< Exodus 35 >

1 And Moses assembles all the congregation of the sons of Israel and says to them, “These [are] the things which YHWH has commanded—to do them:
Mose pe gbogbo ìjọ Israẹli ó sì wí fún wọn pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ohun ti Olúwa ti pàṣẹ fún un yín láti ṣe.
2 [For] six days work is done, and on the seventh day there is a holy [day] for you, a Sabbath of rest to YHWH; any who does work in it is put to death;
Fún ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi ṣiṣẹ́, ṣùgbọ́n ọjọ́ keje yóò jẹ́ ọjọ́ mímọ́ fún yín, ọjọ́ ìsinmi ni sí Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe iṣẹ́ kankan ni ọjọ́ náà ní a ó pa.
3 you do not burn a fire in any of your dwellings on the Sabbath day.”
Ẹ má ṣe dáná kankan ní ibùgbé yín ní ọjọ́ ìsinmi.”
4 And Moses speaks to all the congregation of the sons of Israel, saying, “This [is] the thing which YHWH has commanded, saying,
Mose sọ fún gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ.
5 Take a raised-offering for YHWH from among you; everyone whose heart [is] willing brings it [as] the raised-offering of YHWH: gold, and silver, and bronze,
Láti inú ohun tí ẹ ni ni kí ẹ ti mú ọrẹ fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ ni kí ó mú ọrẹ fún Olúwa ní ti: “wúrà, fàdákà àti idẹ;
6 and blue, and purple, and scarlet, and linen, and goats’ [hair],
aṣọ aláró, elése àlùkò, òdòdó àti ọ̀gbọ̀ dáradára; àti irun ewúrẹ́;
7 and rams’ skins made red, and tachashim skins, and shittim wood,
awọ àgbò tí a kùn ní pupa àti awọ màlúù; odò igi kasia;
8 and oil for the light, and spices for the anointing oil, and for the spice-incense,
òróró olifi fún títan iná; olóòórùn fún òróró ìtasórí, àti fún tùràrí dídùn;
9 and shoham stones, and stones for settings, for an ephod, and for a breastplate.
òkúta óníkìsì àti òkúta tí a tò sí ẹ̀wù efodu àti ìgbàyà.
10 And all the wise-hearted among you come in, and make all that YHWH has commanded:
“Gbogbo ẹni tí ó ní ọgbọ́n láàrín yín, kí ó wa, kí ó sì wá ṣe gbogbo ohun tí Olúwa ti pàṣẹ:
11 the Dwelling Place, its tent, and its covering, its hooks, and its boards, its bars, its pillars, and its sockets,
“àgọ́ náà pẹ̀lú àgọ́ rẹ àti ìbòrí rẹ̀, kọ́kọ́rọ́ rẹ̀, pákó rẹ̀, ọ̀pá rẹ̀, ọ̀wọ́n rẹ̀ àti ihò ìtẹ̀bọ̀ rẹ̀;
12 the Ark and its poles, the propitiatory covering, and the veil of the covering,
Àpótí náà pẹ̀lú ọ̀pá rẹ̀, ìbò àánú àti aṣọ títa náà tí ó síji bò ó.
13 the table and its poles, and all its vessels, and the Bread of the Presentation,
Tábìlì náà pẹ̀lú òpó rẹ̀ àti gbogbo ohun èlò rẹ̀ àti àkàrà ìfihàn náà.
14 and the lampstand for the light, and its vessels, and its lamps, and the oil for the light,
Ọ̀pá fìtílà tí ó wà fún títanná pẹ̀lú ohun èlò rẹ̀, fìtílà àti òróró fún títanná.
15 and the altar of incense, and its poles, and the anointing oil, and the spice-incense, and the covering of the opening at the opening of the Dwelling Place,
Pẹpẹ tùràrí náà pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀, òróró ìtasórí àti tùràrí dídùn; aṣọ títa fún ọ̀nà ìlẹ̀kùn ní ẹnu-ọ̀nà sí àgọ́ náà.
16 the altar of burnt-offering and the bronze grate which it has, its poles, and all its vessels, the laver and its base,
Pẹpẹ ẹbọ sísun pẹ̀lú ojú ààrò idẹ rẹ̀, òpó rẹ̀ àti gbogbo ohun èlò rẹ̀; agbada idẹ pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀.
17 the hangings of the court, its pillars, and their sockets, and the covering of the gate of the court,
Aṣọ títa ti àgbàlá pẹ̀lú, ọ̀wọ́n àti ihò ìtẹ̀bọ̀ rẹ̀ àti aṣọ títa fún ẹnu-ọ̀nà àgbàlá náà.
18 the pins of the Dwelling Place, and the pins of the court, and their cords,
Èèkàn àgọ́ náà fún àgọ́ náà àti fún àgbàlá àti okùn wọn.
19 the colored garments, to do service in the holy place, the holy garments for Aaron the priest, and the garments of his sons to act as priest in.”
Aṣọ híhun láti ṣiṣẹ́ ní ibi mímọ́ aṣọ mímọ́ fún Aaroni àlùfáà àti aṣọ fún àwọn ọmọ rẹ̀ nígbà tí wọ́n sìn bí àlùfáà.”
