< Ézéchiel 7 >

1 Et la parole du Seigneur me fut adressée, disant:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Et toi, fils d’un homme, voici ce que dit le Seigneur Dieu à la terre d’Israël: La fin vient, elle vient la fin sur les quatre côtés de la terre.
“Ọmọ ènìyàn, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí ilé Israẹli: “‘Òpin! Òpin ti dé sí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilẹ̀ náà!
3 Maintenant la fin est sur toi, et j’enverrai ma fureur contre toi; et je te jugerai selon tes voies, et je poserai contre toi toutes tes abominations.
Òpin tí dé sí ọ báyìí, èmi yóò sì tú ìbínú mi jáde sí ọ, èmi yóò dájọ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìwà rẹ, èmi yóò sì san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìwà ìríra rẹ.
4 Et mon œil ne t’épargnera pas, et je n’aurai pas de pitié; mais tes voies, je les poserai sur toi, et tes abominations seront au milieu de toi; et vous saurez que je suis le Seigneur.
Ojú mi kò ní i dá ọ sì, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò ṣàánú; ṣùgbọ́n èmi yóò san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti gbogbo ìwà ìríra tó wà láàrín rẹ. Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
5 Voici ce que dit le Seigneur Dieu: Une affliction unique, une affliction, voici qu’elle vient.
“Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ibi! Ibi kan ṣoṣo. Kíyèsi, ó bọ̀ ní orí rẹ!
6 La fin vient, elle vient la fin, elle s’est éveillée contre toi; voici qu’elle vient.
Òpin ti dé! Òpin ti dé! Ó ti dìde lòdì sí ọ. Kíyèsi, ó ti dé!
7 La ruine vient sur toi, qui habites la terre; il vient, le temps; il est près, le jour de la tuerie, et non de la gloire des montagnes.
Ìparun ti dé sórí rẹ, ìwọ tó ń gbé ní ilẹ̀ náà. Àkókò náà dé! Ọjọ́ wàhálà ti súnmọ́ etílé! Kì í ṣe ọjọ́ ariwo ayọ̀ lórí òkè.
8 C’est maintenant de près que je répandrai ma colère sur toi, et que j’assouvirai ma fureur sur toi; et que je te jugerai selon tes voies; et que je t’imposerai tous tes crimes;
Mo ṣetán láti tú ìbínú gbígbóná mi lé ọ lórí àti láti lo ìbínú mi lórí rẹ gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀nà rẹ, èmi yóò sì dá ọ lẹ́jọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti gẹ́gẹ́ bí ìwà ìríra rẹ ni èmi yóò sì san án fún ọ.
9 Et mon œil n’épargnera pas, et je n’aurai pas de pitié; mais tes voies, je te les imposerai; et tes abominations seront au milieu de toi; et vous saurez que moi je suis le Seigneur qui frappe.
Ojú mi kò ní i dá ọ sí, Èmi kò sì ní wò ọ́ pẹ̀lú àánú; èmi yóò san án fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ àti fún gbogbo ìwà ìríra tí wà láàrín rẹ. “‘Nígbà náà ní ẹ o mọ̀ pé Èmi Olúwa lo kọlù yín.
10 Voici le jour, voici qu’il vient: la ruine est sortie, la verge a fleuri, l’orgueil a germé;
“‘Ọjọ́ náà dé! Kíyèsi ó ti dé! Ìparun ti bú jáde, ọ̀pá ti tanná, ìgbéraga ti rúdí!
11 L’iniquité s’est élevée sur la verge de l’impiété; il ne restera rien d’eux, ni du peuple, ni de leur bruit; et il n’y aura pas de repos pour eux.
Ìwà ipá ti di ọ̀pá ìwà búburú; ọ̀pá láti jẹ ẹni búburú ní ìyà. Kò sí nínú wọn tí yóò ṣẹ́kù, tàbí nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn, kò sí nínú ọrọ̀ wọn, kò sí ohun tí ó ní iye.
12 Il est venu le temps, il s’est approché le jour; que celui qui achète ne se réjouisse point; et que celui qui vend ne s’afflige pas, parce que la colère est sur tout son peuple.
Àkókò náà dé! Ọjọ́ náà ti dé! Kí òǹrajà má ṣe yọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ki òǹtajà má ṣe ṣọ̀fọ̀; nítorí, ìbínú gbígbóná wà lórí gbogbo ènìyàn.
13 Parce que celui qui vend ne reviendra pas à ce qu’il a vendu, lors même qu’ils seraient encore au nombre des vivants; parce que la vision qui regarde tout le peuple ne reviendra pas sans être accomplie; et l’homme par l’iniquité ne sera pas affermi.
Nítorí pé òǹtajà kì yóò rí gbà padà dúkìá èyí tó tà níwọ̀n ìgbà ti àwọn méjèèjì bá wà láààyè. Nítorí ìran tó kan gbogbo ènìyàn yìí kò ní yí padà. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, kò sí ọ̀kan nínú wọn tí yóò gba ara rẹ̀ là.
14 Sonnez de la trompette; que tous se préparent, et il n’est personne qui aille au combat; car ma colère est sur tout son peuple.
“‘Wọ́n ti fọn ìpè ogun, tí wọ́n sì pèsè ohun gbogbo sílẹ̀, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí yóò lọ ojú ogun, nítorí ìbínú gbígbóná mi ti wà lórí gbogbo ènìyàn.
15 Le glaive au dehors; et la peste et la famine au dedans; celui qui est dans la campagne mourra par l’épée; et ceux qui sont dans la cité seront dévorés par la peste et par la famine.
