< Ézéchiel 8 >

1 Or il arriva en la sixième année, au sixième mois, au cinquième jour du mois, que, lorsque j’étais assis dans ma maison, et que les vieillards de Juda étaient assis devant moi, tomba là sur moi la main du Seigneur Dieu.
Ní ọjọ́ karùn-ún, oṣù kẹfà ọdún kẹfà bí mo ṣe jókòó nílé mi pẹ̀lú àwọn àgbàgbà Juda níwájú mi, ọwọ́ Olúwa Olódùmarè bà lé mi níbẹ̀.
2 Et je vis, et voilà la ressemblance d’un homme, comme l’aspect d’un feu; de l’aspect de ses reins et au-dessous c’était du feu; et des reins et au-dessus, comme l’aspect d’une splendeur, comme la vue du succin.
Nígbà tí mo wò, mo rí ohun kan tí ó jọ ènìyàn. Láti ibi ìbàdí rẹ lọ sísàlẹ̀ dàbí iná, láti ibi ìbàdí yìí sókè sì mọ́lẹ̀ bí idẹ tó ń kọ mọ̀nà.
3 Et la ressemblance d’une main envoyée par cet homme me saisit par une boucle de cheveux de ma tête; et un esprit m’éleva entre le ciel et la terre, et m’amena à Jérusalem dans une vision de Dieu, près de la porte intérieure qui regardait du côté de l’aquilon, où était placée l’idole de la jalousie, pour provoquer la jalousie.
Ó na ohun tó dàbí ọwọ́ jáde, ó fi gba mi ní irun orí mú, Ẹ̀mí sì gbé mi sókè sí agbede-méjì ayé àti ọ̀run, ó sì mú mi lọ rí ìran Ọlọ́run, mo sì lọ sí Jerusalẹmu, ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òde àríwá níbi tí ère owú tí ó ń mú ni bínú wá níwájú mi.
4 Et voici que là était la gloire du Dieu d’Israël, selon la vision que j’avais vue dans la plaine.
Sì kíyèsi i, ògo Ọlọ́run Israẹli wà níbẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìran ti mo rí ni pẹ̀tẹ́lẹ̀.
5 Et il me dit: Fils d’un homme, lève tes yeux vers la voie de l’aquilon. Et je levai mes yeux vers la voie de l’aquilon; et voilà que du côté de l’aquilon de la porte de l’autel était l’idole de la jalousie à l’entrée même.
Ó sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbójú sókè sí ìhà àríwá.” Èmi náà sì gbójú sókè sí ìhà àríwá mo sì rí ère tí ó ń mú ni jowú ní ẹnu-ọ̀nà ibi pẹpẹ.
6 Et il me dit: Fils d’un homme, vois-tu, toi, ce que font ceux-ci, les grandes abominations que la maison d’Israël fait ici, afin que je me retire loin de mon sanctuaire? et si tu te tournes encore, tu verras des abominations plus grandes.
Ó sì wí fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, ṣé o rí ohun tí wọ́n ń ṣe ohun ìríra ńlá tí ilé Israẹli ń ṣe, láti lé mi jìnnà réré sí ibi mímọ́ mi? Ṣùgbọ́n ìwọ yóò tún rí àwọn ìríra ńlá tó tóbi jù èyí lọ.”
7 Et il me conduisit à l’entrée du parvis, et voilà que je vis un trou dans la muraille.
Ó mú mi wá sí ẹnu-ọ̀nà àgbàlá. Mo wò ó, mo sì rí ihò kan lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri.
8 Et il me dit: Fils d’un homme, perce la muraille. Et lorsque j’eus percé la muraille, parut une porte.
Nígbà náà ló sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbẹ́ inú ògiri náà,” nígbà tí mo sì gbẹ́ inú ògiri, mo rí ìlẹ̀kùn kan.
9 Et il me dit: Entre, et vois les abominations horribles que ces gens font ici.
Ó sì wí fún mi pé, “Wọlé kí ìwọ kí ó rí ohun ìríra búburú tí wọ́n ń ṣe níbẹ̀.”
10 Et étant entré, je vis, et voici que toute sorte d’images de reptiles et d’animaux, l’abomination et toutes les idoles de la maison d’Israël étaient peintes sur la muraille tout autour.
Mo wọlé, mo sì rí àwòrán oríṣìíríṣìí ẹranko tí ń fà nílẹ̀ àti àwọn ẹranko ìríra àti gbogbo òrìṣà ilẹ̀ Israẹli tí wọ́n yà sára ògiri.
