< Psalms 85 >
1 “To the chief musician, by the sons of Korach, a psalm.” Thou hast been favorable, O Lord, unto thy land: thou hast brought back the captivity of Jacob.
Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ìwọ fi ojúrere hàn fún ilé rẹ, Olúwa; ìwọ mú ohun ìní Jakọbu bọ̀ sí ipò.
2 Thou hast forgiven the iniquity of thy people: thou hast covered over all their sin. (Selah)
Ìwọ dárí àìṣedéédéé àwọn ènìyàn rẹ jì ìwọ sì bó ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́lẹ̀. (Sela)
3 Thou hast taken away all thy wrath: thou hast relinquished the fierceness of thy anger.
Ìwọ fi àwọn ìbínú rẹ sápá kan ìwọ sì yípadà kúrò nínú ìbínú gbígbóná rẹ.
4 Return to us, O God of our salvation, and cause thy ill-will toward us to cease.
Yí wa padà, Ọlọ́run ìgbàlà wa, kí o sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ wa.
5 Wilt thou be wroth with us for ever? wilt thou extend thy anger from generation to generation?
Ìwọ yóò ha máa bínú sí wa títí láé? Ìwọ yóò ha mú ìbínú rẹ pẹ́ yí gbogbo ìran ká?
6 Wilt thou not [now] revive us again, that thy people may rejoice in thee?
Ìwọ kì yóò ha sọ wá jí padà mọ́, pé kí àwọn ènìyàn rẹ lè yọ nínú rẹ?
7 Show us thy kindness, O Lord, and grant us thy salvation.
Fi ìfẹ́ rẹ tí kò le è kùnà hàn wá, Olúwa, kí o sì fún wa ní ìgbàlà rẹ.
8 I will hear what God the Lord will speak; for he will speak peace unto his people, and to his pious ones: only let them not turn again to folly.
Èmi ó gbọ́ ohun tí Olúwa Ọlọ́run yóò wí; ó ṣèlérí àlàáfíà fún àwọn ènìyàn rẹ̀, àní ẹni mímọ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí wọn padà sí àìmoye.
9 Surely, nigh is his salvation unto those that fear him: that glory may dwell in our land.
Nítòótọ́ ìgbàlà rẹ̀ súnmọ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, pé kí ògo rẹ̀ kí ó lè gbé ní ilẹ̀ wa.
10 Kindness and truth are met together: righteousness and peace kiss each other.
Ìfẹ́ àti òtítọ́ parapọ̀; òdodo àti àlàáfíà fẹnu ko ara wọn.
11 Truth will grow up out of the earth, and righteousness will look down from heaven.
Òtítọ́ ń sun jáde láti ilẹ̀ wá òdodo sì bojú wolẹ̀ láti ọ̀run.
12 Yea, the Lord will also give the good, and our land will yield its products.
Olúwa yóò fi ohun dídára fún ni nítòótọ́, ilẹ̀ wa yóò sì mú ìkórè rẹ̀ jáde.
13 Righteousness will walk firmly before him, and will make [level] the way by its steps.
Òdodo síwájú rẹ lọ o sì pèsè ọ̀nà fún ìgbésẹ̀ rẹ̀.