< Jérémie 39 >

1 qu’en la neuvième année de Sédécias, roi de Juda, au dixième mois, Nebucadretsar, roi de Babylone, vint, et toute son armée, contre Jérusalem, et ils l’assiégèrent.
Ó sì ṣe, nígbà tí a kó Jerusalẹmu, ní ọdún kẹsànán Sedekiah, ọba Juda, nínú oṣù kẹwàá, Nebukadnessari ọba Babeli gbógun ti Jerusalẹmu pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀, wọ́n sì dó tì í.
2 En la onzième année de Sédécias, au quatrième mois, le neuvième [jour] du mois, la brèche fut faite à la ville.
Ní ọjọ́ kẹsànán, oṣù kẹrin ọdún kọkànlá Sedekiah, ni a wó odi ìlú náà.
3 Et tous les princes du roi de Babylone entrèrent, et s’assirent dans la porte intérieure: Nergal-Sharétser, Samgar-Nebu, Sarsekim, chef des eunuques, Nergal-Sharétser, chef des mages, et tout le reste des princes du roi de Babylone.
Nígbà náà ni gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli wá, wọ́n sì jókòó ní àárín ẹnu ibodè, àní Nergali-Ṣareseri ti Samgari, Nebo-Sarsikimu olórí ìwẹ̀fà, Nergali-Ṣareseri, olórí amòye, pẹ̀lú gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli yóò kú.
4 Et il arriva que, quand Sédécias, roi de Juda, et tous les hommes de guerre les eurent vus, ils s’enfuirent, et sortirent de nuit de la ville, par le chemin du jardin du roi, par la porte qui était entre les deux murailles; et il sortit par le chemin de la plaine.
Nígbà tí Sedekiah ọba Juda àti àwọn ọmọ-ogun rí wọn, wọ́n sá, wọ́n kúrò ní ìlú ní alẹ́, wọ́n gba ọ̀nà ọgbà ọba lọ láàrín ẹnu ibodè pẹ̀lú odi méjì, wọ́n dojúkọ aginjù.
5 Et l’armée des Chaldéens les poursuivit, et ils atteignirent Sédécias dans les plaines de Jéricho, et ils le prirent, et le firent monter vers Nebucadnetsar, roi de Babylone, à Ribla, dans le pays de Hamath; et il prononça son jugement.
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ọmọ-ogun Babeli lé wọn, wọ́n bá Sedekiah láàrín aginjù Jeriko. Wọ́n mú un ní ìgbèkùn, wọ́n sì mú u tọ Nebukadnessari ọba Babeli àti Ribla ní ilẹ̀ Hamati, níbi tí wọ́n ti ṣe ìdájọ́ rẹ̀.
6 Et le roi de Babylone égorgea les fils de Sédécias, à Ribla, devant ses yeux; et le roi de Babylone égorgea tous les nobles de Juda;
Níbẹ̀ ní Ribla, ni ọba Babeli ti dúńbú àwọn ọmọ Sedekiah lójú rẹ̀, tí ó sì tún pa gbogbo àwọn ọlọ́lá ilẹ̀ Juda.
7 et il creva les yeux à Sédécias, et le lia avec des chaînes d’airain, pour le mener à Babylone.
Nígbà náà ni ó fọ́ ojú Sedekiah, ó sì dè é pẹ̀lú ẹ̀wọ̀n láti gbé e lọ sí ilẹ̀ Babeli.
8 Et les Chaldéens brûlèrent par le feu la maison du roi et les maisons du peuple, et ils abattirent les murailles de Jérusalem.
Àwọn Babeli dáná sun ààfin ọba àti ilé àwọn ènìyàn, wọ́n sì wó odi Jerusalẹmu.
9 Et le reste du peuple qui était demeuré de reste dans la ville, et les transfuges qui étaient allés se rendre à lui, et le reste du peuple, ceux qui étaient de reste, Nebuzaradan, chef des gardes, les transporta à Babylone.
Nebusaradani olórí àwọn ọmọ-ogun mú lọ sí ìgbèkùn Babeli pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó ṣẹ́kù nínú ìlú.
10 Mais d’entre le peuple, Nebuzaradan, chef des gardes, laissa les pauvres, ceux qui n’avaient rien, dans le pays de Juda; et en ce jour-là il leur donna des vignes et des champs.
Ṣùgbọ́n Nebusaradani olórí ogun fi àwọn aláìní sílẹ̀ ní Juda, àwọn tí kò ní ohun kankan ní àkókò náà, ó fún wọn ní ọgbà àjàrà àti oko.
11 Et Nebucadretsar, roi de Babylone, avait commandé par Nebuzaradan, chef des gardes, touchant Jérémie, disant:
Nísinsin yìí, Nebukadnessari ọba àwọn Babeli pàṣẹ lórí Jeremiah, láti ọ̀dọ̀ Nebusaradani olórí ogun wá wí pé:
12 Prends-le, et aie les yeux sur lui, et ne lui fais aucun mal; mais selon ce qu’il te dira, ainsi agis avec lui.
“Ẹ gbé e, kí ẹ sì bojútó o. Ẹ má ṣe ṣe ohun búburú fún un, ṣùgbọ́n ohunkóhun tó bá béèrè ni kí ẹ fi fún un.”
13 Et Nebuzaradan, chef des gardes, envoya, et Nebushazban, chef des eunuques, et Nergal-Sharétser, chef des mages, et tous les chefs du roi de Babylone,
Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ pẹ̀lú, Nebusaradani balógun ìṣọ́, àti Nebusaradani olórí ìwẹ̀fà, àti Nergali-Ṣareseri, olórí amòye àti gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli,
14 envoyèrent, et prirent Jérémie de la cour de la prison, et le remirent à Guedalia, fils d’Akhikam, fils de Shaphan, pour le mener dehors, à la maison. Et il demeura au milieu du peuple.
ránṣẹ́ láti mú Jeremiah kúrò nínú túbú. Wọ́n gbé e lọ fún Gedaliah ọmọ Ahikamu ọmọ Ṣafani láti mú padà lọ sí ilé àti máa wà pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀.
15 Et la parole de l’Éternel vint à Jérémie, pendant qu’il était enfermé dans la cour de la prison, disant:
Nígbà tí Jeremiah wà nínú túbú, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ọ́ wá wí pé:
16 Va, et tu parleras à Ébed-Mélec, l’Éthiopien, disant: Ainsi dit l’Éternel des armées, le Dieu d’Israël: Voici, je fais venir mes paroles sur cette ville pour le mal, et non pour le bien; et elles auront lieu devant toi, en ce jour-là.
“Lọ sọ fún Ebedimeleki ará Kuṣi, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Èmi ṣetán láti mú ọ̀rọ̀ mi ṣẹ lórí ìlú yìí nípa àjálù kì í ṣe àlàáfíà. Ní àkókò náà ni yóò ṣẹ lójú rẹ.
17 Et je te délivrerai en ce jour-là, dit l’Éternel, et tu ne seras point livré en la main des hommes dont tu as peur;
Ṣùgbọ́n, Èmi yóò gbà ọ́ lọ́jọ́ náà ni Olúwa wí. A kò ní fi ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí o bẹ̀rù.
18 car certainement je te sauverai, et tu ne tomberas pas par l’épée; et tu auras ta vie pour butin; car tu as eu confiance en moi, dit l’Éternel.
Èmi yóò gbà ọ́ là; o kò ní ṣubú láti ipa idà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ, nítorí pé ìwọ ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú mi, ni Olúwa wí.’”

< Jérémie 39 >