< Genesis 34 >

1 And Dinah, daughter of Leah, whom she has borne to Jacob, goes out to look on the daughters of the land,
Ní ọjọ́ kan, Dina ọmọbìnrin tí Lea bí fún Jakọbu jáde lọ bẹ àwọn ọmọbìnrin ilẹ̀ náà wò.
2 and Shechem, son of Hamor the Hivite, a prince of the land, sees her, and takes her, and lies with her, and humbles her;
Nígbà tí Ṣekemu ọmọ ọba Hamori ará Hifi rí i, ó mú un, ó sì fi ipá bá a lo pọ̀.
3 and his soul cleaves to Dinah, daughter of Jacob, and he loves the young person, and speaks to the heart of the young person.
Ọkàn rẹ sì fà sí Dina ọmọ Jakọbu gan an, ó sì fẹ́ràn rẹ̀ ó sì bá ọmọbìnrin náà sọ̀rọ̀ ìfẹ́.
4 And Shechem speaks to his father Hamor, saying, “Take for me this girl for a wife.”
Ṣekemu sì wí fún Hamori baba rẹ̀ pé, “Fẹ́ ọmọbìnrin yìí fún mi bí aya.”
5 And Jacob has heard that he has defiled his daughter Dinah, and his sons were with his livestock in the field, and Jacob kept silent until their coming.
Nígbà tí Jakọbu gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ pé a fi ipá bá Dina ọmọbìnrin òun ní ògo jẹ́, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ rẹ̀ wà nínú pápá níbi tí wọ́n ti ń daran nítorí náà ó mú sùúrù títí tí wọ́n fi dé.
6 And Hamor, father of Shechem, goes out to Jacob to speak with him;
Hamori baba Ṣekemu sì jáde wá láti bá Jakọbu sọ̀rọ̀.
7 and the sons of Jacob came in from the field when they heard, and the men grieve themselves, and it [is] very displeasing to them, for folly he has done against Israel, to lie with the daughter of Jacob—and so it is not done.
Àwọn ọmọ Jakọbu sì ti oko dé, wọ́n sì gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ inú wọn sì bàjẹ́, ó sì ń bí wọn nínú gidigidi, nítorí tí ó ṣe ohun búburú ní Israẹli, ní ti ó bá ọmọbìnrin ọmọ Jakọbu lòpọ̀—irú ohun tí kò yẹ kí ó ṣẹlẹ̀ rárá.
8 And Hamor speaks with them, saying, “Shechem, my son, his soul has cleaved to your daughter; please give her to him for a wife,
Hamori sì bá wọn sọ̀rọ̀ pé, “Ọkàn ọmọ mi Ṣekemu fà sí ọmọ rẹ. Jọ̀wọ́ fi fún un gẹ́gẹ́ bí aya.
9 and join in marriage with us; you give your daughters to us, and you take our daughters for yourselves,
Ẹ jẹ́ kí a máa ṣe ìgbéyàwó láàrín ara wa, kí àwọn ọmọ yín kó máa fẹ́ àwọn ọmọ wa.
10 and you dwell with us, and the land is before you; dwell and trade [in] it, and have possessions in it.”
Ẹ lè máa gbé láàrín wa, ibikíbi tí ó bá tẹ́ yín lọ́rùn láàrín wa ni ẹ lè gbé, ẹ máa ṣe òwò yín kí ẹ sì kó ọrọ̀ jọ fún ara yín.”
11 And Shechem says to her father and to her brothers, “Let me find grace in your eyes, and that which you say to me, I give;
Ṣekemu sì wí fún baba àti arákùnrin Dina pé, “Ẹ jọ̀wọ́, ẹ jẹ́ kí n rí ojúrere yín, èmi yóò sì fún yín ní ohunkóhun tí ẹ̀yin bá fẹ́ gbà.
12 multiply on me dowry and gift exceedingly, and I give as you say to me, and give to me the young person for a wife.”
Iyekíye tí owó orí rẹ̀ bá jẹ́ àti ẹ̀bùn gbogbo tí ẹ bá fẹ́, bí ó ti wù kí ó pọ̀ tó, èmi yóò san án, kí ẹ sá à jẹ́ kí ń fi ọmọ náà ṣe aya.”
13 And the sons of Jacob answer Shechem and his father Hamor deceitfully, and they speak (because he defiled their sister Dinah),
Àwọn ọmọ Jakọbu sì fi ẹ̀tàn dá Ṣekemu àti Hamori baba rẹ̀ lóhùn, wọ́n sì wí pé, nítorí tí ó ti ba ògo Dina arábìnrin wọn jẹ́.
14 and say to them, “We are not able to do this thing, to give our sister to one who has a foreskin, for it [is] a reproach to us.
Wọ́n wí fún wọn pé, “Àwa kò le ṣe nǹkan yìí láti fi arábìnrin wa fún aláìkọlà, nítorí àbùkù ni èyí yóò jẹ́ fún wa.
15 Only for this we consent to you: if you are as we, to have every male of you circumcised,
Àwa yóò fi ara mọ́ ọn bí ẹ̀yin yóò bá gbà láti dàbí i tiwa, wí pé ẹ̀yin pẹ̀lú yóò kọ gbogbo ọkùnrin yín ní ilà.
16 then we have given our daughters to you, and we take your daughters for ourselves, and we have dwelt with you, and have become one people;
Nígbà náà ni àwa yóò le máa fún yín ní ọmọ wa, tí àwa náà yóò máa fẹ́ ẹ yín. A ó máa gbé láàrín yín, a ó sì di ara kan pẹ̀lú yín.
