< Hosea 2 >
1 [At that time, ] you will say to your fellow-Israeli men, “[You are] God’s people,” and [you will say] to your fellow-Israeli women, “You are ones whom God loves.”
“Sọ fún àwọn arákùnrin rẹ, ‘Ènìyàn mi,’ kí o sì wí fún àwọn arábìnrin rẹ ‘Àyànfẹ́ mi.’
2 [Yahweh also said to me], “I want you to accuse the Israeli people. [It is as though] [MET] this nation is your mother, but this nation is [no longer as though it is] [MET] my wife, and it is [no longer as though] [MET] I am its husband. Tell the Israeli people that they must stop [acting like] a prostitute [by worshiping other gods]; they must stop showing by their behavior that they (are unfaithful to/have abandoned) [me] [MET].
“Ẹ bá ìyá yín wí, ẹ bá a wí, nítorí pé kì í ṣe ìyàwó mi, Èmi náà kì í sì í ṣe ọkọ rẹ̀. Jẹ́ kí ó yọ àgbèrè rẹ̀ kúrò lójú rẹ̀ àti àìṣòótọ́ kúrò ní àyà rẹ̀.
3 If they do not do that, I will not give them [food and] clothes [as a husband should give to his wife]; I will take away those things, and I will cause their nation to become [as deserted] as it was on the day that I [brought their ancestors out of Egypt and caused them to become a nation] [MET]. I will cause their country to be like [SIM] a desert; there will be no rain to water the ground [MET].
Àìṣe bẹ́ẹ̀ èmi yóò tú u sí ìhòhò, Èmi yóò sì gbé e kalẹ̀ bí ọjọ́ tí a bí i. Èmi yóò ṣe ọ́ bí i aṣálẹ̀ ilẹ̀, Èmi yóò sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀ Èmi yóò sì fi òǹgbẹ gbẹ ẹ́.
4 I will not pity the people, because they have [abandoned me] as [MET] prostitutes abandon their husbands.
Èmi kò ní fi àánú mi hàn sí àwọn ọmọ rẹ̀ nítorí ọmọ àgbèrè ni wọ́n jẹ́.
5 Their parents are like prostitutes [MET]: they have been unfaithful [to me], and they have done [very] disgraceful things. They said, ‘We will run to [our idols/gods] who love us; [they are the ones] who give us food and water and wool and linen and [olive] oil, and [wine to] drink.’
Nítorí ìyá wọn ti hùwà àgbèrè, ó sì lóyún wọn nínú ìtìjú. Ó wí pé, ‘Èmi ó tún tọ́ àwọn àyànfẹ́ mi lẹ́yìn, tó ń fún mi ní oúnjẹ àti omi, ní irun àgùntàn mi àti ọ̀gbọ̀ mi, òróró mi àti ohun mímu mi.’
6 So [it will be as though] [MET] I am blocking their road with thornbushes, and putting put a wall around them so that they do not know which way to go.
Nítorí náà, èmi ó fi ẹ̀gún dì í lọ́nà, Èmi ó mọ odi yí i ká kí ó má ba à rọ́nà lọ.
7 They will run to their idols/gods that [they think] love them, but they will not find them. They will search for their false gods, but they will not find them. Then they will say, ‘[Perhaps] we should return to [Yahweh], whom we worshiped previously [MET], because things were better for us then than they are now.’
Yóò sáré lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ ṣùgbọ́n kò ní bá wọn; yóò wá wọn ṣùgbọ́n kò ní rí wọn. Nígbà náà ni yóò sọ pé, ‘Èmi ó padà sí ọ̀dọ̀ ọkọ mi àkọ́kọ́ nítorí pé ó dára fún mi nígbà náà ju ìsinsin yìí lọ.’
8 But they do not realize that I, [Yahweh], am the one who gave them grain and wine and [olive] oil; I am the one who gave them silver and gold which they used to worship Baal.
Nítorí pé kò tí ì mọ̀ pé èmi ni àti ẹni tó fún un ní ọkà, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ẹni tí ó fún un ní fàdákà àti wúrà lọ́pọ̀lọ́pọ̀, èyí tí wọ́n lò fún Baali.
9 Therefore I will return and take my grain and grapes from them when they are ripe. I will take from them the wool and linen that I gave to them [to make their clothes] [MTY].
“Nítorí náà, èmi yóò mú ọkà mi kúrò nígbà tó bá pọ́n, èmi yóò sì mú wáìnì mi kúrò ní àsìkò rẹ̀. Èmi yóò sì gba irun àgùntàn àti ọ̀gbọ̀ mi padà ti mo ti fi fún un láti bo ìhòhò rẹ̀.
10 I will show those false gods/idols that what my people are doing is disgusting [MET], and no one will be able to hinder me from [punishing them].
Èmi yóò sì fi ìwà ìtìjú rẹ̀ hàn lójú àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ kò sí ẹni tí yóò gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ mi,
11 I will cause their religious celebrations to cease, the festivals that they celebrate every year and at every new moon and on their (Sabbath days/weekly days of rest). I will cause all their religious celebrations to cease.
