< Lamentations 3 >
1 Je suis l’homme qui ai vu l’affliction par la verge de sa fureur.
Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
2 Il m’a conduit et amené dans les ténèbres, et non dans la lumière.
Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
3 Certes c’est contre moi qu’il a tout le jour tourné et retourné sa main.
Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
4 Il a fait vieillir ma chair et ma peau; il a brisé mes os.
Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
5 Il a bâti contre moi, et m’a environné de fiel et de peine.
Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
6 Il m’a fait habiter dans des lieux ténébreux, comme ceux qui sont morts depuis longtemps.
Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
7 Il a fait une clôture autour de moi, afin que je ne sorte point; il a appesanti mes chaînes.
Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
8 Même quand je crie et que j’élève ma voix, il ferme l’accès à ma prière.
Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
9 Il a barré mes chemins avec des pierres de taille; il a bouleversé mes sentiers.
Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
10 Il a été pour moi un ours aux embûches, un lion dans les lieux cachés.
Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
11 Il a fait dévier mes chemins et m’a déchiré; il m’a rendu désolé.
Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
12 Il a bandé son arc, et m’a placé comme un but pour la flèche.
Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
13 Il a fait entrer dans mes reins les flèches de son carquois.
Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
14 Je suis la risée de tout mon peuple, leur chanson tout le jour.
Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
15 Il m’a rassasié d’amertumes, il m’a abreuvé d’absinthe.
Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
16 Il m’a brisé les dents avec du gravier; il m’a couvert de cendre.
Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
17 Et tu as rejeté mon âme loin de la paix, j’ai oublié le bonheur;
Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
18 et j’ai dit: Ma confiance est périe, et mon espérance en l’Éternel.
Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
19 Souviens-toi de mon affliction, et de mon bannissement, de l’absinthe et du fiel.
Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
20 Mon âme s’en souvient sans cesse, et elle est abattue au-dedans de moi. –
Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
21 Je rappelle ceci à mon cœur, c’est pourquoi j’ai espérance:
Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
22 Ce sont les bontés de l’Éternel que nous ne sommes pas consumés, car ses compassions ne cessent pas;
Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
23 elles sont nouvelles chaque matin; grande est ta fidélité!
Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
24 L’Éternel est ma portion, dit mon âme; c’est pourquoi j’espérerai en lui.
Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
25 L’Éternel est bon pour ceux qui s’attendent à lui, pour l’âme qui le cherche.
Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
26 C’est une chose bonne qu’on attende, et dans le silence, le salut de l’Éternel.
Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
27 Il est bon à l’homme de porter le joug dans sa jeunesse:
Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
28 Il est assis solitaire, et se tait, parce qu’il l’a pris sur lui;
Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
29 il met sa bouche dans la poussière: peut-être y aura-t-il quelque espoir.
Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
30 Il présente la joue à celui qui le frappe, il est rassasié d’opprobres.
Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
31 Car le Seigneur ne rejette pas pour toujours;
Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
32 mais, s’il afflige, il a aussi compassion, selon la grandeur de ses bontés;
Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
33 car ce n’est pas volontiers qu’il afflige et contriste les fils des hommes.
Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
34 Qu’on écrase sous les pieds tous les prisonniers de la terre,
Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
35 qu’on fasse fléchir le droit d’un homme devant la face du Très-haut,
Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
36 qu’on fasse tort à un homme dans sa cause, le Seigneur ne le voit-il point?
láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
37 Qui est-ce qui dit une chose, et elle arrive, quand le Seigneur ne l’a point commandée?
Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
38 N’est-ce pas de la bouche du Très-haut que viennent les maux et les biens?
Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
39 Pourquoi un homme vivant se plaindrait-il, un homme, à cause de la peine de ses péchés?
Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
40 Recherchons nos voies, et scrutons-les, et retournons jusqu’à l’Éternel.
Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
41 Élevons nos cœurs avec nos mains vers Dieu dans les cieux.
Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
42 Nous avons désobéi et nous avons été rebelles; tu n’as pas pardonné.
“Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
43 Tu t’es enveloppé de colère et tu nous as poursuivis; tu as tué, tu n’as point épargné.
“Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
44 Tu t’es enveloppé d’un nuage, de manière à ce que la prière ne passe point.
Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
45 Tu nous as faits la balayure et le rebut au milieu des peuples.
Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
46 Tous nos ennemis ont ouvert la bouche sur nous.
“Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
47 La frayeur et la fosse sont venues sur nous, la destruction et la ruine.
Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
48 Des ruisseaux d’eaux coulent de mes yeux à cause de la ruine de la fille de mon peuple.
Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
49 Mon œil se fond en eau, il ne cesse pas et n’a point de relâche,
Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
50 jusqu’à ce que l’Éternel regarde et voie des cieux.
títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
51 Mon œil afflige mon âme à cause de toutes les filles de ma ville.
Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
52 Ceux qui sont mes ennemis sans cause m’ont donné la chasse comme à l’oiseau.
Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
53 Ils m’ont ôté la vie dans une fosse, et ont jeté des pierres sur moi.
Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
54 Les eaux ont coulé par-dessus ma tête; j’ai dit: Je suis retranché!
Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
55 J’ai invoqué ton nom, ô Éternel! de la fosse des abîmes.
Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
56 Tu as entendu ma voix; ne cache point ton oreille à mon soupir, à mon cri.
Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
57 Tu t’es approché au jour où je t’ai invoqué; tu as dit: Ne crains pas.
O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
58 Seigneur, tu as pris en main la cause de mon âme, tu as racheté ma vie.
Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
59 Tu as vu, Éternel, le tort qu’on me fait; juge ma cause.
O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
60 Tu as vu toute leur vengeance, toutes leurs machinations contre moi.
Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
61 Tu as entendu leurs outrages, ô Éternel! toutes leurs machinations contre moi,
Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
62 les lèvres de ceux qui s’élèvent contre moi, et ce qu’ils se proposent contre moi tout le jour.
ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
63 Regarde quand ils s’asseyent et quand ils se lèvent: je suis leur chanson.
Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
64 Rends-leur une récompense, ô Éternel! selon l’ouvrage de leurs mains.
Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
65 Donne-leur un cœur cuirassé; ta malédiction soit sur eux!
Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
66 Poursuis-les dans ta colère et détruis-les de dessous les cieux de l’Éternel.
Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.