< 2 Chroniques 19 >

1 Et Josaphat, roi de Juda, revint en son palais à Jérusalem.
Nígbà tí Jehoṣafati ọba Juda padà ní àlàáfíà sí ilé rẹ̀ ní Jerusalẹmu,
2 Et le prophète Jéhu, fils d'Anani, sortit à sa rencontre, et il lui dit Roi Josaphat, n'as-tu pas porté secours à un impie, et donné ton amitié à un ennemi du Seigneur? A cause de cela, la colère du Seigneur a été excitée contre toi.
Jehu aríran, ọmọ Hanani jáde lọ láti lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí fún ọba pé, “Ṣé ìwọ yóò máa ran ènìyàn búburú lọ́wọ́, kí o sì fẹ́ràn àwọn tí ó kórìíra Olúwa? Nítorí èyí, ìbínú Olúwa wà lórí wa.
3 Cependant, il s'est trouvé du bon en toi; car tu as détruit les bois sacrés en la terre de Juda, et, d'un cœur droit, tu as cherché Dieu.
Bí ó ti wù kí ó rí, ohun rere wà nínú rẹ, nítorí tí ìwọ ti mú àwọn ilé àwọn ère òrìṣà Aṣerah kúrò, tí o sì múra ọkàn rẹ láti wá Ọlọ́run.”
4 Et Josaphat résida en Jérusalem; il en sortit encore une fois pour visiter le peuple depuis Bersabée jusqu'aux montagnes d'Ephraïm, et il les ramena au Seigneur Dieu de leurs pères.
Jehoṣafati sì ń gbé ní Jerusalẹmu ó sì jáde lọ padà láàrín àwọn ènìyàn láti Beerṣeba dé òkè ìlú Efraimu, ó sì mú wọn padà sọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run baba wọn.
5 Et il institua des juges dans toutes les places fortes de Juda: un par ville.
Ó sì yan àwọn onídàájọ́ sí ilẹ̀ náà, ní olúkúlùkù ìlú olódi Juda.
6 Et il dit aux juges: Soyez attentifs à ce que vous faites; car vous ne jugez pas pour l'homme, mais pour le Seigneur, et les paroles du jugement sont avec vous.
Ó sì wí fun wọ́n pé, “Ẹ kíyèsi ohun tí ẹ̀yin ń ṣe, nítorí ìwọ kò ṣe ìdájọ́ fun ènìyàn ṣùgbọ́n fún Olúwa, ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ ní ìdájọ́.
7 Que la crainte du Seigneur soit donc en vous; veillez et agissez; car, avec le Seigneur notre Dieu, il n'est point d'iniquité; il n'y a point à considérer la personne, ni à recevoir des présents.
Nísinsin yìí jẹ́ kí ìbẹ̀rù Olúwa kí ó wá sí ọkàn rẹ̀. Ṣe ìdájọ́ pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́, nítorí pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run kò sí àìṣedéédéé tàbí ojúsàájú tàbí gbígba àbẹ̀tẹ́lẹ̀.”
8 Et Josaphat institua en Jérusalem des prêtres, des lévites et des chefs de familles d'Israël, pour juger les choses du Seigneur et les habitants de la ville.
Ní Jerusalẹmu pẹ̀lú, Jehoṣafati yan díẹ̀ lára àwọn Lefi, àwọn àlùfáà àti àwọn olórí ìdílé Israẹli si pípa òfin Olúwa mọ́ àti láti ṣe ìdájọ́. Wọn sì ń gbé ní Jerusalẹmu.
9 Et il leur donna ses ordres, disant: Vous ferez votre devoir avec la crainte de Dieu, en la plénitude et en la sincérité de votre cœur.
Ó sì kìlọ̀ fún wọn wí pé. “Ìwọ gbọdọ̀ sìn pẹ̀lú òtítọ́ àti pẹ̀lú ọkàn pípé ní ìbẹ̀rù Olúwa.
10 Quels que soient ceux de vos frères qui, de leurs villes, viendront à vous en justice, soit pour une décision entre le sang et le sang, soit pour une application des commandements et des préceptes, déterminez bien pour eux le droit et la sentence; et ils ne pècheront pas envers le Seigneur, et il n'y aura point de colère, ni contre vos frères, ni contre vous. Faites ainsi, et vous ne pècherez pas.
Ní gbogbo ẹjọ́ tí ó bá wà níwájú rẹ láti ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin yín tí ń gbé ìlú wọn bóyá ẹ̀jẹ̀ tí ń sàn tàbí ìyókù òfin pẹ̀lú, pa á láṣẹ ìlànà àti ẹ̀tọ́, ìwọ gbọdọ̀ kìlọ̀ fún wọn láti má ṣe dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ìbínú yóò sì wá sórí yín, àti sórí àwọn arákùnrin. Ṣe èyí, ìwọ kì yóò sì jẹ̀bi.
11 Et Ananias le prêtre sera votre chef en ce qui concernera le Seigneur; Zabdias, fils d'Ismaël, prince de la maison de Juda, sera votre chef en ce qui concernera le roi, et vous aurez avec vous des scribes et des lévites; fortifiez-vous, et faites, et le Seigneur sera avec les bons.
“Amariah àlùfáà ni yóò jẹ́ olórí yín nínú gbogbo ọ̀ràn tí ó jẹ́ ti Olúwa, àti Sebadiah ọmọ Iṣmaeli alákòóso ìdílé Juda, ní yóò jẹ́ olórí ní gbogbo ọ̀rọ̀ tí ọba, àti àwọn ará Lefi pẹ̀lú yin yóò sìn gẹ́gẹ́ bí ìjòyè níwájú yín. Ẹ ṣe é pẹ̀lú ìmọ́kànle, Olúwa yóò sì wà pẹ̀lú àwọn tó bá ń ṣe rere.”

< 2 Chroniques 19 >