< 2 Athamaki 6 >

1 Na rĩrĩ, thiritũ ya anabii ĩkĩĩra Elisha atĩrĩ, “Rora, handũ haha tũgomanaga nawe nĩ hanini mũno.
Àwọn ọmọ wòlíì sọ fún Eliṣa pé, “Wò ó, ní ibi tí a ti pàdé pẹ̀lú rẹ, ó kéré fún wa.
2 Twĩtĩkĩrie tũthiĩ Jorodani, o mũndũ witũ akuue ĩtugĩ kuo; na ũtwĩtĩkĩrie twake handũ ha gũtũũraga kũu.” Nake akĩmeera atĩrĩ, “Thiĩi.”
Jẹ́ kí àwa kí ó lọ sí Jordani, ní ibi tí ẹnìkọ̀ọ̀kan ti le rí ọ̀pá kan, jẹ́ kí àwa kí ó kọ́lé síbẹ̀ fún wa láti gbé.” Ó sì wí pé, “Lọ.”
3 Ningĩ ũmwe wao akĩmwĩra atĩrĩ, “Ndagũthaitha wĩtĩkĩre gũthiĩ na ndungata ciaku.” Nake Elisha agĩcookia atĩrĩ, “Ĩĩ, nĩtũgũthiĩ na inyuĩ.”
Nígbà náà ni ọ̀kan lára wọn wí pé, “Kí ó wù ọ́, èmí bẹ̀ ọ́, láti bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ?” Eliṣa dá a lóhùn pé, “Èmi yóò lọ,”
4 Nake Elisha agĩthiĩ hamwe nao. Nao magĩthiĩ Jorodani na makĩambĩrĩria gũtema mĩtĩ.
Ó sì lọ pẹ̀lú wọn. Wọ́n sì lọ sí Jordani wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní gé igi.
5 Na rĩrĩa ũmwe wao aatemaga mũtĩ-rĩ, ithanwa rĩkĩgũa maaĩ-inĩ. Nake agĩkaya, akiuga atĩrĩ, “Mwathi wakwa, riuma rĩa kũhooya!”
Bí ọ̀kan ṣe gé igi náà, àáké irin náà bọ́ sínú omi, ó kígbe sókè pé, “O! Olúwa mi, mo yá a ni!”
6 Nake mũndũ wa Ngai akĩũria atĩrĩ, “Rĩagũa ha?” Na rĩrĩa aamuonirie handũ hau, Elisha agĩtinia kamũtĩ, agĩgaikia ho, narĩo ithanwa rĩkĩrera maaĩ igũrũ.
Ènìyàn Ọlọ́run sì béèrè pé, “Níbo ni ó bọ́ sí?” Nígbà tí ó fi ibẹ̀ hàn án, Eliṣa gé igi kan ó sì jù ú síbẹ̀, ó sì mú irin náà fò lójú omi.
7 Nake akĩmwĩra atĩrĩ, “Oya ithanwa.” Nake mũndũ ũcio agĩtambũrũkia guoko, akĩrĩoya.
Ó wí pé, “Gbé e jáde.” Lẹ́yìn náà ọkùnrin náà na ọwọ́ rẹ̀ jáde ó sì mú un.
8 Na rĩrĩ, mũthamaki wa Suriata aarĩ na mbaara na andũ a Isiraeli. Thuutha wa kũrĩkanĩra na anene ake, akĩmeera atĩrĩ, “Ngwamba kambĩ handũ hana na hana.”
Nísinsin yìí ọba Aramu wà ní ogun pẹ̀lú Israẹli ó sì bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ gbèrò, ó wí pé, “Èmi yóò ṣe ibùdó mi sí ibí yìí nínú èyí náà àti bí ibí yìí.”
9 Mũndũ wa Ngai agĩtũmana kũrĩ mũthamaki wa Isiraeli, akĩmwĩra atĩrĩ, “Wĩhũũge, na ndũkagerere handũ hana tondũ andũ a Suriata nĩho maraikũrũkĩra.”
