< 2 Athamaki 5 >

1 Na rĩrĩ, Naamani aarĩ mũnene wa mbũtũ cia ita cia mũthamaki wa Suriata. Aarĩ mũndũ mũnene maitho-inĩ ma mwathi wake na aarĩ mũndũ watĩĩkĩte mũno, tondũ Jehova nĩamũhũthĩrĩte kũhe andũ a Suriata ũhootani. Aarĩ mũthigari njamba, no aarĩ na mangũ.
Naamani jẹ́ olórí ogun ọba Aramu. Ó jẹ́ ènìyàn ńlá níwájú ọ̀gá rẹ̀, wọ́n sì bu ọlá fún un, nítorí nípasẹ̀ rẹ̀ ni Olúwa ti fi ìṣẹ́gun fún Aramu. Òun jẹ́ alágbára, akọni ọkùnrin ṣùgbọ́n, ó dẹ́tẹ̀.
2 Na rĩrĩ, mbũtũ cia Suriata nĩciathiĩte nja na igataha mũirĩtu mũnini kuuma Isiraeli, nake aatungatagĩra mũtumia wa Naamani.
Nísinsin yìí ẹgbẹgbẹ́ láti Aramu ti jáde lọ láti mú ọmọ obìnrin kékeré kan ní ìgbèkùn láti Israẹli, ó sì sin ìyàwó Naamani.
3 Nake mũirĩtu ũcio akĩĩra mwathi wake mũndũ-wa-nja atĩrĩ, “Naarĩ korwo mwathi wakwa Naamani no one mũnabii ũrĩa ũrĩ Samaria! No amũhonie mangũ make.”
Ó sọ fún ọ̀gá rẹ̀ obìnrin pé, “Tí ó bá jẹ́ wí pé ọ̀gá mi lè rí wòlíì tí ó wà ní Samaria! Yóò wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
4 Naamani agĩthiĩ kũrĩ mũthamaki mwathi wake na akĩmwĩra ũrĩa mũirĩtu ũcio woimĩte Isiraeli oigĩte.
Naamani lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ̀ ó sì wí fún un ohun tí ọmọbìnrin Israẹli ti sọ.
5 Nake mũthamaki ũcio wa Suriata akĩmũcookeria atĩrĩ, “Geria ũthiĩ. Nĩngũtũmĩra mũthamaki wa Isiraeli marũa.” Nĩ ũndũ ũcio Naamani akiumagara na agĩkuua taranda ikũmi cia betha, na cekeri 6,000 cia thahabu, na nguo cia magarũrĩra ikũmi.
“Ní gbogbo ọ̀nà, lọ,” ọba Aramu dá a lóhùn pé, “Èmi yóò fi ìwé ránṣẹ́ sí ọba Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni Naamani lọ, ó sì mú pẹ̀lú rẹ̀ tálẹ́ǹtì fàdákà mẹ́wàá, ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ìwọ̀n wúrà àti ìpààrọ̀ aṣọ mẹ́wàá.
6 Marũa marĩa atwarĩire mũthamaki wa Isiraeli maandĩkĩtwo atĩrĩ: “Nĩndatũma ndungata yakwa Naamani na marũa maya kũrĩ we, nĩgeetha ũmũhonie mangũ make.”
Ìwé tí ó mú lọ sọ́dọ̀ ọba Israẹli kà pé, “Pẹ̀lú ìwé yìí èmi ń rán ìránṣẹ́ mi Naamani sí ọ pé o lè wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
7 Rĩrĩa mũthamaki wa Isiraeli aathomire marũa macio-rĩ, agĩtembũranga nguo ciake, akiuga atĩrĩ, “Niĩ ndĩ Ngai? Ndaahota kũũraga na gũcookia muoyo rĩngĩ? Nĩ kĩĩ gĩgũtũma mũndũ ũyũ atũme mũndũ kũrĩ niĩ atĩ ahonio mangũ make? Ta kĩone, arageria kũnjũgita!”
Bí ọba Israẹli ti ka ìwé náà ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì wí pé, “Èmi ha jẹ́ Ọlọ́run? Ǹjẹ́ èmi le pa kí n sì mú wá sí ààyè padà? Kí ni ó dé tí eléyìí rán ènìyàn sí mi láti wo ààrùn ẹ̀tẹ̀ rẹ sàn, kí ẹ wo bí ó ti ń wá ọ̀nà láti wá ìjà pẹ̀lú mi!”
8 Rĩrĩa Elisha mũndũ wa Ngai aiguire atĩ mũthamaki wa Isiraeli nĩatembũrangĩte nguo ciake-rĩ, akĩmũtũmĩra ndũmĩrĩri ĩno: “Nĩ kĩĩ gĩgũtũma ũtembũrange nguo ciaku? Reke mũndũ ũcio oke kũrĩ niĩ, na nĩekũmenya atĩ nĩ kũrĩ mũnabii thĩinĩ wa Isiraeli.”
