< Job 1 >
1 Il y avait en la terre de Hus, un homme appelé Job; et cet homme était intègre, irréprochable, juste, pieux, et il s'abstenait de toute mauvaise action.
Ọkùnrin kan wà ní ilẹ̀ Usi, orúkọ ẹni tí í jẹ́ Jobu; ọkùnrin náà sì ṣe olóòtítọ́, ó dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó kórìíra ìwà búburú.
2 Et il avait sept fils et trois filles.
A sì bi ọmọkùnrin méje àti ọmọbìnrin mẹ́ta fún un.
3 Et ses troupeaux étaient sept mille moutons, trois mille chamelles, cinq cents paires de bœufs, cinq cents ânesses au pâturage, et il avait une multitude de serviteurs et de grands travaux sur la terre; et cet homme avait la noblesse des fils de l'Orient.
Ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin àgùntàn, àti ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ìbákasẹ, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta àjàgà ọ̀dá màlúù, àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì pọ̀; bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin yìí sì pọ̀jù gbogbo àwọn ará ìlà-oòrùn lọ.
4 Et ses fils, se réunissant tour à tour, faisaient chaque jour un festin, et ils accueillaient aussi leurs trois sœurs pour boire et manger avec eux.
Àwọn ọmọ rẹ̀ a sì máa lọ í jẹun àsè nínú ilé ara wọn, olúkúlùkù ní ọjọ́ rẹ̀; wọn a sì máa ránṣẹ́ pé arábìnrin wọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta láti jẹun àti láti pẹ̀lú wọn.
5 Et dès que leurs jours de repas étaient écoulés, Job, s'étant levé de grand matin, les convoquait; et il les purifiait, et il immolait autant de victimes que le comportait leur nombre et de plus un bœuf pour le péché de leurs âmes. Car Job disait: Qui sait si les fils au fond du cœur, n'ont pas eu de mauvaises pensées contre Dieu? Ainsi faisait donc Job toutes les fois.
Ó sì ṣe, nígbà tí ọjọ́ àsè wọn pé yíká, ni Jobu ránṣẹ́ lọ í yà wọ́n sí mímọ́, ó sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì rú ẹbọ sísun níwọ̀n iye gbogbo wọn; nítorí tí Jobu wí pé: bóyá àwọn ọmọ mi ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣọpẹ́ fún Ọlọ́run lọ́kàn wọn. Bẹ́ẹ̀ ní Jobu máa ń ṣe nígbà gbogbo.
6 Or, l'un de ces jours-là, les anges de Dieu s'en vinrent comparaître devant le Seigneur, et le diable vint avec eux.
Ǹjẹ́ ó di ọjọ́ kan, nígbà tí àwọn ọmọ Ọlọ́run wá í pé níwájú Olúwa, Satani sì wá pẹ̀lú wọn.
7 Et le Seigneur dit au diable: D'où viens-tu? Et le diable répondit: J'arrive après avoir fait le tour de la terre et parcouru tout ce qui est sous le ciel.
Olúwa sì bi Satani wí pé, “Níbo ni ìwọ ti wá?” Nígbà náà ní Satani dá Olúwa lóhùn wí pé, “Ní ìlọsíwá-sẹ́yìn lórí ilẹ̀ ayé, àti ní ìrìnkèrindò nínú rẹ̀.”
8 Et le Seigneur reprit: As-tu remarqué Job, mon serviteur? as-tu reconnu qu'il n'a point son pareil sur la terre, que c'est un homme irréprochable, sincère, pieux, et qui s'abstient de toute mauvaise action?
Olúwa sì sọ fún Satani pé, “Ìwọ ha kíyèsi Jobu ìránṣẹ́ mi, pé kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ̀ ní ayé, ọkùnrin tí í ṣe olóòtítọ́, tí ó sì dúró ṣinṣin, ẹni tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, ti ó sì kórìíra ìwà búburú.”
9 Et le diable répondit et dit devant le Seigneur: Est-ce gratis que Job honore le Seigneur?
Nígbà náà ni Satani dá Olúwa lóhùn wí pé, “Jobu ha bẹ̀rù Ọlọ́run ní asán bí?”
10 N'avez-vous point fortifié sa maison, au-dedans comme au dehors, et, alentour tout ce qui lui appartient? n'avez-vous béni ses œuvres et multiplié ses troupeaux sur la terre?
“Ìwọ kò ha ti ṣọgbà yìí ká, àti yí ilé rẹ̀ àti yí ohun tí ó ní ká, ní ìhà gbogbo? Ìwọ bùsi iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀, ohun ọ̀sìn rẹ̀ sì ń pọ̀ si ní ilẹ̀.
11 Mais étendez votre main et qu'elle touche à ce qu'il possède, sinon il vous bénira en face.
Ǹjẹ́, nawọ́ rẹ nísinsin yìí, kí ó sì fi tọ́ ohun gbogbo tí ó ni; bí kì yóò sì bọ́hùn ni ojú rẹ.”
12 Alors le Seigneur dit au diable: Tu vois tout ce qui est à lui, je te le livre, mais ne touche pas à sa personne. Et le diable sortit de devant le Seigneur.
