< Osée 14 >

1 Israël, reviens à ton Dieu; car tes fils s'énervent, à cause de tes iniquités.
Yípadà ìwọ Israẹli sí Olúwa Ọlọ́run rẹ. Ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ló fa ìparun rẹ!
2 Prenez avec vous de bonnes paroles, et convertissez-vous au Seigneur votre Dieu: dites-Lui que vous renoncez aux récompenses de l'iniquité pour choisir le bien; dites-Lui: Nous T'offrons les fruits de nos lèvres!
Ẹ gba ọ̀rọ̀ Olúwa gbọ́, kí ẹ sì yípadà sí Olúwa. Ẹ sọ fún un pé, “Darí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá kí o sì fi oore-ọ̀fẹ́ gbà wá, kí àwa kí ó lè fi ètè wa sán an fún ọ
3 Assur ne nous sauvera pas; nous ne monterons plus à cheval; nous ne dirons plus aux œuvres de nos mains: Vous êtes nos dieux; Celui qui est en vous, Seigneur, aura pitié de l'orphelin!
Asiria kò le gbà wá là; a kò ní í gorí ẹṣin ogun. A kò sì ní tún sọ ọ́ mọ́ láé, ‘Àwọn ni òrìṣà wa’ sí àwọn ohun tí ó fi ọwọ́ wa ṣe; nítorí pé lọ́dọ̀ rẹ ni àwọn aláìní baba tí ń rí àánú.”
4 Le Seigneur a dit: Je restaurerai leurs demeures, Je les aimerai manifestement, parce qu'ils ont détourné d'eux Ma colère.
“Èmi wo àgàbàgebè wọn sàn, Èmi ó sì fẹ́ràn wọn, lọ́fẹ̀ẹ́, nítorí ìbínú mi ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn.
5 Je serai pour Israël comme la rosée; il fleurira comme le lis, et il jettera ses racines comme le cèdre du Liban.
Èmi o dàbí ìrì sí Israẹli, wọn o sì yọ ìtànná bi ewéko lílì. Bi kedari ti Lebanoni yóò si ta gbòǹgbò.
6 Ses rameaux s'étendront; il sera chargé de fruits comme un olivier, et il répandra ses parfum comme l'encens.
Àṣẹ̀ṣẹ̀yọ ẹ̀ka rẹ̀ yóò dàgbà, dídán ẹwà yóò rẹ̀ dànù bí igi olifi. Òórùn rẹ yóò sì dàbí igi kedari ti Lebanoni.
7 Les peuples se convertiront et viendront s'asseoir sous son ombre; ils vivront et se rassasieront de son pain; et son mémorial fleurira comme une vigne, comme le vin du Liban
Àwọn ènìyàn yóò tún padà gbé lábẹ́ òjijì rẹ̀. Yóò rúwé bi ọkà. Yóò sì yọ ìtànná bi àjàrà, òórùn rẹ yóò dàbí ti wáìnì Lebanoni.
8 en Éphraïm. Qu'y a-t-il encore de commun entre lui et les idoles? Je l'ai humilié, et Je rétablirai ses forces. Je suis comme un genièvre touffu; c'est de moi que viennent tes fruits.
Ìwọ Efraimu, kín ló tún kù tí mo ní ṣe pẹ̀lú ère òrìṣà? Èmi ó dá a lóhùn, èmi ó sì ṣe ìtọ́jú rẹ. Mo dàbí igi junifa tó ń fi gbogbo ìgbà tutù, èso tí ìwọ ń so si ń wá láti ọ̀dọ̀ mi.”
9 Qui est sage et comprendra ces choses? Qui est savant et les connaîtra? Les voies du Seigneur sont étroites; les justes y marchent, les impies y trébucheront.
Ta ni ọlọ́gbọ́n? Òun yóò mòye àwọn nǹkan wọ̀nyí. Ta a ní ó mọ̀? Òun yóò ní ìmọ̀ wọn. Títọ́ ni ọ̀nà Olúwa àwọn olódodo si ń rìn nínú wọn, ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́tẹ̀ ni yóò kọsẹ̀ nínú wọn.

< Osée 14 >