Wĩcaragĩrie gĩa kũrĩa kuo, na ũrathage maũndũ ũrĩ kuo.
Nígbà náà ni Amasiah sọ fún Amosi pé, “Lọ jáde, ìwọ aríran! Padà sí ilẹ̀ àwọn Juda. Kí o máa jẹun rẹ níbẹ̀, kí o sì máa sọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ níbẹ̀.
13 Ndũkaarathĩre ũhoro rĩngĩ gũkũ Betheli tondũ gũkũ nĩkuo kwamũrĩirwo gĩikaro kĩa mũthamaki na hekarũ ya ũthamaki.”
Má ṣe sọtẹ́lẹ̀ mọ ni Beteli nítorí ibi mímọ́ ọba ni àti ibi tẹmpili ìjọba rẹ̀.”
14 Amosi agĩcookeria Amazia atĩrĩ, “Niĩ-rĩ, ndiarĩ mũnabii kana mũrũ wa mũnabii, no ndaarĩ mũrĩithi wa mahiũ na ningĩ mũmenyereri wa mĩkũyũ.
Amosi dá Amasiah lóhùn pé, “Èmi kì í ṣe wòlíì tàbí àwọn ọmọ wòlíì, ṣùgbọ́n mo jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn, mo sì ń ṣe ìtọ́jú igi ọ̀pọ̀tọ́ sikamore.
15 No Jehova akĩnduta rũũru-inĩ rwa mahiũ akĩnjĩĩra atĩrĩ, ‘Thiĩ ũkarathĩre andũ akwa a Isiraeli ũhoro.’
Ṣùgbọ́n Olúwa mu mi bí mo ti ń tọ́ agbo ẹran lẹ́yìn, ó sì wí fun mi pé, ‘Lọ sọtẹ́lẹ̀ fun àwọn Israẹli ènìyàn mi.’
16 Na rĩrĩ, kĩigue ũhoro wa Jehova. Wee ũroiga atĩrĩ, “‘Ndũkarathĩre Isiraeli ũndũ mũũru, na ũtige kũhunjia maũndũ ma gũũkĩrĩra nyũmba ya Isaaka.’
Nítorí náà nísinsin yìí, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Ìwọ wí pé, “‘Má ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí Israẹli, má sì ṣe wàásù sí ilé Isaaki.’
17 “Nĩ ũndũ ũcio Jehova ekuuga ũũ: “‘Mũtumia waku nĩagatuĩka mũmaraya itũũra-inĩ inene, nao aanake aku na airĩtu aku makooragwo na rũhiũ rwa njora. Bũrũri waku ũgaathimwo na ũgayanio, na wee mwene-rĩ, ũgaakuĩra bũrũri wa andũ matooĩ Ngai. Na ti-itherũ andũ a Isiraeli no nginya magaatahwo, matwarwo kũraya na bũrũri wao.’”
“Nítorí náà, èyí ni ohun ti Olúwa wí: “‘Ìyàwó rẹ yóò di panṣágà ni ìlú, àwọn ọmọ ọkùnrin àti obìnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú. A ó fi okùn wọn ilẹ̀ rẹ, a ó sì pín in àti ìwọ pẹ̀lú yóò kú ni ilẹ̀ àìmọ́. Israẹli yóò sì lọ sí ìgbèkùn, kúrò ní ilẹ̀ ìní wọn.’”

< Amosi 7 >