Ènìyàn Ọlọ́run rán iṣẹ́ sí ọba Israẹli pé, “Kíyèsi ara láti kọjá ní ibẹ̀ yẹn, nítorí pé ará Aramu wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ síbẹ̀.”
10 Nĩ ũndũ ũcio mũthamaki wa Isiraeli agĩtũma andũ magatuĩrie ũhoro wa handũ hau mũndũ wa Ngai aarĩtie ũhoro waho. Mahinda maingĩ Elisha nĩeragĩra mũthamaki wa Isiraeli kũndũ kũrĩa aagĩrĩirwo nĩ kwĩmenyerera, nake agaikaraga ehũũgĩte.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli wo ibi tí ènìyàn Ọlọ́run náà fihàn, ní ẹ̀ẹ̀kan sí i Eliṣa kìlọ̀ fún ọba, bẹ́ẹ̀ ni ó wà lórí sísọ ní ibẹ̀.
11 Ũndũ ũcio ũkĩrakaria mũthamaki wa Suriata mũno. Nake agĩĩta anene ake na akĩmeera atĩrĩ, “Ngwenda kũmenya kuuma kũrĩ inyuĩ ũũ, nũũ witũ ũrĩ mwena wa mũthamaki wa Isiraeli?”
Èyí mú ọba Aramu bínú. Ó pe àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣé ìwọ kò ní sọ fún mi èwo nínú wa ni ó wà ní ẹ̀gbẹ́ ọba Israẹli?”
12 Nake ũmwe wa anene ake akĩmwĩra atĩrĩ, “Mũthamaki mwathi wakwa, gũtirĩ o na ũmwe witũ ũrĩ mwena wake. No rĩrĩ, Elisha ũrĩa mũnabii kũu Isiraeli nĩwe wĩraga mũthamaki wa Isiraeli ciugo nginya iria waragia ũrĩ nyũmba yaku ya toro.”
Ọ̀kan lára ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí pé, “Kò sí ọ̀kan nínú wa, olúwa ọba mi, ṣùgbọ́n Eliṣa, wòlíì tí ó wà ní Israẹli, sọ fún ọba Israẹli ọ̀rọ̀ gangan tí ó sọ nínú yàrá rẹ̀.”
13 Nake mũthamaki agĩathana, akiuga atĩrĩ, “Thiĩi mũgatuĩrie kũrĩa arĩ, nĩguo ndũme andũ mamũnyiite.” Nake mũthamaki agĩcookerio ũhoro akĩĩrwo atĩrĩ, “Elisha arĩ Dothani.”
Ọba pa á láṣẹ, “Lọ, kí ẹ lọ wo ibi tí ó wà, kí èmi kí ó lè rán ènìyàn láti lọ mú un wá.” Ìròyìn padà wá wí pé, “Ó wà ní Dotani.”
14 Nake mũthamaki agĩtũma mbarathi na ngaari cia ita, na mbũtũ yarĩ na hinya kũu. Igĩthiĩ ũtukũ, ikĩrigiicĩria itũũra rĩu.
Nígbà náà ni ó rán àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ àti ogun ńlá tí ó le síbẹ̀. Wọ́n sì lọ ní alẹ́ wọ́n sì yí ìlú náà ká.
15 Na rĩrĩa ndungata ya mũndũ wa Ngai yokĩrire, ĩkiuma nja rũciinĩ tene, ĩkĩona atĩ mbũtũ ya ita, na mbarathi, na ngaari cia ita nĩciarigiicĩirie itũũra. Nayo ndungata ĩkĩũria atĩrĩ, “Wũi, mwathi wakwa-ĩ, tũgwĩka atĩa?”
Nígbà tí ìránṣẹ́ ènìyàn Ọlọ́run dìde ó sì jáde lọ ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, ogun pẹ̀lú ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ wọn ti yí ìlú náà ká. “Yé è, olúwa mi! Kí ni kí àwa kí ó ṣe?” ìránṣẹ́ náà béèrè.
16 Nake mũnabii akĩmũcookeria atĩrĩ, “Tiga gwĩtigĩra, nĩgũkorwo arĩa marĩ mwena witũ nĩ aingĩ gũkĩra arĩa marĩ mwena wao.”
