< Lamentations 1 >

1 Comment est-elle assise solitaire, la ville pleine de peuple? elle est devenue comme veuve, la maîtresse des nations; la reine des provinces a été assujettie au tribut.
Báwo ni ìlú ṣe jókòó nìkan, nígbà kan tí ó sì kún fún ènìyàn! Ó ti fìgbà kan jẹ́ ìlú olókìkí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó wà ní ipò opó, ẹni tí ó jẹ́ ọmọ ọbabìnrin láàrín ìlú ni ó padà di ẹrú.
2 Pleurant, elle a pleuré pendant la nuit, et ses larmes coulent sur ses joues; et il n’est personne qui la console, parmi ceux qui lui étaient chers; tous ses amis l’ont méprisée et sont devenus ses ennemis.
Ọ̀gànjọ́ òru ni ó fi máa ń sọkún kíkorò pẹ̀lú omijé ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ tí ó dúró sí ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀. Nínú gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ kò sí ọ̀kan nínú wọn láti rẹ̀ ẹ́ lẹ́kún. Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ ti jọ̀wọ́ rẹ̀ wọ́n ti di alátakò rẹ̀.
3 Juda a émigré à cause de son affliction et de la grandeur de son esclavage: il a habité parmi les nations, et n’a pas trouvé de repos: ses persécuteurs l’ont saisi dans ses angoisses.
Lẹ́yìn ìjìyà àti ìpọ́njú nínú oko ẹrú, Juda lọ sí àjò Ó tẹ̀dó láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ṣùgbọ́n kò rí ibi ìsinmi. Àwọn tí ó ń tẹ̀lé ká á mọ́ ibi tí kò ti le sá àsálà.
4 Les voies de Sion sont en deuil, de ce qu’il n’y a personne qui vienne pour une solennité; toutes ses portes sont détruites; ses prêtres gémissent, ses vierges sont défigurées; elle-même est plongée dans l’amertume.
Gbogbo ọ̀nà tí ó wọ Sioni ń ṣọ̀fọ̀, nítorí ẹnìkan kò wá sí àjọ̀dún tí a yàn. Gbogbo ẹnu-bodè rẹ̀ dahoro, àwọn àlùfáà rẹ̀ kẹ́dùn, àwọn wúńdíá rẹ̀ sì ń káàánú, òun gan an wà ní ọkàn kíkorò.
5 Ses ennemis sont devenus maîtres, ses adversaires se sont enrichis, parce que le Seigneur a parlé contre elle à cause de la multitude de ses iniquités; ses petits enfants ont été emmenés en captivité devant la face de celui qui les tourmentait.
Àwọn aninilára rẹ̀ gbogbo di olúwa rẹ̀, nǹkan sì rọrùn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀, Olúwa ti fún un ní ìjìyà tó tọ́ nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀. Àwọn ẹ̀ṣọ́ wẹ́wẹ́ rẹ̀ lọ sí oko ẹrú, ìgbèkùn níwájú àwọn ọ̀tá.
6 Toute la beauté de la fille de Sion s’est retirée d’elle; ses princes sont devenus comme des béliers ne trouvant pas de pâturages; ils s’en sont allés sans force devant la face de celui qui les poursuivait.
Gbogbo ẹwà ti di ohun ìgbàgbé kúrò lọ́dọ̀ ọmọbìnrin Sioni. Àwọn ìjòyè rẹ̀ dàbí i àgbọ̀nrín tí kò rí ewé tútù jẹ; nínú àárẹ̀ wọ́n sáré níwájú ẹni tí ó ń lé wọn.
7 Jérusalem s’est souvenue des jours de son affliction, et de la prévarication de toutes les choses précieuses qu’elle avait eues dès les jours anciens, lorsque son peuple tombait sous une main ennemie et qu’il n’avait pas de défenseur; ses ennemis l’ont vue, et ils se sont moqués de ses sabbats.