20 And all the congregation of the sons of Israel go out from the presence of Moses,
Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sì kúrò níwájú Mose,
21 and they come in—every man whom his heart has lifted up, and everyone whom his spirit has made willing—they have brought in the raised-offering of YHWH for the work of the Tent of Meeting, and for all its service, and for the holy garments.
olúkúlùkù ẹni tí ó fẹ́ àti ẹni tí ọkàn rẹ̀ gbé sókè wá, wọ́n sì mú ọrẹ fún Olúwa, fún iṣẹ́ àgọ́ àjọ, fún gbogbo ìsìn rẹ̀ àti fún aṣọ mímọ́ náà.
22 And they come in—the men with the women—every willing-hearted one—they have brought in nose-ring, and earring, and seal-ring, and necklace, all golden goods, even everyone who has waved a wave-offering of gold to YHWH.
Gbogbo àwọn tí ó fẹ́, ọkùnrin àti obìnrin, wọ́n wá wọ́n sì mú onírúurú ìlẹ̀kẹ̀ wúrà: òrùka etí, òrùka àti ọ̀ṣọ́. Gbogbo wọn mú wúrà gẹ́gẹ́ bí ọrẹ wá fún Olúwa.
23 And every man with whom has been found blue, and purple, and scarlet, and linen, and goats’ [hair], and rams’ skins made red, and tachashim skins, have brought [them] in;
Olúkúlùkù ẹni tí ó ni aṣọ aláró elése àlùkò, òdòdó àti ọ̀gbọ̀ dáradára, tàbí irun ewúrẹ́, awọ àgbò tí a rì ní pupa tàbí awọ màlúù odò, kí ó mú wọn wá.
24 everyone lifting up a raised-offering of silver and bronze has brought in the raised-offering of YHWH; and everyone with whom has been found shittim wood for any work of the service brought [it] in.
Àwọn tí ó mú ọrẹ fàdákà tàbí idẹ wá, mú ọrẹ wá fún Olúwa, àti olúkúlùkù ẹni tí ó ní igi ṣittimu fún ipa kankan nínú iṣẹ́ mú un wá.
25 And every wise-hearted woman has spun with her hands, and they bring in yarn—of the blue, and the purple, [and] the scarlet—and the linen;
Gbogbo àwọn obìnrin tí ó ní ọgbọ́n ríran owú pẹ̀lú ọwọ́ rẹ̀, kí ó mú èyí ti ó ti ran wá ti aláró, ti elése àlùkò, ti òdòdó tàbí ti ọ̀gbọ̀ dáradára.
26 and all the women whose heart has lifted them up in wisdom, have spun the goats’ [hair].
Gbogbo àwọn obìnrin tí ó fẹ́, tí ó sì ní ọgbọ́n ń ran òwú irun ewúrẹ́.
27 And the princes have brought in the shoham stones, and the stones for settings, for the ephod, and for the breastplate,
Àwọn olórí mú òkúta óníkìsì wá láti tò ó lórí ẹ̀wù efodu àti ìgbàyà.
28 and the spices, and the oil for the light, and for the anointing oil, and for the spice-incense;
Wọ́n sì tún mú olóòórùn àti òróró olifi wá fún títanná àti fún òróró ìtasórí àti fún tùràrí dídùn.
29 every man and woman of the sons of Israel (whom their heart has made willing to bring in for all the work which YHWH commanded to be done by the hand of Moses) brought in a willing-offering to YHWH.
Gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli ọkùnrin àti obìnrin ẹni tí ó fẹ́ mú ọrẹ àtinúwá fún Olúwa fún gbogbo iṣẹ́ tí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn láti ṣe nípasẹ̀ Mose.
30 And Moses says to the sons of Israel, “See, YHWH has called Bezaleel, son of Uri, son of Hur, of the tribe of Judah, by name,
Nígbà náà ni Mose wí fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Wò ó, Olúwa ti yan Besaleli ọmọ Uri, ọmọ Huri, ti ẹ̀yà Juda,
31 and He fills him [with] the Spirit of God, in wisdom, in understanding, and in knowledge, and in all work,
Ó sì ti fi Ẹ̀mí Ọlọ́run kún un, pẹ̀lú ọgbọ́n, òye, ìmọ̀ àti gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
32 even to devise inventions to work in gold, and in silver, and in bronze,
Láti máa ṣe aláràbarà iṣẹ́ ní ti wúrà, fàdákà àti idẹ,
33 and in a carving of stones for settings, and in a carving of wood to work in any work of design.
láti gbẹ́ òkúta àti láti tò ó, láti fún igi àti láti ṣiṣẹ́ ni gbogbo onírúurú iṣẹ́ ọnà.
34 And He has put [it] in his heart to direct, he and Aholiab, son of Ahisamach, of the tribe of Dan;
Ó sì fún òun àti Oholiabu ọmọ Ahisamaki ti ẹ̀yà Dani, ni agbára láti kọ́ àwọn tókù.
35 He has filled them with wisdom of heart to do every work, of engraver, and designer, and embroiderer (in blue, and in purple, in scarlet, and in linen), and weaver, who does any work, and of designers of designs.”
Ó sì fi ọgbọ́n kún wọn láti ṣe gbogbo onírúurú iṣẹ́, ti oníṣọ̀nà, ti ayàwòrán, ti aránsọ, ti aláṣọ aláró, ti elése àlùkò, ti òdòdó àti ní ọ̀gbọ̀ dáradára àti ti ahunṣọ, gbogbo èyí tí ọ̀gá oníṣẹ́-ọnà àti ayàwòrán ń ṣe.

< Exodus 35 >