Nígbà tí Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run gbọ́ pé ọba Israẹli ti ya aṣọ rẹ̀, ó sì rán iṣẹ́ yìí sí i pé, “Kí ni ó dé tí o fi fa aṣọ rẹ ya? Jẹ́ kí ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi. Òun yóò sì mọ̀ pé wòlíì wà ní Israẹli.”
9 Nĩ ũndũ ũcio Naamani agĩthiĩ hamwe na mbarathi ciake na ngaari cia ita o nginya mũromo-inĩ wa nyũmba ya Elisha.
Bẹ́ẹ̀ ni Naamani sì lọ pẹ̀lú ẹṣin rẹ̀ àti kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Eliṣa.
10 Nake Elisha akĩmũtũmĩra mũndũ amwĩre atĩrĩ, “Thiĩ wĩthambe maita mũgwanja rũũĩ-inĩ rwa Jorodani, na mwĩrĩ waku nĩũkũhonio, na nĩũgũthera.”
Eliṣa rán ìránṣẹ́ láti lọ sọ fún un pé, “Lọ, wẹ̀ ara rẹ ní ìgbà méje ní odò Jordani, ẹran-ara rẹ yóò sì tún padà bọ̀ sípò, ìwọ yóò sì mọ́.”
11 No Naamani agĩthiĩ arakarĩte, akiuga atĩrĩ, “Ngwĩciiragia atĩ ti-itherũ mũnabii nĩekuuma nja oke kũrĩ niĩ, na arũgame akaĩre rĩĩtwa rĩa Jehova Ngai wake, acooke athũngũthie guoko gwake igũrũ rĩa handũ hau harũaru, aahonie mangũ.
Ṣùgbọ́n Naamani lọ pẹ̀lú ìbínú ó sì wí pé, “Mo lérò pé yóò sì dìde jáde wá nítòótọ́ sí mi, yóò sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run, fi ọwọ́ rẹ̀ lórí ibẹ̀ kí ó sì wo ẹ̀tẹ̀ mi sàn.
12 Githĩ njũũĩ cia Dameski, na Abana, o na Faripari ti njega gũkĩra maaĩ o mothe ma Isiraeli? Githĩ ndingĩĩthambire thĩinĩ wacio therio?” Nĩ ũndũ ũcio akĩhũndũka, agĩthiĩ arakarĩte mũno.
Abana àti Fapari, odò Damasku kò ha dára ju gbogbo omi Israẹli lọ? Ṣé èmi kò le wẹ̀ nínú wọn kí n sì mọ́?” Bẹ́ẹ̀ ni ó yípadà, ó sì lọ pẹ̀lú ìrunú.
13 Ndungata cia Naamani igĩthiĩ harĩ we ikĩmwĩra atĩrĩ, “Ithe witũ, korwo mũnabii akwĩrire wĩke ũndũ mũnene gũkĩra ũyũ-rĩ, githĩ ndũngĩwĩkire? Githĩ to wĩke makĩria ũndũ ũyũ aakwĩra, ‘Wĩthambe, ũtherio!’”
Ìránṣẹ́ Naamani lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ó sì wí pé, “Baba mi, tí wòlíì bá ti sọ fún ọ láti ṣe ohun ńlá kan, ṣé ìwọ kì bá ti ṣe, mélòó mélòó nígbà náà, nígbà tí ó sọ fún ọ pé, ‘Wẹ̀ kí o sì mọ́’!”
14 Nĩ ũndũ ũcio Naamani agĩikũrũka, agĩĩtobokia Jorodani maita mũgwanja, o ta ũrĩa mũndũ wa Ngai aamwĩrĩte, naguo mwĩrĩ wake ũkĩhona, ũgĩthera ũkĩhaana ta wa kaana kanini.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ ó sì tẹ ara rẹ̀ bọ inú odò Jordani ní ìgbà méje, gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run ti sọ fún un, ẹran-ara rẹ̀ sì tún padà sí mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ọmọkùnrin kékeré.
15 Hĩndĩ ĩyo Naamani na arĩa othe maamũteithagia magĩcooka kũrĩ mũndũ wa Ngai. Nake akĩrũgama mbere yake, akiuga atĩrĩ, “Rĩu nĩndamenya atĩ gũtirĩ Ngai ũngĩ thĩ yothe tiga gũkũ Isiraeli. Ndagũthaitha wĩtĩkĩre kuoya kĩheo kuuma kũrĩ ndungata yaku.”