“Má ṣe bẹ̀rù,” wòlíì náà dáhùn, “Àwọn tí ó wà pẹ̀lú wa, wọ́n pọ̀ ju àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn lọ.”
17 Nake Elisha akĩhooya atĩrĩ, “Wee Jehova, mũhingũre maitho nĩguo oone.” Nake Jehova akĩhingũra maitho ma ndungata ĩyo, nayo ĩkĩrora, ĩkĩona kũu irĩma-inĩ kũiyũire mbarathi na ngaari cia ita irĩ na mwaki, ciothe irigiicĩirie Elisha.
Eliṣa sì gbàdúrà, “Olúwa, la ojú rẹ̀ kí ó ba à lè ríran.” Nígbà náà Olúwa la ojú ìránṣẹ́ náà, ó sì wò, ó sì rí òkè ńlá tí ó kún fún ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ iná gbogbo yí Eliṣa ká.
18 Na rĩrĩa thũ ciake ciaikũrũkaga irorete kũrĩ we-rĩ, Elisha akĩhooya Jehova, akiuga atĩrĩ, “Hũũra andũ aya na ũtumumu.” Nĩ ũndũ ũcio Jehova akĩmahũũra na ũtumumu, o ta ũrĩa Elisha aahooete.
Bí àwọn ọ̀tá ṣe ń sọ̀kalẹ̀ wá níwájú rẹ, Eliṣa gbàdúrà sí Olúwa pé. “Bu ìfọ́jú lu àwọn ènìyàn wọ̀nyí,” Olúwa sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Eliṣa ti béèrè.
19 Elisha akĩmeera atĩrĩ, “Ĩno tiyo njĩra, o na rĩĩrĩ tirĩo itũũra. Nũmĩrĩrai, na nĩngũmũtwara kũrĩ mũndũ ũrĩa mũracaria.” Nake akĩmatwara nginya Samaria.
Eliṣa sọ fún wọn pé, “Èyí kì í ṣe ọ̀nà bẹ́ẹ̀ ni èyí kì í ṣe ìlú náà. Tẹ̀lé mi, èmi yóò mú u yín lọ sí ọ̀dọ̀ ọkùnrin tí ẹ̀yin ń wá.” Ó sì sìn wọ́n lọ sí Samaria.
20 Maarĩkia kũingĩra itũũra rĩu inene, Elisha akiuga atĩrĩ, “Jehova hingũra andũ aya maitho nĩgeetha mone.” Nake Jehova akĩmahingũra maitho, nao makĩona, magĩĩkora marĩ thĩinĩ wa Samaria.
Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n wọ ìlú náà, Eliṣa wí pé, “Olúwa, la ojú àwọn ọkùnrin wọ̀nyí kí wọn kí ó lè ríran.” Nígbà náà Olúwa la ojú wọn, wọ́n sì ríran, wọ́n sì wà níbẹ̀, nínú Samaria.
21 Rĩrĩa mũthamaki wa Isiraeli aamoonire-rĩ, akĩũria Elisha atĩrĩ, “Baba ndĩmoorage? Nĩ wega ndĩmoorage?”
Nígbà tí ọba Israẹli rí wọn, ó béèrè lọ́wọ́ Eliṣa pé, “Ṣé kí èmi kí ó pa wọ́n, baba mi? Ṣé kí èmi kí ó pa wọ́n?”
22 Nake Elisha akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ndũkamoorage. No ũũrage andũ arĩa wĩnyiitĩire na rũhiũ rwaku rwa njora kana ũta? Mahe irio na maaĩ, marĩe na manyue, macooke mathiĩ kũrĩ mwathi wao.”
“Má ṣe pa wọ́n,” ó dáhùn. “Ṣé ìwọ yóò pa àwọn ọkùnrin tí ìwọ mú pẹ̀lú idà rẹ tàbí ọrun rẹ? Gbé oúnjẹ àti omi síwájú wọn kí wọn kí ó lè jẹ kí wọn sì mu, nígbà náà kí wọn padà lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn.”
