< Lamentations 3 >
1 I [, the one who am writing this, ] am a man who has been afflicted/punished [MTY] by Yahweh because he was angry.
Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
2 [It was as though] he caused me to walk in a very dark place without any light [at all].
Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
3 He has punished [IDM] me many times, all day, [every] day.
Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
4 He has caused my skin and my flesh to become old. He has broken my bones.
Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
5 He has surrounded me [DOU] with bitterness and suffering.
Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
6 [It is as though] he has buried me in a dark place like [SIM] [the graves of] those who have been dead for a long time.
Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
7 [It is as though] [MET] he has built a wall around me, and fastened/tied me with heavy chains, and I cannot escape.
Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
8 Although I call out and cry out for him to help me, he does not pay attention to my prayers.
Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
9 [It is as though] he has blocked my path with a [high] stone [wall] and has caused my path to become crooked.
Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
10 He has waited to attack me like [SIM] a bear or a lion hides and waits [to attack other animals].
Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
11 [It is as though] he has dragged me off the path and (mauled me/torn me into pieces), and left me without help.
Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
12 [It is as though] [MET] he bent his bow and caused me to become the target [at which he shot] his arrows.
Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
13 [It is as though] he shot his arrows deep into my body.
Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
14 All my relatives laugh at me; all day, [every] day they sing songs that make fun of me.
Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
15 He has filled me with (bitterness/great suffering), [like] [MET] someone who drinks a very bitter liquid suffers.
Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
16 [It is as though] he has caused me to chew gravel that broke my teeth, and he has trampled me in the dirt.
Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
17 Things no longer go well for me; I no longer remember being prosperous.
Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
18 I [continued to] say [to myself], “I no longer expect to live much longer; I no longer confidently expect [to receive good things] from Yahweh!”
Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
19 When I think about my suffering and my wandering [away from home], [it is like drinking] a very bitter [DOU] liquid.
Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
20 I will never forget this time when I feel very depressed/discouraged [IDM].
Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
21 However, I confidently expect [Yahweh to do good things for me again] when I think about this:
Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
22 Yahweh never stops faithfully loving [us], and he never stops being kind to us.
Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
23 [He is the one whom we can] always trust/lean on. Every morning he is merciful [to us again].
Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
24 [So] I say to myself, “Yahweh is all that I need; so I will confidently wait for him [to do good things for me].”
Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
25 Yahweh is good to [all] those who depend on him, to those who seek his [help].
Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
26 [So] it is good for us to wait quietly for Yahweh to save/rescue [us].
Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
27 And it is good for us to [patiently] endure [suffering] while we are young.
Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
28 Those [who seek his help] should sit by themselves, silently, [knowing that] it is Yahweh who has allowed/caused them to suffer.
Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
29 They should lie in the dirt, with their faces on the ground, [because] they can still hope [that Yahweh will help them].
Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
30 If someone strikes us on one cheek, we should turn the other cheek toward that person [in order that he may strike it, too], and accept/endure it when we are insulted.
Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
31 Yahweh does not abandon [us his people] forever.
Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
32 Sometimes he causes us to suffer, but sometimes he is kind [to us] because he continually and faithfully loves [us].
Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
33 And he is not happy about causing human beings to suffer or to be sad.
Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
34 If people (mistreat all the prisoners/crush all the prisoners under their feet)
Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
35 or if they rebel against God by refusing to give to people the things that it is right for them [to receive],
Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
36 or if they cause judges to decide matters unjustly, (does Yahweh not see all those things?/Yahweh certainly sees all those things!) [RHQ]
láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
37 No one can [RHQ] command something to happen [and then cause it to happen] if Yahweh has not already decided that it should happen.
Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
38 God in heaven [MTY] is [RHQ] the one who causes disasters to happen, and he [also] causes good things to happen.
Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
39 [So] it is certainly not [RHQ] right for us, who are only humans, to complain when he punishes us for the sins that we have committed.
Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
40 Instead, we should (examine/think carefully about) our behavior; we should turn back to Yahweh.
Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
41 We should pray [IDM] sincerely and lift up our arms toward God in heaven, [and say, ]
Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
42 “We have sinned and rebelled [against you], and you have not forgiven [us].
“Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
43 You have surrounded us with your anger and pursued us; you have slaughtered [us] without pitying us.
“Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
44 You have hidden yourself in a cloud, with the result that you do not hear [us] when we pray.
Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
45 You have caused [the people of other] nations to consider us to be only garbage [DOU].
Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
46 All our enemies have insulted us.
“Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
47 We are constantly afraid [DOU], [because] we have experienced disasters and ruin [DOU].”
Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
48 I cry a lot because my people have been destroyed.
Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
49 My tears continually flow; they will not stop
Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
50 until Yahweh looks down from heaven and sees [us].
títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
51 I am very grieved because of [what has happened to] the women of my city.
Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
52 Those who are my enemies hunted for me like [SIM] [people hunt for] a bird [to kill it] [even though] there was no reason [for them to do that].
Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
53 They threw me into a pit to kill me, and they threw stones on top of me.
Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
54 The water [in the pit] rose above my head, and I said [to myself], “I am about to die/drown!”
Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
55 But from the bottom of the pit I cried out to you [MTY], “Yahweh, [help me]!”
Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
56 I pleaded with you, “Do not refuse to heed [MTY] me while I cry out to you!”
Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
57 Then you answered me and said, “Do not be afraid!”
O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
58 Yahweh, you defended me; you did not allow me to die.
Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
59 [Now], Yahweh, you have seen the evil things that my enemies have done to me, [so] decide my case [and show that I am right]!
O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
60 You know the evil things that they have planned to do to me.
Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
61 Yahweh, you have heard them insult [me] and what they have planned to do to me.
Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
62 Every day they whisper and mutter things about me, all day long.
ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
63 Look at them! Whether they are standing or sitting they make fun of me with the songs that they sing.
Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
64 Yahweh, cause them to suffer in return for their causing [me] to suffer!
Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
65 Curse them [IDM] [for] their being very stubborn [IDM].
Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
66 Because you are angry with them, pursue them and get rid of them, [until none of them remain] on the earth.
Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.