< Žalmy 119 >

1 Aleph. Blahoslavení ti, kteříž jsou ctného obcování, kteříž chodí v zákoně Hospodinově.
Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ọ̀nà wọn wà láìlẹ́ṣẹ̀, ẹni tí í rìn ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa.
2 Blahoslavení, kteříž ostříhají svědectví jeho, a kteříž ho celým srdcem hledají.
Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́ tí wọn sì ń wá a pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
3 Nečiní zajisté nepravosti, ale kráčejí po cestách jeho.
Wọn kò ṣe ohun tí kò dára; wọ́n rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
4 Ty jsi přikázal, aby pilně bylo ostříháno rozkazů tvých.
Ìwọ ti la ìlànà rẹ̀ sílẹ̀ kí a sì pa wọ́n mọ́ gidigidi.
5 Ó by spraveny byly cesty mé k ostříhání ustanovení tvých.
Ọ̀nà mi ìbá dúró ṣinṣin láti máa pa òfin rẹ̀ mọ́!
6 Tehdážť nebudu zahanben, když budu patřiti na všecka přikázaní tvá.
Nígbà náà, ojú kò ní tì mí nígbà tí mo bá ń kíyèsi àṣẹ rẹ̀ gbogbo.
7 Oslavovati tě budu v upřímnosti srdce, když se vyučovati budu právům spravedlnosti tvé.
Èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú ọkàn ìdúró ṣinṣin bí èmi bá ti kọ́ òfin òdodo rẹ̀.
8 Ustanovení tvých budu ostříhati s pilností, toliko neopouštěj mne.
Èmi yóò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ pátápátá.
9 Beth. Jakým způsobem očistí mládenec stezku svou? Takovým, aby se choval vedlé slova tvého.
Báwo ni àwọn ọ̀dọ́ yóò ti ṣe pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́? Láti máa gbé ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ rẹ.
10 Celým srdcem svým hledám tebe, nedopouštějž mi blouditi od přikázaní tvých.
Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi má ṣe jẹ́ kí èmi yapa kúrò nínú àṣẹ rẹ.
11 V srdci svém skládám řeč tvou, abych nehřešil proti tobě.
Èmi ti pa ọ̀rọ̀ rẹ mọ́ ní ọkàn mi kí èmi má ba à ṣẹ̀ sí ọ.
12 Ty chvály hodný Hospodine, vyuč mne ustanovením svým.
Ìyìn ni fún Olúwa; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
13 Rty svými vypravuji o všech soudech úst tvých.
Pẹ̀lú ètè mi èmi tún ṣírò gbogbo òfin tí ó wá láti ẹnu rẹ.
14 Z cesty svědectví tvých raduji se více, než z největšího zboží.
Èmi ń yọ̀ ní ọ̀nà ẹ̀rí rẹ, bí ènìyàn ṣe ń yọ̀ nínú ọláńlá.
15 O přikázaních tvých přemyšluji, a patřím na stezky tvé.
Èmi ń ṣe àṣàrò nínú ìlànà rẹ èmi sì kíyèsi ọ̀nà rẹ.
16 V ustanoveních tvých se kochám, aniž se zapomínám na slovo tvé.
Inú mi dùn sí àṣẹ rẹ; èmi kì yóò gbàgbé ọ̀nà rẹ.
17 Gimel Tu milost učiň s služebníkem svým, abych, dokudž jsem živ, ostříhal slova tvého.
Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ, èmi yóò sì wà láààyè; èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ.
18 Otevři oči mé, abych spatřoval divné věci z zákona tvého.
La ojú mi kí èmi lè ríran rí ohun ìyanu tí ó wà nínú òfin rẹ.
19 Příchozí jsem na tom světě, neukrývejž přede mnou přikázaní svých.
Àlejò ní èmi jẹ́ láyé, má ṣe pa àṣẹ rẹ mọ́ fún mi.
20 Umdlévá duše má pro žádost soudů tvých všelikého času.
Ọkàn mi pòruurù pẹ̀lú ìfojúsọ́nà nítorí òfin rẹ nígbà gbogbo.
21 Vyhlazuješ pyšné, zlořečené, kteříž bloudí od přikázaní tvých.
Ìwọ fi àwọn agbéraga bú, àwọn tí a fi gégùn ún tí ó ṣìnà kúrò nínú àṣẹ rẹ.
22 Odejmi ode mne útržku a potupu, neboť ostříhám svědectví tvých.
Mú ẹ̀gàn àti àbùkù kúrò lára mi, nítorí èmi pa òfin rẹ mọ́.
23 Také i knížata se zasazují, a mluví proti mně, služebník pak tvůj přemýšlí o ustanoveních tvých.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn alákòóso kójọpọ̀, wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ ń ṣe àṣàrò nínú àṣẹ rẹ.
24 Svědectví tvá zajisté jsou mé rozkoše a moji rádcové.
Òfin rẹ ni dídùn inú mi; àwọn ní olùbádámọ̀ràn mi.
