< Néhémie 10 >

1 Et à la tête de ceux qui la scellèrent furent Néhémias artasastha, fils d'Achalias, et Sédécias,
Àwọn tí ó fi èdìdì dì í ni: Nehemiah baálẹ̀, ọmọ Hakaliah. Sedekiah
2 Fils d'Araïas, et Azarias, et Jérémie,
Seraiah, Asariah, Jeremiah,
3 Phasur, Amarias, Melchias,
Paṣuri, Amariah, Malkiah,
4 Attus, Sebani, Maluch,
Hattusi, Ṣebaniah, Malluki,
5 Iram, Meramoth, Abdia,
Harimu, Meremoti, Obadiah,
6 Daniel, Gannathon, Baruch,
Daniẹli, Ginetoni, Baruku,
7 Mesulam, Abia, Miamin,
Meṣullamu, Abijah, Mijamini,
8 Maazia, Belgaï, Samaïa, tous ceux-là prêtres.
Maasiah, Bilgai àti Ṣemaiah. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà.
9 Puis les lévites: Josué, fils d'Azanias, Banaïu, des fils d'Enadad, Cadmiel;
Àwọn ọmọ Lefi: Jeṣua ọmọ Asaniah, Binnui ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Henadadi, Kadmieli,
10 Et ses frères Sabanias, Oduïa, Calitan, Phélia, Anan,
àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn: Ṣebaniah, Hodiah, Kelita, Pelaiah, Hanani,
11 Micha, Roob, Asébias,
Mika, Rehobu, Haṣabiah,
12 Zacchor, Sarabia, Sebania,
Sakkuri, Ṣerebiah, Ṣebaniah,
13 Odum; les fils de Banuaï,
Hodiah, Bani àti Beninu.
14 Chefs du peuple: Pharos, Phaath-Moab, Zathuïa, fils de Bani,
Àwọn olórí àwọn ènìyàn: Paroṣi, Pahati-Moabu, Elamu, Sattu, Bani,
15 Asgad, Bébaï,
Bunni, Asgadi, Bebai.
16 Adania, Bagoï, Hédin,
Adonijah, Bigfai, Adini,
17 Ater, Ezéchias, Azur,
Ateri, Hesekiah, Assuri,
18 Oduïa, Esam, Bési,
Hodiah, Haṣumu, Besai,
19 Ariph, Anathoth, Nobaï,
Harifu, Anatoti, Nebai,
20 Megaphès, Mesollam, Hézir,
Magpiaṣi, Meṣullamu, Hesiri
21 Mesozébel, Saduc, Jeddua,
Meṣesabeli, Sadoku, Jaddua
22 Phattia, Anan, Anaïa,
Pelatiah, Hanani, Anaiah,
23 Osée, Ananias, Asub,
Hosea, Hananiah, Haṣubu,
24 Aloès, Phalaï, Sobec,
Halloheṣi, Pileha, Ṣobeki,
25 Reüm, Essabana, Maasia,
Rehumu, Haṣabna, Maaseiah,
26 Et Aïa, Ainan, Enam,
Ahijah, Hanani, Anani,
27 Maluch, Héram, Baana.
Malluki, Harimu, àti Baanah.
28 Et tout le reste du peuple, les prêtres, les lévites, les portiers, les chantres, les Nathinéens et tous ceux qui s'étaient retirés des gentils de la terre, pour revenir à la loi de Dieu, et leurs femmes et leurs filles; tous ceux qui avaient savoir et intelligence,
“Àwọn ènìyàn tókù—àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn aṣọ́nà, àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti gbogbo àwọn tí wọ́n ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn àjèjì nítorí òfin Ọlọ́run, papọ̀ pẹ̀lú ìyàwó wọn, gbogbo ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, tí òye yé
29 Furent pressants avec leurs frères, et les excitèrent par leurs malédictions; et ceux-ci s'engagèrent, par malédictions et serments, à marcher selon la loi que Dieu a donnée par la main de Moïse, serviteur de Dieu, à garder les jugements, les préceptes et les commandements du Seigneur;
gbogbo wọn fi ara mọ́ àwọn arákùnrin wọn, àwọn ọlọ́lá, wọ́n sì fi ègún àti ìbúra dé ara wọn láti máa tẹ̀lé òfin Ọlọ́run tí a fi fún wọn ní ipasẹ̀ Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run àti láti pa gbogbo àṣẹ, ìlànà àti òfin Olúwa, wa mọ́ dáradára.
30 À ne point donner nos filles en mariage aux peuples de la terre, et à ne point prendre leurs filles pour nos fils.
“A ti ṣe ìlérí pé, a kò ní fi àwọn ọmọbìnrin wa fún àwọn tí wọ́n wà ní àyíká wa bí ìyàwó, tàbí fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin wa.
31 Nous n'achèterons rien, avons-nous dit, aux peuples de la terre qui viendront vendre le jour du sabbat; nous ne trafiquerons, ni le jour du sabbat; ni les jours sanctifiés; nous remettrons les dettes la septième année.
“Nígbà tí àwọn ènìyàn àdúgbò bá mú ọjà tàbí oúnjẹ wá ní ọjọ́ ìsinmi láti tà, àwa kò ní rà á ní ọwọ́ wọn ní ọjọ́ ìsinmi tàbí ní ọjọ́ mímọ́ kankan. Ní gbogbo ọdún keje àwa kò ní ro ilẹ̀ náà, a ó sì pa gbogbo àwọn gbèsè rẹ́.