Idà wà ní ìta, àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìyàn wà nílé, idà yóò pa ẹni tó bá wà ní orílẹ̀-èdè, àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìyàn yóò pa ẹni tó bá wà ní ìlú.
16 Et seront sauvés ceux qui d’entre eux auront fui: mais ils seront sur les montagnes comme les colombes des vallées, tout tremblants, chacun dans son iniquité.
Gbogbo àwọn tí ó bọ́ nínú wọn yóò sálà, wọn yóò sì wà lórí òkè. Bí i àdàbà inú àfonífojì, gbogbo wọn yóò máa ṣọ̀fọ̀, olúkúlùkù nítorí àìṣedéédéé rẹ̀.
17 Toutes les mains seront affaiblies, et l’eau coulera de tous les genoux.
Gbogbo ọwọ́ yóò rọ, gbogbo orúnkún yóò di aláìlágbára bí omi.
18 Et ils se revêtiront de cilices, et la frayeur les couvrira; sur toute face sera la confusion, et sur toutes les têtes la calvitie.
Wọn yóò wọ aṣọ ọ̀fọ̀, ẹ̀rù yóò sì bò wọ́n mọ́lẹ̀, ìtìjú yóò mù wọn, wọn yóò sì fá irun wọn.
19 Leur argent sera jeté dehors, et leur or sera comme du fumier. Leur argent et leur or ne pourront les délivrer au jour de la fureur du Seigneur; ils ne rassasieront pas leur âme, et leurs ventres ne seront pas remplis, parce que c’est devenu une pierre d’achoppement dans leur iniquité.
“‘Wọn yóò dà fàdákà wọn sí ojú pópó, wúrà wọn yóò sì dàbí èérí fàdákà àti wúrà wọn kò ní le gbà wọ́n ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná Olúwa. Wọn kò ní le jẹun tẹ́ ra wọn lọ́rùn tàbí kí wọn kún ikùn wọn pẹ̀lú oúnjẹ nítorí pé ó ti di ohun ìkọ̀sẹ̀ fún wọn.
20 Ils ont fait servir l’ornement de leurs colliers à leur orgueil; et ils en ont fait les images de leurs abominations et de leurs simulacres; à eau se de cela, je l’ai rendu pour eux un objet immonde;
Wọ́n ń ṣe ìgbéraga pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́ wọn tí ó lẹ́wà, wọn sì ti fi ṣe òrìṣà, wọn sì tún ya àwòrán ìríra wọn níbẹ̀. Nítorí náà, èmi yóò sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí di aláìmọ́ fún wọn.
21 Et je le livrerai aux mains des étrangers pour être pillé, et aux impies de la terre pour être leur proie; et ils le souilleront,
Èmi yóò sì fi àwọn nǹkan wọ̀nyí ṣe ìjẹ fún àjèjì àti ìkógun fún àwọn ènìyàn búburú ayé, wọn yóò sì sọ ọ́ di aláìmọ́.
22 Et je détournerai ma face d’eux; et ils violeront mon secret; et des émissaires y entreront et le souilleront.
Èmi yóò gbójú mi kúrò lára wọn, àwọn ọlọ́ṣà yóò sì sọ ibi ìṣúra mi di aláìmọ́; àwọn ọlọ́ṣà yóò wọ inú rẹ̀, wọn yóò sì bà á jẹ́.
23 Fais la conclusion, parce que la terre est pleine de jugements de sang et que la cité est remplie d’iniquité.
“‘Rọ ẹ̀wọ̀n irin! Nítorí pé ilẹ̀ náà kún fún ẹ̀ṣẹ̀ ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìlú náà sí kún fún ìwà ipá.
24 Et j’amènerai les plus méchants d’entre les nations, et ils posséderont leurs maisons; et je ferai cesser l’orgueil des puissants, et ces méchants posséderont leurs sanctuaires.
Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè ti ó búburú jùlọ láti jogún ilé wọn. Èmi yóò sì fi òpin sí ìgbéraga àwọn alágbára, ibi mímọ́ wọn yóò sì di bíbàjẹ́.
25 L’angoisse survenant, ils chercheront la paix, et il n’y en aura pas.
Nígbà tí ìpayà bá dé, wọn yóò wá àlàáfíà, lórí asán.
26 Trouble sur trouble viendra, et bruit sur bruit; ils chercheront quelque vision auprès d’un prophète, et la loi manquera au prêtre, et le conseil aux anciens.
Wàhálà lórí wàhálà yóò dé, ìdágìrì lórí ìdágìrì. Nígbà náà ni wọn yóò wá ìran lọ́dọ̀ wòlíì, ṣùgbọ́n ẹ̀kọ́ òfin yóò parun lọ́dọ̀ àlùfáà, bẹ́ẹ̀ ni ìmọ̀ràn yóò ṣègbé lọ́dọ̀ àwọn àgbàgbà.
27 Le roi sera en deuil, le prince sera couvert de tristesse, et les mains du peuple de la terre trembleront. Selon leur voie je leur rendrai, et selon leurs jugements je les jugerai; et ils sauront que je suis le Seigneur.
Ọba yóò ṣọ̀fọ̀, ọmọ-aládé yóò wà láìní ìrètí, ọwọ́ àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà yóò wárìrì. Èmi yóò ṣe é fún wọn gẹ́gẹ́ bí ìṣe wọn, èmi yóò ṣe ìdájọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìgbékalẹ̀ wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa.’”

< Ézéchiel 7 >