< Jérémie 42 >

1 Et s’approchèrent tous les princes des hommes de guerre, Johanan, fils de Carée, et Jézonias, fils d’Osaïas, et tout le reste du peuple, depuis le petit jusqu’au grand;
Nígbà náà ní gbogbo àwọn olórí ogun àti Johanani ọmọkùnrin Karea àti Jesaniah ọmọkùnrin Hoṣaiah àti kékeré títí dé orí ẹni ńlá wá.
2 Et ils dirent à Jérémie, le prophète: Que notre prière tombe en ta présence; et prie pour nous le Seigneur ton Dieu pour tous ces restes, parce que nous avons été laissés un petit nombre d’un bien plus grand, comme les yeux nous voient;
Sí ọ̀dọ̀ Jeremiah wòlíì náà, wọ́n sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wa, kí o sì gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún gbogbo ìyókù yìí. Nítorí gẹ́gẹ́ bi ìwọ ṣe rí i nísinsin yìí pé a pọ̀ níye nígbà kan rí; ṣùgbọ́n báyìí àwa díẹ̀ la ṣẹ́kù.
3 Et que le Seigneur ton Dieu nous annonce la voie par laquelle nous devons marcher, et la parole que nous devons accomplir.
Gbàdúrà pé kí Olúwa Ọlọ́run rẹ sọ ibi tí àwa yóò lọ fún wa àti ohun tí àwa yóò ṣe.”
4 Or Jérémie, le prophète, leur dit: J’ai entendu; voici que moi je prie le Seigneur votre Dieu, selon vos paroles; toute parole quelconque qu’il me répondra, je vous la ferai connaître, et je ne vous cacherai rien.
Wòlíì Jeremiah sì dáhùn wí pé, “Mo ti gbọ́. Èmi yóò gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run yín gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ṣe béèrè. Èmi yóò sọ gbogbo ohun tí Olúwa bá sọ fún un yín, ń kò sì ní fi ohunkóhun pamọ́ fún un yín.”
5 Et ceux-ci dirent à Jérémie: Que le Seigneur soit entre nous témoin de la vérité et de notre bonne foi, si nous n’agissons pas conformément à toute parole avec laquelle le Seigneur ton Dieu t’aura envoyé vers nous.
Nígbà náà ni wọ́n sọ fún Jeremiah wí pé, “Kí Olúwa ṣe ẹlẹ́rìí òtítọ́ àti òdodo láàrín wa, bí àwa kò bá ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá rán ọ láti sọ fún wa.
6 Soit bonne, soit défavorable, nous obéirons à la voix du Seigneur notre Dieu, vers qui nous t’envoyons, afin que bien nous soit, lorsque nous aurons écouté la voix du Seigneur notre Dieu.
Ìbá à ṣe rere, ìbá à ṣe búburú, àwa yóò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, èyí tí àwa ń rán ọ sí, kí ó ba à lè dára fún wa. Nítorí pé àwa yóò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”
7 Or, lorsque dix jours eurent été accomplis, la parole du Seigneur fut adressée à Jérémie.
Lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́wàá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá,
8 Et il appela Johanan, fils de Carée, tous les princes des Sommes de guerre qui étaient avec lui et tout le peuple, depuis le plus petit jusqu’au grand.
O sì pe Johanani ọmọkùnrin Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀; àti gbogbo àwọn ènìyàn láti orí ẹni tí ó kéré dé orí ẹni ńlá.
9 Et il leur dit: Voici ce que di t le Seigneur, Dieu d’Israël, vers qui vous m’avez envoyé afin de répandre vos prières en sa présence:
Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: ‘Èyí ni ẹni tí ẹ̀yin ti rán láti gbé ẹ̀bẹ̀ yín lọ síwájú mi.
10 Si vous demeurez en repos dans cette terre, je vous édifierai, et je ne détruirai pas; je planterai, et je n’arracherai pas; car je suis apaisé par le mal que je vous ai fait.
Bí ẹ̀yin bá gbé ní ilẹ̀ yìí, èmi yóò gbé e yín ró, n kò sí ní fà yín lulẹ̀, èmi yóò gbìn yín, n kì yóò fà yín tu nítorí wí pé èmi yí ọkàn padà ní ti ibi tí mo ti ṣe sí i yín.
11 Ne craignez pas la face du roi de Babylone, que tremblants d’effroi vous redoutez; ne le craignez pas, dit le Seigneur, parce que moi je suis avec vous, afin de vous sauver, et de vous tirer de sa main.
Ẹ má ṣe bẹ̀rù ọba Babeli tí ẹ̀yin ń bẹ̀rù, báyìí ẹ má ṣe bẹ̀rù rẹ̀ ni Olúwa wí; nítorí tí èmi wà pẹ̀lú yín láti pa yín mọ́ àti láti gbà yín ní ọwọ́ rẹ̀.
12 Et je vous donnerai mes miséricordes et j’aurai pitié de vous, et je vous ferai habiter dans votre terre.
Èmi yóò fi àánú hàn sí i yín, kí ó lè ṣàánú fún un yín, kí ó sì mú un yín padà sí ilẹ̀ yín.’