Èmi yóò mú gbogbo ayọ̀ rẹ̀ wá sí òpin: àjọ̀dún ọdọọdún rẹ̀, oṣù tuntun rẹ̀, ọjọ́ ìsinmi, àti gbogbo àwọn àjọ̀dún tí a yàn.
12 I will destroy [all] their grapevines and fig trees, which they said were what their [idols/gods] who loved them paid them for worshiping those idols. I will cause those places to become a desert, and wild animals will eat the fruit [that remains].
Èmi yóò pa àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀ run, èyí tí ó pè ní èrè rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, Èmi yóò sọ wọ́n di igbó, àwọn ẹranko búburú yóò sì jẹ́ wọn run.
13 I will punish my people for [all] the times that they burned incense to [honor] the idols of Baal. They decorated themselves with rings and jewelry, and they went to worship those [false gods/idols] that [they thought] [IRO] loved them, but they abandoned/forgot me! [That is what I], Yahweh, say.
Èmi yóò bẹ̀ ọjọ́ Baalimu wò ní ara rẹ̀ nínú èyí tó ń fi tùràrí jóná fún Baali; tí ó fi òrùka etí àti ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́, tó sì tẹ̀lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ lọ. Ṣùgbọ́n èmi ni òun gbàgbé,” ni Olúwa wí.
14 But listen! [Some day] I will persuade my people [to worship me again]; I will lead them [out] into the desert and speak kindly to them [there].
“Nítorí náà, èmi yóò tàn án, Èmi ó sì mú u lọ sí ilẹ̀ aṣálẹ̀, Èmi ó fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ bá a sọ̀rọ̀
15 I will give their vineyards [back] to them, and I will cause Achor Valley, [which means ‘valley of trouble'], to become a valley where they will confidently expect [me to do good things for them]. They will (respond to/want to please) me there like they did long ago, when I freed them from [being slaves in] Egypt.
Níbẹ̀ ni èmi yóò ti dá ọgbà àjàrà rẹ̀ padà fún un, Èmi yóò fi àfonífojì Akori ṣe ìlẹ̀kùn ìrètí fún un. Yóò sì kọrin níbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà èwe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tó kúrò ní Ejibiti.
16 At that time, they will say to me, ‘[It is as though] [MET] you are our husband.’ They will not say that I am their [master, like they considered that] Baal [was].
“Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò pè mí ní ‘ọkọ mi’; ìwọ kò sì ní pè mí ní ‘olúwa à mi mọ́,’ ni Olúwa wí.
17 I will not allow them to speak [MTY] the names of Baal; they will never use those names again.
Èmi yóò mú orúkọ, àwọn òrìṣà Baali kúrò lẹ́nu rẹ̀; ìwọ kò sì ní rí orúkọ òrìṣà Baali pè mọ́.
18 At that time [it will be as though] I will make an agreement with [all] the wild animals and birds, and [even with] the little animals that scurry across the ground, so that they will never harm my people [again]. And I will remove from their nation all the weapons [for fighting] battles, [like] swords and bows [and arrows]. The result will be that my people will live peacefully and safely, and will not be afraid.
Ní ọjọ́ náà, èmi yóò ṣe májẹ̀mú fún wọn àti àwọn ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹ̀dá tí ń rìn lórí ilẹ̀. Kí wọn má bà á bẹ̀rù ara wọn mọ́. Ọfà, idà àti ogun jíjà ni èmi ó parun ní ilẹ̀ náà kí gbogbo ènìyàn bá a lè wà ní àìléwu.
19 I will cause them to be [as though they are] [MET] my bride forever. I will be righteous and fair/just; I will faithfully love them and be kind to them.
Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi títí láé; Èmi ó fẹ́ ọ ní ìwà òdodo àti òtítọ́, ní ìfẹ́ àti àánú.
20 I will not abandon them, and they will realize [that I] Yahweh, [have the power to do what I say that I will do.]
Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi ní òtítọ́ ìwọ yóò sì mọ Olúwa.
21 At that time, [when they request me to do things for them], [I will do those things]. When they request clouds and rain to fall on their land, I will speak to the clouds, and rain will fall on the earth,
“Èmi yóò sì dáhùn ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí; “Èmi yóò dá àwọn ọ̀run lóhùn àwọn ọ̀run yóò sì dá ilẹ̀ lóhùn;
22 and grain will grow, and the vineyards and the olive trees will grow in Jezreel [Valley].
ilẹ̀ náà yóò sì dá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró lóhùn Gbogbo wọn ó sì dá Jesreeli lóhùn.
23 [At that time], I will take care of the Israeli people [like a farmer plants and takes care of his crops] [MET]. I will love those people that I previously said were ones I did not love, and I previously said, ‘You are not my people,’ and [then] they will say to me, ‘You are our God.’”
Èmi ó sì gbìn ín fún ara mi lórí ilẹ̀ náà, Èmi yóò ṣàánú fún ẹni tí kò tì í ri ‘Àánú gbà.’ Èmi yóò sọ fún àwọn tí ‘Kì í ṣe ènìyàn mi pé,’ ‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi’; àwọn náà yóò sì wí pé, ‘Ìwọ ni Ọlọ́run mi.’”