25 Daleth Přilnula k prachu duše má; obživiž mne podlé slova svého.
Ọkàn mí lẹ̀ mọ́ erùpẹ̀; ìwọ sọ mí di ààyè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
26 Cesty své předložilť jsem, a vyslýchals mne; vyuč mne ustanovením svým.
Èmi tún ọ̀nà mi ṣírò ìwọ sì dá mi lóhùn; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
27 Cestě rozkazů tvých dej ať vyrozumívám, a ať přemýšlím o divných skutcích tvých.
Jẹ́ kí n mọ ẹ̀kọ́ ìlànà rẹ: nígbà náà ni èmi yóò ṣe àṣàrò iṣẹ́ ìyanu rẹ.
28 Rozplývá se zámutkem duše má, očerstviž mne podlé slova svého.
Ọkàn mi ń ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́; fi agbára fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
29 Cestu lživou odvrať ode mne, a zákon svůj z milosti dej mi.
Pa mí mọ́ kúrò nínú ọ̀nà ẹ̀tàn fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ nípa òfin rẹ.
30 Cestu pravou jsem vyvolil, soudy tvé sobě předkládám.
Èmi ti yan ọ̀nà òtítọ́ èmi ti gbé ọkàn mi lé òfin rẹ.
31 Svědectví tvých se přídržím, Hospodine, nedejž mi zahanbenu býti.
Èmi yára di òfin rẹ mú. Olúwa má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
32 Cestou rozkazů tvých poběhnu, když ty rozšíříš srdce mé.
Èmi sáré ní ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ, nítorí ìwọ, ti tú ọkàn mi sílẹ̀.
33 He Vyuč mne, Hospodine, cestě ustanovení svých, kteréž bych ostříhal do konce.
Kọ́ mi, Olúwa, láti tẹ̀lé àṣẹ rẹ; nígbà náà ni èmi yóò pa wọ́n mọ́ dé òpin.
34 Dej mi ten rozum, ať šetřím zákona tvého, a ať ho ostříhám celým srdcem.
Fún mi ní òye, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́ èmi yóò sì máa kíyèsi i pẹ̀lú ọkàn mi.
35 Dej, ať chodím cestou přikázaní tvých; nebo v tom svou rozkoš skládám.
Fi ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ hàn mí, nítorí nínú rẹ̀ ni èmi rí inú dídùn.
36 Nakloň srdce mého k svědectvím svým, a ne k lakomství.
Yí ọkàn mi padà sí òfin rẹ kí ó má ṣe sí ojúkòkòrò mọ́.
37 Odvrať oči mé, ať nehledí marnosti; na cestě své obživ mne.
Yí ojú mi padà kúrò láti máa wo ohun asán: pa ọ̀nà mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
38 Potvrď služebníku svému řeči své, kterýž se oddal k službě tvé.
Mú ìlérí rẹ sẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí òfin rẹ dára.
39 Odvrať ode mne pohanění, jehož se bojím; nebo soudové tvoji dobří jsou.
Yí ẹ̀gàn mi padà tí mo bẹ̀rù nítorí tí ìdájọ́ rẹ dára.
40 Aj, toužím po rozkázaních tvých; dej, ať jsem živ v spravedlnosti tvé.
Kíyèsi i, ọkàn mi ti fà sí ẹ̀kọ́ rẹ! Pa ayé mi mọ́ nínú òdodo rẹ.
41 Vav Ó ať se přiblíží ke mně milosrdenství tvá, Hospodine, a spasení tvé vedlé řeči tvé,
Jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà wá bá mi, Olúwa, ìgbàlà rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
42 Tak abych odpovědíti uměl utrhači svému skutkem, že doufání skládám v slovu tvém.
Nígbà náà ni èmi yóò dá ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi lóhùn, nítorí èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.
43 A nevynímej z úst mých slova nejpravějšího; neboť na soudy tvé očekávám.
Má ṣe gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ láti ẹnu mi nítorí èmi ti gbé ìrètí mi sínú àṣẹ rẹ.
44 I budu ostříhati zákona tvého ustavičně, od věků až na věky,
Èmi yóò máa gbọ́rọ̀ sí òfin rẹ nígbà gbogbo láé àti láéláé.
45 A bez přestání choditi na širokosti, neboť jsem se dotázal rozkazů tvých.
Èmi yóò máa rìn káàkiri ní òmìnira, nítorí èmi ti kígbe ẹ̀kọ́ rẹ jáde.
46 Nýbrž mluviti budu o svědectvích tvých i před králi, a nebudu se hanbiti.
Èmi yóò sọ̀rọ̀ òfin rẹ níwájú àwọn ọba ojú kì yóò sì tì mí,
47 Nebo rozkoš svou skládám v přikázaních tvých, kteráž jsem zamiloval.
nítorí èmi ní inú dídùn nínú àṣẹ rẹ nítorí èmi ní ìfẹ́ wọn.