Nígbà náà Naamani àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ padà lọ sí ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run. Ó sì dúró níwájú rẹ̀ ó sì wí pé, “Nísinsin yìí èmi mọ̀ pé kò sí Ọlọ́run ní gbogbo àgbáyé àyàfi ní Israẹli nìkan. Jọ̀wọ́ gba ẹ̀bùn láti ọwọ́ ìránṣẹ́ rẹ.”
16 Nake mũnabii akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ti-itherũ o ta ũrĩa Jehova ũrĩa ndungatagĩra atũũraga muoyo-rĩ, niĩ ndingĩĩtĩkĩra kuoya kĩndũ o na kĩ.” Na rĩrĩ, o na gũtuĩka Naamani nĩamũringĩrĩirie mũno-rĩ, nĩaregire.
Wòlíì náà dáhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ẹni tí mo ń sìn, èmi kò nígbà ohun kan,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Naamani rọ̀ ọ́ láti gbà á, ó kọ̀.
17 Nake Naamani akiuga atĩrĩ, “Angĩkorwo ndũngĩoya-rĩ, ndagũthaitha ũreke niĩ ndungata yaku heo tĩĩri ũrĩa wothe ũngĩkuuo nĩ nyũmbũ igĩrĩ, nĩgũkorwo ndungata yaku ndĩrĩ hĩndĩ ĩgacooka kũruta maruta ma njino kana magongona kũrĩ ngai ĩngĩ, tiga o Jehova.
Naamani wí pé, “Tí o kò bá nígbà, jọ̀wọ́ jẹ́ kí a fi fún èmi ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ ẹrù erùpẹ̀ tí ìbáaka méjì le rù, nítorí láti òní lọ ìránṣẹ́ rẹ kì yóò rú ẹbọ sísun àti rú ẹbọ sí ọ̀kan lára àwọn ọlọ́run mìíràn mọ́ bí kò ṣe sí Olúwa.
18 No rĩrĩ, Jehova arorekera ndungata yaku ũndũ-inĩ o ũyũ ũmwe: Rĩrĩa mũthamaki mwathi wakwa arĩĩtoonyaga hekarũ ya Rimoni amĩinamĩrĩre etiranĩtie na guoko gwakwa, na niĩ nyinamĩrĩre ho-rĩ, rĩrĩa ngainamĩrĩra ndĩ hekarũ-inĩ ya Rimoni, Jehova arorekera ndungata yaku nĩ ũndũ wa gwĩka ũguo.”
Ṣùgbọ́n kí Olúwa kí ó dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún nǹkan yìí. Nígbà tí ọ̀gá mi wọ inú ilé Rimoni láti fi orí balẹ̀ tí ó sì fi ara ti ọwọ́ mi tí mo sì tẹ ara mi ba pẹ̀lú níbẹ̀. Nígbà tí èmi tẹ ara mi ba ní ilé Rimoni, kí Olúwa dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún èyí.”
19 Hĩndĩ ĩyo Elisha akĩmwĩra atĩrĩ, “Thiĩ na thayũ.” Thuutha wa Naamani gũkorwo athiĩte itĩĩna-rĩ,
Eliṣa wí pé, “Máa lọ ní àlàáfíà.” Lẹ́yìn ìgbà tí Naamani tí rin ìrìnàjò tí ó jìnnà,
20 Gehazi, ndungata ya Elisha mũndũ wa Ngai, agĩĩciiria atĩrĩ, “Mwathi wakwa nĩahũthĩria Naamani ũcio Mũsuriata maũndũ nĩ kũrega kwamũkĩra indo iria ekũmũreheire. Ti-itherũ o ta ũrĩa Jehova atũũraga muoyo-rĩ, niĩ nĩ ngũhanyũka ndĩmũkinyĩre nĩguo njoe kĩndũ kuuma harĩwe.”
Gehasi, ìránṣẹ́ Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run, ó wí fún ara rẹ̀ pé, “Ọ̀gá mi jẹ́ ẹni tí ó rọ́nú lórí Naamani, ará Aramu, nípa pé kò gba ohunkóhun ní ọwọ́ rẹ̀ ohun tí ó mú wá, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, èmi yóò sá tẹ̀lé e èmi yóò sì gba ohun kan ní ọwọ́ rẹ̀.”
21 Tondũ ũcio Gehazi akĩhiũha nĩguo akinyĩre Naamani. Rĩrĩa Naamani aamuonire ahanyũkĩte arorete na kũrĩ we-rĩ, akiuma ngaari-inĩ ya ita nĩguo amũtũnge. Akĩmũũria atĩrĩ, “Maũndũ mothe nĩ mega?”
Bẹ́ẹ̀ ni Gehasi sáré tẹ̀lé Naamani. Nígbà tí Naamani rí i tí ó ń sáré tẹ̀lé e, ó sì sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ̀. “Ṣé gbogbo nǹkan wà dáradára?” ó béèrè.