23 Nĩ ũndũ ũcio akĩmathondekera iruga inene, nao maarĩkia kũrĩa na kũnyua, akĩmoigĩra ũhoro nao magĩcooka kũrĩ mwathi wao. Nĩ ũndũ ũcio mbũtũ cia ita cia Suriata igĩtiga gũtharĩkĩra bũrũri wa Isiraeli rĩngĩ.
Bẹ́ẹ̀ ni ó pèsè àsè ńlá fún wọn, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jẹ tí wọ́n mu, ó sì rán wọn lọ, wọ́n sì padà sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá wọn. Bẹ́ẹ̀ ni ẹgbẹ́ láti Aramu dáwọ́ ìgbógunti ilẹ̀ Israẹli dúró.
24 Na rĩrĩ, thuutha ũcio Beni-Hadadi mũthamaki wa Suriata agĩcookanĩrĩria mbũtũ ciake cia ita ciothe, igĩthiĩ, ikĩrigiicĩria Samaria irĩtunyane.
Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, ni Beni-Hadadi ọba Aramu kó gbogbo àwọn ogun rẹ̀ jọ wọ́n sì yan sókè wọ́n sì dúró ti Samaria.
25 Na gũkĩgĩa na ngʼaragu nene mũno itũũra rĩu inene. Kũrigiicĩrio kwarĩo gũgĩikara ihinda iraaya ũũ atĩ mũtwe wa ndigiri wendagio cekeri mĩrongo ĩnana cia betha, nakĩo kĩbaba kĩmwe kĩa mai ma ndutura gĩkeendio cekeri ithano.
Ìyàn ńlá sì mú ní ìlú Samaria; wọ́n dúró tí ì tó bẹ́ẹ̀ tí a fi ń ta orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan ní ọgọ́rùn-ún ìwọ̀n fàdákà àti ìdámẹ́rin òsùwọ̀n kábù imí ẹyẹlé, fún ìwọ̀n fàdákà márùn-ún.
26 Na rĩrĩa mũthamaki wa Isiraeli aahĩtũkagĩra rũthingo igũrũ-rĩ, mũtumia ũmwe akĩmũkaĩra, akĩmwĩra atĩrĩ, “Mũthamaki, mwathi wakwa, ndeithia!”
Gẹ́gẹ́ bí ọba Israẹli ti ń kọjá lọ lórí odi, obìnrin kan sọkún sí i pé, “Ràn mí lọ́wọ́, olúwa ọba mi!”
27 Nake mũthamaki akĩmũcookeria atĩrĩ, “Angĩkorwo Jehova ndangĩgũteithia-rĩ, niĩ ingĩkũrutĩra ũteithio kũ? Nĩ kuuma kĩhuhĩro-inĩ kĩa ngano, kana nĩ kuuma kĩhihĩro-inĩ kĩa ndibei?”
Ọba sì dá a lóhùn pé, “Bí Olúwa kò bá gbà ọ́, níbo ni èmi yóò gbé ti gbà ọ́? Láti inú ilẹ̀ ìpakà, tàbí láti inú ibi ìfúntí?”
28 Ningĩ agĩcooka akĩmũũria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ kĩragũthĩĩnia?” Nake agĩcookia atĩrĩ, “Mũtumia ũyũ aranjĩĩrire atĩrĩ, ‘Ruta mũrũguo nĩgeetha tũmũrĩe ũmũthĩ, naruo rũciũ tũkaarĩa mũriũ wakwa.’
Nígbà náà ọba béèrè lọ́wọ́ obìnrin náà pé, “Kí ni ó ṣẹlẹ̀?” Obìnrin náà dáhùn pé, “Obìnrin yìí wí fún mi pé, ‘Mú ọmọkùnrin rẹ wá kí àwa kí ó lè jẹ ẹ́ lónìí, ní ọ̀la àwa yóò jẹ ọmọkùnrin tèmi.’