48 Přičinímť i ruce své k přikázaním tvým, kteráž miluji, a přemýšleti budu o ustanoveních tvých.
Èmi gbé ọwọ́ mi sókè nítorí àṣẹ rẹ, èyí tí èmi fẹ́ràn, èmi sì ń ṣe àṣàrò òfin rẹ̀.
49 Zajin Rozpomeň se na slovo k služebníku svému, kterýmž jsi mne ubezpečil.
Rántí ọ̀rọ̀ rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ ti fún mi ní ìrètí.
50 Toť jest má útěcha v ssoužení mém, že mne slovo tvé obživuje.
Ìtùnú mi nínú ìpọ́njú mi ni èyí: ìpinnu rẹ pa ayé mi mọ́.
51 Pyšní mi se velmi posmívají, však od zákona tvého se neuchyluji.
Àwọn agbéraga fi mí ṣe ẹlẹ́yà láì dádúró, ṣùgbọ́n èmi kò padà nínú òfin rẹ.
52 Neboť se rozpomínám na soudy tvé věčné, Hospodine, kterýmiž se potěšuji.
Èmi rántí àwọn òfin rẹ ìgbàanì, Olúwa, èmi sì rí ìtùnú nínú wọn.
53 Děsím se nad bezbožnými, kteříž opouštějí zákon tvůj.
Ìbínú dì mímú ṣinṣin nítorí àwọn ẹni búburú, tí wọ́n ti kọ òfin rẹ sílẹ̀.
54 Ustanovení tvá jsou mé písničky na místě mého putování.
Òfin rẹ ni ọ̀rọ̀ ìpìlẹ̀ orin mi níbikíbi tí èmi ń gbé.
55 Rozpomínám se i v noci na jméno tvé, Hospodine, a ostříhám zákona tvého.
Ní òru èmi rántí orúkọ rẹ, Olúwa, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́
56 Toť mám odtud, abych ostříhal rozkazů tvých.
nítorí tí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ gbọ́.
57 Cheth Díl můj, řekl jsem, Hospodine, ostříhati výmluvnosti tvé.
Ìwọ ni ìpín mi, Olúwa: èmi ti pinnu láti tẹríba sí ọ̀rọ̀ rẹ.
58 Modlívám se milosti tvé v celém srdci: Smiluj se nade mnou podlé slova svého.
Èmi ti wá ojú rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
59 Rozvážil jsem na mysli cesty své, a obrátil jsem nohy své k tvým svědectvím.
Èmi ti kíyèsi ọ̀nà mi èmi sì ti gbé ìgbésẹ̀ mi sí òfin rẹ.
60 Pospíchámť a neodkládám ostříhati rozkazů tvých.
Èmi yóò yára, ń kò ni lọ́ra láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
61 Rota bezbožníků zloupila mne, na zákon tvůj se nezapomínám.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹni búburú dì mí pẹ̀lú okùn, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
62 O půlnoci vstávám, abych tě oslavoval v soudech spravedlnosti tvé.
Ní àárín ọ̀gànjọ́ òru èmi dìde láti fi ọpẹ́ fún ọ nítorí òfin òdodo rẹ.
63 Účastník jsem všech, kteříž se bojí tebe, a těch, kteříž ostříhají přikázaní tvých.
Èmi jẹ́ ọ̀rẹ́ sí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ, sí gbogbo àwọn tí ń tẹ̀lé ẹ̀kọ́ rẹ.
64 Milosrdenství tvého, Hospodine, plná jest země, ustanovením svým vyuč mne.
Ayé kún fún ìfẹ́ rẹ, Olúwa, kọ́ mi ní òfin rẹ.
65 Teth Dobrotivě jsi nakládal s služebníkem svým, Hospodine, podlé slova svého.
Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa.
66 Pravému soudu a umění vyuč mne, nebo jsem přikázaním tvým uvěřil.
Kọ́ mi ní ìmọ̀ àti ìdájọ́ rere, nítorí mo gbàgbọ́ nínú àṣẹ rẹ.
67 Prvé než jsem snížen byl, bloudil jsem, ale nyní výmluvnosti tvé ostříhám.
Kí a tó pọ́n mi lójú èmi ti ṣìnà, ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí èmi gbọ́rọ̀ sí ọ̀rọ̀ rẹ.
68 Dobrý jsi ty a dobrotivý, vyuč mne ustanovením svým.
Ìwọ dára, ohun tí ìwọ sì ń ṣe rere ni; kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
69 Složiliť jsou lež proti mně pyšní, ale já celým srdcem ostříhám přikázaní tvých.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn agbéraga ti gbìmọ̀ èké sí mí, èmi pa ẹ̀kọ́ rẹ mọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi.