22 Nake Gehazi agĩcookia atĩrĩ, “Ĩĩ, maũndũ mothe nĩ mega. Mwathi wakwa aandũma ngwĩre atĩrĩ, ‘Aanake eerĩ kuuma thiritũ-inĩ ya anabii mooka kũrĩ niĩ o rĩu, moimĩte bũrũri ũrĩa ũrĩ irĩma wa Efiraimu. Ndagũthaitha ũmahe taranda ĩmwe ya betha, na nguo cia magarũrĩra meerĩ.’”
“Gbogbo nǹkan wà dáradára,” Gehasi dá a lóhùn. “Ọ̀gá mi rán mi láti sọ wí pé, ‘Àwọn ọ̀dọ́ ọmọkùnrin méjì láti ọ̀dọ̀ ọmọ wòlíì wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ mi láti orí òkè ìlú ti Efraimu. Jọ̀wọ́ fún wọn ní ẹ̀bùn fàdákà àti ìpààrọ̀ aṣọ méjì.’”
23 Nake Naamani akiuga atĩrĩ, “Ĩtĩkĩra woe taranda igĩrĩ.” Agĩthaitha Gehazi aciĩtĩkĩre, ningĩ akĩoha taranda igĩrĩ cia thahabu agĩciĩkĩra mĩhuko-inĩ ĩĩrĩ hamwe na nguo cia magarũrĩra meerĩ. Nake akĩnengera ndungata ciake igĩrĩ, igĩkuua, igĩthiĩ mbere ya Gehazi.
Naamani wí pé, “Ní gbogbo ọ̀nà, mú ẹ̀bùn méjì.” Ó sì rọ Gehasi láti gbà wọ́n, ó sì di ẹ̀bùn méjì náà ti fàdákà ní inú àpò méjì, pẹ̀lú ìpààrọ̀ aṣọ méjì, ó sì fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ méjì, wọ́n sì kó wọn lọ sọ́dọ̀ Gehasi.
24 Rĩrĩa Gehazi aakinyire kĩrĩma-inĩ, agĩĩtia ndungata indo icio, agĩciiga nyũmba. Nake akiugĩra ndungata icio ũhoro, nacio igĩĩthiĩra.
Nígbà tí Gehasi sì dé ibi ilé ìṣọ́, ó gbà wọ́n lọ́wọ́ wọn, ó sì tó wọ́n sínú ilé, ó sì jọ̀wọ́ àwọn ọkùnrin náà lọ́wọ́ lọ, wọ́n sì jáde lọ.
25 Thuutha ũcio agĩtoonya nyũmba akĩrũgama mbere ya mwathi wake Elisha. Nake Elisha akĩmũũria atĩrĩ, “Gehazi uuma kũ?” Nake Gehazi akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ndungata yaku ndĩrĩ kũndũ ĩgũthiĩte.”
Nígbà náà ó sì wọlé wá ó sì dúró níwájú ọ̀gá rẹ̀ Eliṣa. “Níbo ni o ti wà Gehasi?” Eliṣa béèrè. “Ìránṣẹ́ rẹ kò lọ sí ibìkan kan.” Gehasi dá a lóhùn.
26 Nowe Elisha akĩmwĩra atĩrĩ, “Githĩ roho wakwa nduuma hamwe nawe rĩrĩa mũndũ ũcio oimire ngaari-inĩ ya ita agũtũnge? Nĩ ihinda rĩa kuoya mbeeca, kana kwamũkĩra nguo, na mĩgũnda ya mĩtamaiyũ na ya mĩthabibũ, na ndũũru cia mbũri na ngʼombe, na ndungata cia arũme na cia andũ-a-nja?
Ṣùgbọ́n Eliṣa wí fún un pé, “Ẹ̀mí mi kò ha wà pẹ̀lú rẹ nígbà tí ọkùnrin náà sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ? Ṣé àsìkò tí ó yẹ láti gba owó nìyìí, tàbí láti gba aṣọ, ọgbà olifi, ọgbà àjàrà, àgùntàn, màlúù tàbí ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin?
27 Mangũ ma Naamani nĩwe mekwĩgwatĩrĩra na njiaro ciaku nginya tene.” Hĩndĩ ĩyo Gehazi akĩehera harĩ Elisha arĩ na mangũ na akerũha, akahaana o ta ira.
Ẹ̀tẹ̀ Naamani yóò lẹ̀ mọ́ ọ àti sí irú-ọmọ rẹ títí láé.” Nígbà náà Gehasi kúrò níwájú Eliṣa, ó sì di adẹ́tẹ̀, ó sì funfun gẹ́gẹ́ bí ẹ̀gbọ̀n òwú.

< 2 Athamaki 5 >