29 Nĩ ũndũ ũcio tũraruga mũriũ wakwa na tũramũrĩa. Mũthenya ũyũ ũngĩ ndĩramwĩra atĩrĩ, ‘Ruta mũrũguo nĩgeetha tũmũrĩe,’ no aramũhitha.”
Bẹ́ẹ̀ ni a ṣe ọmọkùnrin mi a sì jẹ ẹ́. Ní ọjọ́ kejì mo wí fún un pé, ‘Mú ọmọkùnrin rẹ wá kí àwa kí ó lè jẹ,’ ṣùgbọ́n ó ti gbé e pamọ́.”
30 Na rĩrĩa mũthamaki aaiguire ciugo cia mũtumia ũcio-rĩ, agĩtembũranga nguo ciake. O agĩthiiagĩra rũthingo igũrũ-rĩ, andũ magĩcũthĩrĩria, makĩona atĩ eehumbĩte nguo ya ikũnia thĩinĩ.
Nígbà tí ọba gbọ́ ọ̀rọ̀ obìnrin náà, ó fa aṣọ rẹ̀ ya. Gẹ́gẹ́ bí ó sì ti ń kọjá lọ sí orí odi, àwọn ènìyàn wò ó níbẹ̀ ní abẹ́, ó ní aṣọ ọ̀fọ̀ ní ara rẹ̀.
31 Nake akiuga atĩrĩ, “Ngai aronjĩka ũũru, na akĩrĩrĩrie kũnjĩka ũũru, angĩkorwo mũtwe wa Elisha mũrũ wa Shafatu nĩũgũkorwo ũnyiitaine na mwĩrĩ wake ũmũthĩ!”
Ó sì wí pé, “Kí Ọlọ́run kí ó fi ìyà jẹ mí, àti jù bẹ́ẹ̀ lọ dájúdájú, pé orí ọmọkùnrin Eliṣa ọmọ Ṣafati kì ó wà ní ọrùn rẹ̀ ní òní!”
32 Na rĩrĩ, Elisha aikarĩte gwake nyũmba arĩ hamwe na athuuri. Nake mũthamaki agĩtũma mũndũ athiiage mbere yake, no mũndũ ũcio ataanakinya, Elisha akĩĩra athuuri acio atĩrĩ, “Hĩ! Ĩĩ nĩmũrona ũrĩa mũũragani ũyũ andũmĩire mũndũ oke andinie mũtwe? Atĩrĩrĩ, mũndũ ũcio ooka-rĩ, mũhinge mũrango, na mũũnyiitĩrĩre ndakaingĩre. Githĩ mũkubio wa magũrũ ma mwathi wake ndũrĩ o thuutha wake?”
Nísinsin yìí Eliṣa jókòó ní ilé rẹ̀ àwọn àgbàgbà náà jókòó pẹ̀lú rẹ̀. Ọba sì rán oníṣẹ́ síwájú rẹ̀, ṣùgbọ́n kí ó tó dé ibẹ̀, Eliṣa sọ fún àwọn àgbàgbà pé, “Ṣé ẹ̀yin kò rí bí apànìyàn ti ń rán ẹnìkan láti gé orí mi kúrò? Ẹ wò ó, nígbà tí ìránṣẹ́ náà bá dé, ẹ ti ìlẹ̀kùn kí ẹ sì dìímú ṣinṣin ní ẹnu-ọ̀nà, ìró ẹsẹ̀ olúwa rẹ̀ kò ha wà lẹ́yìn rẹ?”
33 O akĩaria nao-rĩ, mũndũ ũcio watũmĩtwo agĩikũrũka, agĩkinya harĩ we. Nake mũthamaki akiuga atĩrĩ, “Mwanangĩko ũyũ uumĩte kũrĩ Jehova. Nĩ kĩĩ kĩngĩtũma njeterere Jehova makĩria ma ũguo?”
Nígbà tí ó sì ń sọ̀rọ̀ sí wọn, ìránṣẹ́ náà sọ̀kalẹ̀ wá bá a. Ọba náà sì wí pé, “Ibi yìí láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni. Kí ni ó dé tí èmi yóò fi dúró de Olúwa sí i?”

< 2 Athamaki 6 >