70 Zbřidlo jako tuk srdce jejich, já zákonem tvým se potěšuji.
Ọkàn wọn yigbì kò sì ní àánú, ṣùgbọ́n èmi ní inú dídùn nínú òfin rẹ.
71 K dobrémuť jest mi to, že jsem pobyl v trápení, abych se naučil ustanovením tvým.
Ó dára fún mi kí a pọ́n mi lójú nítorí kí èmi lè kọ́ òfin rẹ.
72 Za lepší sobě pokládám zákon úst tvých, nežli na tisíce zlata a stříbra.
Òfin tí ó jáde láti ẹnu rẹ ju iyebíye sí mi lọ ó ju ẹgbẹ̀rún ẹyọ fàdákà àti wúrà lọ.
73 Jod Ruce tvé učinily a sformovaly mne, dej mi ten rozum, abych se naučil přikázaním tvým,
Ọwọ́ rẹ ni ó dá mi tí ó sì mọ mí; fún mi ní òye láti kọ́ àṣẹ rẹ.
74 Tak aby bojící se tebe mne vidouce, radovali se, že na slovo tvé očekávám.
Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ máa yọ̀ nígbà tí wọ́n bá rí mi, nítorí èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
75 Seznávámť, Hospodine, že jsou spravedliví soudové tvoji, a že jsi mne hodně potrestal.
Èmi mọ, Olúwa, nítorí òfin rẹ òdodo ni, àti ní òtítọ́ ni ìwọ pọ́n mi lójú.
76 Nechať jest již zřejmé milosrdenství tvé ku potěšení mému, podlé řeči tvé mluvené služebníku tvému.
Kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà jẹ́ ìtùnú mi, gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ.
77 Přiďtež na mne slitování tvá, abych živ býti mohl; nebo zákon tvůj rozkoš má jest.
Jẹ́ kí àánú rẹ kí ó tọ̀ mí wá, kí èmi kí ó lè yè, nítorí òfin rẹ jẹ́ ìdùnnú mi.
78 Zahanbeni buďte pyšní, proto že lstivě chtěli mne podvrátiti, já pak přemyšluji o přikázaních tvých.
Kí ojú kí ó ti àwọn agbéraga nítorí wọn pa mí lára láìnídìí ṣùgbọ́n èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
79 Obraťtež se ke mně, kteříž se bojí tebe, a kteříž znají svědectví tvá.
Kí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ yí padà sí mi, àwọn tí ó ní òye òfin rẹ.
80 Budiž srdce mé upřímé při ustanoveních tvých, tak abych nebyl zahanben.
Jẹ́ kí ọkàn mi wà láìlẹ́bi sí òfin rẹ, kí ojú kí ó má ṣe tì mí.
81 Kaph Touží duše má po spasení tvém, na slovo tvé očekávám.
Ọkàn mi ń fojú ṣọ́nà nítorí ìgbàlà rẹ, ṣùgbọ́n èmi ti fi ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
82 Hynou i oči mé žádostí výmluvností tvých, když říkám: Skoro-liž mne potěšíš?
Ojú mi kùnà, pẹ̀lú wíwo ìpinnu rẹ; èmi wí pé, “Nígbà wo ni ìwọ yóò tù mí nínú?”
83 Ačkoli jsem jako nádoba kožená v dymu, na ustanovení tvá však jsem nezapomenul.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi dàbí awọ-wáìnì lójú èéfín, èmi kò gbàgbé ìlànà rẹ.
84 Mnoho-liž bude dní služebníka tvého? Skoro-liž soud vykonáš nad těmi, kteříž mi protivenství činí?
Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe dúró pẹ́ tó? Nígbà wo ni ìwọ yóò bá àwọn tí ń ṣe inúnibíni sí mi wí?
85 Vykopali mi pyšní jámy, kterážto věc není podlé zákona tvého.
Àwọn agbéraga wa ihò ìṣubú fún mi, tí ó lòdì sí òfin rẹ.
86 Všecka přikázaní tvá jsou pravda; bez příčiny mi se protiví, spomoziž mi.
Gbogbo àṣẹ rẹ yẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé; ràn mí lọ́wọ́, nítorí ènìyàn ń ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí.
87 Téměřť jsou mne již v nic obrátili na zemi, já jsem však neopustil přikázaní tvých.
Wọ́n fẹ́rẹ pa mí rẹ́ kúrò nínú ayé, ṣùgbọ́n èmi kò kọ ẹ̀kọ́ rẹ.
88 Podlé milosrdenství svého obživ mne, abych ostříhal svědectví úst tvých.
Pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ, èmi yóò sì gba ẹ̀rí ẹnu rẹ̀ gbọ́.
89 Lamed Na věky, ó Hospodine, slovo tvé trvánlivé jest v nebesích.
Ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa, títí láé ni; ó dúró ṣinṣin ní ọ̀run.
90 Od národu do pronárodu pravda tvá, utvrdil jsi zemi, a tak stojí.
Òtítọ́ rẹ̀ ń lọ dé gbogbo ìran dé ìran; ìwọ ti dá ayé, ó sì dúró ṣinṣin.
