< Amos 4 >

1 Écoutez cette parole, génisses de la Basanite, qui êtes en la montagne de Samarie, vous qui opprimez les pauvres, qui foulez aux pieds les indigents, et qui dites à vos maîtres: Donnez-nous afin que nous buvions.
Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ẹ̀yin màlúù Baṣani lórí òkè Samaria, ẹ̀yin obìnrin tí ó ń ni tálákà lára, tí ó ń tẹ aláìní mọ́lẹ̀, tí ó wí fún ọkọ rẹ̀, “Gbé wá kí a sì mu!”
2 Le Seigneur jure par Ses saints que les temps arrivent contre vous, où l'on vous enlèvera avec des armes, et où les hommes de pestilence, enflammés de colère, jetteront ceux qui seront avec vous en des chaudières bouillantes.
Olúwa Olódùmarè ti fi ìwà mímọ́ rẹ̀ búra: “Àkókò náà yóò dé nítòótọ́ nígbà tí a ó fi ìwọ̀ mú un yín lọ, ẹni tí ó kẹ́yìn pẹ̀lú ìwọ̀ ẹja.
3 Et vous, vous serez entraînées nues, les unes devant les autres, et vous serez précipitées en la montagne de Rhomman, dit le Seigneur.
Ẹni kọ̀ọ̀kan yín yóò jáde lọ gba àárín odi yíya a ó sì lé e yín sí Harmoni,” ni Olúwa wí.
4 Vous êtes entrés à Béthel, et vous avez péché, et vous avez multiplié vos impiétés en Galgala; dès le matin, vous avez offert vos oblations, et donné vos dîmes durant les trois jours.
“Ẹ lọ sí Beteli láti dẹ́ṣẹ̀; ẹ lọ sí Gilgali kí ẹ sì dẹ́ṣẹ̀ sí i. Ẹ mú ẹbọ sísun yín láràárọ̀ wá, ìdámẹ́wàá yín ní ọdọọdún mẹ́ta.
5 Et ils ont lu la loi au dehors; et ils ont fait des invocations à haute voix. publiez que les fils d'Israël ont aimé ces choses, dit le Seigneur.
Kí ẹ mú ọ̀rẹ́ ìdúpẹ́ ìyẹ̀fun ìwúkàrà ti a sun kí ẹ sì mú ọrẹ àtinúwá lọ fi wọ́n yangàn, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli, nítorí èyí ni ẹ fẹ́ láti ṣe,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
6 Et Moi, en toutes vos villes, Je vous ferai grincer des dents; il y aura disette de pain en toutes vos maisons, et vous ne vous êtes point convertis à Moi, dit le Seigneur.
“Èmi fún un yín ní mímọ́ eyín ní gbogbo ìlú yín, àti àìní oúnjẹ ní gbogbo ibùgbé yín, síbẹ̀, ẹ̀yin kò yípadà sọ́dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
7 Et Moi, Je vous ai refusé la pluie, trois mois avant la vendange; Je ferai pleuvoir sur telle ville; sur telle autre, Je ne ferai point pleuvoir; sur tel terrain, il pleuvra; et tel autre, où il n'aura pas plu, sera desséché.
“Àti pẹ̀lú mo mú òjò dúró nígbà tí ìkórè ku oṣù mẹ́ta. Mo rán òjò sí ibùgbé kan ṣùgbọ́n kò rọ̀ sí ìlú mìíràn. Oko kan ní òjò; àwọn mìíràn kò ní ó sì gbẹ.
8 Et les habitants de deux ou trois villes se rassembleront en une seule ville, pour boire de l'eau, et ils ne seront point désaltérés; et vous ne vous êtes point convertis à Moi, dit le Seigneur.
Àwọn ènìyàn ń rìn láti ìlú kan sí ìlú mìíràn fún omi wọn kò rí mu tẹ́ wọn lọ́rùn, síbẹ̀ ẹ̀yin kò padà sí ọ̀dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
9 Je vous ai frappés de la fièvre et de la jaunisse. Vous avez multipliés vos jardins et vos vignes; mais les chenilles ont dévoré vos plants de figuiers et d'oliviers; et vous ne vous êtes point convertis à Moi, dit le Seigneur.
“Lọ́pọ̀ ìgbà ni mo kọlu ọgbà àti ọgbà àjàrà yín mo fi ìrẹ̀dànù àti ìmúwòdù lù wọ́n. Eṣú sì jẹ igi ọ̀pọ̀tọ́ àti igi olifi yín, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
10 Je vous ai envoyé la mort par les chemins de l'Égypte; J'ai fait tomber vos jeunes gens sous le glaive, et vos chevaux ont été pris; dans Ma colère, J'ai livré vos camps à la flamme; et, même après cela, vous ne vous êtes point convertis à Moi, dit le Seigneur.
“Mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn sí i yín bí mo ti ṣe sí Ejibiti. Mo fi idà pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín. Pẹ̀lú àwọn ẹṣin tí a kó ní ìgbèkùn. Mo kún imú yín fún òórùn ibùdó yín, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
11 Je vous ai renversés, comme Dieu renversa Sodome et Gomorrhe, et vous êtes devenus semblables au tison que l'on retire du foyer; et, même après cela, vous ne vous êtes point convertis à Moi, dit le Seigneur.
“Mo ti bì ṣubú nínú yín, bí Ọlọ́run ti bi Sodomu àti Gomorra ṣubú ẹ̀yin sì dàbí ògúnná tí a fa yọ kúrò nínú iná, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
12 Et c'est pourquoi J'agirai ainsi envers toi, ô Israël; et parce que J'agirai ainsi, prépare-toi à invoquer ton Dieu, ô Israël.
“Nítorí náà, èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí i yín, Israẹli, àti nítorí tí èmi ó ṣe èyí sí i yín, ẹ múra láti pàdé Ọlọ́run yín, ẹ̀yin Israẹli.”
13 Car Me voici, Moi qui affermis le tonnerre, qui fais naître les vents, qui annonce aux hommes Mon Christ, qui fais l'aurore et la brume, qui monte sur les hauts lieux de la terre. Le Seigneur tout-puissant, voilà Mon Nom.
Ẹni tí ó dá àwọn òkè tí ó dá afẹ́fẹ́ tí ó sì fi èrò rẹ̀ hàn sí ènìyàn, ẹni tí ó yípadà sí òkùnkùn tí ó sì tẹ ibi gíga ayé. Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.

< Amos 4 >