Ní ọjọ́ ìpọ́njú àti àrìnká rẹ̀ ni Jerusalẹmu rántí àwọn ohun ìní dáradára rẹ̀ tí ó jẹ́ tirẹ̀ ní ọjọ́ pípẹ́. Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ṣubú ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá, kò sì ṣí olùrànlọ́wọ́ fún un. Àwọn ọ̀tá rẹ̀ wò ó wọ́n sì ń fi ìparun rẹ̀ ṣẹlẹ́yà.
8 Elle a beaucoup péché, Jérusalem; à cause de cela elle est
Jerusalẹmu sì ti dẹ́ṣẹ̀ púpọ̀ ó sì ti di aláìmọ́. Àwọn tí ó ń tẹríba fún un sì kẹ́gàn rẹ̀, nítorí wọ́n ti rí ìhòhò rẹ̀; ó kérora fúnra rẹ̀, ó sì lọ kúrò.
9 Ses souillures ont paru sur ses pieds, et elle ne s’est pas souvenue de sa fin; elle a été prodigieusement abaissée, n’ayant pas de consolateur; voyez, Seigneur, mon affliction, parce que l’ennemi s’est élevé.
Ìdọ̀tí wà ní etí aṣọ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò wo ọjọ́ iwájú rẹ̀. Ìṣubú rẹ̀ ya ni lẹ́nu; olùtùnú kò sì ṣí fún un. “Wo ìpọ́njú mi, Olúwa, nítorí àwọn ọ̀tá ti borí.”
10 L’ennemi a porté la main sur toutes ses choses précieuses; et elle a vu des nations entrer dans son sanctuaire, nations au sujet desquelles vous aviez ordonné quelles n’entreraient pas dans votre assemblée.
Ọ̀tá ti gbọ́wọ́ lé gbogbo ìní rẹ; o rí pé àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n wọ ibi mímọ́ rẹ— àwọn tí o ti kọ̀sílẹ̀ láti wọ ìpéjọpọ̀ rẹ.
11 Tout son peuple est gémissant et cherchant du pain; ils ont donné toutes leurs choses précieuses pour une nourriture qui ranimât leur âme. Voyez, Seigneur, et considérez combien je suis avilie.
Àwọn ènìyàn rẹ̀ ń kérora bí wọ́n ti ń wá oúnjẹ; wọ́n fi ohun ìní wọn ṣe pàṣípàrọ̀ oúnjẹ láti mú wọn wà láààyè. “Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó, nítorí a kọ̀ mí sílẹ̀.”
12 Ô vous tous qui passez par la voie, prêtez attention, et voyez s’il est une douleur comme ma douleur; parce que le Seigneur, comme il l’a dit, m’a vendangée au jour de la colère de sa fureur.
“Kò ha jẹ́ nǹkan kan sí i yín? Gbogbo ẹ̀yin tí ń rékọjá. Ǹjẹ́ ẹnìkan ń jìyà bí èmi ti ń jìyà tí a fi fún mi, ti Olúwa mú wá fún mi ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ̀.
13 D’en haut il a envoyé un feu dans mes os, et il m’a châtiée; il a tendu un fil à mes pieds, et il m’a fait tomber en arrière, il m’a rendue désolée, accablée de chagrin tout le jour
“Ó rán iná láti òkè sọ̀kalẹ̀ sínú egungun ara mi. Ó dẹ àwọ̀n fún ẹsẹ̀ mi, ó sì yí mi padà. Ó ti pa mí lára mó ń kú lọ ní gbogbo ọjọ́.
14 Le joug de mes iniquités s’est éveillé; elles ont été roulées dans sa main, et imposées sur mon cou; ma force s’est affaiblie; le Seigneur m’a livrée à une main dont je ne pourrai sortir.
“Ẹ̀ṣẹ̀ mi ti di sísopọ̀ sí àjàgà; ọwọ́ rẹ̀ ni a fi hun ún papọ̀. Wọ́n ti yí ọrùn mi ká Olúwa sì ti dín agbára mi kù. Ó sì ti fi mí lé àwọn tí n kò le dojúkọ lọ́wọ́.
15 Le Seigneur a enlevé du milieu de moi tous mes hommes illustres; il a appelé contre moi le temps afin de briser mes élus; le Seigneur a foulé le pressoir pour la vierge fille de Juda.