91 Vedlé úsudků tvých stojí to vše do dnešního dne, všecko to zajisté jsou služebníci tvoji.
Òfin rẹ dúró di òní nítorí ohun gbogbo ń sìn ọ́.
92 Byť zákon tvůj nebyl mé potěšení, dávno bych byl zahynul v svém trápení.
Bí òfin rẹ̀ kò bá jẹ́ dídùn inú mi, èmi ìbá ti ṣègbé nínú ìpọ́njú mi.
93 Na věky se nezapomenu na rozkazy tvé; jimi zajisté obživil jsi mne.
Èmi kì yóò gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ láé, nítorí nípa wọn ni ìwọ ti pa ayé mi mọ́.
94 Tvůjť jsem já, zachovávejž mne; nebo přikázaní tvá zpytuji.
Gbà mí, nítorí èmi jẹ́ tìrẹ èmi ti wá ẹ̀kọ́ rẹ.
95 Očekávajíť na mne bezbožní, aby mne zahubili, já pak svědectví tvá rozvažuji.
Àwọn ẹni búburú dúró láti pa mí run, ṣùgbọ́n èmi yóò kíyèsi ẹ̀rí rẹ.
96 Každé věci dokonalé vidím skončení; rozkaz tvůj jest přeširoký náramně.
Sí ohun pípé gbogbo èmi ti rí òpin; ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ aláìlópin ni.
97 Mem Ó jak miluji zákon tvůj, tak že každého dne on jest mé přemyšlování.
Báwo ni èmi ti fẹ́ òfin rẹ tó! Èmi ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ pípẹ́ wá.
98 Nad nepřátely mé moudřejšího mne činíš přikázaními svými; nebo mám je ustavičně před sebou.
Àṣẹ rẹ mú mi gbọ́n ju àwọn ọ̀tá mi lọ, nítorí wọ́n wà pẹ̀lú mi láé.
99 Nade všecky své učitele rozumnější jsem učiněn; nebo svědectví tvá jsou má přemyšlování.
Èmi ní iyè inú ju gbogbo olùkọ́ mi lọ, nítorí èmi ń ṣe àṣàrò nínú òfin rẹ.
100 I nad starce opatrnější jsem, nebo přikázaní tvých ostříhám.
Èmi ni òye ju àwọn àgbà lọ, nítorí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ.
101 Od každé cesty zlé zdržuji nohy své, abych ostříhal slova tvého.
Èmi ti pa ẹsẹ̀ mi mọ́ nínú gbogbo ọ̀nà ibi nítorí kí èmi lè gba ọ̀rọ̀ rẹ.
102 Od soudů tvých se neodvracuji, proto že ty mne vyučuješ.
Èmi kò yà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ìwọ fúnra rẹ̀ ni ó kọ́ mi.
103 Ó jak jsou sladké dásním mým výmluvnosti tvé, nad med ústům mým.
Báwo ni ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣe dùn mọ́ mi lẹ́nu tó, ó dùn ju oyin lọ ní ẹnu mi!
104 Z přikázaní tvých rozumnosti jsem nabyl, a protož všeliké cesty bludné nenávidím.
Èmi rí òye gbà nínú ẹ̀kọ́ rẹ; nítorí náà èmi kórìíra gbogbo ọ̀nà tí kò tọ́.
105 Nun Svíce nohám mým jest slovo tvé, a světlo stezce mé.
Ọ̀rọ̀ rẹ ni fìtílà sí ẹsẹ̀ mi àti ìmọ́lẹ̀ sí ipa ọ̀nà mi.
106 Přisáhl jsem, což i splním, že chci ostříhati soudů spravedlnosti tvé.
Èmi ti ṣe ìbúra èmi sì ti tẹnumọ́ ọn wí pé èmi yóò máa tẹ̀lé òfin òdodo rẹ.
107 Ztrápenýť jsem přenáramně, Hospodine, obživiž mne vedlé slova svého.
A pọ́n mi lójú gidigidi; Olúwa, sọ mi di ààyè, gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ rẹ
108 Dobrovolné oběti úst mých, žádám, oblib, Hospodine, a právům svým vyuč mne.
Olúwa, gba ìyìn àtinúwá ẹnu mi, kí o sì kọ́ mi ní òfin rẹ̀.
109 Duše má jest v ustavičném nebezpečenství, a však na zákon tvůj se nezapomínám.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé mi wà ni ọwọ́ mi nígbà gbogbo, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
110 Polékli jsou mi bezbožní osídlo, ale já od rozkazů tvých se neodvracím.
Àwọn ẹni búburú ti dẹ okùn sílẹ̀ fún mi, ṣùgbọ́n èmi kò ṣìnà kúrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
111 Za dědictví věčné ujal jsem svědectví tvá, neboť jsou radost srdce mého.
Òfin rẹ ni ogún mi láéláé; àwọn ni ayọ̀ ọkàn mi.