Olúwa sì dá Satani lóhùn wí pé, “Kíyèsi i, ohun gbogbo tí ó ní ń bẹ ní ìkáwọ́ rẹ, kìkì òun tìkára rẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ fi ọwọ́ rẹ kàn.” Bẹ́ẹ̀ ni Satani jáde lọ kúrò níwájú Olúwa.
13 Or, peu de temps après ce jour-là, les fils de Job et ses filles buvaient du vin en la maison de l'aîné de leurs frères.
Ó sì di ọjọ́ kan nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti obìnrin, tí wọ́n mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n wọn ọkùnrin,
14 Et un messager entra chez Job et il lui dit: Tes attelages de bœufs étaient au labour et les ânesses paissaient tout auprès.
oníṣẹ́ kan sì tọ Jobu wá wí pé, “Àwọn ọ̀dá màlúù ń tulẹ̀, àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì ń jẹ ní ẹ̀gbẹ́ wọn,
15 Et des hommes en armes sont venus et ils les ont enlevés, et ils ont tué tes serviteurs à coups de glaive; j'ai seul échappé et j'accours t'en apporter la nouvelle.
àwọn ará Sabeani sì kọlù wọ́n, wọ́n sì ń kó wọn lọ pẹ̀lú, wọ́n ti fi idà sá àwọn ìránṣẹ́ pa, èmi nìkan ṣoṣo ní ó sá àsálà láti ròyìn fún ọ.”
16 Comme celui-ci parlait encore survint un autre messager, et il dit à Job: Le feu du ciel est tombé et il a brûlé tes brebis, et il a dévoré pareillement les bergers; j'ai seul échappé et j'accours t'en apporter la nouvelle.
Bí ó ti ń sọ ní ẹnu; ẹnìkan dé pẹ̀lú tí ó sì wí pé, “Iná ńlá Ọlọ́run ti ọ̀run bọ́ sí ilẹ̀, ó sì jó àwọn àgùntàn àti àwọn ìránṣẹ́; èmi nìkan ṣoṣo ní ó sálà láti ròyìn fún ọ.”
17 Comme celui-ci parlait encore survint un autre messager, et il dit à Job: Des cavaliers nous ont attaqués sur trois points, et ils ont enveloppé tes chamelles, et ils les ont enlevées; et ils ont tué tes serviteurs à coups de glaive; j'ai seul échappé et j'accours t'en apporter la nouvelle.
Bí ó sì ti ń sọ ní ẹnu, ẹnìkan sì dé pẹ̀lú tí ó wí pé, “Àwọn ará Kaldea píngun sí ọ̀nà mẹ́ta, wọ́n sì kọlù àwọn ìbákasẹ, wọ́n sì kó wọn lọ, pẹ̀lúpẹ̀lú wọ́n sì fi idà sá àwọn ìránṣẹ́ pa; èmi nìkan ṣoṣo ni ó sá àsálà láti ròyìn fún ọ!”
18 Comme celui-ci parlait encore survint un autre messager, et il dit à Job: Tandis que tes fils et tes filles étaient à manger et à boire chez leur frère aîné,
Bí ó ti ń sọ ní ẹnu, ẹnìkan dé pẹ̀lú tí ó sì wí pé àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin ń jẹ, wọ́n ń mu ọtí wáìnì nínú ilé ẹ̀gbọ́n.
19 Soudain un grand vent est venu du désert et il a saisi les quatre coins de la maison; et elle s'est écroulée sur tes enfants; et ils sont morts; j'ai seul échappé et j'accours t'en apporter la nouvelle.
Sì kíyèsi i, ẹ̀fúùfù ńlá ńlá ti ìhà ijù fẹ́ wá kọlu igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilé, ó sì wó lu àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin náà, wọ́n sì kú, èmi nìkan ṣoṣo ni ó yọ láti ròyìn fún ọ.
20 Or, Job s'étant levé déchira ses vêtements, et il se coupa toute la chevelure, et, s'est prosternant la face contre terre, il adora, et il dit:
Nígbà náà ni Jobu dìde, ó sì fa aṣọ ìgúnwà rẹ̀ ya, ó sì fá orí rẹ̀ ó wólẹ̀ ó sì gbàdúrà
21 Nu je suis sorti des entrailles de ma mère, nu je partirai d'ici; le Seigneur n'avait donné, le Seigneur m'a ôté, il est advenu comme il a plu au Seigneur; béni soit le nom du Seigneur.
wí pé, “Ní ìhòhò ní mo ti inú ìyá mi jáde wá, ni ìhòhò ní èmi yóò sì tún padà lọ. Olúwa fi fún ni, Olúwa sì gbà á lọ, ìbùkún ni fún orúkọ Olúwa.”
22 Malgré tout ce qui lui est arrivé, Job ne pécha point contre le Seigneur; et il n'accusa point Dieu d'avoir manqué de sagesse.
Nínú gbogbo èyí Jobu kò ṣẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sì fi òmùgọ̀ pe Ọlọ́run lẹ́jọ́.