“Olúwa kọ àwọn akọni mi sílẹ̀, ó rán àwọn ológun lòdì sí mi kí wọn pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin mi run. Nínú ìfúntí wáìnì rẹ̀ Olúwa tẹ́ àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Juda.
16 C’est pour cela que moi je pleure, et que mon œil a fait couler des eaux; parce qu’il s’est éloigné de moi, le consolateur qui devait faire revenir mon âme; mes fils sont perdus, parce que l’ennemi est devenu le plus fort.
“Ìdí nìyí tí mo fi ń sọkún tí omijé sì ń dà lójú mi. Olùtùnú àti ẹni tí ó le mú ọkàn mi sọjí jìnnà sí mi, kò sí ẹni tí yóò dá ẹ̀mí mi padà. Àwọn ọmọ mi di aláìní nítorí ọ̀tá ti borí.”
17 Sion a étendu ses mains, il n’y a personne qui la console; le Seigneur a appelé de tous côtés contre Jacob ses ennemis; Jérusalem est devenue au milieu d’eux comme une femme souillée par ses mois.
Sioni na ọwọ́ jáde, ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún un. Olúwa ti pàṣẹ fún Jakọbu pé àwọn ará ilé rẹ̀ di ọ̀tá fún un Jerusalẹmu ti di ohun aláìmọ́ láàrín wọn.
18 Le Seigneur est juste, parce que j’ai provoqué sa bouche au courroux; écoutez, je vous en conjure, vous tous, peuples, et voyez ma douleur; mes vierges et mes jeunes hommes sont allés en captivité.
“Olóòtítọ́ ni Olúwa, ṣùgbọ́n mo ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀. Ẹ gbọ́, gbogbo ènìyàn; ẹ wò mí wò ìyà mi. Gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi ni a ti kó lọ sí ìgbèkùn.
19 J’ai appelé mes amis et ils m’ont trompée; mes prêtres et mes vieillards ont été consumés dans la ville, lorsqu’ils ont cherché de la nourriture pour ranimer leur âme.
“Mo pe àwọn ọ̀rẹ́ mi ṣùgbọ́n wọ́n dà mí. Àwọn olórí àlùfáà àti àgbàgbà mi ṣègbé sínú ìlú nígbà tí wọ́n ń wá oúnjẹ tí yóò mú wọn wà láààyè.
20 Voyez, Seigneur, que je suis dans la tribulation; mes entrailles sont émues; mon cœur est bouleversé au dedans de moi, parce que je suis remplie d’amertume; au dehors le glaive tue; au dedans, c’est de même la mort.
“Olúwa, wò ó, bí mo ti wà nínú ìnira! Tí mo sì ń jẹ̀rora nínú mi, ìdààmú dé bá ọkàn mi nítorí pé a ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi gidigidi. Ní gbangba ni idà ń parun; ikú wà nínú ilé pẹ̀lú.
21 Ils ont appris que je gémis, et qu’il n’y a personne qui me console; tous mes ennemis ont appris mon malheur; ils se sont réjouis, parce que c’est vous qui l’avez fait; vous amènerez le jour de ma consolation, et ils seront semblables à moi.
“Àwọn ènìyàn ti gbọ́ ìrora mi, ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún mi. Àwọn ọ̀tá mi ti gbọ́ ìparun mi; wọ́n yọ̀ sí ohun tí o ṣe. Kí o mú ọjọ́ tí o ti kéde, kí wọ́n le dàbí tèmi.
22 THAU. Que tout le mal qu’ils ont fait vienne devant vous; et vendangez-les, comme vous m’avez vendangée à cause de toutes mes iniquités; car mes gémissements sont nombreux, et mon cœur est triste.
“Jẹ́ kí ìwà ìkà wọn wá síwájú rẹ; jẹ wọ́n ní yà bí o ṣe jẹ mí ní yà nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi. Ìrora mi pọ̀ ọkàn mi sì rẹ̀wẹ̀sì.”

< Lamentations 1 >