112 Naklonil jsem srdce svého k vykonávání ustanovení tvých ustavičně, až i do konce.
Ọkàn mi ti lé pípa òfin rẹ mọ́ láé dé òpin.
113 Samech Výmyslků nenávidím, zákon pak tvůj miluji.
Èmi kórìíra àwọn ọlọ́kàn méjì, ṣùgbọ́n èmi fẹ́ òfin rẹ.
114 Skrýše má a pavéza má ty jsi, na slovo tvé očekávám.
Ìwọ ni ààbò mi àti asà mi; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
115 Odstuptež ode mne nešlechetníci, abych ostříhal přikázaní Boha svého.
Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin olùṣe búburú, kí èmi lè pa àṣẹ Ọlọ́run mi mọ́!
116 Zdržujž mne podlé slova svého, tak abych živ byl, a nezahanbuj mne v mém očekávání.
Gbé mi sókè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, kí èmi kí ó lè yè Má sì jẹ́ kí ojú ìrètí mi kí ó tì mí.
117 Posiluj mne, abych zachován byl, a patřil k ustanovením tvým ustavičně.
Gbé mi sókè, èmí yóò sì wa láìléwu; nígbà gbogbo ni èmi yóò máa júbà òfin rẹ.
118 Potlačuješ všecky ty, kteříž odstupují od ustanovení tvých; neboť jest lživá opatrnost jejich.
Ìwọ kọ gbogbo àwọn tí ó ṣìnà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ẹ̀tàn wọn asán ni.
119 Jako trůsku odmítáš všecky bezbožníky země, a protož miluji svědectví tvá.
Gbogbo àwọn ẹni búburú ní ayé ni ìwọ yọ kúrò bí i ìdàrọ́; nítorí náà, èmi fẹ́ òfin rẹ̀.
120 Děsí se strachem před tebou tělo mé; nebo soudů tvých bojím se.
Ara mi wárìrì ní ìbẹ̀rù nítorí rẹ̀: èmi dúró ní ìbẹ̀rù òfin rẹ.
121 Ajin Činím soud a spravedlnost, nevydávejž mne mým násilníkům.
Èmi ti ṣe ohun tí i ṣe òdodo àti ẹ̀tọ́: má ṣe fi mí sílẹ̀ fún àwọn tó ń ni mí lára.
122 Zastup sám služebníka svého k dobrému, tak aby mne pyšní nepotlačili.
Mú kí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ dájú: má ṣe jẹ́ kí àwọn agbéraga ni mi lára.
123 Oči mé hynou čekáním na spasení tvé, a na výmluvnost spravedlnosti tvé.
Ojú mi kùnà, fún wíwo ìgbàlà rẹ, fún wíwo ìpinnu òdodo rẹ.
124 Nalož s služebníkem svým vedlé milosrdenství svého, a ustanovením svým vyuč mne.
Ṣe pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí dídúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ kí o sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
125 Služebník tvůj jsem já, dejž mi rozumnost, abych uměl svědectví tvá.
Èmi ni ìránṣẹ́ rẹ; ẹ fún mi ní òye kí èmi lè ní òye òfin rẹ
126 Časť jest, abys se přičinil, Hospodine; zrušili zákon tvůj.
Ó tó àsìkò fún ọ láti ṣe iṣẹ́, Olúwa; nítorí òfin rẹ ti fọ́.
127 Z té příčiny miluji přikázaní tvá více nežli zlato, i to, kteréž jest nejlepší.
Nítorí èmi fẹ́ràn àṣẹ rẹ ju wúrà, àní ju wúrà dídára lọ,
128 A proto, že všecky rozkazy tvé o všech věcech pravé býti poznávám, všeliké stezky bludné nenávidím.
nítorí èmi kíyèsi gbogbo ẹ̀kọ́ òtítọ́ rẹ̀, èmi kórìíra gbogbo ipa ọ̀nà búburú.
129 Pe Předivnáť jsou svědectví tvá, a protož jich ostříhá duše má.
Òfin rẹ̀ ìyanu ni: nítorí náà èmi gbà wọ́n gbọ́.
130 Začátek učení tvého osvěcuje, a vyučuje sprostné rozumnosti.
Ìṣípayá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú ìmọ́lẹ̀ wá; ó fi òye fún àwọn òpè.
131 Ústa svá otvírám, a dychtím, nebo přikázaní tvých jsem žádostiv.
Èmi ya ẹnu mi mo sì mí hẹlẹ, nítorí èmi fojú ṣọ́nà sí àṣẹ rẹ.
132 Popatřiž na mne, a smiluj se nade mnou podlé práva těch, kteříž milují jméno tvé.
Yí padà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi, bí ìwọ ṣe máa ń ṣe nígbà gbogbo sí àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ.