11 Et soixante-dix d’entre les anciens de la maison d’Israël se tenaient debout devant les peintures, et Jézonias, fils de Saphan, était au milieu d’eux; et chacun d’eux avait un encensoir en sa main; et une vapeur comme un nuage s’élevait de l’encens.
Níwájú wọn ni àádọ́rin ọkùnrin tó jẹ́ àgbàgbà ilé Israẹli dúró sí, Jaaṣaniah ọmọ Ṣafani sì dúró sí àárín wọn. Ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sì mú àwo tùràrí lọ́wọ́, òórùn sì ń tú jáde.
12 Et il me dit: Certes tu vois, fils d’un homme, ce que les anciens de la maison d’Israël font dans les ténèbres, chacun dans le secret de sa chambre; car ils disent: Le Seigneur ne nous voit point; le Seigneur a délaissé la terre.
Ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, ṣé o ti rí ohun tí àwọn àgbàgbà ilé Israẹli ń ṣe nínú òkùnkùn, olúkúlùkù ní yàrá òrìṣà rẹ̀? Wọ́n ní, ‘Olúwa kò rí wa; Olúwa ti kọ̀ ilé náà sílẹ̀.’”
13 Et il me dit: Si tu te tournes encore, tu verras des abominations plus grandes que celles que ces gens font.
Ó tún sọ fún mi pé, “Ìwọ yóò rí wọn tí wọ́n ń ṣe àwọn ohun ìríra tó burú jù bẹ́ẹ̀ lọ.”
14 Et il me conduisit à l’entrée de la porte de la maison du Seigneur, qui regardait du côté de l’aquilon, et voici que là les femmes étaient assises pleurant Adonis.
Ó mú mi wá sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tó wà ní ìhà àríwá, mo sì rí àwọn obìnrin tó jókòó, tí wọ́n sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tó wà ní ìhà àríwá, mo sì rí àwọn obìnrin tó jókòó, tí wọ́n sì ń ṣọ̀fọ̀ fún Tamusi.
15 Et il me dit: Certes, tu as vu, fils d’un homme; si tu te tournes encore, tu verras des abominations plus grandes que celles-ci.
Ó sọ fún mi pé, “Ṣé ìwọ rí báyìí, ọmọ ènìyàn? Ìwọ yóò tún rí ìríra tó ga jù èyí lọ.”
16 Et il me conduisit dans le parvis intérieur de la maison du Seigneur; et voilà qu’à l’entrée du temple du Seigneur, entre le vestibule et l’autel, environ vingt-cinq hommes tournant le dos au temple du Seigneur, et la face vers l’orient; et ils adoraient vers le lever du soleil.
Ó mú mi wá sí ibi àgbàlá ilé Olúwa, ní ẹnu-ọ̀nà tẹmpili Olúwa, láàrín ìloro àti pẹpẹ, ni ìwọ̀n ọkùnrin mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n wà, tí wọ́n kẹ́yìn sí tẹmpili Olúwa tí wọn sì kọjú sí ìlà-oòrùn, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún oòrùn ní apá ìlà-oòrùn.
17 Et il me dit: Certes, tu as vu, fils d’un homme; est-ce peu à la maison de Juda d’avoir fait les abominations qu’ils ont faites ici, puisque remplissant la terre d’iniquité, ils se sont appliqués à m’irriter? et voici qu’ils approchent le rameau de leurs narines.
Ó sì wí fún mi, “Ṣé ìwọ ti rí èyí ọmọ ènìyàn? Ǹjẹ́ ohun kékeré ni fún ilé Juda láti ṣe àwọn ohun ìríra tí wọn ń ṣe níbi yìí? Ṣé o tún yẹ kí wọ́n fi ìwà ipá kún ilẹ̀ kí wọn sì máa mú mi bínú ní gbogbo ìgbà? Wò wọn bi wọn ṣe n fi ẹ̀ka wọn sínú inú wọn.
18 Ainsi donc moi aussi j’agirai dans ma fureur; mon œil n’épargnera pas, je n’aurai pas de pitié; et lorsqu’ils crieront à mes oreilles à haute voix, je ne les écouterai point.
Nítorí náà, èmi yóò fi ìbínú bá wọn wí; èmi kò ní i dá wọn sí bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì ní fojú àánú wò wọ́n. Bí wọ́n tilẹ̀ ń pariwo sí mi létí, èmi kò ní fetí sí wọn.”

< Ézéchiel 8 >