32 Nous établirons une ordonnance afin de lever sur nous un tiers de drachme, par an, pour le service du temple de notre Dieu;
“Àwa gbà ojúṣe láti máa pa àṣẹ mọ́ pé, a ó máa san ìdámẹ́ta ṣékélì ní ọdọọdún fún iṣẹ́ ilé Ọlọ́run wa:
33 Pour les pains de proposition, pour le sacrifice perpétuel, et pour l'holocauste perpétuel, tant des sabbats que des nouvelles lunes, pour les fêtes et les jours saints, pour les péchés, pour les hosties pacifiques et pour les travaux du temple de notre Dieu.
nítorí oúnjẹ tí ó wà lórí tábìlì; nítorí ọrẹ ohun jíjẹ àti ẹbọ sísun ìgbà gbogbo; nítorí ọrẹ ọjọ́ ìsinmi, ti àyajọ́ oṣù tuntun àti àjọ̀dún tí a yàn; nítorí ọrẹ mímọ́; nítorí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣe ètùtù fún Israẹli; àti fún gbogbo iṣẹ́ ilé Ọlọ́run wa.
34 Nous avons ensuite jeté les sorts, entre les prêtres, les lévites et le peuple, par familles paternelles, pour régler l'oblation du bois dans le temple de notre Dieu, aux époques prescrites chaque année, pour faire les holocaustes sur l'autel du Seigneur notre Dieu, comme il est écrit en la loi;
“Àwa, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi àti àwọn ènìyàn náà ti dìbò láti pinnu ìgbà tí olúkúlùkù àwọn ìdílé yóò mú ọrẹ igi wá láti sun lọ́ríi pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa sí ilé Ọlọ́run wa, ní àkókò tí a yàn ní ọdọọdún. Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sínú ìwé òfin.
35 Pour que nous apportions les prémices des champs, et des arbres à fruit d'année en année, dans le temple du Seigneur,
“Àwa tún gbà ojúṣe láti mú àkọ́so àwọn èso wa wá àti gbogbo èso igi wá ní ilé Olúwa.
36 Et l'évaluation des fils premiers-nés, celle des premiers-nés des bêtes de somme, entre les mains des prêtres et des lévites de service dans le temple de Dieu; comme il est écrit en la loi, et les premiers-nés de nos bœufs et de nos brebis;
“Gẹ́gẹ́ bí a sì ti kọ ọ́ sínú ìwé òfin, àwa yóò mú àkọ́bí àwọn ọmọkùnrin wa, ti ohun ọ̀sìn wa, ti àwọn abo màlúù àti ti àwọn àgùntàn wa, wá sí ilé Ọlọ́run wa, fún àwọn àlùfáà tí ń ṣiṣẹ́ níbẹ̀.
37 Et pour que nous apportions aux prêtres, pour le trésor du temple de Dieu, les prémices de notre blé, des fruits de nos arbres, du vin et de l'huile; et aux lévites la dîme de notre terre, et pour que les lévites perçoivent la dîme en toutes les villes de la terre que nous cultivons.
“Síwájú sí i, àwa yóò mú àkọ́so oúnjẹ ilẹ̀ wa ti ọrẹ oúnjẹ, ti gbogbo èso àwọn igi àti ti wáìnì tuntun wa àti ti òróró wá sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ilé Ọlọ́run wa àti fún àwọn àlùfáà. Àwa yóò sì mú ìdámẹ́wàá ohun ọ̀gbìn wá fún àwọn ọmọ Lefi, nítorí àwọn ọmọ Lefi ni ó ń gba ìdámẹ́wàá ní gbogbo àwọn ìlú tí a ti ń ṣiṣẹ́.
38 Et nous avons dit: Le prêtre, fils d'Aaron, aura part avec le lévite à la dîme des lévites; et les lévites offriront le dixième de leur dîme dans le temple de notre Dieu, et dans le trésor du temple.
Àlùfáà tí o ti ìdílé Aaroni wá ni yóò wá pẹ̀lú àwọn ọmọ Lefi nígbà tí wọ́n bá ń gba ìdámẹ́wàá, àwọn ọmọ Lefi yóò sì mú ìdámẹ́wàá ti ìdámẹ́wàá náà wá sí ilé Ọlọ́run, sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí inú ilé ìṣúra.
39 Car, les fils d'Israël et les fils de Lévi apporteront au trésor les prémices de leur blé, de leur vin, de leur huile; et c'est là que seront les vases saints, sous la garde des prêtres, des serviteurs du temple, des chantres et des portiers; et nous n'abandonnerons pas le temple de notre Dieu.
Àwọn ènìyàn Israẹli, àti àwọn ọmọ Lefi gbọdọ̀ mú ọrẹ oúnjẹ, wáìnì tuntun àti òróró wá sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí níbi tí a pa ohun èlò ibi mímọ́ mọ́ sí àti ibi tí àwọn àlùfáà tí ń ṣe ìránṣẹ́ lọ́wọ́, àwọn aṣọ́nà àti àwọn akọrin máa ń dúró sí. “Àwa kì yóò gbàgbé tàbí ṣe àìbìkítà nípa ilé Ọlọ́run wa.”

< Néhémie 10 >