133 Kroky mé utvrzuj v slovu svém, a nedej, aby nade mnou panovati měla jaká nepravost.
Fi ìṣísẹ̀ mi múlẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ rẹ, má ṣe jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ borí mi.
134 Vysvoboď mne z nátisků lidských, abych ostříhal rozkazů tvých.
Rà mí padà lọ́wọ́ aninilára ènìyàn, kí èmi lè gbọ́ ẹ̀kọ́ rẹ.
135 Zasvěť tvář svou nad služebníkem svým, a ustanovením svým vyuč mne.
Jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tàn sí ìránṣẹ́ rẹ lára kí ó sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
136 Potůčkové vod vyplývají z očí mých příčinou těch, kteříž neostříhají zákona tvého.
Omijé sàn jáde ní ojú mi, nítorí wọn kò gba pé òfin rẹ̀ jẹ́ òtítọ́.
137 Tsade Spravedlivý jsi, Hospodine, a upřímý v soudech svých.
Olódodo ni ìwọ Olúwa ìdájọ́ rẹ sì dúró ṣinṣin.
138 Ty jsi vydal spravedlivá svědectví svá, a vší víry hodná.
Òfin ti ìwọ gbé kalẹ̀ jẹ́ òdodo: wọ́n yẹ ni ìgbẹ́kẹ̀lé.
139 Až svadnu, tak horlím, že se zapomínají na slovo tvé nepřátelé moji.
Ìtara mi ti pa mí run, nítorí àwọn ọ̀tá mi fi ojú fo ọ̀rọ̀ rẹ dá.
140 Zprubovanáť jest řeč tvá dokonale, tou příčinou ji miluje služebník tvůj.
Wọ́n ti dán ìpinnu rẹ wò pátápátá ìránṣẹ́ rẹ sì fẹ́ràn wọ́n.
141 Maličký a opovržený jsem já, však na rozkazy tvé se nezapomínám.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti ẹni ẹ̀gàn èmi kò ni gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ.
142 Spravedlnost tvá jest spravedlnost věčná, a zákon tvůj pravda.
Òdodo rẹ wà títí láé òtítọ́ ni òfin rẹ̀.
143 Ssoužení a nátisk mne stihají, přikázaní tvá jsou mé rozkoše.
Ìyọnu àti ìpọ́njú wá sórí mi, ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ ni inú dídùn mi.
144 Spravedlnost svědectví tvých trvá na věky; dej mi z ní rozumnosti nabýti, tak abych živ býti mohl.
Òfin rẹ jẹ́ òtítọ́ láé; fún mi ní òye kí èmi lè yè.
145 Koph Z celého srdce volám, vyslyšiž mne, ó Hospodine, abych ostříhal ustanovení tvých.
Èmi kígbe pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: dá mi lóhùn Olúwa, èmi yóò sì gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
146 K tobě volám, vysvoboď mne, abych šetřil svědectví tvých.
Èmi kígbe pè ọ́; gbà mí èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́.
147 Předstihám svitání a volám, na tvéť slovo očekávám.
Èmi dìde ṣáájú àfẹ̀mọ́júmọ́ èmi ké fún ìrànlọ́wọ́; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
148 Předstihají oči mé bdění proto, abych přemýšlel o výmluvnostech tvých.
Ojú mi ṣáájú ìṣọ́ òru, nítorí kí èmi lè ṣe àṣàrò nínú ọ̀rọ̀ rẹ.
149 Hlas můj slyš podlé svého milosrdenství, Hospodine, podlé soudů svých obživ mne.
Gbọ́ ohùn mi ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ìfẹ́ rẹ: pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
150 Přibližují se následovníci nešlechetnosti, ti, kteříž se od zákona tvého vzdálili.
Àwọn tí ń gbìmọ̀ ìlànà búburú wà ní tòsí, ṣùgbọ́n wọ́n jìnnà sí òfin rẹ.
151 Ty blíže jsi, Hospodine; nebo všecka přikázaní tvá jsou pravda.
Síbẹ̀ ìwọ wà ní tòsí, Olúwa, àti gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òtítọ́.
152 Jižť to dávno vím o svědectvích tvých, že jsi je stvrdil až na věky.
Láti ọjọ́ pípẹ́ wá èmi ti kọ́ nínú òfin rẹ tí ìwọ ti fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé.
153 Reš Popatřiž na mé trápení, a vysvoboď mne; neboť se na zákon tvůj nezapomínám.
Wo ìpọ́njú mi kí o sì gbà mí, nítorí èmi kò gbàgbé òfin rẹ.
154 Zasaď se o mou při, a ochraň mne; pro řeč svou obživ mne.
Gba ẹjọ́ mi rò kí o sì rà mí padà; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
155 Dalekoť jest od bezbožných spasení, nebo nedotazují se na ustanovení tvá.
Ìgbàlà jìnnà sí àwọn ẹni búburú nítorí wọn kò wá àṣẹ rẹ.