17 and if you do not listen to us to be circumcised, then we have taken our daughter, and have gone.”
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá kọ̀ láti kọlà, àwa yóò mú arábìnrin wa, á ó sì máa lọ.”
18 And their words are good in the eyes of Hamor, and in the eyes of Shechem, Hamor’s son;
Àbá náà sì dùn mọ́ Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀.
19 and the young man did not delay to do the thing, for he had delight in Jacob’s daughter, and he is honorable above all the house of his father.
Ọ̀dọ́mọkùnrin náà, ẹni tí ó jẹ́ ẹni iyì jùlọ ní ilé baba rẹ̀, kò jáfara láti ṣe ohun tí wọ́n wí. Nítorí tí ó fẹ́ràn ọmọbìnrin Jakọbu.
20 And Hamor comes—his son Shechem also—to the gate of their city, and they speak to the men of their city, saying,
Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀ sì wá sí ẹnu ibodè ìlú náà wọn sì bá àwọn ará ìlú náà sọ̀rọ̀.
21 “These men are peaceable with us; then let them dwell in the land, and trade [in] it; and the land, behold, [is] wide before them; their daughters let us take to ourselves for wives, and our daughters give to them.
Wí pé, “Ìwà àwọn ọkùnrin wọ̀nyí dára, ẹ jẹ́ kí wọn máa gbé ní àárín wa, kí wọn sì máa ṣòwò, ilẹ̀ kúkú wà rẹpẹtẹ tó gba ààyè dáradára. A lè fẹ́ àwọn ọmọ wọ́n, ki wọn sì fẹ́ tiwa pẹ̀lú.
22 Only for this do the men consent to us, to dwell with us, to become one people, in every male of us being circumcised, as they are circumcised;
Ṣùgbọ́n kín ní kan ni a lè ṣe kí wọn tó gbà láti gbé pẹ̀lú wa, ìyẹn sì ni pé àwọn ọkùnrin wa yóò kọlà bí i tiwọn.
23 their livestock, and their substance, and all their beasts—are they not ours? Only let us consent to them, and they dwell with us.”
Ṣe bí àwọn ẹran wọn àti ẹrú wọn àti àwọn ohun ọ̀sìn wọn ni yóò di tiwa bí a bá lè gbà bẹ́ẹ̀, wọn yóò sì máa gbé ni àárín wa.”
24 And to Hamor, and to his son Shechem, do all those going out of the gate of his city listen, and every male is circumcised, all those going out of the gate of his city.
Gbogbo àwọn ọkùnrin tí ń jáde ní ẹnu-bodè ìlú náà sì gbọ́ ti Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀. Gbogbo ọkùnrin ìlú náà sì kọlà.
25 And it comes to pass, on the third day, in their being pained, that two of the sons of Jacob, Simeon and Levi, Dinah’s brothers, take each his sword, and come in against the city confidently, and slay every male;
Lẹ́yìn ọjọ́ kẹta, nígbà tí gbogbo wọn sì wà nínú ìrora. Àwọn ọmọ Jakọbu méjì, Simeoni àti Lefi tí ó jẹ́ ẹ̀gbọ́n fún Dina, sì mú idà wọn pẹ̀lú ìgboyà, wọ́n sì pa gbogbo ọkùnrin ìlú náà.
26 and Hamor, and his son Shechem, they have slain by the mouth of the sword, and they take Dinah out of Shechem’s house, and go out.
Wọ́n sì fi idà pa Hamori àti Ṣekemu ọmọ rẹ̀, wọ́n mú Dina kúrò ní ilé wọn, wọ́n sì jáde.
27 Jacob’s sons have come in on the wounded, and they spoil the city, because they had defiled their sister;
Àwọn ọmọ Jakọbu sì wọlé àwọn tí a pa, wọ́n sì kó ẹrù ìlú tí a ti ba ògo arábìnrin wọn jẹ́.
28 their flock and their herd, and their donkeys, and that which [is] in the city, and that which [is] in the field, have they taken;
Wọ́n kó màlúù wọn àti agbo ẹran wọn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti ohun gbogbo tí ó wà nínú ìlú àti ní oko.
29 and all their wealth, and all their infants, and their wives they have taken captive, and they spoil also all that [is] in the house.
Gbogbo ọrọ̀ wọn, gbogbo obìnrin ìlú àti àwọn ọmọ wẹẹrẹ pátápátá ni wọ́n kó. Wọ́n sì kó gbogbo ohun tí ó wà nínú ilé wọn bí ìkógun.
30 And Jacob says to Simeon and to Levi, “You have troubled me, by causing me to stink among the inhabitants of the land, among the Canaanite, and among the Perizzite: and I [am] few in number, and they have been gathered against me, and have struck me, and I have been destroyed, I and my house.”
Nígbà náà ni Jakọbu wí fún Simeoni àti Lefi wí pé, “Ẹ̀yin ti kó ìyọnu bá mi nípa sísọ mí di olóòórùn láàrín ará Kenaani àti Peresi, tí ó ń gbé ilẹ̀ yìí. Àwa kò pọ̀, bí wọn bá wá parapọ̀ ṣígun sí wa, gbogbo wa pátápátá ni wọn yóò parun.”
31 And they say, “Does he make our sister as a harlot?”
Ṣùgbọ́n wọ́n dáhùn pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí ó ṣe arábìnrin wa bí panṣágà?”

< Genesis 34 >