< Psalms 84 >

1 “To the chief musician upon Gittith, by the sons of Korach, a psalm.” How lovely are thy dwelling-places, O Lord of hosts!
Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti gittiti. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ibùgbé rẹ̀ ti lẹ́wà tó, Olúwa àwọn ọmọ-ogun!
2 My soul desired, yea, it also longed for the courts of the Lord: my heart and my flesh shout with joy unto the living God.
Ọkàn mi ń ṣàfẹ́rí nítòótọ́ ó tilẹ̀ pòǹgbẹ fún àgbàlá Olúwa àyà mi àti ara mi ń kọrin ayọ̀ sí Ọlọ́run alààyè.
3 Even as the sparrow hath found a house, and the swallow a nest for herself, where she may lay her young: —[have I found] thy altars, O Lord of hosts, my King, and my God.
Nítòótọ́ ológoṣẹ́ ri ilé, ẹyẹ alápáǹdẹ̀dẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ fún ara rẹ̀, níbi tí yóò máa pa ọmọ rẹ̀ mọ́ sí: ibùgbé ní tòsí pẹpẹ rẹ̀, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ọba mí àti Ọlọ́run mi.
4 Happy are they who dwell in thy house: they will be continually praising thee. (Selah)
Ìbùkún ní fún àwọn tí ó ń gbé inú ilé rẹ; wọn ó máa yìn ọ́ títí láé.
5 Happy is the man whose strong confidence is in thee, [all] whose heart reflecteth on the paths [of righteousness].
Ìbùkún ni fún àwọn tí agbára wọn wà nínú rẹ àwọn tí wọ́n gbé ọkàn lé bíbẹ ibi mímọ́ wò.
6 Passing through the valley of weeping, they will change it into a spring: also the early rain covereth it with blessings.
Àwọn tí ń la àfonífojì omijé lọ wọn sọ ọ́ di kànga àkọ́rọ̀ òjò sì fi ìbùkún bò ó.
7 They go from strength to strength, each of them appeareth before God in Zion.
Wọ́n ń lọ láti ipa dé ipá títí tí ọ̀kọ̀ọ̀kan fi farahàn níwájú Ọlọ́run ní Sioni.
8 O Lord God of hosts, hear my prayer: give ear, O God of Jacob. (Selah)
Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa Ọlọ́run Alágbára; tẹ́tí sí mi, Ọlọ́run Jakọbu.
9 [Thou, ] our shield, behold, O God, and look upon the face of thy anointed.
Wo asà wa, Ọlọ́run; fi ojú àánú wò àwọn ẹni àmì òróró rẹ.
10 For better is a day in thy courts than a thousand [elsewhere]: I would rather choose to wait at the threshold of the house of my God, than to dwell in the tents of wickedness.
Dídára ní ọjọ́ kan ní ààfin rẹ ju ẹgbẹ̀rún ọjọ́ lọ; èmi o kúkú máa ṣe aṣọ́nà nínú ilé Ọlọ́run mi jù láti gbé ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú.
11 For a sun and shield is the Lord God; grace and glory will the Lord give; he will not withhold any good from those that walk with integrity.
Nítorí Olúwa Ọlọ́run jẹ́ òòrùn àti asà; Olúwa fún ni ní ojúrere àti ọlá; kò sí ohun rere kan tí yóò fàsẹ́yìn fún àwọn tí ó rìn ní àìlábùkù.
12 O Lord of hosts, happy is the man that trusteth in thee.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.

< Psalms 84 >