156 Slitování tvá mnohá jsou, Hospodine; podlé soudů svých obživ mne.
Ìyọ́nú rẹ̀ tóbi, Olúwa; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
157 Jakžkoli jsou mnozí protivníci moji a nepřátelé moji, však od svědectví tvých se neuchyluji.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn ọ̀tá tí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí mi, ṣùgbọ́n èmi kò tí ì yípadà kúrò nínú òfin rẹ.
158 Viděl jsem ty, kteříž se převráceně měli, velmi to těžce nesa, že řeči tvé neostříhali.
Èmi wo àwọn ẹlẹ́tàn, inú mi sì bàjẹ́ nítorí wọn kò gba ọ̀rọ̀ rẹ gbọ́.
159 Popatřiž, žeť rozkazy tvé miluji, Hospodine; podlé milosrdenství svého obživ mne.
Wo bí èmi ṣe fẹ́ràn ẹ̀kọ́ rẹ; pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ.
160 Nejpřednější věc slova tvého jest pravda, a na věky trvá všeliký úsudek spravedlnosti tvé.
Òtítọ́ ni gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ; gbogbo òfin òdodo rẹ láéláé ni.
161 Šin Knížata mi se protiví bez příčiny, však slova tvého děsí se srdce mé.
Àwọn alákòóso ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí, ṣùgbọ́n ọkàn mi wárìrì sí ọ̀rọ̀ rẹ.
162 Já raduji se z řeči tvé tak jako ten, kterýž dochází hojné kořisti.
Èmi yọ̀ nínú ìpinnu rẹ bí ẹni tí ó rí ìkógun púpọ̀.
163 Falše pak nenávidím, a jí v ohavnosti mám; zákon tvůj miluji.
Èmi kórìíra mo sì kọ èké ṣíṣe ṣùgbọ́n mo fẹ́ràn òfin rẹ.
164 Sedmkrát za den chválím tě z soudů tvých spravedlivých.
Èmi yìn ọ́ ní ìgbà méje lójúmọ́ nítorí òfin òdodo rẹ.
165 Pokoj mnohý těm, kteříž milují zákon tvůj, a nemají žádné urážky.
Àlàáfíà púpọ̀ wà fún àwọn tí ó ní ìfẹ́ sí òfin rẹ, kò sì ṣí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ̀.
166 Očekávám na spasení tvé, Hospodine, a přikázaní tvá vykonávám.
Èmi yóò dúró de ìgbàlà rẹ, Olúwa, èmi yóò sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ.
167 Ostříhá duše má svědectví tvých, nebo je velice miluji.
Èmi gba òfin rẹ gbọ́, nítorí mo fẹ́ràn wọn púpọ̀púpọ̀.
168 Ostříhám rozkazů tvých a svědectví tvých; nebo všecky cesty mé jsou před tebou.
Èmi ṣe ìgbọ́ràn sí ẹ̀kọ́ rẹ àti òfin rẹ, nítorí ìwọ mọ gbogbo ọ̀nà mi.
169 Thav Předstupiž úpění mé před oblíčej tvůj, Hospodine, a podlé slova svého uděl mi rozumnosti.
Jẹ́ kí igbe mi wá sí iwájú rẹ, Olúwa; fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
170 Vejdiž pokorná prosba má před tvář tvou, a vedlé řeči své vytrhni mne.
Jẹ́ kí ẹ̀bẹ̀ mi wá sí iwájú rẹ; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
171 I vynesou rtové moji chválu, když ty mne vyučíš ustanovením svým.
Ètè mi yóò sọ ìyìn jáde, nítorí ìwọ kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
172 Zpívati bude i jazyk můj slovo tvé, a že všecka přikázaní tvá jsou spravedlnost.
Jẹ́ kí ahọ́n mi kọ orin ọ̀rọ̀ rẹ, nítorí gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òdodo.
173 Budiž mi ku pomoci ruka tvá; neboť jsem sobě zvolil přikázaní tvá.
Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣetán láti ràn mí lọ́wọ́, nítorí èmi ti yan ẹ̀kọ́ rẹ.
174 Toužím po spasení tvém, Hospodine, a zákon tvůj jest rozkoš má.
Èmi wo ọ̀nà fún ìgbàlà rẹ, Olúwa, àti òfin rẹ jẹ́ dídùn inú mi.
175 Živa bude duše má, a bude tě chváliti, a soudové tvoji budou mi na pomoc.
Jẹ́ kí èmi wà láààyè ki èmi lè yìn ọ́, kí o sì jẹ́ kí òfin rẹ mú mi dúró.
176 Bloudím jako ovce ztracená, hledejž služebníka svého, neboť se na přikázaní tvá nezapomínám.
Èmí ti ṣìnà bí àgùntàn tí ó sọnù. Wá ìránṣẹ́ rẹ, nítorí èmi kò gbàgbé àṣẹ rẹ.

< Žalmy 119 >