13 Mais si vous dites: Nous n’habiterons pas dans cette terre, et nous n’écouterons pas la voix du Seigneur notre Dieu,
“Ṣùgbọ́n sá, bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Àwa kò ní gbé ilẹ̀ yìí,’ ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run yín.
14 Disant: En aucune manière; mais nous irons dans la terre d’Egypte, où nous ne verrons pas la guerre, où nous n’entendrons pas le bruit de la trompette, où nous ne souffrirons pas la faim, et nous y habiterons:
Àti pé bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò lọ gbé ní Ejibiti; níbi tí àwa kì yóò rí ìró ogunkógun, tí a kì yóò sì gbọ́ ìró fèrè, tí ebi oúnjẹ kì yóò sì pa wá, níbẹ̀ ni àwa ó sì máa gbé,’
15 À cause de cela, écoutez maintenant la parole du Seigneur, restes de Juda. Voici ce que dit le Seigneur des armées, Dieu d’Israël: Si vous tournez votre face afin d’entrer en Egypte, et que vous y entriez pour y habiter,
nítorí náà, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ìyókù Juda èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: ‘Bí ẹ̀yin bá pinnu láti lọ sí Ejibiti láti lọ ṣe àtìpó níbẹ̀.
16 Le glaive, que vous redoutez, vous atteindra là, dans la terre d’Egypte; et la famine, au sujet de laquelle vous êtes inquiets, s’attachera à vous en Egypte, et vous y mourrez.
Yóò sì ṣe, idà tí ẹ̀yin bẹ̀rù yóò sì lé e yín bá níbẹ̀; àti ìyanu náà tí ẹ̀yin ń bẹ̀rù yóò sì tẹ̀lé yín lọ sí Ejibiti àti pé ibẹ̀ ni ẹ̀yin yóò kú sí.
17 Et tous les hommes qui ont tourné leurs faces afin d’entrer en Egypte et d’y habiter seront détruits par le glaive, et par la famine, et par la peste; et nul d’entre eux ne demeurera, et n’échappera à la face du mal que moi j’amènerai sur eux.
Nítorí náà, gbogbo àwọn tí ó ti pinnu láti ṣe àtìpó ní Ejibiti ni yóò ti ipa idà kú, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn kò sì ní jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú wọn yè tàbí sá àsálà nínú ibi tí èmi yóò mú wá sórí wọn.’
18 Parce que voici ce que dit le Seigneur des armées, Dieu d’Israël: Comme ma colère et ma fureur se sont allumées contre les habitants de Jérusalem, ainsi s’allumera contre vous mon indignation, lorsque vous serez entrés en Egypte; et vous serez en exécration, en stupeur, en malédiction et en opprobre; et jamais plus vous ne verrez ce lieu.
Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Gẹ́gẹ́ bí èmi ti da ìbínú àti ìrunú síta sórí àwọn tí ó ń gbé ní Jerusalẹmu, bẹ́ẹ̀ ni ìrunú mi yóò dà síta sórí yín, nígbà tí ẹ̀yin bá lọ sí Ejibiti. Ẹ̀yin ó sì di ẹni ègún àti ẹni ẹ̀gàn àti ẹ̀sín, ẹ̀yin kì yóò sì rí ibí yìí mọ́.’
19 Voici la parole du Seigneur sur vous, restes de Juda: N’entrez pas en Egypte; sachant, vous saurez que je vous ai protesté aujourd’hui,
“Ẹ̀yin yòókù Juda, Olúwa ti sọ fún un yín pé, ‘Kí ẹ má ṣe lọ sí Ejibiti.’ Ẹ mọ èyí dájú, èmi kìlọ̀ fún un yín lónìí,
20 Que vous avez trompé vos âmes; car c’est vous qui m’avez envoyé vers le Seigneur notre Dieu, disant: Prie pour nous le Seigneur notre Dieu; et tout ce que t’aura dit le Seigneur notre Dieu, annonce-nous-le, et nous le ferons.
pé àṣìṣe ńlá gbá à ni ẹ̀yin ṣe nígbà tí ẹ̀yin rán mi sí Olúwa Ọlọ́run yín pé, ‘Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa; sọ fún wa gbogbo ohun tí ó bá sọ, àwa yóò sì ṣe é.’
21 Et je vous l’ai annoncé aujourd’hui, et vous n’avez pas écouté la voix du Seigneur votre Dieu, dans toutes les choses pour lesquelles il m’a envoyé vers vous.
Mo ti sọ fún un yín lónìí, ṣùgbọ́n síbẹ̀ ẹ̀yin kò tí ì gbọ́ ohùn Olúwa Ọlọ́run yín, àti gbogbo ohun tí ó rán mi láti sọ fún un yín.
22 Maintenant donc, sachant, vous saurez que c’est par le glaive, et par la famine, et par la peste que vous mourrez dans le lieu dans lequel vous avez voulu entrer afin d’y habiter.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí ẹ mọ èyí dájú pé, ẹ̀yin yóò kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn níbikíbi tí ẹ̀yin bá fẹ́ lọ láti ṣe àtìpó.”

< Jérémie 42 >